-
Jésù Mú Àsọtẹ́lẹ̀ Àìsáyà ṢẹJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
Bíbélì sọ pé: “Wò ó! Ìránṣẹ́ mi tí mo yàn, àyànfẹ́ mi, ẹni tí mo tẹ́wọ́ gbà! Màá fi ẹ̀mí mi sára rẹ̀, ó sì máa jẹ́ kí ìdájọ́ òdodo ṣe kedere sí àwọn orílẹ̀-èdè. Kò ní jiyàn, kò ní pariwo, ẹnikẹ́ni ò sì ní gbọ́ ohùn rẹ̀ láwọn ọ̀nà tó wà ní gbangba. Kò ní fọ́ esùsú kankan tó ti ṣẹ́, kò sì ní pa òwú àtùpà kankan tó ń jó lọ́úlọ́ú, tí wọ́n fi ọ̀gbọ̀ ṣe, títí ó fi máa ṣe ìdájọ́ òdodo láṣeyọrí. Ní tòótọ́, àwọn orílẹ̀-èdè máa ní ìrètí nínú orúkọ rẹ̀.”—Mátíù 12:18-21; Àìsáyà 42:1-4.
-
-
Jésù Mú Àsọtẹ́lẹ̀ Àìsáyà ṢẹJésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
-
-
Kí ló túmọ̀ sí pé “kò ní jiyàn, kò ní pariwo, ẹnikẹ́ni ò sì ní gbọ́ ohùn rẹ̀ láwọn ọ̀nà tó wà ní gbangba”? Tí Jésù bá wo àwọn èèyàn sàn, kì í jẹ́ káwọn tó wò sàn tàbí àwọn ẹ̀mí èṣù “jẹ́ kí àwọn èèyàn mọ òun.” (Máàkù 3:12) Ìdí sì ni pé bí ìròyìn òkèèrè ò bá lé, ńṣe ló máa ń dín, kò sì fẹ́ kó jẹ́ pé ohun tí kì í ṣe òótọ́ làwọn èèyàn á gbọ́ nípa òun.
-