-
Ète Jèhófà Ń Ṣàṣeyọrí OlógoJọ́sìn Ọlọ́run Tòótọ́ Kan Ṣoṣo Náà
-
-
Àgbàyanu Òmìnira Ń Bẹ Níwájú
11. Àgbàyanu òmìnira wo làwọn tó bá la ìpọ́njú ńlá já yóò gbádùn?
11 Lẹ́yìn tí ìpọ́njú ńlá pẹ̀lú Amágẹ́dọ́nì tó máa fòpin sí i bá ti gbá ìwà ibi kúrò lórí ilẹ̀ ayé, Sátánì Èṣù kò tún ní jẹ́ “ọlọ́run ètò àwọn nǹkan yìí” mọ́. Kò ní sí pé àwọn olùjọsìn Jèhófà yóò tún máa fara da ipa búburú ti Sátánì mọ́. (2 Kọ́ríńtì 4:4; Ìṣípayá 20:1, 2) Ìsìn èké kò tún ní parọ́ mọ́ Jèhófà mọ́, kò sì ní í jẹ́ ipa tó ń pín àwùjọ ẹ̀dá ènìyàn níyà mọ́. Kò ní sí pé à ń rẹ́ àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run tòótọ́ jẹ mọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn aláṣẹ ayé kò sì ní kó wọn nífà mọ́. Ẹ ò rí i pé àgbàyanu òmìnira la óò gbádùn!
12. Báwo ni gbogbo èèyàn yóò ṣe bọ́ lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti àwọn ipa tó ń ní?
12 Gẹ́gẹ́ bí “Ọ̀dọ́ Àgùntàn Ọlọ́run, tí ó kó ẹ̀ṣẹ̀ ayé lọ,” Jésù yóò lo ìtóye ẹbọ rẹ̀ láti mú ẹ̀ṣẹ̀ aráyé kúrò. (Jòhánù 1:29) Nígbà tí Jésù wà lórí ilẹ̀ ayé, tó dárí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnì kan jì í, ó mú ẹni yẹn lára dá gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí ìdáríjì náà. (Mátíù 9:1-7; 15:30, 31) Bákan náà, gẹ́gẹ́ bí Ọba Ìjọba Ọlọ́run, Kristi Jésù yóò wo àwọn afọ́jú, àwọn odi, àwọn adití, àwọn arọ, àwọn wèrè àtàwọn tó ní àwọn àìsàn èyíkéyìí mìíràn sàn lọ́nà ìyanu. (Ìṣípayá 21:3, 4) Gbogbo àwọn onígbọràn ni yóò bọ́ lọ́wọ́ “òfin ẹ̀ṣẹ̀” kí èrò inú àti ìṣe wọn lè máa múnú tiwọn àti ti Ọlọ́run dùn. (Róòmù 7:21-23) Ní òpin Ẹgbẹ̀rúndún náà, a ó ti mú wọn wá sí ìjẹ́pípé ẹ̀dá ènìyàn, ní ‘àwòrán àti ìrí’ Ọlọ́run tòótọ́ kan ṣoṣo náà.—Jẹ́nẹ́sísì 1:26.
