ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • A Rí Ojútùú Ohun Ìjìnlẹ̀ Kan Tó Ṣeni Ní Kàyéfì
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • 13. (a) Kí ni dídarapọ̀ táwọn aṣáájú ìsìn ayé dara pọ̀ mọ́ àjọ Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè láti bẹ̀bẹ̀ fún àlàáfíà fi hàn? (b) Ìmúṣẹ àsọtẹ́lẹ̀ wo ni igbe fún àlàáfíà yóò jálẹ̀ sí?

      13 Bákan náà, báwọn aṣáájú ìsìn ayé ṣe dara pọ̀ mọ́ àjọ Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè láti bẹ̀bẹ̀ fún àlàáfíà lákòókò yìí fi nǹkan kan hàn. Àwọn aṣáájú ìsìn náà yóò fẹ́ láti darí Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè fún àǹfààní ara wọn, pàápàá lóde òní tí ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ ìjọ wọn ń pa ìsìn tì. Bíi tàwọn aláìṣòótọ́ aṣáájú Ísírẹ́lì ayé àtijọ́, wọ́n ń kéde pé, “‘Àlàáfíà wà! Àlàáfíà wà!’ nígbà tí kò sí àlàáfíà.” (Jeremáyà 6:14) Ó dájú pé igbe wọn fún àlàáfíà ò ní yéé dún, ńṣe ni yóò máa dún sókè sí i láti fi hàn pé ohun tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ tẹ́lẹ̀ yóò nímùúṣẹ. Pọ́ọ̀lù sọ pé: “Ọjọ́ Jèhófà ń bọ̀ gẹ́gẹ́ bí olè ní òru. Ìgbà yòówù tí ó jẹ́ tí wọ́n bá ń sọ pé: ‘Àlàáfíà àti ààbò!’ nígbà náà ni ìparun òjijì yóò dé lọ́gán sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ìroragógó wàhálà lórí obìnrin tí ó lóyún; wọn kì yóò sì yèbọ́ lọ́nàkọnà.”—1 Tẹsalóníkà 5:2, 3.

      14. Ọ̀nà wo ló ṣeé ṣe kí igbe “Àlàáfíà àti ààbò!” gbà dún, kí sì lẹnì kan lè ṣe tí ìyẹn ò fi ní tàn án jẹ?

      14 Láwọn ọdún àìpẹ́ yìí, àwọn olóṣèlú ti lo gbólóhùn náà, “àlàáfíà àti ààbò” láti fi ṣàpèjúwe oríṣiríṣi ohun tí àwọn ènìyàn ń gbèrò láti ṣe. Ǹjẹ́ akitiyan tí àwọn aṣáájú ayé ń ṣe yìí ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmúṣẹ 1 Tẹsalóníkà 5:3? Àbí gbankọgbì ìṣẹ̀lẹ̀ kan tó máa gbàfiyèsí gbogbo ayé ni Pọ́ọ̀lù ń sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀? Níwọ̀n bó ti jẹ́ pé lẹ́yìn tí àwọn àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì bá ṣẹ tán tàbí nígbà tí wọ́n bá ń ṣẹ lọ́wọ́ la sábà máa ń lóye wọn ní kíkún, a ní láti ṣe sùúrù ká wo ibi tí ọ̀rọ̀ náà máa já sí. Àmọ́, ó dá àwọn Kristẹni lójú pé bí ayé tiẹ̀ ń sọ pé ọwọ́ àwọn tẹ àlàáfíà àti ààbò lọ́nà kan tàbí òmíràn, ohunkóhun ò ní yí padà. Ìdí ni pé, ìmọtara-ẹni-nìkan, ìkórìíra, ìwà ọ̀daràn, fífọ́ tí ìdílé ń fọ́, ìṣekúṣe, àìsàn, ìbànújẹ́ àti ikú á ṣì máa ṣẹlẹ̀. Ìdí nìyẹn tí kò fi yẹ kí igbe “àlàáfíà àti ààbò” kankan tan ìwọ jẹ tó o bá ń wà lójúfò láti mọ ìtumọ̀ àwọn ohun tó ń ṣẹlẹ̀ láyé tó o sì ń kọbi ara sí ìkìlọ̀ tó wà nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.—Máàkù 13:32-37; Lúùkù 21:34-36.

