-
“Ènìyàn Mìíràn Kò Tíì Sọ̀rọ̀ Báyìí R픓Máa Tọ̀ Mí Lẹ́yìn”
-
-
ORÍ KỌKÀNLÁ
“Ènìyàn Mìíràn Kò Tíì Sọ̀rọ̀ Báyìí Rí”
1, 2. (a) Kí nìdí táwọn ọlọ́pàá tí wọ́n rán pé kí wọ́n lọ mú Jésù wá fi padà lọ́wọ́ òfo? (b) Kí nìdí tí Jésù fi jẹ́ olùkọ́ tó ju olùkọ́ lọ?
INÚ ń bí àwọn Farisí burúkú burúkú. Jésù sì wà nínú tẹ́ńpìlì tó ń kọ́ àwọn èèyàn nípa Bàbá rẹ̀. Èrò àwọn tó ń gbọ́rọ̀ Jésù yàtọ̀ síra; èyí tó pọ̀ lára wọn ló gba Jésù gbọ́, àwọn míì sì ń fẹ́ kí wọ́n fi àṣẹ ọba mú un. Nítorí pé àwọn aṣáájú ìsìn ò lè mú ìbínú wọn mọ́ra mọ́, wọ́n ní káwọn ọlọ́pàá lọ mú Jésù wá. Àmọ́ ọwọ́ òfo làwọn ọlọ́pàá náà padà dé. Olórí àlùfáà àtàwọn Farisí bi wọ́n pé: “Èé ṣe tí ẹ kò fi mú un wá?” Èsì àwọn ọlọ́pàá náà ni pé: “Ènìyàn mìíràn kò tíì sọ̀rọ̀ báyìí rí.” Ọ̀rọ̀ Jésù wọ̀ wọ́n lọ́kàn débi pé kò wù wọ́n láti fi àṣẹ ọba mú un.a—Jòhánù 7:45, 46.
-
-
“Ènìyàn Mìíràn Kò Tíì Sọ̀rọ̀ Báyìí R픓Máa Tọ̀ Mí Lẹ́yìn”
-
-
a Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé àwọn Sànhẹ́dírìn àtàwọn olórí àlùfáà làwọn ọlọ́pàá náà ń ṣiṣẹ́ fún.
-