-
“Àwọn Olódodo Yóò Máa Tàn Yòò Bí Oòrùn”Ilé Ìṣọ́—2010 | March 15
-
-
3. Ṣàlàyé ìṣòro tó dojú kọ ọkùnrin inú àpèjúwe yìí àti bó ṣe pinnu láti yanjú ìṣòro náà.
3 Àpèjúwe náà rèé: “Ìjọba ọ̀run wá dà bí ọkùnrin kan tí ó fún irúgbìn àtàtà sínú pápá rẹ̀. Nígbà tí àwọn ènìyàn ń sùn, ọ̀tá rẹ̀ wá, ó sì tún fún àwọn èpò sí àárín àlìkámà náà, ó sì lọ. Nígbà tí ewé ọ̀gbìn náà rú jáde, tí ó sì mú èso jáde, nígbà náà ni àwọn èpò fara hàn pẹ̀lú. Nítorí náà, àwọn ẹrú baálé ilé náà wá, wọ́n sì wí fún un pé, ‘Ọ̀gá, kì í ha ṣe irúgbìn àtàtà ni ìwọ fún sínú pápá rẹ? Nígbà náà, báwo ni ó ṣe wá ní àwọn èpò?’ Ó wí fún wọn pé, ‘Ọ̀tá kan, ọkùnrin kan, ni ó ṣe èyí.’ Wọ́n wí fún un pé, ‘Ìwọ ha fẹ́ kí àwa, nígbà náà, jáde lọ kí a sì kó wọn jọ?’ Ó wí pé, ‘Ó tì o; kí ó má bàa jẹ́ pé nípa èèṣì, nígbà tí ẹ bá ń kó àwọn èpò jọ, ẹ óò hú àlìkámà pẹ̀lú wọn. Ẹ jẹ́ kí àwọn méjèèjì dàgbà pa pọ̀ títí di ìkórè; ní àsìkò ìkórè, ṣe ni èmi yóò sì sọ fún àwọn akárúgbìn pé, Ẹ kọ́kọ́ kó àwọn èpò jọ, kí ẹ sì dì wọ́n ní ìdìpọ̀-ìdìpọ̀ láti sun wọ́n, lẹ́yìn náà ẹ lọ kó àlìkámà jọ sínú ilé ìtọ́jú nǹkan pa mọ́ mi.’”—Mát. 13:24-30.
-
-
“Àwọn Olódodo Yóò Máa Tàn Yòò Bí Oòrùn”Ilé Ìṣọ́—2010 | March 15
-
-
3. Ṣàlàyé ìṣòro tó dojú kọ ọkùnrin inú àpèjúwe yìí àti bó ṣe pinnu láti yanjú ìṣòro náà.
3 Àpèjúwe náà rèé: “Ìjọba ọ̀run wá dà bí ọkùnrin kan tí ó fún irúgbìn àtàtà sínú pápá rẹ̀. Nígbà tí àwọn ènìyàn ń sùn, ọ̀tá rẹ̀ wá, ó sì tún fún àwọn èpò sí àárín àlìkámà náà, ó sì lọ. Nígbà tí ewé ọ̀gbìn náà rú jáde, tí ó sì mú èso jáde, nígbà náà ni àwọn èpò fara hàn pẹ̀lú. Nítorí náà, àwọn ẹrú baálé ilé náà wá, wọ́n sì wí fún un pé, ‘Ọ̀gá, kì í ha ṣe irúgbìn àtàtà ni ìwọ fún sínú pápá rẹ? Nígbà náà, báwo ni ó ṣe wá ní àwọn èpò?’ Ó wí fún wọn pé, ‘Ọ̀tá kan, ọkùnrin kan, ni ó ṣe èyí.’ Wọ́n wí fún un pé, ‘Ìwọ ha fẹ́ kí àwa, nígbà náà, jáde lọ kí a sì kó wọn jọ?’ Ó wí pé, ‘Ó tì o; kí ó má bàa jẹ́ pé nípa èèṣì, nígbà tí ẹ bá ń kó àwọn èpò jọ, ẹ óò hú àlìkámà pẹ̀lú wọn. Ẹ jẹ́ kí àwọn méjèèjì dàgbà pa pọ̀ títí di ìkórè; ní àsìkò ìkórè, ṣe ni èmi yóò sì sọ fún àwọn akárúgbìn pé, Ẹ kọ́kọ́ kó àwọn èpò jọ, kí ẹ sì dì wọ́n ní ìdìpọ̀-ìdìpọ̀ láti sun wọ́n, lẹ́yìn náà ẹ lọ kó àlìkámà jọ sínú ilé ìtọ́jú nǹkan pa mọ́ mi.’”—Mát. 13:24-30.
-