-
Bí Gáyọ́sì Ṣe Ran Àwọn Ará Lọ́wọ́Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2017 | May
-
-
Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé míṣọ́nnárì tàbí àwọn aṣojú Jòhánù làwọn àlejò yìí, wọ́n sì lè jẹ́ alábòójútó arìnrìn-àjò. Èyí ó wù kí wọ́n jẹ́, torí kí wọ́n lè polongo ìhìn rere ni wọ́n ṣe ń rìnrìn-àjò. Jòhánù sọ pé: “Tìtorí orúkọ rẹ̀ ni wọ́n ṣe jáde lọ.” (3 Jòh. 7) Orúkọ Jèhófà ni Jòhánù ń tọ́ka sí nígbà tó sọ pé “tìtorí orúkọ rẹ̀,” ìdí ni pé ó ṣẹ̀sẹ̀ sọ̀rọ̀ nípa Ọlọ́run ní ẹsẹ kẹfà ni. Torí náà, ara ìjọ Kristẹni làwọn arìnrìn-àjò yìí, ó sì yẹ kí wọ́n tọ́jú wọn. Bí Jòhánù ṣe sọ ọ́ gan-an ló rí, pé: “A wà lábẹ́ iṣẹ́ àìgbọ́dọ̀máṣe láti gba irú àwọn ẹni bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ẹ̀mí aájò àlejò, kí a lè di alábàáṣiṣẹ́pọ̀ nínú òtítọ́.”—3 Jòh. 8.
-
-
Bí Gáyọ́sì Ṣe Ran Àwọn Ará Lọ́wọ́Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2017 | May
-
-
Lákọ̀ọ́kọ́, àwọn Kristẹni tó rìnrìn-àjò láti kọ́ àwọn èèyàn nípa Jèhófà ló jẹ́ kí ọ̀pọ̀ wa kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́ lónìí. Òótọ́ ni pé kì í ṣe gbogbo àwa tá a wà nínú ìjọ Kristẹni lónìí là ń lọ sọ́nà jíjìn láti tan ìhìn rere kálẹ̀. Síbẹ̀ bíi ti Gáyọ́sì, àwa náà lè ṣèrànwọ́ fáwọn tó ń rìnrìn-àjò nítorí ìhìn rere, irú bí alábòójútó àyíká àti ìyàwó rẹ̀. Bákan náà, a lè ṣèrànwọ́ fáwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin tó ṣí lọ sáwọn ibi tí àìní gbé pọ̀ yálà lórílẹ̀-èdè wọn tàbí lórílẹ̀-èdè míì. Torí náà, ẹ jẹ́ kí gbogbo wa “máa tẹ̀ lé ipa ọ̀nà aájò àlejò.”—Róòmù 12:13; 1 Tím. 5:9, 10.
-