-
Ìfaradà—Ṣekókó fún Àwọn KristianIlé-Ìṣọ́nà—1993 | September 15
-
-
Ìfaradà—Ṣekókó fún Àwọn Kristian
‘Ẹ fi ìfaradà kún ìgbàgbọ́ yín.’—2 PETERU 1:5, 6, NW.
1, 2. Èéṣe tí gbogbo wa fi níláti faradà á títí dé òpin?
ALÁBÒÓJÚTÓ arìnrìn-àjò àti aya rẹ̀ ń ṣèbẹ̀wò sọ́dọ̀ Kristian ẹlẹgbẹ́ wọn kan tí ó wà nínú àwọn àádọ́rùn-ún ọ̀dún rẹ̀. Ó ti lo ọ̀pọ̀ ẹ̀wádún nínú iṣẹ́-òjíṣẹ́ alákòókò kíkún. Bí wọ́n ti ń sọ̀rọ̀, arákùnrin àgbàlagbà náà ronú padà sẹ́yìn nípa díẹ̀ lára àwọn àǹfààní tí ó ti gbádùn la àwọn ọdún já. “Ṣùgbọ́n,” ni ó fi ìbànújẹ́ sọ bí omijé ti bẹ̀rẹ̀ síí ṣàn sílẹ̀ ní ojú rẹ̀, “nísinsìnyí èmi kò lè ṣe púpọ̀ nínú ohunkóhun mọ́.” Alábòójútó arìnrìn-àjò náà ṣí Bibeli rẹ̀ ó sì ka Matteu 24:13, níbi tí a ti ṣàyọlò ọ̀rọ̀ Jesu Kristi tí ó sọ pé: “Ẹni tí ó bá forítì í títí dé òpin, òun náà ni a ó gbàlà.” Lẹ́yìn náà ni alábòójútó náà wo arákùnrin ọ̀wọ́n náà tí ó sì wí pé: “Iṣẹ́ àyànfúnni tí ó gbẹ̀yìn tí gbogbo wa ní, láìka bí èyí tí a lè ṣe ti pọ̀ tàbí kéré tó, ni láti faradà títí dé òpin.”
2 Bẹ́ẹ̀ni, gẹ́gẹ́ bíi Kristian gbogbo wa gbọdọ̀ faradà títí dé òpin ètò-ìgbékalẹ̀ àwọn nǹkan yìí tàbí dé òpin ìwàláàyè wa. Kò sí ọ̀nà mìíràn tí a lè gbà jèrè ìtẹ́wọ́gbà Jehofa fún ìgbàlà. A wà nínú eré-ìje kan fún ìyè, a sì gbọ́dọ̀ “fi ìfaradà sáré” títí di ìgbà tí a bá tó kọjá ìlà ìparí. (Heberu 12:1, NW) Aposteli Peteru tẹnumọ́ ìjẹ́pàtàkì ànímọ́ yìí nígbà tí ó rọ àwọn Kristian ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ pé: ‘Ẹ fi ìfaradà kún ìgbàgbọ́ yín.’ (2 Peteru 1:5, 6, NW) Ṣùgbọ́n kí ni ìfaradà níti gàsíkíyá?
Ìfaradà—Ohun Tí Ó Túmọ̀sí
3, 4. Kí ni ó túmọ̀sí láti faradà?
3 Kí ni ó túmọ̀sí láti faradà? Ọ̀rọ̀ Griki náà fún “faradà” (hy·po·meʹno) lóréfèé túmọ̀sí “dúró títílọ tàbí wà lábẹ́.” Ó farahàn ní ìgbà mẹ́tàdínlógún nínú Bibeli. Gẹ́gẹ́ bí olùṣètumọ̀-èdè W. Baner, F. W. Gingrich, àti F. Danker ti wí, ó túmọ̀sí “dúró títílọ dípò sísá fún . . . , mú ìdúró ẹni, báa lọ ní kíkojú.” Ọ̀rọ̀-orúkọ Griki náà fún “ìfaradà” (hy·po·mo·neʹ) farahàn ní ìgbà tí ó ju ọgbọ̀n lọ. Nípa rẹ̀, A New Testament Wordbook, láti ọwọ́ William Barclay, sọ pé: “Ó jẹ́ ẹ̀mí náà tí ó lè fàyà rán àwọn nǹkan, kìí wulẹ̀ ṣe pẹ̀lú yíyọwọ́yọsẹ̀, ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrètí gbígbóná janjan . . . Ó jẹ́ ànímọ́ kan èyí tí ń mú ọkùnrin kan dúró ní ìdojúkọ atẹ́gùn. Ó jẹ́ agbára ìtóye náà tí ó lè yí ìrísí àdánwò lílekoko jùlọ padà sí ògo nítorí pé rékọjá ìrora ó ń rí góńgó náà.”
4 Ìfaradà, nígbà náà, ń mú kí ó ṣeéṣe fún wa láti mú ìdúró wa kí á má sì sọ ìrètí nù ní ojú ìdènà tàbí ìnira. (Romu 5:3-5) Ó ń wo góńgó náà—ẹ̀bùn-eré-ìje, tàbí ẹ̀bùn, ti ìyè ayérayé, yálà ní ọ̀run tàbí lórí ilẹ̀-ayé rékọjá ìrora ti ìsinsìnyí.—Jakọbu 1:12.
Ìfaradà—Èéṣe?
5. (a) Èéṣe tí gbogbo àwọn Kristian fi “nílò ìfaradà”? (b) Sí àwọn ìsọ̀rí méjì wo ni a lè pín àwọn àdánwò wa sí?
5 Gẹ́gẹ́ bíi Kristian, gbogbo wa “nílò ìfaradà.” (Heberu 10:36, NW) Èéṣe? Ní ìpìlẹ̀ nítorí pé a ń “bọ́ sínú onírúurú ìdánwò.” Ọ̀rọ̀ ẹsẹ-ìwé èdè Griki níhìn-ín ní Jakọbu 1:2 dámọ̀ràn ìbápàdé tí a kò retí tẹ́lẹ̀ tàbí èyí tí a kò tẹ́wọ́gbà, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí adigunjalè bá ko ẹnìkan lójú. (Fiwé Luku 10:30.) A ń ṣalábàápàdé àwọn àdánwò tí a lè pín sí ìsọ̀rí méjì: ìwọnnì tí ó wọ́pọ̀ fún àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ìyọrísí ẹ̀ṣẹ̀ tí a ti jogúnbá, àti ìwọnnì tí ó gbèrú nítorí ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run wa. (1 Korinti 10:13; 2 Timoteu 3:12) Kí ni díẹ̀ nínú àwọn àdánwò wọ̀nyí?
6. Báwo ni Ẹlẹ́rìí kan ṣe faradà nígbà tí ó ní àmódi onírora kan?
6 Àmódi líléwu. Bíi ti Timoteu, àwọn Kristian kan gbọ́dọ̀ farada “àìlera . . . ìgbàkúùgbà.” (1 Timoteu 5:23) Ní pàtàkì nígbà tí a bá dojúkọ àmódi tí kò sàn bọ̀rọ̀, bóyá tí ó kún fún ìrora gan-an, ni àìní wà fún wa láti lo ìfaradà, láti mú ìdúró wa, pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Ọlọrun kí á má sì ṣe gbàgbé ìrètí Kristian wa. Gbé àpẹẹrẹ Ẹlẹ́rìí kan tí ó wà ní ìbẹ̀rẹ̀ àwọn àádọ́ta ọdún rẹ̀ yẹ̀wò ẹni tí ó wọ ṣòkòtò kan-náà pẹ̀lú kókó-ọlọ́yún aburúbògìrì tí ń yára dàgbà kan. La iṣẹ́-abẹ méjì kọjá ó ń báa lọ ní dídúró gbọnyingbọnyin nínú ìgbèròpinnu rẹ̀ láti máṣe gba ìfàjẹ̀sínilára. (Iṣe 15:28, 29) Ṣùgbọ́n kókó-ọlọ́yún náà tún padà farahàn ní abonú rẹ̀ ó sì bẹ̀rẹ̀ síí dàgbà lọ sí ìtòsí ògóóró ẹ̀yìn rẹ̀. Bí ó ti ń ṣe bẹ́ẹ̀, ó ń nírìírí ìrora ti ara tí kò ṣeéronúwòye tí kò sí iye ìtọ́jú ìṣègùn tí ó lè mú un rẹlẹ̀. Síbẹ̀, rékọjá ìrora ìsinsìnyí ó ń wo ẹ̀bùn ìyè nínú ayé titun náà. Ó ń báa lọ láti ṣàjọpín ìrètí rẹ̀ gbígbóná janjan pẹ̀lú àwọn dókítà, nọ́ọ̀sì, àti àwọn olùbẹ̀wò. Ó faradà á títí dé òpin—òpin ìwàláàyè rẹ̀. Ìṣòro ìlera rẹ lè má jẹ̀ èyí tí ń halẹ̀ mọ́ ìwàláàyè tàbí kún fún ìrora tó èyí tí arákùnrin ọ̀wọ́n yẹn nírìírí rẹ̀, ṣùgbọ́n ó ṣì lè gbé ìdánwò ìfaradà ńláǹlà ka iwájú rẹ.