  • Pípa Bábílónì Ńlá Run
    Ìṣípayá—Ìparí Rẹ̀ Ológo Kù sí Dẹ̀dẹ̀!
    • Orí 35

      Pípa Bábílónì Ńlá Run

      1. Báwo ni áńgẹ́lì náà ṣe ṣàlàyé ẹranko ẹhànnà aláwọ̀ rírẹ̀dòdò yẹn, irú ọgbọ́n wo la sì nílò láti lóye àwọn ohun ìṣàpẹẹrẹ inú Ìṣípayá?

      ÁŃGẸ́LÌ náà tún ṣàlàyé síwájú sí i fún Jòhánù nípa ẹranko ẹhànnà aláwọ̀ rírẹ̀dòdò tí Ìṣípayá 17:3 sọ náà, ó ní: “Níhìn-ín ni ibi tí làákàyè tí ó ní ọgbọ́n ti wọlé: Orí méje náà túmọ̀ sí òkè ńlá méje, níbi tí obìnrin náà jókòó lé. Ọba méje ni ó sì ń bẹ: márùn-ún ti ṣubú, ọ̀kan wà, ọ̀kan tí ó kù kò tí ì dé, ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá dé, yóò dúró fún ìgbà kúkúrú.” (Ìṣípayá 17:9, 10) Ọgbọ́n tó wá látòkè ni áńgẹ́lì yìí ń sọ, ìyẹn ọgbọ́n kan ṣoṣo tó lè mú wa lóye àwọn ohun ìṣàpẹẹrẹ inú ìwé Ìṣípayá. (Jákọ́bù 3:17) Ọgbọ́n yìí ló ń mú kí ẹgbẹ́ Jòhánù àtàwọn alábàákẹ́gbẹ́ rẹ̀ lóye bí àkókò tá à ń gbé yìí ti ṣe pàtàkì tó. Ó ń jẹ́ káwọn tó ń fi gbogbo ọkàn sin Jèhófà mọrírì àwọn ìdájọ́ Jèhófà tó máa wáyé láìpẹ́, ó sì ń jẹ́ ká mọ bá a ṣe lè bẹ̀rù Jèhófà lọ́nà tó yẹ. Gẹ́gẹ́ bí Òwe 9:10 ṣe wí: “Ìbẹ̀rù Jèhófà ni ìbẹ̀rẹ̀ ọgbọ́n, ìmọ̀ Ẹni Mímọ́ Jù Lọ sì ni ohun tí òye jẹ́.” Kí ni ọgbọ́n Ọlọ́run ṣí payá fún wa nípa ẹranko ẹhànnà yìí?

      2. Kí ni ìtumọ̀ orí méje ẹranko ẹhànnà aláwọ̀ rírẹ̀dòdò náà, báwo ló sì ṣe jẹ́ pé “márùn-ún ti ṣubú, [tí] ọ̀kan [sì] wà”?

      2 Orí méje ẹranko tó rorò yẹn túmọ̀ sí “òkè ńlá” méje, tàbí “ọba” méje. Ìwé Mímọ́ lo èdè méjèèjì náà láti tọ́ka sí agbára ìṣàkóso. (Jeremáyà 51:24, 25; Dáníẹ́lì 2:34, 35, 44, 45) Bíbélì mẹ́nu kan agbára ayé mẹ́fà tí wọ́n ti ní ipa kan tàbí òmíràn lórí ìgbòkègbodò àwọn èèyàn Ọlọ́run. Àwọn agbára ayé náà ni: Íjíbítì, Ásíríà, Bábílónì, Mídíà òun Páṣíà, Gíríìsì, àti Róòmù. Lákòókò tí Jòhánù rí ìran Ìṣípayá yìí, márùn-ún lára àwọn agbára ayé náà ò sí mọ́, Róòmù ló wà nípò gẹ́gẹ́ bí agbára ayé nígbà náà. Èyí bá gbólóhùn náà mu pé, “márùn-ún ti ṣubú, ọ̀kan wà.” Ṣùgbọ́n èwo ni “ọ̀kan tí ó kù” tí ò tíì dé?

