-
Àwọn Ohun Tó Gbọ́dọ̀ Ṣẹlẹ̀ Láìpẹ́Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
Ọ̀nà Tí Ìhìn Náà Gbà Wá
5. Báwo ni ìwé Ìṣípayá ṣe tẹ àpọ́sítélì Jòhánù lọ́wọ́, báwo ló sì ṣe dé ọ̀dọ̀ àwọn ìjọ lẹ́yìn náà?
5 Ìṣípayá 1:1b, 2 sọ pé: “Ó [ìyẹn Jésù] sì rán áńgẹ́lì rẹ̀ jáde, ó sì gbé e [ìyẹn Ìṣípayá] kalẹ̀ nípa àwọn àmì nípasẹ̀ rẹ̀ fún ẹrú rẹ̀ Jòhánù, ẹni tí ó jẹ́rìí sí ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run fúnni àti sí ẹ̀rí tí Jésù Kristi jẹ́, àní sí gbogbo ohun tí ó rí.” Nípa báyìí, Jòhánù gba àkọsílẹ̀ onímìísí náà nípasẹ̀ ońṣẹ́ kan tó jẹ́ áńgẹ́lì. Ó kọ ọ́ sínú àkájọ ìwé kan, ó sì fi ránṣẹ́ sí àwọn ìjọ tí ń bẹ nígbà ayé rẹ̀. Ó mú wa láyọ̀ pé Ọlọ́run ti tọ́jú rẹ̀, kó lè fún iye ìjọ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tó fẹ́rẹ̀ẹ́ tó ọ̀kẹ́ márùn-ún [100,000] tí wọ́n wà ní ìṣọ̀kan lórí ilẹ̀ ayé lónìí níṣìírí.
6. Kí ni Jésù pe ọ̀nà tí òun yóò lò láti pèsè oúnjẹ tẹ̀mí fún ‘àwọn ẹrú’ rẹ̀ lónìí?
6 Ọlọ́run ní ọ̀nà tó ṣètò tí ìwé Ìṣípayá gbà wá nígbà ayé Jòhánù, Jòhánù sì jẹ́ apá kan ọ̀nà náà lórí ilẹ̀ ayé. Bákan náà, Ọlọ́run ní ọ̀nà tó gbà ń fún ‘àwọn ẹrú’ rẹ̀ ní oúnjẹ tẹ̀mí lónìí. Nínú àsọtẹ́lẹ̀ ńlá rẹ̀ nípa òpin ètò àwọn nǹkan, Jésù jẹ́ ká mọ ọ̀nà yìí sí “ẹrú olóòótọ́ àti olóye tí ọ̀gá rẹ̀ yàn sípò lórí àwọn ará ilé rẹ̀, láti fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àkókò tí ó bẹ́tọ̀ọ́ mu.” (Mátíù 24:3, 45-47) Ó ń lo ẹgbẹ́ Jòhánù yìí láti jẹ́ ká mọ ìtumọ̀ àsọtẹ́lẹ̀.
7. (a) Kí ló yẹ káwọn àmì tá a rí nínú ìwé Ìṣípayá sún wa ṣe? (b) Báwo ló ti pẹ́ tó tí àwọn kan lára ẹgbẹ́ Jòhánù ti ń nípìn-ín nínú ìmúṣẹ àwọn ìran inú ìwé Ìṣípayá?
7 Àpọ́sítélì Jòhánù kọ̀wé pé Jésù fi Ìṣípayá hàn “nípa àwọn àmì,” tàbí àwọn ìṣàpẹẹrẹ. Àwọn wọ̀nyí ṣe kedere, a ó sì gbádùn ṣíṣàyẹ̀wò wọn. Wọ́n fi ìgbòkègbodò tó lágbára hàn, nítorí náà, ó yẹ kó ru àwa náà sókè láti fi ìtara sapá láti jẹ́ kí àwọn ẹlòmíràn mọ àsọtẹ́lẹ̀ yìí àti ìtumọ̀ rẹ̀. Ìṣípayá fi ọ̀pọ̀ ìran amúnitakìjí hàn wá, Jòhánù sì kópa yálà ní tààràtà tàbí gẹ́gẹ́ bí òǹwòran nínú ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn. Àwọn tí wọ́n jẹ́ ara ẹgbẹ́ Jòhánù, tí àwọn kan lára wọn ti nípìn-ín nínú ìmúṣẹ ìran wọ̀nyí fún ọ̀pọ̀ ọdún, láyọ̀ pé ẹ̀mí Ọlọ́run ti ṣí ìtumọ̀ rẹ̀ payá kí wọ́n bàa lè ṣàlàyé rẹ̀ fún àwọn ẹlòmíràn.
-
-
Àwọn Ohun Tó Gbọ́dọ̀ Ṣẹlẹ̀ Láìpẹ́Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
9. (a) Bíi ti Jòhánù, kí ni ẹgbẹ́ Jòhánù ti òde òní ti ṣe? (b) Báwo ni Jòhánù ṣe fi ọ̀nà bá a ṣe lè di aláyọ̀ hàn wá?
9 Jòhánù fi ìṣòtítọ́ jẹ́rìí sí ìhìn tí Ọlọ́run fi fún un nípasẹ̀ Jésù Kristi. Ó ṣe kúlẹ̀kúlẹ̀ àpèjúwe “gbogbo ohun tí ó rí.” Ẹgbẹ́ Jòhánù ti fi gbogbo ọkàn wá ìtọ́sọ́nà lọ́dọ̀ Ọlọ́run àti Jésù Kristi láti lè lóye àsọtẹ́lẹ̀ náà ní kíkún kí wọ́n sì sọ àwọn kókó inú rẹ̀ di mímọ̀ fún àwọn èèyàn Ọlọ́run. Fún àǹfààní ìjọ àwọn ẹni àmì òróró (àti àwọn ogunlọ́gọ̀ ńlá jákèjádò àwọn orílẹ̀-èdè, àwọn ẹni tí Ọlọ́run yóò pa mọ́ láàyè la ìpọ́njú ńlá náà já), Jòhánù kọ̀wé pé: “Aláyọ̀ ni ẹni tí ń ka àwọn ọ̀rọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ yìí sókè àti àwọn tí ń gbọ́, tí wọ́n sì ń pa àwọn ohun tí a kọ sínú rẹ̀ mọ́; nítorí àkókò tí a yàn kalẹ̀ ti sún mọ́lé.”—Ìṣípayá 1:3.
-