7. Irú ìrora wo ni ìfaradà ní nínú fún díẹ̀ lára àwọn arákùnrin àti arábìnrin wa tẹ̀mí?
7 Ìrora ti èrò-ìmọ̀lára. Láti ìgbà dé ìgbà, díẹ̀ lára àwọn ènìyàn Jehofa ń fàyàrán “ìbìnújẹ́ àyà” tí ń yọrísí ‘ọkàn tí a mú rẹ̀wẹ̀sì.’ (Owe 15:13) Ìsoríkọ́ mímúná kò ṣàìwọ́pọ̀ ní “ìgbà ewu” wọ̀nyí. (2 Timoteu 3:1) Ìwé-ìròyìn Science News ti December 5, 1992, róyìn pé: “Iye ìsoríkọ́ mímúná, tí ó sábà máa ń dánilọ́wọ́kọ́ ti pọ̀ síi nínú ìran àtẹ̀lé kọ̀ọ̀kan tí a ń bí láti 1915 wá.” Àwọn okùnfà irú ìkárísọ bẹ́ẹ̀ yàtọ̀ síra, láti orí àwọn okùnfà ìṣiṣẹ́-ara sí àwọn ìrírí ríronilára tí kò gbádùnmọ́ni. Fún àwọn Kristian kan, ìfaradà wémọ́ ìjàkadì ojoojúmọ́ láti mú ìdúró wọn lójú èrò-ìmọ̀lára. Síbẹ̀, wọn kò jọ̀gọ̀nù. Wọ́n dúró gẹ́gẹ́ bí olùṣòtítọ́ sí Jehofa láìka àwọn omijé náà sí.—Fiwé Orin Dafidi 126:5, 6.
8. Àdánwò ìṣúnná-owó wo ni a lè ṣalábàápàdé?
8 Àwọn onírúurú àdánwò tí a ń bá pàdé lè ní ìnira ìṣúnná-owó lílekoko nínú. Nígbà tí arákùnrin kan ní New Jersey, U.S.A., dédé bá araarẹ̀ nípò àìníṣẹ́lọ́wọ́, òun lọ́nà tí ó yéni ṣàníyàn nípa bíbọ́ ìdílé rẹ̀ àti láti máṣe di ẹni tí a gba ilé rẹ̀ mọ́ lọ́wọ́. Bí ó ti wù kí ó rí, òun kò gbàgbé ìrètí Ìjọba náà. Nígbà tí ó ń wá iṣẹ́ mìíràn, ó lo àǹfààní náà láti ṣiṣẹ́sìn gẹ́gẹ́ bí aṣáájú-ọ̀nà olùrànlọ́wọ́. Àsẹ̀yìnwá-àsẹ̀yìnbọ̀, ó ríṣẹ́.—Matteu 6:25-34.
9. (a) Báwo ni àdánù olólùfẹ́ kan nínú ikú ṣe lè béèrè fún ìfaradà? (b) Àwọn ẹsẹ ìwé mímọ́ wo ni ó fihàn pé kò lódì láti sun ẹkún ìbànújẹ́?
9 Bí o bá ti nírìíri ìpàdánù olólùfẹ́ kan nínú ikú, ìwọ nílò ìfaradà tí ó wà fún ìgbà pípẹ́ lẹ́yìn tí àwọn wọnnì tí wọ́n yí ọ ká bá ti padà sẹ́nu iṣẹ́ ojoojúmọ́ wọn. Ìwọ tilẹ̀ lè rí i pé a máa ṣòro ní pàtàkì fún ọ lọ́dọọdún ní nǹkan bí àkókò tí olólùfẹ́ rẹ yẹn kú. Fífarada irú àdánù bẹ́ẹ̀ kò túmọ̀sí pé kò tọ̀nà láti sọkún ìbànújẹ́. Ó bá ìwà-ẹ̀dá mu láti ṣọ̀fọ̀ ikú ẹnìkan tí a fẹ́ràn, èyí kò sì fi àìní ìgbàgbọ́ nínú ìrètí àjíǹde hàn rárá. (Genesisi 23:2; fiwé Heberu 11:19.) Jesu “sọkún” lẹ́yìn tí Lasaru kú, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Òun ti fi ìgboyà sọ fun Marta pé: “Arákùnrin rẹ yóò jíǹde.” Lasaru sì jíǹde nítòótọ́!—Johannu 11:23, 32-35, 41-44.
10. Èéṣe tí àwọn ènìyàn Jehofa fi ní àìní aláìlẹ́gbẹ́ fún ìfaradà?
10 Ní àfikún sí fífarada àwọn àdánwò tí ó wọ́pọ̀ fún gbogbo ènìyàn, àwọn ènìyàn Jehofa ní àìní aláìlẹ́gbẹ́ fún ìfaradà. “A ó sì kórìíra yín lọ́dọ̀ gbogbo orílẹ̀-èdè nítorí orúkọ mi,” ni Jesu kìlọ̀. (Matteu 24:9) Ó tún sọ pé: “Bí wọ́n bá ti ṣe inúnibíni sí mi, wọn ó ṣe inúnibíni sí yín pẹ̀lú.” (Johannu 15:20) Èrèdí gbogbo ìkórìíra àti inúnibíni náà? Ìdí ni pé láìka ibi yòówù tí a ń gbé lórí ilẹ̀-ayé yìí gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ Ọlọrun sí, Satani ń gbìyànjú láti ba ìwàtítọ́ wa sí Jehofa jẹ́. (1 Peteru 5:8; fiwé Ìfihàn 12:17.) Nítorí ìdí èyí Satani ti sábà máa ń fẹ́ná mọ́ inúnibíni, ní fífi ìfaradà wa sínú ìdánwò mímúná.
11, 12. (a) Àwọn Ẹlẹ́rìí Jehofa àti àwọn ọmọ wọn dojúkọ ìdánwò ìfaradà wo ni àwọn ọdún 1930 àti ìbẹ̀rẹ̀ àwọn ọdún 1940? (b) Èéṣe tí àwọn Ẹlẹ́rìí Jehofa kò fi kí ohun ìṣàpẹẹrẹ orílẹ̀-èdè?
11 Fún àpẹẹrẹ, ní àwọn ọdún 1930 àti ìbẹ̀rẹ̀ àwọn ọdún 1940, àwọn Ẹlẹ́rìí Jehofa àti àwọn ọmọ wọn ní United States àti Canada di àyànṣojú fún inúnibíni nítorí pé wọ́n kò kí ohun ìṣàpẹẹrẹ orílẹ̀-èdè nítorí ìdí tí ó jẹ́ ti ẹ̀rí-ọkàn. Àwọn Ẹlẹ́rìí ń bọ̀wọ̀ fún ohun ìṣàpẹẹrẹ ti ó jẹ́ ti orílẹ̀-èdè tí wọ́n ń gbé nínú rẹ̀, ṣùgbọ́n wọ́n hùwà ní ìbámu pẹ̀lú ìlànà tí a là kalẹ̀ nínú Òfin Ọlọrun ní Eksodu 20:4, 5 pé: “Ìwọ kò gbọ́dọ̀ yá ère fún ara rẹ, tàbí àwòrán ohun kan tí ń bẹ lókè ọ̀run, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ ni ìsàlẹ̀ ilẹ̀, tàbí ti ohun kan tí ń bẹ nínú omi ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀. Ìwọ kò gbọ́dọ̀ tẹ orí ara rẹ ba fún wọn, bẹ́ẹ̀ni ìwọ kò gbọ́dọ̀ sìn wọ́n: nítorí èmi ni OLUWA Ọlọrun rẹ, Ọlọrun owú ni mí.” Nígbà tí a lé àwọn ọmọ ilé-ẹ̀kọ́ díẹ̀ tí wọ́n jẹ́ Ẹlẹ́rìí jáde kúrò nítorí pé wọ́n fẹ́ láti darí ìjọsìn wọn sí Jehofa Ọlọrun nìkanṣoṣo, àwọn Ẹlẹ́rìí náà dá àwọn Ilé-Ẹ̀kọ́ Ìjọba sílẹ̀ fún ìtọ́ni wọn. Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ wọ̀nyí padà sí àwọn ilé-ẹ̀kọ́ gbogbogbòò nígbà tí Ilé-Ẹjọ́ Gíga Jùlọ ti United States mọ ipò wọn tí ó jẹ́ ti ìsìn ní àmọ̀jẹ́wọ́, gẹ́gẹ́ bí àwọn orílẹ̀-èdè tí ó lajú ti ń ṣe lónìí. Bí ó ti wù kí ó rí, ìfaradà onígboyà ti àwọn ọ̀dọ́langba wọ̀nyí ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ dídára tayọ pàápàá jùlọ fún àwọn èwe tí wọ́n jẹ́ Kristian tí wọ́n lè dojúkọ ìfiniṣẹlẹ́yà nísinsìnyí nítorí pé wọ́n sakun láti gbé ní ìbámu pẹ̀lú àwọn ọ̀pá-ìdiwọ̀n Bibeli.—1 Johannu 5:21.