      3. (a) Báwo ni Ilẹ̀ Ọba Róòmù ṣe pín sí méjì? (b) Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wo ló wáyé ní apá ti Ìwọ̀ Oòrùn? (d) Kí ló yẹ kó jẹ́ èrò wa nípa àgbègbè tí wọ́n ń pè ní Ilẹ̀ Ọba Róòmù Mímọ́?

      3 Ilẹ̀ Ọba Róòmù wà fúngbà pípẹ́, kódà ó tiẹ̀ tún gbòòrò sí i fún ọgọ́rọ̀ọ̀rún ọdún lẹ́yìn ìgbà ayé Jòhánù pàápàá. Lọ́dún 330 Sànmánì Kristẹni, Olú Ọba Kọnsitatáìnì sọ ìlú Bìsáńṣíọ̀mù di olú ìlú rẹ̀ dípò ìlú Róòmù, ó sì yí orúkọ ìlú yìí padà sí Kọnsitantinópù. Nígbà tó di ọdún 395 Sànmánì Kristẹni ilẹ̀ ọba Róòmù pín sí méjì, ó di Ilẹ̀ Ọba Róòmù ti Ìlà Oòrùn àti Ilẹ̀ Ọba Róòmù ti Ìwọ̀ Oòrùn. Ọba kan tó ń jẹ́ Alaric ṣẹ́gun ìlú Róòmù lọ́dún 410 Sànmánì Kristẹni. Alaric yìí jẹ́ ọba àwọn Visigoth tí í ṣe ẹ̀yà kan nílẹ̀ Jámánì tí wọ́n di ara ẹ̀ya ìsìn Kristẹni kan tí Arius dá sílẹ̀. Àwọn ẹ̀yà kan nílẹ̀ Jámánì táwọn náà jẹ́ “Kristẹni” ṣẹ́gun orílẹ̀-èdè Sípéènì àti ọ̀pọ̀ lára àwọn àgbègbè tí Róòmù ń ṣàkóso ní Àríwá Áfíríkà. Àwọn ọ̀rúndún kan wà tí nǹkan ò fara rọ nílẹ̀ Yúróòpù, tó jẹ́ pé rògbòdìyàn òun wàhálà ṣíṣe onírúurú àtúntò ni ṣáá. Àwọn olú ọba alágbára bẹ̀rẹ̀ sí í ṣàkóso ní Ilẹ̀ Ọba Róòmù ti Ìwọ̀ Oòrùn, irú bíi Charlemagne tó bá Póòpù Leo Kẹta wọnú àdéhùn ní ọ̀rúndún kẹsàn-án àti Frederick Kejì tó ṣàkóso ní ọ̀rúndún kẹtàlá. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Ilẹ̀ Ọba Róòmù Mímọ́ ni wọ́n ń pe àgbègbè tí wọ́n ṣàkóso lé lórí, síbẹ̀ ó kéré jọjọ bá a bá fi wé ibi tí ìṣàkóso Ilẹ̀ Ọba Róòmù ti tẹ́lẹ̀ dé nígbà tó gbòòrò jù lọ. Àgbègbè tí wọn ṣàkóso lé lórí tí wọn pè ní Ilẹ̀ Ọba Róòmù Mímọ́ kì í ṣe ilẹ̀ ọba tuntun, ńṣe ló dà bí ìgbà tí wọ́n kàn ṣàtúnṣe sí ilẹ̀ ọba ti tẹ́lẹ̀ tàbí bíi pé ilẹ̀ ọba ti tẹ́lẹ̀ náà ló ṣì wà.

      4. Àwọn àṣeyọrí wo ni apá kan Ilẹ̀ Ọba Róòmù ti Ìlà Oòrùn ṣe, ṣùgbọ́n kí ló ṣẹlẹ̀ sí púpọ̀ lára àwọn àgbègbè tó wà lábẹ́ ìjọba Róòmù ìgbàanì ní Àríwá Áfíríkà, Sípéènì, àti Síríà?