13. Ní òpin Ẹgbẹ̀rúndún Ìṣàkóso náà, kí ni Kristi yóò ṣe, kí ni yóò sì yọrí sí?
13 Nígbà tí Kristi bá ti gbé ìran ènìyàn dé ìjẹ́pípé, yóò wá dá ọlá àṣẹ tí a fún un láti fi ṣe iṣẹ́ yìí padà fún Baba: “[Yóò] . . . fi ìjọba lé Ọlọ́run àti Baba rẹ̀ lọ́wọ́, nígbà tí ó bá ti sọ gbogbo ìjọba àti gbogbo ọlá àṣẹ àti agbára di asán. Nítorí ó ní láti ṣàkóso gẹ́gẹ́ bí ọba títí Ọlọ́run yóò fi fi gbogbo àwọn ọ̀tá sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.” (1 Kọ́ríńtì 15:24, 25) Ìṣàkóso Ẹgbẹ̀rúndún Ìjọba náà yóò ti mú ète tó wà fún ṣẹ ní kíkún; nítorí náà a ò tún ní í nílò àkóso amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ kankan láti wà láàárín Jèhófà àti ìran ènìyàn mọ́. Níwọ̀n bí a ó ti mú ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú kúrò pátápátá nígbà yẹn, tí a ó sì ti ra ènìyàn padà, jíjẹ́ tí Jésù jẹ́ Olùtúnniràpadà dópin nìyẹn. Bíbélì ṣàlàyé pé: “Nígbà náà ni Ọmọ fúnra rẹ̀ pẹ̀lú yóò fi ara rẹ̀ sábẹ́ Ẹni tí ó fi ohun gbogbo sábẹ́ rẹ̀, kí Ọlọ́run lè jẹ́ ohun gbogbo fún olúkúlùkù.”—1 Kọ́ríńtì 15:28.
14. Kí la ó ṣe fún gbogbo ẹ̀dá ènìyàn pípé, èé sì ti ṣe?
14 Lẹ́yìn èyí, a óò fún àwọn ẹ̀dá ènìyàn pípé láǹfààní láti fi hàn pé Ọlọ́run tòótọ́ kan ṣoṣo náà làwọn yàn láti sìn títí láé. Nítorí náà, kí Jèhófà tóó tẹ́wọ́ gbà wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọmọ rẹ̀, yóò ṣe ìdánwò ìkẹyìn fún gbogbo ẹ̀dá ènìyàn pípé. A óò tú Sátánì àtàwọn ẹ̀mí èṣù rẹ̀ kúrò nínú ọ̀gbun àìnísàlẹ̀. Èyí kò ní fa ìpalára tó máa wà pẹ́ títí fáwọn tó dìídì nífẹ̀ẹ́ Jèhófà. Ṣùgbọ́n àwọn tó bá fi àìṣòótọ́ gbà kí a mú àwọn ṣàìgbọràn sí Jèhófà yóò pa run títí láé, pa pọ̀ pẹ̀lú ọlọ̀tẹ̀ láéláé nì àtàwọn ẹ̀mí èṣù rẹ̀.—Ìṣípayá 20:7-10.
15. Ipò wo ni yóò tún padà wà láàárín gbogbo àwọn ẹ̀dá onílàákàyè tí Jèhófà dá?
15 Gbogbo ẹ̀dá ènìyàn pípé tó bá rọ̀ mọ́ ipò Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí ọba aláṣẹ ní àkókò ìdánwò ìkẹyìn yẹn ni Jèhófà yóò wá tẹ́wọ́ gba pé wọ́n jẹ́ ọmọ òun. Láti àkókò yẹn lọ, wọ́n á gbádùn òmìnira ológo ti àwọn ọmọ Ọlọ́run dé ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ gẹ́gẹ́ bí apá kan ìdílé àgbáyé ti Ọlọ́run. Gbogbo ẹ̀dá onílàákàyè ní ọ̀run àti lórí ilẹ̀ ayé yóò tún wà ní ìṣọ̀kan nínú jíjọ́sìn Ọlọ́run tòótọ́ kan ṣoṣo náà lẹ́ẹ̀kan sí i. Ète Jèhófà yóò ti ṣàṣeyọrí ológo nígbà yẹn! Ṣé o fẹ́ wà lára ìdílé àgbáyé tó jẹ́ aláyọ̀, tó sì máa wà títí láé yẹn? Tó bá rí bẹ́ẹ̀, a rọ̀ ọ́ láti kọbi ara sí ohun tí Bíbélì sọ nínú 1 Jòhánù 2:17 pé: “Ayé ń kọjá lọ, bẹ́ẹ̀ sì ni ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run ni yóò dúró títí láé.”