12 Àwọn onírúurú àdánwò tí a ń ṣalábàápàdé—àwọn wọnnì tí ó wọ́pọ̀ fún àwọn ènìyàn àti àwọn wọnnì tí a ń dojúkọ nítorí ìgbàgbọ́ Kristian wa—fi ìdí tí a fi nílò ìfaradà hàn. Ṣùgbọ́n báwo ni a ṣe lè faradà?
Faradà Títí Dé Òpin—Báwo?
13. Báwo ni Jehofa ṣe ń pèsè ìfaradà?
13 Àwọn ènìyàn Ọlọrun ní àǹfààní pàtó kan lórí àwọn wọnnì tí wọn kò jọ́sìn Jehofa. Fún ìrànlọ́wọ́, a lè fọ̀ràn lọ “Ọlọrun tí ń fúnni ní ìfaradà.” (Romu 15:5, NW) Báwo, nígbà náà, ni Jehofa ṣe ń fúnni ní ìfaradà? Ọ̀nà kan tí ó ń gbà ṣe bẹ́ẹ̀ ni nípasẹ̀ àwọn àpẹẹrẹ ìfaradà tí a kọsílẹ̀ nínú Ọ̀rọ̀ rẹ̀, Bibeli. (Romu 15:4) Bí a ti ń ronú lórí ìwọ̀nyí, kìí ṣe kìkì pé a fún wa níṣìírí láti faradà nìkan ni ṣùgbọ́n a tún kẹ́kọ̀ọ́ ohun púpọ̀ síi nípa bí a ṣe lè faradà. Gbé àwọn àpẹẹrẹ títayọ méjì yẹ̀wò—ìfaradà onígboyà ti Jobu àti ìfaradà aláìlábùkù ti Jesu Kristi.—Heberu 12:1-3; Jakọbu 5:11.
14, 15. (a) Àwọn àdánwò wo ni Jobu faradà? (b) Báwo ni ó ṣe ṣeéṣe fún Jobu láti farada àwọn àdánwò tí ó dojúkọ?
14 Àwọn ipò wo ni ó fi ìfaradà Jobu sínú ìdánwò? Ó jìyà ìnira ìṣúnná-owó nígbà tí ó pàdánù ọ̀pọ̀ jùlọ nínú àwọn ohun-ìní rẹ̀. (Jobu 1:14-17; fiwé Jobu 1:3.) Jobu mọ ìrora àdánù náà lára nígbà tí ìjì-ẹ̀fúùfù pa gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ mẹ́wẹ̀ẹ̀wá. (Jobu 1:18-21) Ó nírìírí àmódi líléwu, tí ó kún fún ìrora gidigidi. (Jobu 2:7, 8; 7:4, 5) Aya òun fúnraarẹ̀ yọ ọ́ lẹ́nu láìsinmi láti yípadà kúrò lọ́dọ̀ Ọlọrun. (Jobu 2:9) Àwọn alábàákẹ́gbẹ́ tímọ́tímọ́ sọ àwọn ohun tí ó jẹ́ èyí tí ń baninínújẹ́, aláìnínúure, àti aláìjóòótọ́. (Fiwé Jobu 16:1-3 àti Jobu 42:7.) Là gbogbo èyí já, bí ó ti wù kí ó rí, Jobu mú ìdúró rẹ̀, ní pípa ìwàtítọ́ mọ́. (Jobu 27:5) Àwọn ohun tí ó faradà dọ́gba pẹ̀lú àwọn àdánwò tí àwọn ènìyàn Jehofa ń bá pàdé lónìí.
15 Báwo ni Jobu ṣe lè farada gbogbo àdánwò wọ̀nyí? Ohun kan ní pàtàkì tí ó gbé Jobu ró ni ìrètí. “Ìrètí wà fún igi pàápàá,” ni ó polongo. “Bí a bá ké e lulẹ̀, yóò tún rú lẹ́ẹ̀kan síi, èéhù-ẹ̀ka rẹ̀ fúnraarẹ̀ kì yóò sì dáwọ́ dúró láti wà.” (Jobu 14:7, NW) Ìrètí wo ni Jobu ní? Gẹ́gẹ́ bi a ti ṣàkíyèsí rẹ̀ ní àwọn ẹsẹ díẹ̀ lẹ́yìn náà, ó sọ pé: “Bí ọkùnrin abarapá kan bá kú òun ha lè wàláàyè lẹ́ẹ̀kan síi bí? . . . Ìwọ yóò pè, èmi fúnraàmi yóò sì dá ọ lóhùn. Nítorí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ ni ìwọ yóò ṣàfẹ́rí [tàbí, yánhànhàn fún].” (Jobu 14:14, 15, NW) Bẹ́ẹ̀ni, Jobu ríran rékọjá ìrora rẹ̀ ti lọ́ọ́lọ́ọ́. Ó mọ̀ pé àwọn àdánwò òun kì yóò wà títí láé. Pátápinrá rẹ̀ òun yóò níláti faradà títí dé ojú ikú. Ìfojúsọ́nà rẹ̀ tí ó kún fún ìrètí ni pé Jehofa, ẹni tí ó fi tìfẹ́tìfẹ́ nífẹ̀ẹ́-ọkàn láti jí àwọn òkú dìde, yóò mú òun padà wá sí ìyè.—Iṣe 24:15.
16. (a) Ẹ̀kọ́ wo ni a kọ́ nípa ìfaradà láti inú àpẹẹrẹ Jobu? (b) Báwo ni ìrètí Ìjọba náà ṣe gbọ́dọ̀ jẹ́ gidi sí wa tó, èésìtiṣe?
16 Kí ni a kọ́ láti inú ìfaradà Jobu? Láti faradà dé òpin, a kò gbọ́dọ̀ gbàgbé ìrètí wa. Rántí, pẹ̀lú, pé ìdánilójú ìrètí Ìjọba náà túmọ̀sí pé ìjìyà èyíkéyìí tí a bá ṣalábàápàdé wà “fún ìgbà kúkúrú” ní ìfiwéra. (2 Korinti 4:16-18) Ìrètí wa ṣíṣeyebíye lọ́nà tí kò lè yẹsẹ̀ ni a gbé karí ìlérí Jehofa nípa àkókò kan ní ọjọ́-ọ̀la tí kò jìnnà nígbà tí “[oun] yóò . . . nu omijé gbogbo nù kúrò ní ojú [wa]; kì yóò sì sí ikú mọ́, tàbí ọ̀fọ̀, tàbí ẹkún, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò sí ìrora mọ́.” (Ìfihàn 21:3, 4) Ìrètí yẹn, èyí tí “kìí . . . sinni lọ sí ìjákulẹ̀,” gbọ́dọ̀ ṣọ́ ìrònú wa. (Romu 5:4, 5, NW; 1 Tessalonika 5:8) Ó gbọ́dọ̀ jẹ́ gidi sí wa—kí ó jẹ́ gidi gan-an débi pé nípasẹ̀ ojú ìgbàgbọ́, a lè yàwòrán araawa pé a wà nínú ayé titun—láì wọ̀jàkadì pẹ̀lú àmódi àti ìsoríkọ́ mọ́ ṣùgbọ́n tí a ń jí lójoojúmọ́ pẹ̀lú ìlera dídára àti pẹ̀lú èrò-inú ṣíṣe kedere; láì tún ṣàníyàn nípa àwọn ìkìmọ́lẹ̀ ìṣúnná-owó líléwu mọ́ ṣùgbọ́n gbígbé nínú àìléwu; kò sí ṣíṣọ̀fọ̀ ikú àwọn olólùfẹ́ mọ́ ṣùgbọ́n nínírìírí ayọ̀-amóríyá ti rírí i tí a ń jí wọn dìde. (Heberu 11:1) Láìsí irú ìrètí bẹ́ẹ̀ a lè bò wá mọ́lẹ̀ búrúbúrú nípasẹ̀ àwọn àdánwò wa ti lọ́ọ́lọ́ọ́ débi pé a lè juwọ́sílẹ̀. Pẹ̀lú ìrètí wa, irú ìṣírí gígadabú wo ni a ní láti máa báa lọ ní jíjà, láti máa báa lọ ní fífaradà títí dé òpin!