      4 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé wàhálà ń wáyé láàárín Ilẹ̀ Ọba Róòmù ti Ìlà Oòrùn tí ibùjókòó ìjọba rẹ̀ wà ní Kọnsitantinópù àti Ilẹ̀ Ọba Róòmù ti Ìwọ Oòrùn, apá ti Ìlà Oòrùn ń bá ìṣàkóso rẹ̀ lọ. Ní ọ̀rúndún kẹfà, olú ọba ti Ìlà Oòrùn tó ń jẹ́ Justinian Kìíní ṣẹ́gun ọ̀pọ̀ àgbègbè ní Àríwá Áfíríkà, ó sì tún dá sí ọ̀ràn orílẹ̀-èdè Sípéènì àti Ítálì. Ní ọ̀rúndún keje, Justinian Kejì gba gbogbo ilẹ̀ tó wà ní Makedóníà padà èyí táwọn ẹ̀yà Slav tó ṣẹ́gun wọn tẹ́lẹ̀ gbà. Ṣùgbọ́n, nígbà tó fi máa di ọ̀rúndún kẹjọ, púpọ̀ lára ibi tó wà lábẹ́ ìjọba Róòmù ìgbàanì ní Àríwá Áfíríkà, Sípéènì, àti Síríà ti kúrò lábẹ́ Kọnsitantinópù àti Róòmù, ó sì ti di tàwọn ẹlẹ́sìn Ìsìláàmù tó ṣẹ̀ṣẹ̀ gbàkóso.

      5. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ṣẹ́gun ìlú Róòmù lọ́dún 410 Sànmánì Kristẹni, báwo ló ṣe jẹ́ pé ọ̀pọ̀ ọ̀rúndún sí i kọjá kó tó di pé ọwọ́ àkóso Ilẹ̀ Ọba Róòmù kúrò láwùjọ pátápátá?

      5 Ìlú Kọnsitantinópù ní tirẹ̀ wà bó ṣe wà fún ọ̀pọ̀ ọdún. Lemọ́lemọ́ làwọn ará Páṣíà, Arébíà, Bulgaria, àti Rọ́ṣíà bá ìlú náà jà tí wọn ò borí ẹ̀ kí wọ́n tó wá ṣẹ́gun rẹ̀ lọ́dún 1203. Àmọ́ kì í ṣe àwọn Mùsùlùmí ló ṣẹ́gun rẹ̀, àwọn Ajagun ẹ̀sìn Kristẹni tó wá láti Ìwọ̀ Oòrùn nítorí àtigba Ilẹ̀ Mímọ́ padà ló ṣẹ́gun rẹ̀. Nígbà tó wá di ọdún 1453, Mehmed Kejì tó jẹ́ Mùsùlùmí tó ń ṣojú àwọn Ottoman ṣẹ́gun ìlú Kọnsitantinópù, kò sì pẹ́ tí ìlú náà fi di olú ìlú Ilẹ̀ Ọba Ottoman, tàbí Turkey. Nípa báyìí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ṣẹ́gun ìlú Róòmù lọ́dún 410 Sànmánì Kristẹni, ọ̀pọ̀ ọ̀rúndún sí i ló kọjá kó tó di pé ọwọ́ àkóso Ilẹ̀ Ọba Róòmù kúrò láwùjọ pátápátá. Síbẹ̀, wọ́n ṣì ń kan ipa rẹ̀ lágbo ìsìn nípasẹ̀ àwọn póòpù tó ń ṣàkóso ní Róòmù àtàwọn ṣọ́ọ̀ṣì Ọ́tọ́dọ́ọ̀sì Ìlà Oòrùn Ayé.

      6. Àwọn orílẹ̀-èdè wo tó fẹ́ máa ṣàkóso gbogbo ayé ló bọ́ sójútáyé, èwo ló sì kẹ́sẹ járí jù lọ nínú wọn?

      6 Ṣùgbọ́n, nígbà tó di ọ̀rúndún kẹẹ̀ẹ́dógún, àwọn orílẹ̀-èdè kan bẹ̀rẹ̀ sí í wá ọ̀nà àtidá àwọn ilẹ̀ ọba tuntun sílẹ̀. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ara àwọn ibi tí Ilẹ̀ Ọba Róòmù ń ṣàkóso nígbà kan rí ni díẹ̀ lára àwọn orílẹ̀-èdè tó ń gbèrò àtidi ilẹ̀ ọba wọ̀nyí, ìṣàkóso wọn yàtọ̀ sí ti Róòmù pátápátá. Ilẹ̀ Potogí, Sípéènì, Faransé àti Holland wá ń gbókèèrè ṣàkóso àwọn ilẹ̀ mìíràn. Ṣùgbọ́n Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì ló kẹ́sẹ járí jù lọ nítorí pé ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè ló ń ṣàkóso lé lórí tó sì tipa bẹ́ẹ̀ jẹ́ ilẹ̀ ọba gbígbòòrò kan tó jẹ́ pé bí oòrùn bá ṣe ń wọ̀ ní apá kan ilẹ̀ ọba rẹ̀ ni yóò máa yọ ní ibòmíràn. Díẹ̀díẹ̀ ni àkóso ilẹ̀ ọba yìí ń tàn títí tó fi dé ọ̀pọ̀ lára àwọn orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà ti Àríwá, Áfíríkà, Íńdíà, àti Ìlà Oòrùn Éṣíà tó fi mọ́ àwọn Gúúsù Pàsífíìkì tó lọ salalu.

