-
A Rí Ìtumọ̀ Àṣírí Ọlọ́wọ̀ KanÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
16. (a) Àwọn wo ni àwọn aṣáájú ìsìn ṣọ́ọ̀ṣì ní ìkórìíra ńlá fún? (b) Kí ló ṣẹlẹ̀ nínú ìsìn àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì ní Ìbẹ̀rẹ̀ Ìgbà Ọ̀làjú? (d) Ǹjẹ́ àtakò àwọn Pùròtẹ́sítáǹtì tàbí àtúnṣe wọn yí ìpẹ̀yìndà àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì padà?
16 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn aṣáájú ìsìn ṣọ́ọ̀ṣì sọ pé àwọn jẹ́ olùṣọ́ àgùntàn agbo Ọlọ́run, wọ́n ní ìkórìíra ńlá fún ẹnikẹ́ni tó bá gbìyànjú láti fún àwọn ẹlòmíì níṣìírí láti ka Bíbélì tàbí ẹnikẹ́ni tó bá túdìí àṣírí àwọn ohun tí wọ́n ń ṣe tí kò bá Ìwé Mímọ́ mu. John Hus àti William Tyndale tó jẹ́ olùtumọ̀ Bíbélì ni wọ́n ṣenúnibíni sí tí wọ́n sì pa. Ní Ìbẹ̀rẹ̀ Ìgbà Ọ̀làjú, ìṣàkóso àwọn Kristẹni apẹ̀yìndà bá a débi pé ìjọ Kátólíìkì gbé ilé ẹjọ́ kan kalẹ̀ tó ń fi ìwà ìkà ṣèwádìí àwọn tó bá sọ tàbí tó ṣe ohun tó yàtọ̀ sí ẹ̀kọ́ ṣọ́ọ̀ṣì. Ẹnikẹ́ni tó bá ta ko ẹ̀kọ́ tàbí àṣẹ ṣọ́ọ̀ṣì ni wọ́n fìyà jẹ láìsí ojú àánú, àìlóǹkà ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn tí wọ́n pè ní olùyapa ni wọ́n sì dá lóró títí tí wọ́n fi kú tàbí tí wọ́n dáná sun lórí òpó igi. Báyìí ni Sátánì ṣe gbìyànjú láti rí i dájú pé òun tètè gbẹ̀mí ẹnikẹ́ni tó bá jẹ́ ojúlówó irú-ọmọ ètò Ọlọ́run tó dà bí obìnrin. Nígbà táwọn Pùròtẹ́sítáǹtì ta ko ẹ̀kọ́ Kátólíìkì, ìyẹn ni pé, nígbà tí wọ́n fẹ́ ṣàtúnṣe sí àwọn ẹ̀kọ́ Kátólíìkì (láti ọdún 1517 síwájú), ọ̀pọ̀ lára àwọn ṣọ́ọ̀ṣì Pùròtẹ́sítáǹtì fi irú ẹ̀mí yìí kan náà hàn, wọ́n fi hàn pé àwọn ò lè fàyè gba ohun táwọn ò fẹ́. Àwọn náà jẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ nípa fífi ikú pa àwọn tí wọ́n gbìyànjú láti jẹ́ adúróṣinṣin sí Ọlọ́run àti Kristi. Ní tòdodo, wọ́n tú “ẹ̀jẹ̀ àwọn ẹni mímọ́” jáde yàlàyàlà!—Ìṣípayá 16:6; fi wé Mátíù 23:33-36.
-
-
A Rí Ìtumọ̀ Àṣírí Ọlọ́wọ̀ KanÌṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
-
-
[Àwọn àwòrán tó wà ní ojú ìwé 31]
Àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì mú ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ ńlá wá sórí ara wọn. Wọ́n ṣe bẹ́ẹ̀ ní ti pé wọ́n ṣe inúnibíni, wọ́n sì pa àwọn tí wọ́n ń ṣètumọ̀ Bíbélì, àwọn tí wọ́n ń kà á, tàbí àwọn tí wọ́n tilẹ̀ ní in lọ́wọ́
-