-
Bí Ìṣípayá Ṣe Kàn Ọ́Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
6. Kí ni Jèhófà sọ bó ti ń bá àwọn òǹkàwé Ìṣípayá sọ̀rọ̀ fún ìgbà ìkẹyìn nínú àsọtẹ́lẹ̀ náà?
6 Wàyí o, Jèhófà, Ọba ayérayé fẹ́ bá àwọn tí ń ka ìwé Ìṣípayá sọ̀rọ̀ fún ìgbà ìkẹyìn nínú àsọtẹ́lẹ̀ náà, ó ní: “Wò ó! Mo ń bọ̀ kíákíá, èrè tí mo sì ń fi fúnni wà pẹ̀lú mi, láti san fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ ti rí. Èmi ni Ááfà àti Ómégà, ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìkẹyìn, ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ àti òpin. Aláyọ̀ ni àwọn tí ó fọ aṣọ wọn, kí ọlá àṣẹ láti lọ síbi àwọn igi ìyè lè jẹ́ tiwọn, kí wọ́n sì lè gba ẹnubodè wọlé sínú ìlú ńlá náà. Lẹ́yìn òde ni àwọn ajá wà àti àwọn tí ń bá ẹ̀mí lò àti àwọn àgbèrè àti àwọn òṣìkàpànìyàn àti àwọn abọ̀rìṣà àti gbogbo ẹni tí ó fẹ́ràn irọ́, tí ó sì ń bá a lọ ní pípurọ́.”—Ìṣípayá 22:12-15.
-
-
Bí Ìṣípayá Ṣe Kàn Ọ́Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
8. (a) Kìkì àwọn wo ni yóò “lọ síbi àwọn igi ìyè,” kí sì ni èyí túmọ̀ sí? (b) Báwo ni ogunlọ́gọ̀ ńlá ṣe “fọ aṣọ wọn,” báwo sì ni wọ́n ṣe ń bá a lọ láti pa ipò mímọ́ tí kò lábàwọ́n tí wọ́n wà níwájú Ọlọ́run mọ́?
8 Kìkì àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró tí wọ́n ‘fọ aṣọ wọn’ lóòótọ́ kí wọ́n lè wà ní mímọ́ tónítóní lójú Jèhófà, ni Ọlọ́run fún láǹfààní láti “lọ síbi àwọn igi ìyè.” Èyíinì ni pé, wọ́n gba ẹ̀tọ́ àti àṣẹ láti wà láàyè ní àìleèkú ní ipò wọn ní ọ̀run. (Fi wé Jẹ́nẹ́sísì 3:22-24; Ìṣípayá 2:7; 3:4, 5.) Lẹ́yìn ikú wọn gẹ́gẹ́ bí èèyàn, wọ́n wọlé sínú Jerúsálẹ́mù Tuntun nípa àjíǹde. Áńgẹ́lì méjìlá náà fún wọn láyè láti wọlé, nígbà tí wọ́n dínà mọ́ ẹnikẹ́ni tó sọ irọ́ pípa tàbí ìwà àìmọ́ dàṣà bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó sọ pé òun ní ìrètí ti ọ̀run. Ogunlọ́gọ̀ ńlá lórí ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ti “fọ aṣọ wọn, wọ́n sì ti sọ wọ́n di funfun nínú ẹ̀jẹ̀ Ọ̀dọ́ Àgùntàn náà” ó sì jẹ́ ọ̀ranyàn fún wọn láti pa ipò mímọ́ tí kò lábàwọ́n tí wọ́n wà níwájú Ọlọ́run mọ́. Wọ́n á lè máa wà ní mímọ́ bí wọ́n bá yẹra fún àwọn ìwà burúkú tí Jèhófà sọ pé kò dára yìí, tí wọ́n sì fi ìṣílétí tí Jésù fúnni nínú iṣẹ́ tó rán sáwọn ìjọ méje náà sọ́kàn.—Ìṣípayá 7:14; orí 2 àti 3.
-