ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Jésù Dé Tòun-Tìṣírí
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • 1. Àwọn wo ni Jòhánù kọ̀wé sí nísinsìnyí, àwọn wo ló sì yẹ kí wọ́n nífẹ̀ẹ́ sí èyí gidigidi lónìí?

      Ó YẸ kí gbogbo àwọn tó wà nínú ìjọ àwọn èèyàn Ọlọ́run lónìí nífẹ̀ẹ́ sí ohun tó tún kàn báyìí gidigidi. Ohun tó tún kàn náà jẹ́ àwọn iṣẹ́ tá a rán síni. Wọ́n ní ìmúṣẹ pàtó bí “àkókò tí a yàn kalẹ̀” ti ń sún mọ́lé. (Ìṣípayá 1:3) A óò rí àǹfààní ayérayé nínú rẹ̀ tá a bá kọbi ara sí àwọn ìkéde wọ̀nyẹn. Àkọsílẹ̀ náà kà pé: “Jòhánù, sí àwọn ìjọ méje tí ó wà ní àgbègbè Éṣíà: Kí ẹ ní inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ ‘Ẹni náà tí ń bẹ, tí ó ti wà, tí ó sì ń bọ̀,’ àti láti ọ̀dọ̀ ẹ̀mí méje tí ó wà níwájú ìtẹ́ rẹ̀, àti láti ọ̀dọ̀ Jésù Kristi.”—Ìṣípayá 1:4, 5a.

  • Jésù Dé Tòun-Tìṣírí
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • 3. (a) Nínú ìkíni Jòhánù, ibo ni “inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí àti àlàáfíà” ti wá? (b) Ọ̀rọ̀ àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù wo ló jọra pẹ̀lú ìkíni Jòhánù?

      3 “Inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí àti àlàáfíà.” Àwọn ohun wọ̀nyí mà fani lọ́kàn mọ́ra o, pàápàá bá a ṣe mọ ibi tí wọ́n ti wá! “Ẹni” náà tí inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí àti àlàáfíà ń ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ṣàn wá ni Olúwa Ọba Aláṣẹ tìkára rẹ̀, Jèhófà, “Ọba ayérayé,” ẹni tó wà láàyè “láti àkókò tí ó lọ kánrin títí dé àkókò tí ó lọ kánrin.” (1 Tímótì 1:17; Sáàmù 90:2) A tún rí gbólóhùn náà, “ẹ̀mí méje” nínú iṣẹ́ tá a rán sí ìjọ méje náà. Gbólóhùn náà ṣàfihàn ìpé pérépéré iṣẹ́ tí agbára ìṣiṣẹ́ Ọlọ́run, ìyẹn ẹ̀mí mímọ́ ń ṣe, bí ẹ̀mí náà ṣe ń mú kí gbogbo àwọn tó ń fiyè sí àsọtẹ́lẹ̀ náà ní òye àti ìbùkún. Ẹni mìíràn tó tún wà ní ipò pàtàkì ni “Jésù Kristi.” Òun ni Jòhánù kọ̀wé nípa rẹ̀ lẹ́yìn náà pé: “Ó sì kún fún inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí àti òtítọ́.” (Jòhánù 1:14) Nípa báyìí, nínú ìkíni Jòhánù, a rí lára àwọn ohun tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù mẹ́nu kàn nígbà tó ń parí lẹ́tà rẹ̀ kejì sí ìjọ Kọ́ríńtì, pé: “Kí inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí ti Jésù Kristi Olúwa àti ìfẹ́ Ọlọ́run àti ṣíṣe àjọpín nínú ẹ̀mí mímọ́ wà pẹ̀lú gbogbo yín.” (2 Kọ́ríńtì 13:14) Ǹjẹ́ kí ọ̀rọ̀ wọnnì pẹ̀lú jẹ́ ti gbogbo àwa tá a nífẹ̀ẹ́ òtítọ́ lónìí!—Sáàmù 119:97.

      “Ẹlẹ́rìí Aṣeégbíyèlé”

      4. Báwo ni Jòhánù ṣe ń bá a lọ láti ṣàpèjúwe Jésù Kristi, kí sì nìdí tí àwọn èdè tó fi ṣàpèjúwe rẹ̀ wọ̀nyí fi bá a mu gan-an?