-
-
Ète Jèhófà Ń Ṣàṣeyọrí OlógoJọ́sìn Ọlọ́run Tòótọ́ Kan Ṣoṣo Náà
-
-
Àgbàyanu Òmìnira Ń Bẹ Níwájú
11. Àgbàyanu òmìnira wo làwọn tó bá la ìpọ́njú ńlá já yóò gbádùn?
11 Lẹ́yìn tí ìpọ́njú ńlá pẹ̀lú Amágẹ́dọ́nì tó máa fòpin sí i bá ti gbá ìwà ibi kúrò lórí ilẹ̀ ayé, Sátánì Èṣù kò tún ní jẹ́ “ọlọ́run ètò àwọn nǹkan yìí” mọ́. Kò ní sí pé àwọn olùjọsìn Jèhófà yóò tún máa fara da ipa búburú ti Sátánì mọ́. (2 Kọ́ríńtì 4:4; Ìṣípayá 20:1, 2) Ìsìn èké kò tún ní parọ́ mọ́ Jèhófà mọ́, kò sì ní í jẹ́ ipa tó ń pín àwùjọ ẹ̀dá ènìyàn níyà mọ́. Kò ní sí pé à ń rẹ́ àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run tòótọ́ jẹ mọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn aláṣẹ ayé kò sì ní kó wọn nífà mọ́. Ẹ ò rí i pé àgbàyanu òmìnira la óò gbádùn!
12. Báwo ni gbogbo èèyàn yóò ṣe bọ́ lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti àwọn ipa tó ń ní?
12 Gẹ́gẹ́ bí “Ọ̀dọ́ Àgùntàn Ọlọ́run, tí ó kó ẹ̀ṣẹ̀ ayé lọ,” Jésù yóò lo ìtóye ẹbọ rẹ̀ láti mú ẹ̀ṣẹ̀ aráyé kúrò. (Jòhánù 1:29) Nígbà tí Jésù wà lórí ilẹ̀ ayé, tó dárí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnì kan jì í, ó mú ẹni yẹn lára dá gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí ìdáríjì náà. (Mátíù 9:1-7; 15:30, 31) Bákan náà, gẹ́gẹ́ bí Ọba Ìjọba Ọlọ́run, Kristi Jésù yóò wo àwọn afọ́jú, àwọn odi, àwọn adití, àwọn arọ, àwọn wèrè àtàwọn tó ní àwọn àìsàn èyíkéyìí mìíràn sàn lọ́nà ìyanu. (Ìṣípayá 21:3, 4) Gbogbo àwọn onígbọràn ni yóò bọ́ lọ́wọ́ “òfin ẹ̀ṣẹ̀” kí èrò inú àti ìṣe wọn lè máa múnú tiwọn àti ti Ọlọ́run dùn. (Róòmù 7:21-23) Ní òpin Ẹgbẹ̀rúndún náà, a ó ti mú wọn wá sí ìjẹ́pípé ẹ̀dá ènìyàn, ní ‘àwòrán àti ìrí’ Ọlọ́run tòótọ́ kan ṣoṣo náà.—Jẹ́nẹ́sísì 1:26.
