-
A Lè Borí Àdánwò Èyíkéyìí!Ilé Ìṣọ́—2005 | June 15
-
-
Bíbélì sọ pé àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run yóò “bá onírúurú àdánwò pàdé.” (Jákọ́bù 1:2) Kíyè sí ọ̀rọ̀ náà “onírúurú” tá a fi tú ọ̀rọ̀ Gíríìkì náà, poi·kiʹlos. Tá a bá wo bí wọ́n ṣe ń lo ọ̀rọ̀ Gíríìkì yìí láyé ọjọ́un, ohun tó túmọ̀ sí ni “onírúurú nǹkan” tàbí “onírúurú àwọ̀,” ó sì jẹ́ ọ̀rọ̀ tá a fi ń mọ̀ pé ‘àdánwò náà pín sí onírúurú ẹ̀ka.’ Nípa bẹ́ẹ̀, tá a bá sọ pé “onírúurú àdánwò” ó túmọ̀ sí pé àwọn àdánwò náà pín sí oríṣiríṣi ọ̀nà. Bó sì ti wù kó rí, Jèhófà máa ń ràn wá lọ́wọ́ láti borí wọn níkọ̀ọ̀kan. Kí ló mú èyí dá wa lójú?
-
-
A Lè Borí Àdánwò Èyíkéyìí!Ilé Ìṣọ́—2005 | June 15
-
-
Bẹ́ẹ̀ ni o, àdánwò tàbí ìṣòro yòówù ká ní, inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Ọlọ́run yóò jẹ́ ká lè borí wọn. (Jákọ́bù 1:17) Ìrànlọ́wọ́ tó máa ń bọ́ sákòókò tó sì máa ń bá a mu gẹ́ẹ́ tí Jèhófà ń ṣe fáwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ láìka bí ìṣòro tàbí àdánwò wọn ṣe pọ̀ tó jẹ́ ọ̀kan lára ọ̀nà tí Ọlọ́run gbà ń lo “ọ̀pọ̀ oríṣiríṣi ọgbọ́n” rẹ̀. (Éfésù 3:10) Ǹjẹ́ o ò gbà bẹ́ẹ̀?
-