      7. Báwo ló ṣe di pé orílẹ̀-èdè méjì para pọ̀ di agbára ayé, báwo sì ni Jòhánù ṣe sọ pé ‘orí’ keje, tàbí agbára ayé keje, ṣe máa pẹ́ tó?

      7 Nígbà tó fi máa di ọ̀rúndún kọkàndínlógún, díẹ̀ lára àwọn ibi tí Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì ń gbókèèrè ṣàkóso lé lórí ní Amẹ́ríkà ti Àríwá ti kúrò lábẹ́ Ìjọba Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì tí wọ́n sì para pọ̀ di Orílẹ̀-Èdè Amẹ́ríkà. Àmọ́ rògbòdìyàn òṣèlú ṣì ń bá a lọ láàárín orílẹ̀-èdè tuntun náà àti Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì tó ń ṣàkóso rẹ̀ tẹ́lẹ̀. Ṣùgbọ́n Ogun Àgbáyé Kìíní jẹ́ kí orílẹ̀-èdè méjèèjì rí ìdí tó fi yẹ kí wọ́n jọ fìmọ̀ ṣọ̀kan, ni wọ́n bá jọ wọnú àjọṣe tó jinlẹ̀. Bí orílẹ̀-èdè méjèèjì, ìyẹn Orílẹ̀-Èdè Amẹ́ríkà tó jẹ́ orílẹ̀-èdè tó lọ́rọ̀ jù lọ báyìí àti Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì tó ń ṣàkóso ibi tó pọ̀ jù lọ ṣe para pọ̀ di agbára ayé nìyẹn, tí wọ́n jọ ń ṣàkóso gbogbo ayé. Ìṣàkóso tá à ń sọ yìí ni ‘orí’ keje, tàbí agbára ayé keje, èyí tó ṣì wà lójú ọpọ́n ní àkókò òpin yìí, tó sì ń ṣàkóso àgbègbè táwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà òde òní kọ́kọ́ fìdí múlẹ̀ sí. Bá a bá fi ìwọ̀n àkókò tí orí keje fi ṣàkóso wé èyí tí orí kẹfà fi ṣàkóso, “ìgbà kúkúrú” ni orí keje fi máa wà títí dìgbà tí Ìjọba Ọlọ́run fi máa pa gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tó kù run.

      Ọba Kẹjọ Kẹ̀?

      8, 9. Kí ni áńgẹ́lì náà pe ẹranko ẹhànnà ìṣàpẹẹrẹ náà tó ní àwọ̀ rírẹ̀dòdò, ọ̀nà wo ló sì gbà jáde wá látinú àwọn méje náà?