13. Ní òpin Ẹgbẹ̀rúndún Ìṣàkóso náà, kí ni Kristi yóò ṣe, kí ni yóò sì yọrí sí?
13 Nígbà tí Kristi bá ti gbé ìran ènìyàn dé ìjẹ́pípé, yóò wá dá ọlá àṣẹ tí a fún un láti fi ṣe iṣẹ́ yìí padà fún Baba: “[Yóò] . . . fi ìjọba lé Ọlọ́run àti Baba rẹ̀ lọ́wọ́, nígbà tí ó bá ti sọ gbogbo ìjọba àti gbogbo ọlá àṣẹ àti agbára di asán. Nítorí ó ní láti ṣàkóso gẹ́gẹ́ bí ọba títí Ọlọ́run yóò fi fi gbogbo àwọn ọ̀tá sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.” (1 Kọ́ríńtì 15:24, 25) Ìṣàkóso Ẹgbẹ̀rúndún Ìjọba náà yóò ti mú ète tó wà fún ṣẹ ní kíkún; nítorí náà a ò tún ní í nílò àkóso amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ kankan láti wà láàárín Jèhófà àti ìran ènìyàn mọ́. Níwọ̀n bí a ó ti mú ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú kúrò pátápátá nígbà yẹn, tí a ó sì ti ra ènìyàn padà, jíjẹ́ tí Jésù jẹ́ Olùtúnniràpadà dópin nìyẹn. Bíbélì ṣàlàyé pé: “Nígbà náà ni Ọmọ fúnra rẹ̀ pẹ̀lú yóò fi ara rẹ̀ sábẹ́ Ẹni tí ó fi ohun gbogbo sábẹ́ rẹ̀, kí Ọlọ́run lè jẹ́ ohun gbogbo fún olúkúlùkù.”—1 Kọ́ríńtì 15:28.
14. Kí la ó ṣe fún gbogbo ẹ̀dá ènìyàn pípé, èé sì ti ṣe?
14 Lẹ́yìn èyí, a óò fún àwọn ẹ̀dá ènìyàn pípé láǹfààní láti fi hàn pé Ọlọ́run tòótọ́ kan ṣoṣo náà làwọn yàn láti sìn títí láé. Nítorí náà, kí Jèhófà tóó tẹ́wọ́ gbà wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọmọ rẹ̀, yóò ṣe ìdánwò ìkẹyìn fún gbogbo ẹ̀dá ènìyàn pípé. A óò tú Sátánì àtàwọn ẹ̀mí èṣù rẹ̀ kúrò nínú ọ̀gbun àìnísàlẹ̀. Èyí kò ní fa ìpalára tó máa wà pẹ́ títí fáwọn tó dìídì nífẹ̀ẹ́ Jèhófà. Ṣùgbọ́n àwọn tó bá fi àìṣòótọ́ gbà kí a mú àwọn ṣàìgbọràn sí Jèhófà yóò pa run títí láé, pa pọ̀ pẹ̀lú ọlọ̀tẹ̀ láéláé nì àtàwọn ẹ̀mí èṣù rẹ̀.—Ìṣípayá 20:7-10.
15. Ipò wo ni yóò tún padà wà láàárín gbogbo àwọn ẹ̀dá onílàákàyè tí Jèhófà dá?
15 Gbogbo ẹ̀dá ènìyàn pípé tó bá rọ̀ mọ́ ipò Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí ọba aláṣẹ ní àkókò ìdánwò ìkẹyìn yẹn ni Jèhófà yóò wá tẹ́wọ́ gba pé wọ́n jẹ́ ọmọ òun. Láti àkókò yẹn lọ, wọ́n á gbádùn òmìnira ológo ti àwọn ọmọ Ọlọ́run dé ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ gẹ́gẹ́ bí apá kan ìdílé àgbáyé ti Ọlọ́run. Gbogbo ẹ̀dá onílàákàyè ní ọ̀run àti lórí ilẹ̀ ayé yóò tún wà ní ìṣọ̀kan nínú jíjọ́sìn Ọlọ́run tòótọ́ kan ṣoṣo náà lẹ́ẹ̀kan sí i. Ète Jèhófà yóò ti ṣàṣeyọrí ológo nígbà yẹn! Ṣé o fẹ́ wà lára ìdílé àgbáyé tó jẹ́ aláyọ̀, tó sì máa wà títí láé yẹn? Tó bá rí bẹ́ẹ̀, a rọ̀ ọ́ láti kọbi ara sí ohun tí Bíbélì sọ nínú 1 Jòhánù 2:17 pé: “Ayé ń kọjá lọ, bẹ́ẹ̀ sì ni ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run ni yóò dúró títí láé.”
-