      4 Lẹ́yìn Jèhófà, Jésù ni ẹni tó lógo jù lọ láyé-lọ́run, gẹ́gẹ́ bí Jòhánù ṣe mọ̀ tó sì pè é ní “‘Ẹlẹ́rìí Aṣeégbíyèlé,’ ‘Àkọ́bí nínú àwọn òkú,’ àti ‘Olùṣàkóso àwọn ọba ilẹ̀ ayé.’” (Ìṣípayá 1:5b) Bí òṣùpá lójú ọ̀run, a ti fìdí Jésù múlẹ̀ gbọn-in gbọn-in gẹ́gẹ́ bí Ẹlẹ́rìí títóbi jù lọ fún ipò Jèhófà gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run. (Sáàmù 89:37) Lẹ́yìn tó pa ìwà títọ́ mọ́ títí dé ojú ikú ìrúbọ, ó di ẹni àkọ́kọ́ láàárín aráyé tá a gbé dìde sí ìyè àìleèkú tẹ̀mí. (Kólósè 1:18) Nísinsìnyí tó ti wà ní iwájú Jèhófà, a gbé e ga ju gbogbo àwọn ọba orí ilẹ̀ ayé lọ, bó ti jẹ́ pé a gbé “gbogbo ọlá àṣẹ ní . . . ọ̀run àti lórí ilẹ̀ ayé” lé e lọ́wọ́. (Mátíù 28:18; Sáàmù 89:27; 1 Tímótì 6:15) Ní 1914, a fi jẹ Ọba láti máa ṣàkóso láàárín àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ ayé.—Sáàmù 2:6-9.

      5. (a) Báwo ni Jòhánù ṣe ń bá a lọ láti fi ìmọrírì hàn fún Olúwa náà Jésù Kristi? (b) Ta ló jàǹfààní láti inú ẹ̀bùn ìwàláàyè èèyàn pípé ti Jésù, báwo sì ni àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró ṣe nípìn-ín nínú àkànṣe ìbùkún kan?

      5 Jòhánù ń bá a lọ láti fi ìmọrírì hàn fún Olúwa, Jésù Kristi, pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ ìyìn wọ̀nyí: “Fún ẹni tí ó nífẹ̀ẹ́ wa, tí ó sì tú wa kúrò nínú àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa nípasẹ̀ ẹ̀jẹ̀ òun fúnra rẹ̀—ó sì mú kí a jẹ́ ìjọba kan, àlùfáà fún Ọlọ́run àti Baba rẹ̀—bẹ́ẹ̀ ni, òun ni kí ògo àti agbára ńlá jẹ́ tirẹ̀ títí láé. Àmín.” (Ìṣípayá 1:5d, 6) Jésù fi ìwàláàyè èèyàn pípé tó ní rúbọ kí ọmọ aráyé tó bá lo ìgbàgbọ́ nínú rẹ̀ lè rí ìyè pípé gbà padà. Ìwọ òǹkàwé wa ọ̀wọ́n lè jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn wọ̀nyí! (Jòhánù 3:16) Ṣùgbọ́n ikú ìrúbọ Jésù mú kí àkànṣe ìbùkún ṣeé ṣe fún àwọn tí wọ́n di Kristẹni ẹni àmì òróró bíi ti Jòhánù. Àwọn wọ̀nyí la ti polongo ní olódodo lórí ìpìlẹ̀ ẹbọ ìràpadà Jésù. Níwọ̀n bí wọ́n ti gbà láti yááfì gbogbo àǹfààní tó ní í ṣe pẹ̀lú wíwàláàyè lórí ilẹ̀ ayé, gẹ́gẹ́ bí Jésù ti ṣe, a fi ẹ̀mí Ọlọ́run bí àwọn tí wọ́n jẹ́ ara agbo kékeré, wọ́n sì ń wọ̀nà fún dídi ẹni tá a jí dìde láti sìn gẹ́gẹ́ bí ọba àti àlùfáà pẹ̀lú Jésù Kristi nínú Ìjọba rẹ̀. (Lúùkù 12:32; Róòmù 8:18; 1 Pétérù 2:5; Ìṣípayá 20:6) Àǹfààní yìí mà tóbi lọ́lá o! Abájọ tí Jòhánù fi fi ìtẹnumọ́ tó pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ polongo pé kí ògo àti agbára jẹ́ ti Jésù!

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́