17. (a) Àwọn àdánwò wo ni Jesu faradà? (b) Ìjìyà mímúná tí Jesu faradà ni ó ṣeéṣe kí á rí láti inú òtítọ́ wo? (Wo àkíyèsí ẹsẹ̀-ìwé.)
17 Bibeli rọ̀ wá láti “tẹjúmọ́” Jesu kí á sì ‘gbé e yẹ̀wò kínníkínní.’ Àwọn àdánwó wo ni ó faradà? Díẹ̀ nínú wọn jẹ jáde láti inú ẹ̀ṣẹ̀ àti àìpé àwọn ẹlòmíràn. Jesu farada kìí ṣe “ọ̀rọ̀ òdì . . . láti ẹnu àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀” nìkan ṣùgbọ́n àwọn ìṣòro tí ó dìde láàárín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pẹ̀lú, èyí tí ó ní nínú aáwọ̀ léraléra lórí ẹni tí ó tóbi jùlọ. Ju ìyẹn lọ, ó ṣalábàápàdé ìdánwò ìgbàgbọ́ tí kò lẹ́gbẹ́. Ó “farada òpó-igi ìdálóró.” (Heberu 12:1-3, NW; Luku 9:46; 22:24) Ó ṣòro àní láti ronúwòye ìjìyà ti èrò-orí àti ti ara-ìyára tí ó wémọ́ ìrora ìkànmọ́gi àti ìtìjú jíjẹ́ ẹni ti a fìyà-ikú jẹ gẹ́gẹ́ bí asọ̀rọ̀-òdì.a
18. Gẹ́gẹ́ bí aposteli Paulu ti wí, àwọn nǹkan méjì wo ni ó gbé Jesu ró?
18 Kí ni ó mú kí ó ṣeéṣe fún Jesu láti faradà á títí dé òpin? Aposteli Paulu mẹ́nukan àwọn ohun méjì tí ó gbé Jesu ró: ‘àdúrà-ẹ̀bẹ̀ àti ìbéèrè-ẹ̀bẹ̀’ àti “ayọ̀ tí a gbé ka iwájú rẹ̀” pẹ̀lú. Jesu, Ọmọkùnrin pípé Ọlọrun, ni ojú kò tì láti béèrè fún ìrànlọ́wọ́. Ó gbàdúrà “pẹ̀lú igbe kíkankíkan àti omijé.” (Heberu 5:7; 12:2, NW) Ní pàtàkì nígbà tí ìgbẹ́jọ́ onípò-àjùlọ rẹ̀ ń súnmọ́tòsí ni ó rí i pé ó pọndandan láti gbàdúrà fún okun léraléra àti pẹ̀lú ìfọkànsí. (Luku 22:39-44) Ní ìdáhùnpadà sí àwọn àdúrà-ẹ̀bẹ̀ Jesu, Jehofa kò mú àdánwò náà kúrò, ṣùgbọ́n ó fokun fún Jesu láti faradà á. Jesu tún faradà nítorí pé rékọjá òpó-igi ìdálóró òun wo èrè rẹ̀—ayọ̀ tí òun yóò ní nínú ṣíṣètìlẹ́yìn fún ìsọdimímọ́ orúkọ Jehofa àti ìràpadà ìdílé ènìyàn kúrò lọ́wọ́ ikú.—Matteu 6:9; 20:28.
19, 20. Báwo ni àpẹẹrẹ Jesu ṣe ràn wá lọ́wọ́ láti ní ojú-ìwòye tí ó jẹ́ gidi nípa ohun tí ìfaradà ní nínú?
19 Láti inú àpẹẹrẹ Jesu, a kẹ́kọ̀ọ́ iye àwọn ohun tí ń ràn wá lọ́wọ́ láti ní ojú-ìwòye tí ó jẹ́ gidi nípa ohun tí ìfaradà ní nínú. Ipa-ọ̀nà ìfaradà kìí ṣe ọ̀kan tí ó rọrùn. Bí ó bá ṣòro fún wa láti farada àdánwò kan pàtó, ìtùnú wà nínú mímọ̀ pé ohun kan-náà ni ó jẹ́ òtítọ́ nípa Jesu pàápàá. Láti faradà títí dé òpin, a gbọ́dọ̀ gbàdúrà léraléra fún okun. Nígbà tí a bá wà lábẹ́ àdánwò a lè nímọ̀lára àìtóótun láti gbàdúrà nígbà mìíràn. Ṣùgbọ́n Jehofa ń késí wa láti tú ọkàn-àyà wa jáde fún òun ‘nítorí pé òun ń ṣe ìtọ́jú wa.’ (1 Peteru 5:7) Àti nítorí ohun tí Jehofa fúnraarẹ̀ ti ṣèlérí nínú Ọ̀rọ̀ rẹ̀, òun ti sọ́ di àìgbọdọ̀máṣe fún araarẹ̀ láti pèsè “ọláńlá agbara” fún àwọn wọnnì tí ń képè é ní ìgbàgbọ́.—2 Korinti 4:7-9.
20 Nígbà mìíràn a gbọ́dọ̀ faradà pẹ̀lú omijé. Fún Jesu ìrora òpó-igi ìdálóró fúnraarẹ̀ ni kìí ṣe ìdí fún yíyọ̀. Kàkà bẹ́ẹ̀, ayọ̀ náà wà nínú èrè tí a gbé ka iwájú rẹ̀. Nínú ọ̀ràn tiwa kò ní jẹ́ òtítọ́ gidi kan láti reti pé àwa yóò máa fìgbà gbogbo nímọ̀lára ọ̀yàyà tí a ó sì kúnfáyọ̀ nígbà tí a bá wà lábẹ́ àdánwò. (Fiwé Heberu 12:11.) Nípa wíwo iwájú fún èrè náà, bí ó ti wù kí ó rí, yóò lè ṣeéṣe fún wa láti “ka gbogbo rẹ̀ sí ayọ̀” àní nígbà tí a bá ṣalábàápàdé àwọn ipò tí ń dánniwò jùlọ pàápàá. (Jakọbu 1:2-4; Iṣe 5:41) Ohun tí ó ṣe pàtàkì náà ni pé kí a dúró títílọ láìyẹsẹ̀—àní bí ó bá tilẹ̀ níláti jẹ́ pẹ̀lú omijé pàápàá. Ó ṣetán, Jesu kò sọ pé, ‘Ẹni tí ó bá sun ẹkún tí ó kéré jùlọ ni a ó gbàlà’ ṣùgbọ́n, “Ẹni tí ó bá forítì í títí dé òpin, òun náà ni a ó gbàlà.”—Matteu 24:13.
21. (a) Ní 2 Peteru 1:5, 6 (NW), a rọ̀ wá láti fi kí ni kún ìfaradà wa? (b) Àwọn ìbéèrè wo ni a ó gbéyẹ̀wò nínú ọ̀rọ̀-ẹ̀kọ́ tí ó tẹ̀lé e?
21 Ìfaradà tipa báyìí ṣekókó fún ìgbàlà. Bí ó ti wù kí ó rí, ní 2 Peteru 1:5, 6, a rọ̀ wá láti fi ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run kún ìfaradà wa. Kí ni ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run? Báwo ni ó ṣe tan mọ́ ìfaradà, báwo sì ni iwọ ṣe lè ní in? Àwọn ìbéèrè wọ̀nyí ni a ó gbéyẹ̀wò nínú ọ̀rọ̀-ẹ̀kọ́ tí ó tẹ̀lé e.
[Àwọ̀n Àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé]
a Ìjìyà mímúná tí Jesu faradà ní ó ṣeéṣe kí a rí láti inú òtítọ́ náà pé ẹ̀yà-ara-ẹ̀dá pípé rẹ̀ kú lẹ́yìn kìkì ìwọ̀nba wákàtí díẹ̀ lórí òpó-igi, nígbà tí ó jẹ́ pé àwọn olùṣe-búburú tí a kànmọ́gi lẹ́bàá rẹ̀ ni a níláti fọ́ egungun ẹsẹ wọn láti mú ikú wọn yára kánkán. (Johannu 19:31-33) Wọn kò tíì nírìírí ìjìyà ti èrò-orí àti ti ara-ìyára tí Jesu jìyà rẹ̀ lákòókò àìsùn-àìwo la gbogbo òru tí ó ṣáájú ìkànmọ́gi já, bóyá dé orí ibi tí kò tilẹ̀ ti lè gbé òpó-igi ìdálóró tirẹ̀ fúnraarẹ̀ mọ́ pàápàá.—Marku 15:15, 21.
-
-
Ẹ Fi Ìfọkànsìn Oníwà-bí-Ọlọ́run Kún Ìfaradà YínIlé-Ìṣọ́nà—1993 | September 15
-
-
Ẹ Fi Ìfọkànsìn Oníwà-bí-Ọlọ́run Kún Ìfaradà Yín
‘Ẹ fi ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run kún ìfaradà yín, ìfaradà kún ìgbàgbọ́.’—2 PETERU 1:5, 6, NW.
1, 2. (a) Bẹ̀rẹ̀ ní àwọn ọdún 1930, kí ni ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn Ẹlẹ́rìí Jehofa ní àwọn ilẹ̀ tí ó wà lábẹ́ ìdarí Nazi, èésìtiṣe? (b) Báwo ni nǹkan ṣe rí pẹ̀lú àwọn ènìyàn Jehofa lábẹ́ ìbánilò lọ́nà lílekoko yìí?
ÀKÓKÒ ṣíṣú dùdù kan ni ó jẹ́ nínú ìtàn ọ̀rúndún lọ́nà ogún. Bẹ̀rẹ̀ ní àwọn ọdún 1930, ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn Ẹlẹ́rìí Jehofa ní àwọn ilẹ̀ tí ó wà lábẹ́ ìdarí Nazi ni a fi àṣẹ-ọba mú lọ́nà tí kò bá ìdájọ́-òdodo mu tí a sì gbé sọ sínú àwọn àgọ́ ìṣẹ́niníṣẹ̀ẹ́. Èéṣe? Nítorí pé wọ́n gbójúgbóyà láti wà ní àìdásí tọ̀tún-tòsì tí wọ́n sì kọ̀ láti pe Hitler ní olùgbàlà. Ọwọ́ wo ni a fi mú wọn? “Kò sí àwùjọ àwọn ẹlẹ́wọ̀n mìíràn . . . tí a jọ̀wọ́ wọn fún ìwà-ìkà rírorò ti àwọn ọmọ-ogun-SS ní irú ọ̀nà kan bẹ́ẹ̀ bí a ti ṣe sí àwọn Akẹ́kọ̀ọ́ Bibeli [àwọn Ẹlẹ́rìí Jehofa]. Ó jẹ́ ìwà-ìkà rírorò tí ìdálóró ti ara-ìyára àti ti èrò-orí tí ń báa lọ láìdáwọ́dúró láti orí ọ̀kan bọ́ sí òmíràn sàmì sí, irú èyí tí kò sí èdè tí ó lè ṣàpèjúwe rẹ̀ ní ayé.”—Karl Wittig, òṣìṣẹ́-olóyè ìjọba Germany tẹ́lẹ̀rí kan.
2 Báwo ni ọ̀ràn ti rí pẹ̀lú àwọn Ẹlẹ́rìí náà? Nínú ìwé rẹ̀ The Nazi State and the New Religions: Five Case Studies in Non-Conformity, Dókítà nínú ẹ̀kọ́ ọ̀rọ̀-ìtàn Christine E. King sọ pé: “Lòdìsí àwọn Ẹlẹ́rìí Jehofa nìkan [ní ìyàtọ̀ gédégédé sí àwọn àwùjọ ìsìn mìíràn] ni ìjọba ti kùnà láti kẹ́sẹjárí.” Bẹ́ẹ̀ni, àwọn Ẹlẹ́rìí Jehofa lódindi mú ìdúró wọn, àní bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé fún ọgọ́rọ̀ọ̀rún wọn, èyí túmọ̀sí fífaradà dé ojú ikú.
3. Kí ni ó ti mú kí ó ṣeéṣe fún àwọn Ẹlẹ́rìí Jehofa láti farada àwọn àdánwò mímúná?
3 Kí ni ó ti mú kí ó ṣeéṣe fún àwọn Ẹlẹ́rìí Jehofa láti farada irú àwọn àdánwò bẹ́ẹ̀ kìí ṣe ní Nazi Germany nìkan ṣùgbọ́n ní gbogbo ayé? Baba wọn ọ̀run ti ràn wọ́n lọ́wọ́ láti faradà nítorí ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run wọn. “Jehofa mọ bí a ṣeé dá àwọn olùfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run nídè kúrò nínú àdánwò,” ni aposteli Peteru ṣàlàyé. (2 Peteru 2:9, NW) Ṣáájú nínú lẹ́tà kan-náà, Peteru ti gba àwọn Kristian nímọ̀ràn pé: ‘Ẹ fi ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run kún ìfaradà yín, ìfaradà kún ìgbàgbọ́.’ (2 Peteru 1:5, 6, NW) Nítorí náà ìfaradà tan pẹ́kípẹ́kí mọ́ ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run. Ní tòótọ́, láti faradà dé òpin, a gbọ́dọ̀ ‘lépa ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run’ kí á sì fi í hàn. (1 Timoteu 6:11) Ṣùgbọ́n kí ni ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run gan-an ní pàtó?
Ohun ti Ìfọkànsìn Oníwà-bí-Ọlọ́run Jẹ́
4, 5. Kí ni ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run?
4 Ọ̀rọ̀ orúkọ Griki náà fún “ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run” (eu·seʹbei·a) ni a lè túmọ̀ lóréfèé sí “bíbọ̀wọ̀-ńlá tí ó yẹ fún.”a (2 Peteru 1:6, Kingdom Interlinear) Ó dúró fún ìmọ̀lára ọlọ́yàyà látọkànwá síhà ọ̀dọ̀ Ọlọrun. Gẹ́gẹ́ bí W. E. Vine ti wí, arọ́pò ọ̀rọ̀ orúkọ náà eu·se·besʹ, tí ó túmọ̀ lóréfèé sí “ọ̀wọ̀-ńlá tí ó yẹ,” dúró fún “okun náà, tí ó jẹ́ pé bí a bá darí rẹ̀ nípasẹ̀ ìbẹ̀rù-ọlọ́wọ̀ fún Ọlọrun, yóò ní ìfisílò rẹ̀ nínú ìgbòkègbodò onífọkànsìn.”—2 Peteru 2:9, Int.
5 Ọ̀rọ̀ náà “ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run” nígbà náà tọ́ka sí ọ̀wọ̀ tàbí ìfọkànsìn fún Jehofa tí ń sún wa láti ṣe ohun tí ń tẹ́ ẹ lọ́rùn. Èyí ni a ṣe àní ní ojú àwọn àdánwò tí ó ṣòro pàápàá nítorí pé a nífẹ̀ẹ́ Ọlọrun láti inú ọkàn-àyà wá. Ó jẹ́ ìsopọ̀ onídùúróṣinṣin, ti ara-ẹni pẹ̀lú Jehofa tí a fihàn nínú ọ̀nà tí a gbà ń gbé ìgbésí-ayé wa. Àwọn Kristian tòótọ́ ni a rọ̀ láti gbàdúrà pé kí wọn máa gbé “ìgbésí-ayé píparọ́rọ́ àti onídàákẹ́jẹ́ pẹ̀lú ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run kíkún.” (1 Timoteu 2:1, 2, NW) Gẹ́gẹ́ bí àwọn olùtúmọ̀-èdè J. P. Louw àti E. A. Nida ti wí, “nínú iye àwọn èdè kan [eu·seʹbei·a] ní 1 Tm 2.2 ni a lè túmọ̀ lọ́nà tí ó yẹ wẹ́kú sí ‘láti gbé gẹ́gẹ́ bí Ọlọrun yóò ti fẹ́ kí á gbé’ tàbí ‘láti gbé gẹ́gẹ́ bí Ọlọrun ti sọ fún wa pé kí á gbé.’”
6. Kí ni ìsopọ̀ tí ó wà láàárín ìfaradà àti ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run?
6 Àwa lè mọrírì ìsopọ̀ tí ó wà láàárín ìfaradà àti ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run dáradára nísinsìnyí. Nítorí pé a ń gbé gẹ́gẹ́ bí Ọlọrun yóò ti fẹ́ kí á gbé—pẹ̀lú ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run—èyí ń mú kí ayé kórìíra wa, èyí tí ń mú àdánwò ìgbàgbọ́ wá nígbà gbogbo ṣáá. (2 Timoteu 3:12) Ṣùgbọ́n kò sí ọ̀nà tí a lè gbà sún wa láti farada irú àwọn àdánwò bẹ́ẹ̀ bí kìí bá ṣe nítorí ìsopọ̀ ti ara-ẹni pẹ̀lú Baba wa ọ̀run. Jù bẹ́ẹ̀ lọ, Jehofa ń dáhùnpadà sí irú ìfọkànsìn àtọkànwá bẹ́ẹ̀. Ṣá ro bí ó ti gbọ́dọ̀ mú un nímọ̀lára tó láti bojú wolẹ̀ láti ọ̀run kí ó sì rí àwọn wọnnì, tí wọ́n ń làkàkà láti tẹ́ ẹ lọ́rùn láìka gbogbo irú àtakò sí, nítorí ìfọkànsìn wọn sí i. Abájọ tí òun fi ní ìtẹ̀sí láti “dá àwọn olùfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run nídè kúrò nínú àdánwò”!
7. Èéṣe tí a fi gbọ́dọ̀ mú ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run dàgbà?
7 Bí ó ti wù kí ó rí, a kò bí ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run mọ́ wa, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì gbà á láti ọ̀dọ̀ àwọn òbí oníwà-bí-Ọlọ́run láìṣiṣẹ́ fún un. (Genesisi 8:21) Kàkà bẹ́ẹ̀, a gbọ́dọ̀ mú un dàgbà. (1 Timoteu 4:7, 10) A gbọ́dọ̀ ṣiṣẹ́ láti fi ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run kún ìfaradà àti ìgbàgbọ́ wa. Èyí, ni Peteru sọ pé, ó gba “ìsapá onífọkànsí.” (2 Peteru 1:5, NW) Báwo, nígbà náà, ni a ṣe lè sapájèrè ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run?
Báwo ni A Ṣe Lè Sapájèrè Ìfọkànsìn Oníwà-bí-Ọlọ́run?
8. Gẹ́gẹ́ bí aposteli Peteru ti wí, kí ni kọ́kọ́rọ́ náà sí sísapájèrè ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run?
8 Aposteli Peteru ṣàlàyé kọ́kọ́rọ́ náà sí sísapájèrè ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run. Ó sọ pé: “Ǹjẹ́ kí inúrere àìlẹ́tọ̀ọ́sí àti àlááfíà bí síi fún yín nípa ìmọ̀ pípéye níti Ọlọrun àti Jesu Oluwa wa, níwọ̀n bí agbára àtọ̀runwá rẹ̀ ti fún wa ni ohun gbogbo tí ó kan ọ̀ràn ìyè àti ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run lọ́fẹ̀ẹ́ nípa ìmọ̀ pípéye ẹni náà tí ó pè wá nípa ògo àti ìwàfunfun.” (2 Peteru 1:2, 3, NW) Nítorí náà láti fi ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run kún ìgbàgbọ́ àti ìfaradà wa, a gbọ́dọ̀ dàgbà nínú ìmọ̀ pípéye, ìyẹn ni pé, ìmọ̀ kíkún, tàbí èyí tí ó pé pérépéré, nípa Jehofa Ọlọrun àti Jesu Kristi.
9. Báwo ni a ṣe lè ṣàkàwé rẹ̀ pé níní ìmọ̀ pípéye nípa Ọlọrun àti Kristi wémọ́ ohun púpọ̀ ju wíwulẹ̀ mọ ẹni tí wọ́n jẹ́ lọ?
9 Kí ni ó túmọ̀sí láti ní ìmọ̀ pípéye nípa Ọlọrun àti Kristi? Ní kedere, ó ní ohun púpọ̀ nínú ju wíwulẹ̀ mọ ẹni tí wọ́n jẹ́ lọ. Láti ṣàkàwé: Ìwọ lè mọ ẹni tí aládùúgbò tí ó múlé gbè ọ́ jẹ́ o sì tilẹ̀ lè máa fi orúkọ rẹ̀ kí i pàápàá. Ṣùgbọ́n ìwọ yóò ha yá a ní owó ńlá kan bí? Àyàfi bí o bá mọ irú ẹni tí ó jẹ́ níti gidi. (Fiwé Owe 11:15.) Bákan náà, mímọ Jehofa ati Jesu lọ́nà pípéye, tàbí ní kíkún, túmọ̀sí ohun púpọ̀ ju wíwulẹ̀ gbàgbọ́ pé wọ́n wà àti mímọ orúkọ wọn. Láti múratán láti farada àwọn àdánwò nítìtorí wọn àní dé ojú ikú pàápàá, a gbọ́dọ̀ mọ̀ wọ́n tímọ́tímọ́ níti gidi. (Johannu 17:3) Kí ni èyí ní nínú?
10. Níní ìmọ̀ pípéye nípa Jehofa àti Jesu wémọ́ ohun méjì wo, èésìtiṣe?
10 Níní ìmọ̀ pípéye, tàbí ìmọ̀ pípé pérépéré nípa Jehofa àti Jesu wémọ́ ohun méjì: (1) mímọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí ẹni gidi kan—àwọn ànímọ́, ìmọ̀lára, àti ọ̀nà wọn—àti (2) ṣíṣàfarawé àpẹẹrẹ wọn. Ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run wémọ́ ìsopọ̀ tọkàntọkàn, ti ara-ẹni pẹ̀lú Jehofa a sì ń mú un ṣe kedere nípa ọ̀nà tí a gbà ń gbé ìgbésí-ayé wa. Nítorí náà, láti gbà á a gbọ́dọ̀ mọ Jehofa gẹ́gẹ́ bí ẹnìkan kí á sì dojúlùmọ̀ dáadáa pẹ̀lú ìfẹ́-inú àti àwọn ọ̀nà rẹ̀ bí èyí bá ti lè ṣeéṣe níti ẹ̀dá tó. Lóòótọ́ láti mọ Jehofa, ẹni tí a dá wa ní àwòrán rẹ̀, a gbọ́dọ̀ lo irú ìmọ̀ bẹ́ẹ̀ kí á sì làkàkà láti dàbí rẹ̀. (Genesisi 1:26-28; Kolosse 3:10) Níwọ̀n bí Jesu sì ti ṣàfarawé Jehofa lọ́nà pípé nínú àwọn ohun tí ó sọ tí ó sì ṣe, mímọ Jesu lọ́nà tí ó péye jẹ́ àrànṣe ṣíṣeyebíye nínú mímú ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run dàgbà.—Heberu 1:3.
11. (a) Báwo ni a ṣe lè jèrè ìmọ̀ pípéye nípa Ọlọrun àti Kristi? (b) Èéṣe tí ó fi ṣe pàtàkì láti ṣàṣàrò lórí ohun tí a kà?
11 Bí ó ti wù kí ó rí, báwo ni a ṣe lè jèrè irú ìmọ̀ pípéye bẹ́ẹ̀ nípa Ọlọrun àti Kristi? Nípa fífi taápọntaápọn kẹ́kọ̀ọ́ Bibeli àti àwọn ìtẹ̀jáde tí a gbékarí Bibeli ni.b Bí ó ti wù kí ó rí, bí ìdákẹ́kọ̀ọ́ Bibeli wa bá níláti yọrísí jíjèrè ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run fún wa, ó ṣe kókó pé kí a lo àkókò láti ṣàṣàrò, ìyẹn ni pé, kí á ronú síwá-sẹ́yìn, tàbí sìnmẹ̀dọ̀ronú, lórí ohun tí a kà. (Fiwé Joṣua 1:8.) Èéṣe tí èyí fi ṣe pàtàkì? Rántí pé ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run jẹ́ ìmọ̀lára ọ̀yàyà, àtọkànwá síhà Ọlọrun. Nínú Ìwé Mímọ́, àṣàrò ni a sopọ̀ léraléra pẹ̀lú ọkàn-àyà ìṣàpẹẹrẹ—ẹni ti inú. (Orin Dafidi 19:14; 49:3; Owe 15:28) Nígbà tí a bá ronú síwá-sẹ́yìn pẹ̀lú ìmọrírì lórí ohun tí a kà, yóò máa kọjá lọ sí inú wa lọ́hùn-ún, tí yóò sì tipa bẹ́ẹ̀ ru ìmọ̀lára wa sókè, ní gbígbún èrò-ìmọ̀lára wa ní kẹ́ṣẹ́, tí yóò sì nípa lórí ìrònú wa. Kìkì nígbà náà ni ìkẹ́kọ̀ọ́ tó lè fún ìsopọ̀ tímọ́tímọ́ tí a ní pẹ̀lú Jehofa lókun kí ó sì sún wa láti gbé ìgbésí-ayé ní ọ̀nà kan tí ó tẹ́ Ọlọrun lọ́rùn àní ní ojú àwọn ipò-àyíká tí ń peniníjà tàbí àwọn àdánwò tí ó ṣòro.
Sísọ Ìfọkànsìn Oníwà-bí-Ọlọ́run Dàṣà Nínú Ilé
12. (a) Gẹ́gẹ́ bí Paulu ti wí, báwo ni Kristian kan ṣe lè sọ ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run dàṣà nínú ilé? (b) Èéṣe tí àwọn Kristian tòótọ́ fi ń tọ́jú àwọn òbí arúgbó?
12 Ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run ni a níláti kọ́kọ́ sọ dàṣà nínú ilé. Aposteli Paulu sọ pé: “Bí opó èyíkéyìí bá ní àwọn ọmọ tàbí ọmọ-ọmọ, jẹ́ kí àwọn wọ̀nyí kọ́kọ́ kẹ́kọ̀ọ́ láti sọ ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run dàṣà nínú agbo-ilé tiwọn fúnraawọn kí wọ́n sì máa san ìsanfidípò yíyẹ fún àwọn òbí wọn àti àwọn òbí wọn àgbà, nítorí èyí ṣe ìtẹ́wọ́gbà ní ojú Ọlọrun.” (1 Timoteu 5:4, NW) Títọ́jú àwọn òbí tí wọ́n ti darúgbó jẹ́, gẹ́gẹ́ bí Paulu ti sọ, fífí ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run hàn. Àwọn Kristian tòótọ́ ń pèsè irú ìtọ́jú bẹ́ẹ̀ kìí ṣe kìkì nítorí ìmọ̀lára ojúṣe bíkòṣe nítorí ìfẹ́ fún àwọn òbí wọn. Ju ìyẹn lọ, bí ó ti wù kí ó rí, wọ́n mọ ìjẹ́pàtàkì tí Jehofa gbékarí títọ́jú ìdílé ẹni. Wọ́n mọ̀ dáradára pé láti kọ̀ láti ran àwọn òbí wọn lọ́wọ́ ní àkókò àìní yóò báradọ́gba pẹ̀lú ‘sísẹ́ ìgbàgbọ́ Kristian.’—1 Timoteu 5:8.
13. Èéṣe tí sísọ ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run dàṣà nínú ilé fi jẹ́ ìpèníjà gidi kan, ṣùgbọ́n ìtẹ́lọ́rùn wo ni ó ń jẹ jáde láti inú títọ́jú àwọn òbí ẹni?
13 A gbà pé, kìí fìgbà gbogbo rọrùn láti sọ ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run dàṣà nínú ilé. Àwọn mẹ́ḿbà ìdílé ni a lè yàsọ́tọ̀ nípasẹ̀ ọ̀nà jíjìn síra. Àwọn ọmọ tí ó ti dàgbà lè máa gbé ìdílé tiwọn ró wọ́n sì lè máa wọ̀dìmú pẹ̀lú ìṣúnná-owó. Irú tàbí ìwọ̀n ìtọ́jú tí òbí kan nílò lè fi dandan béèrè ohun tí ó pọ̀ jù níti ìlera ara-ìyára, èrò-orí, àti ti èrò-ìmọ̀lára lọ́wọ́ àwọn tí ó ń pèsè ìtọ́jú náà. Síbẹ̀, ìtẹ́lọ́rùn gidi lè wà nínú mímọ̀ pé títọ́jú àwọn òbí ẹ̀ni kò jásí “ìsanfidípòpadà yíyẹ” nìkan ṣùgbọ́n ó tún tẹ́ Ẹni náà ‘tí a ń fi orúkọ rẹ̀ pe gbogbo ìdílé tí ń bẹ ní ọ̀run àti ní ayé’ lọ́rùn.—Efesu 3:14, 15.
14, 15. Sọ àpẹẹrẹ ìtọ́jú oníwà-bí-Ọlọ́run ní ìhà ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ fún òbí kan.
14 Gbé àpẹẹrẹ kan tí ó gbún èrò-ìmọ́lára ní kẹ́ṣẹ́ nítòótọ́ yẹ̀wò. Ellis àti márùn-ún nínú àwọn arákùnrin àti arábìnrin rẹ̀ dojúkọ ìpèníjà gidi kan níti títọ́jú baba wọn nínú ilé. “Ní 1986 àrùn rọpá-rọsẹ̀ kọlu baba mi, èyí tí ó jẹ́ kí ó di arọlápá-rọlẹ́sẹ̀ pátápátá,” ni Ellis ṣàlàyé. Àwọn ọmọ mẹ́fà náà ṣàjọpín nínú bíbójútó àìní baba wọn, tí ó bẹ̀rẹ̀ láti orí wíwẹ̀ ẹ́ dórí rírí i dájú pé a yí i níhà pada kí ó má baà di ẹni tí ibùsùn dápàá sí lára. “A ń kàwé fún un, bá a sọ̀rọ̀, lu ohùn orin fún un. Kò dá wa lójú yálà ó mọ ohun tí ń lọ ní àyíká rẹ̀, ṣùgbọ́n a bá a lò gẹ́gẹ́ bí ẹni pé ó mọ ohun gbogbo lẹ́kùn-ún-rẹ́rẹ́.”
15 Èéṣe tí àwọn ọmọ náà fi tọ́jú baba wọn bí wọ́n ti ṣe? Ellis ń báa lọ pé: “Lẹ́yìn ikú ìyá wa ní 1964, bàbá wa ni ó dánìkan tọ́ wa dàgbà. Ní àkókò yẹn, ọjọ́-orí wa wà láàárín ọdún márùn-ún sí mẹ́rìnlá. Ó wà fún wa nígbà náà; àwa náà sì wà fún un nísinsìnyí.” Ní kedere, kò rọrùn láti pèsè irú ìtọ́jú bẹ́ẹ̀, ìrẹ̀wẹ̀sì a sì máa mú àwọn ọmọ náà nígbà mìíràn. “Ṣùgbọ́n a mọ̀ pé ipò baba wa jẹ́ ìṣòro onígbà kúkúrú kan,” ni Ellis sọ. “A ń wọ̀nà fún àkókò náà nígbà tí a ó mú baba wa padà sí ìlera dídára àwa yóò sì tún lè padà wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìyá wa.” (Isaiah 33:24; Johannu 5:28, 29) Dájúdájú, irú ìtọ́jú onífọkànsìn bẹ́ẹ̀ fún òbí kan gbọ́dọ̀ mú ọkàn-àyà Ẹni náà tí ó pàṣẹ fún àwọn ọmọ láti bọlá fún àwọn òbí wọn yọ̀!c—Efesu 6:1, 2.
Ìfọkànsìn Oníwà-bí-Ọlọ́run àti Iṣẹ́-Òjíṣẹ́ Náà
16. Kí ni ó níláti jẹ́ ìdí àkọ́kọ́ fún ohun tí a bá ṣe nínú iṣẹ́-òjíṣẹ́ náà?
16 Nígbà tí a tẹ́wọ́gba ìkésíni Jesu láti ‘máa tẹ̀lé e lẹ́yìn nígbà gbogbo,’ a wá sábẹ́ àṣẹ àtọ̀runwá kan láti wàásù ìhìnrere nípa Ìjọba náà àti láti sọni di ọmọ-ẹ̀yìn. (Matteu 16:24; 24:14; 28:19, 20) Ní kedere, níní ìpín nínú iṣẹ́-òjíṣẹ́ náà jẹ́ iṣẹ́-àìgbọdọ̀máṣe Kristian ní ‘àwọn ìkẹyìn ọjọ́’ wọ̀nyí. (2 Timoteu 3:1) Bí ó ti wù kí ó rí, ìsúnniṣe wa fún wíwàásù àti kíkọ́ni gbọ́dọ̀ lọ rékọjá ìmọ̀lára ojúṣe tàbí iṣẹ́-àìgbọdọ̀máṣe lásán. Ìfẹ́ jíjinlẹ̀ fún Jehofa gbọ́dọ̀ jẹ́ ìdí àkọ́kọ́ fún ohun tí a ṣe àti bí a ṣe ṣe tó nínú iṣẹ́-òjíṣẹ́ náà. “Nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun inú ni ẹnu í sọ,” ni Jesu wí. (Matteu 12:34) Bẹ́ẹ̀ni, nígbà tí ọkàn-àyà wa bá kún àkúnwọ́sílẹ̀ pẹ̀lú ìfẹ́ fún Jehofa, a ń sún wa láti jẹ́rìí nípa rẹ̀ fún àwọn ẹlòmíràn. Nígbà tí ìfẹ́ fún Ọlọrun bá jẹ́ ìsúnniṣe wa, iṣẹ́-òjíṣẹ́ wa jẹ́ fífi ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọrun wa hàn lọ́nà tí ó nítumọ̀.
17. Báwo ni a ṣe lè mú ìsúnniṣe títọ̀nà dàgbà fún iṣẹ́-òjíṣẹ́ náà?
17 Báwo ni a ṣe lè mú ìsúnniṣe títọ̀nà dàgbà fún iṣẹ́-òjíṣẹ́ náà? Fi ìmọrírì ronú síwá-sẹ́yìn lórí ìdí mẹ́ta tí Jehofa ti fifún wa fún nínífẹ̀ẹ́ rẹ̀. (1) A nífẹ̀ẹ́ Jehofa nítorí àwọn ohun tí ó ti ṣe fun wa. Kò sí ìfẹ́ títóbi tí òun ti lè fihàn sí wa ju bí òun ti ṣe nínú pípèsè ìràpadà náà. (Matteu 20:28; Johannu 15:13) (2) A nífẹ̀ẹ́ Jehofa nítorí ohun tí ó ń ṣe fún wa nísinsìnyí. A ní òmìnira ọ̀rọ̀-sísọ pẹ̀lú Jehofa, ẹni tí ń dáhùn àwọn àdúrà wa. (Orin Dafidi 65:2; Heberu 4:14-16) Bí a ti ń fi àwọn ire Ìjọba sí ipò àkọ́kọ́, a ń gbádùn àwọn ohun kòṣeémánìí ìgbésí-ayé. (Matteu 6:25-33) A ń gba ìpèsè tí kò dáwọ́ dúró ti oúnjẹ tẹ̀mí tí ń ràn wá lọ́wọ́ láti kojú àwọn ìṣòro tí a ń dojúkọ. (Matteu 24:45) A sì ní ìbùkún jíjẹ́ apákan ẹgbẹ́-ará Kristian kárí-ayé tí ó yà wá sọ́tọ̀ nítòótọ́ kùrò lára àwọn ènìyàn yòókù nínú ayé. (1 Peteru 2:17) (3) A tún nífẹ̀ẹ́ Jehofa nítorí àwọn ohun tí ó fẹ́ láti ṣe fún wa síbẹ̀. Nítorí ìfẹ́ rẹ̀, a “di ìyè tòótọ́ mú”—ìyè àìnípẹ̀kun ní ọjọ́-ọ̀la. (1 Timoteu 6:12, 19) Nígbà tí a bá gbé ìfẹ́ Jehofa nítìtorí wa yẹ̀wò, dájúdájú ọkàn-àyà wa yóò sún wa láti ní ìpín onífọkànsìn nínú sísọ fún àwọn ẹlòmíràn nípa rẹ̀ àti àwọn ète ṣíṣeyebíye rẹ̀! Àwọn ẹlòmíràn kò ṣẹ̀ṣẹ̀ ní sọ ohun tí a ó ṣe fún wa tàbí bí a ṣe níláti ṣe púpọ̀ nínú iṣẹ́-òjíṣẹ́ náà tó. Ọkàn-àyà wa yóò sún wa láti ṣe ohun tí a lè ṣe.
18, 19. Ìdènà wo ni arábìnrin kan ṣẹ́pá kí ó baà lè ṣàjọpín nínú iṣẹ́-òjíṣẹ́ náà?
18 Àní lójú àwọn ipò-àyíká tí ń peniníjà pàápàá, ọkàn-àyà tí ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run ru sókè ni a ó sún láti sọ̀rọ̀. (Fiwé Jeremiah 20:9.) Èyí ni a fihàn nípa ọ̀ràn Stella, obìnrin Kristian onítìjú akika kan yẹ̀wò. Nígbà tí ó kọ́kọ́ bẹ̀rẹ̀ síi kẹ́kọ̀ọ́ Bibeli, ó ronú pé, ‘Èmi kò lè lọ láti ilé dé ilé láé!’ Ó ṣàlàyé pé: “Mo sábà máa ń dákẹ́jẹ́ẹ́. Èmi kò lè tọ àwọn ẹlòmíràn lọ láé láti bẹ̀rẹ̀ ìbánisọ̀rọ̀pọ̀.” Bí ó ti ń bá ìkẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀ lọ, ìfẹ́ rẹ̀ fún Jehofa ròkè, ó sì mú ìfẹ́-ọkàn gbígbóná láti bá àwọn ẹlòmíràn sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ dàgbà. “Mo rántí sísọ fún olùkọ́ Bibeli mi pé, ‘Mo fẹ́ gidigidi láti sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kò ṣáà lè ṣe bẹ́ẹ̀, ìyẹn sì ń dà mí láàmú níti gidi.’ Èmi kò jẹ́ gbàgbé ohun tí ó sọ fún mi láé: ‘Stella, kún fún ìmoore pé ìwọ fẹ́ láti sọ̀rọ̀.’”
19 Láìpẹ́ láìjìnnà, Stella bá araarẹ̀ tí ó ń jẹ́rìí fún aládùúgbò tí ó múlé tì í. Lẹ́yìn náà ó gbé ohun tí ó jẹ́ ìṣísẹ̀ rẹ̀ ṣíṣe pàtàkì gidi—ó ṣàjọpín nínú iṣẹ́-òjíṣẹ́ ilé-dé-ilé fún ìgbà àkọ́kọ́. (Iṣe 20:20, 21) Ó padà rántí pé: “Mo kọ ìgbékalẹ̀-ọ̀rọ̀ mi sílẹ̀. Ṣùgbọ́n ẹ̀rù bà mi débi pé bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó wà ní iwájú mi, ojora ti mú mi jù láti wo àwọn àkọsílẹ̀ mi!” Nísinsìnyí, ní ọdún márùndínlógójì lẹ́yìn náà, Stella ṣì ń tijú lọ́nà àdánidá. Síbẹ̀, ó nífẹ̀ẹ́ iṣẹ́-òjíṣẹ́ pápá ó sì ń báa lọ láti ní ìpín tí ó ṣe gúnmọ́ nínú rẹ̀.
20. Àpẹẹrẹ wo ni ó fihàn pé kìí tilẹ̀ ṣe inúnibíni tàbí ìfinisẹ́wọ̀n ni ó lè pa àwọn Ẹlẹ́rìí olùfọkànsìn ti Jehofa lẹ́nu mọ́?
20 Kìí tilẹ̀ ṣe inúnibíni tàbí ìfinisẹ́wọ̀n ni ó lè pa ẹnu àwọn Ẹlẹ́rìí onífọkànsìn tí Jehofa mọ́. Gbé àpẹẹrẹ Ernst àti Hildegard Seliger ti Germany yẹ̀wò. Nítorí ìgbàgbọ́ wọn, àwọn méjèèjì papọ̀ lo àròpọ̀ iye tí ó ju ogójì ọdún lọ nínú àgọ́ ìṣẹ́niníṣẹ̀ẹ́ Nazi àti àwọn ọgbà-ẹ̀wọ̀n Kọmunisti. Àní nínú ẹ̀wọ̀n pàápàá, wọ́n tẹpẹlẹ mọ́ jíjẹ́rìí fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n mìíràn. Hildegard padà rántí pé: “Àwọn òṣìṣẹ́-olóyè ọgbà-ẹ̀wọ̀n kà mí sí ẹni tí ó léwu ní pàtàkì, nítorí pé, gẹ́gẹ́ bí obìnrin ẹ̀ṣọ́ kan ti wí, mo ń sọ̀rọ̀ nípa Bibeli látàárọ̀-ṣúlẹ̀. Nítorí náà wọ́n fi mí sí àjàalẹ̀.” Lẹ́yìn tí a fún wọn ní òmìnira wọn, Arákùnrin àti Arábìnrin Seliger lo àkókò kíkún wọn fún iṣẹ́-òjíṣẹ́ Kristian. Àwọn méjèèjì ṣiṣẹ́sìn pẹ̀lú ìṣòtítọ́ títí di ọjọ́ ikú wọn, Arákùnrin Seliger ni 1985 àti aya rẹ̀ ni 1992.
21. Kí ni a gbọ́dọ̀ ṣe láti fi ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run kún ìfaradà wa?
21 Nípa fífi taápọntaápọn kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọrun àti lílo àkókò láti fi ìmọrírì ṣàṣàrò lóri ohun tí a kọ́, àwa yóò dàgbà nínú ìmọ̀ pípéye nípa Jehofa Ọlọrun àti Jesu Kristi. Èyí, nípa bẹ́ẹ̀, yóò yọrísí gbígba ìwọ̀n tí ó túbọ̀ kún síi nínú ànímọ́ ṣíṣeyebíye yẹn—ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run. Láìsí ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run kò sí ọ̀nà tí a lè gbà farada àwọn onírúurú àdánwò tí ń dé bá wa gẹ́gẹ́ bíi Kristian. Nítorí náà ẹ jẹ́ kí á tẹ̀lé ìmọ̀ràn aposteli Peteru, ní bíbáa lọ láti ‘fi ìfaradà kún ìgbàgbọ́ wa àti ìfọkànsìn oníwà-bí-Ọlọ́run kún ìfaradà.’—2 Peteru 1:5, 6. NW.
-