-
Mímọyì Ipa Tó Ṣàrà Ọ̀tọ̀ Tí Jésù Kó Nínú Mímú Ìfẹ́ Ọlọ́run ṢẹIlé Ìṣọ́—2008 | December 15
-
-
“Àlùfáà Àgbà”
15. Báwo ni ipa tí Jésù kó gẹ́gẹ́ bí Àlùfáà Àgbà ṣe yàtọ̀ sí ti gbogbo àwọn èèyàn tó ti ṣe àlùfáà àgbà rí?
15 Ọ̀pọ̀ èèyàn ló ti ṣe àlùfáà àgbà rí, àmọ́ ká sòótọ́, ipa tí Jésù kó gẹ́gẹ́ bí Àlùfáà Àgbà tún ṣàrà ọ̀tọ̀. Báwo ló ṣe rí bẹ́ẹ̀? Pọ́ọ̀lù ṣàlàyé pé: “Òun kò nílò láti máa rú àwọn ẹbọ lójoojúmọ́, lákọ̀ọ́kọ́ fún àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tirẹ̀ àti lẹ́yìn náà fún ti àwọn ènìyàn, gẹ́gẹ́ bí àlùfáà àgbà wọnnì ti ń ṣe: (nítorí èyí ni ó ṣe lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo láìtún tún un ṣe mọ́ láé nígbà tó fi ara rẹ̀ rúbọ;) nítorí tí Òfin ń yan àwọn ènìyàn tí wọ́n ní àìlera sípò gẹ́gẹ́ bí àlùfáà àgbà, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ìbúra tí a ṣe tí ó wá lẹ́yìn Òfin yan Ọmọ sípò, ẹni tí a sọ di pípé títí láé.”—Héb. 7: 27, 28.b
16. Kí nìdí tí ẹbọ tí Jésù rú fi ṣàrà ọ̀tọ̀ lóòótọ́?
16 Ẹni pípé ni Jésù, bẹ́ẹ̀ náà sì ni Ádámù kó tó dẹ́ṣẹ̀. (1 Kọ́r. 15:45) Torí náà, Jésù nìkan ni èèyàn tó lè rú ẹbọ pípé, tí kò kù síbì kan, ìyẹn ẹbọ tí kò nílò àtúnṣe. Ojoojúmọ́ làwọn èèyàn máa ń rúbọ, nígbà tí wọ́n ń tẹ̀ lé Òfin Mósè. Òjìji sì ni gbogbo ẹbọ tí wọn ń rú wọ̀nyẹn àtàwọn iṣẹ́ táwọn àlùfáà ń ṣe jẹ́ fún àwọn nǹkan ti Jésù máa ṣe láṣeparí. (Héb. 8:5; 10:1) Torí náà, ipa tí Jésù kó gẹ́gẹ́ bí Àlùfáà Àgbà ṣàrà ọ̀tọ̀ ní ti pé ohun tó ṣe láṣeparí pọ̀ ju tàwọn àlùfáà àgbà yòókù lọ àti pé kò tún ní tún un ṣe mọ́.
-
-
Mímọyì Ipa Tó Ṣàrà Ọ̀tọ̀ Tí Jésù Kó Nínú Mímú Ìfẹ́ Ọlọ́run ṢẹIlé Ìṣọ́—2008 | December 15
-
-
b Ọ̀mọ̀wé kan tó ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì sọ pé, ọ̀rọ̀ tá a tú sí “lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo láìtún tún un ṣe mọ́ láé” jẹ́ ká mọ òótọ́ kan tó ṣe pàtàkì látinú Bíbélì, ìyẹn ni pé “òótọ́ ni Kristi kú, ikú ẹ̀ ṣàrà ọ̀tọ̀, ẹ̀ẹ̀kan ṣoṣo ló sì kú.”
-