      8 Áńgẹ́lì náà ṣàlàyé síwájú sí i fún Jòhánù pé: “Ẹranko ẹhànnà tí ó sì ti wà tẹ́lẹ̀ ṣùgbọ́n tí kò sí, òun fúnra rẹ̀ pẹ̀lú ni ọba kẹjọ, ṣùgbọ́n ó jáde wá láti inú àwọn méje náà, ó sì kọjá lọ sínú ìparun.” (Ìṣípayá 17:11) Ẹranko ẹhànnà ìṣàpẹẹrẹ náà tó ní àwọ̀ rírẹ̀dòdò jẹ́ ère “ẹranko ẹhànnà” ìṣáájú tó gòkè wá “láti inú òkun.” Ẹranko ẹhànnà aláwọ̀ rírẹ̀dòdò yìí “jáde wá láti inú” àwọn orí méje “ẹranko ẹhànnà” ìṣáájú náà, ìyẹn ni pé àwọn orí méje náà ló bí i, tàbí lédè mìíràn, àwọn ló jẹ́ kó wà. Ọ̀nà wo ló fi jáde wá látinú àwọn orí méje náà? Bó ṣe rí rèé: Lọ́dún 1919, Gẹ̀ẹ́sì àti Amẹ́ríkà ni agbára ayé tó ń ṣàkóso láàárín orí méje náà. Orí mẹ́fà tó ṣáájú ti subú, ipò agbára ayé sì ti bọ́ sọ́wọ́ orí méjì tó para pọ̀ yìí, òun ló sì ń ṣàkóso gbogbo ayé. Orí keje yìí, tó jẹ́ agbára ayé tó wà lójú ọpọ́n láàárín àwọn agbára ayé mẹ́fà tó ti wà tẹ́lẹ̀, ló fi Ìmùlẹ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè lọ́lẹ̀, òun kan náà ló sì ń ṣe agbátẹrù Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè tó sì ń pèsè owó ìná fún un. Nípa bẹ́ẹ̀, lọ́nà ìṣàpẹẹrẹ, ẹranko ẹhànnà aláwọ̀ rírẹ̀dòdò náà, ìyẹn ọba kẹjọ tí í ṣe Ìmùlẹ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè àti lẹ́yìn náà, Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè, “jáde wá láti inú” orí méje àkọ́kọ́. Bá a bá wò ó lọ́nà yìí, gbólóhùn náà pé ó jáde wá látinú orí méje wà ní ìbámu pẹ̀lú Ìṣípayá ìṣáájú tó sọ pé ẹranko ẹhànnà náà tó ní ìwo méjì bíi ti ọ̀dọ́ àgùntàn (ìyẹn agbára ayé Gẹ̀ẹ́sì àti Amẹ́ríkà, tí í ṣe orí keje ẹranko ẹhànnà ìṣáájú yẹn) ń ṣìpẹ̀ pé kí wọ́n ṣe ère náà, tó sì fún un ní ìyè.—Ìṣípayá 13:1, 11, 14, 15.

      9 Láfikún, yàtọ̀ sí Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì, àwọn orílẹ̀-èdè míì tó para pọ̀ dá àjọ Ìmùlẹ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè sílẹ̀ jẹ́ àwọn ìjọba tó ti ṣàkóso ní àwọn àgbègbè tí àwọn orí tàbí agbára ayé ti ìṣáájú wà tẹ́lẹ̀ rí, ìyẹn àwọn bíi Gíríìsì, orílẹ̀-èdè Iran (ìyẹn Páṣíà ayé ọjọ́un), àti Ítálì (ìyẹn agbára ayé Róòmù ayé ọjọ́un). Nígbà tó yá, àwọn orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba tó ń ṣàkóso àgbègbè tó wà lábẹ́ àwọn agbára ayé mẹ́fà ìṣáájú wá ń ṣètìlẹyìn fún ère ẹranko ẹhànnà náà. Lọ́nà yìí pẹ̀lú, a lè sọ pé ẹranko ẹhànnà aláwọ̀ rírẹ̀dòdò náà jáde wá látinú àwọn agbára ayé méje náà.

      10. (a) Kí nìdí tá a fi lè sọ pé ẹranko ẹhànnà aláwọ̀ rírẹ̀dòdò “fúnra rẹ̀ pẹ̀lú ni ọba kẹjọ”? (b) Báwo ni ọ̀kan lára àwọn aṣáájú Ìjọba Soviet Union tẹ́lẹ̀ rí ṣe ti Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè lẹ́yìn?

      10 Kíyè sí i pé ẹranko ẹhànnà aláwọ̀ rírẹ̀dòdò yìí kan náà tún “ni ọba kẹjọ.” Nípa báyìí, ṣe ní wọ́n gbé Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè kalẹ̀ bí ìjọba tó ń ṣàkóso gbogbo ayé. Kódà nígbà mìíràn, ó máa ń ṣe bí ọba gbogbo ayé nípa bó ṣe máa ń rán àwọn ọmọ ogun lọ sójú ogun láti lọ pẹ̀tù sí ìjà àárín àwọn orílẹ̀-èdè, gẹ́gẹ́ bó ṣe ṣe ní Kòríà, ní àgbègbè Sínáì tí omi fẹ́rẹ̀ẹ́ yí ká, láwọn orílẹ̀-èdè kan nílẹ̀ Áfíríkà, àti ní Lẹ́bánónì. Ṣùgbọ́n ère ọba kan ló wulẹ̀ jẹ́. Bíi ti ère ìsìn, kò lè dá nǹkan gidi kan ṣe kò sì dá agbára kan ní yàtọ̀ sí èyí táwọn tó gbé e kalẹ̀ tí wọ́n sì ń jọ́sìn rẹ̀ bá fún un pé kó lò. Láwọn ìgbà míì, ó máa ń dà bíi pé ó rẹ ẹranko ẹhànnà ìṣàpẹẹrẹ yìí; ṣùgbọ́n kò tíì sígbà kan táwọn orílẹ̀-èdè aláṣẹ bóofẹ́bóokọ̀ tó wà nínú àjọ Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè kọ̀ ọ́ sílẹ̀ pátápátá rí bí wọ́n ṣe kọ Ìmùlẹ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè sílẹ̀ tó fi lọ sínú ọ̀gbun àìnísàlẹ̀. (Ìṣípayá 17:8) Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹnì kan tó jẹ́ ọ̀kan pàtàkì lára àwọn aṣáájú Ìjọba Soviet Union nígbà kan rí kò fara mọ́ èrò àwọn mìíràn lórí àwọn nǹkan kan, síbẹ̀ ní ọdún 1987, òun náà dara pọ̀ mọ́ àwọn póòpù Róòmù láti ṣètìlẹyìn fún àjọ Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè. Kódà ó ní “káwọn ṣètò ààbò tó máa délé dóko ní gbogbo ayé” káwọn sì fi sí ìkáwọ́ àjọ Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè. Bí Jòhánù ṣe mọ̀ nígbà tó yá, ìgbà kan ń bọ̀ tí àjọ Ìparapọ̀ Àwọn Orílẹ̀-Èdè á lo àṣẹ ńlá. Lẹ́yìn náà, òun fúnra ẹ̀ á “lọ sínú ìparun.”

      Ọba Mẹ́wàá fún Wákàtí Kan

      11. Kí ni áńgẹ́lì Jèhófà sọ nípa ìwo mẹ́wàá ẹranko ẹhànnà ìṣàpẹẹrẹ náà tó ní àwọ̀ rírẹ̀dòdò?

      11 Ní Ìṣípayá orí kẹrìndínlógún, áńgẹ́lì kẹfà àti ìkeje da àwọn àwokòtò ìbínú Ọlọ́run jáde. Èyí fi yé wa pé àwọn ọba ilẹ̀ ayé ti ń kóra jọ sí ogun Ọlọ́run ní Amágẹ́dọ́nì àti pé ‘a óò rántí Bábílónì Ńlá níwájú Ọlọ́run.’ (Ìṣípayá 16:1, 14, 19) Ní báyìí, á fẹ́ bẹ̀rẹ̀ sí í gbọ́ kúlẹ̀kúlẹ̀ bí àwọn ìdájọ́ Ọlọ́run ṣe máa ṣẹ lé wọn lórí. Tún gbọ́ ohun tí áńgẹ́lì Jèhófà sọ fún Jòhánù. “Ìwo mẹ́wàá tí ìwọ sì rí túmọ̀ sí ọba mẹ́wàá, tí kò tíì gba ìjọba, ṣùgbọ́n wọ́n gba ọlá àṣẹ bí ọba fún wákàtí kan pẹ̀lú ẹranko ẹhànnà náà. Àwọn wọ̀nyí ní ìrònú kan ṣoṣo, nítorí náà, wọ́n fún ẹranko ẹhànnà náà ní agbára àti ọlá àṣẹ wọn. Àwọn wọ̀nyí yóò bá Ọ̀dọ́ Àgùntàn náà jagun, ṣùgbọ́n, nítorí pé òun ni Olúwa àwọn olúwa àti Ọba àwọn ọba, Ọ̀dọ́ Àgùntàn náà yóò ṣẹ́gun wọn. Pẹ̀lúpẹ̀lù, àwọn tí a pè, tí a yàn, tí wọ́n sì jẹ́ olùