ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Bí Gáyọ́sì Ṣe Ran Àwọn Ará Lọ́wọ́
    Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2017 | May
    • Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé míṣọ́nnárì tàbí àwọn aṣojú Jòhánù làwọn àlejò yìí, wọ́n sì lè jẹ́ alábòójútó arìnrìn-àjò. Èyí ó wù kí wọ́n jẹ́, torí kí wọ́n lè polongo ìhìn rere ni wọ́n ṣe ń rìnrìn-àjò. Jòhánù sọ pé: “Tìtorí orúkọ rẹ̀ ni wọ́n ṣe jáde lọ.” (3 Jòh. 7) Orúkọ Jèhófà ni Jòhánù ń tọ́ka sí nígbà tó sọ pé “tìtorí orúkọ rẹ̀,” ìdí ni pé ó ṣẹ̀sẹ̀ sọ̀rọ̀ nípa Ọlọ́run ní ẹsẹ kẹfà ni. Torí náà, ara ìjọ Kristẹni làwọn arìnrìn-àjò yìí, ó sì yẹ kí wọ́n tọ́jú wọn. Bí Jòhánù ṣe sọ ọ́ gan-an ló rí, pé: “A wà lábẹ́ iṣẹ́ àìgbọ́dọ̀máṣe láti gba irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ẹ̀mí aájò àlejò, kí a lè di alábàáṣiṣẹ́pọ̀ nínú òtítọ́.”​—3 Jòh. 8.

  • Bí Gáyọ́sì Ṣe Ran Àwọn Ará Lọ́wọ́
    Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2017 | May
    • Lákọ̀ọ́kọ́, àwọn Kristẹni tó rìnrìn-àjò láti kọ́ àwọn èèyàn nípa Jèhófà ló jẹ́ kí ọ̀pọ̀ wa kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́ lónìí. Òótọ́ ni pé kì í ṣe gbogbo àwa tá a wà nínú ìjọ Kristẹni lónìí là ń lọ sọ́nà jíjìn láti tan ìhìn rere kálẹ̀. Síbẹ̀ bíi ti Gáyọ́sì, àwa náà lè ṣèrànwọ́ fáwọn tó ń rìnrìn-àjò nítorí ìhìn rere, irú bí alábòójútó àyíká àti ìyàwó rẹ̀. Bákan náà, a lè ṣèrànwọ́ fáwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin tó ṣí lọ sáwọn ibi tí àìní gbé pọ̀ yálà lórílẹ̀-èdè wọn tàbí lórílẹ̀-èdè míì. Torí náà, ẹ jẹ́ kí gbogbo wa “máa tẹ̀ lé ipa ọ̀nà aájò àlejò.”​—Róòmù 12:13; 1 Tím. 5:9, 10.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́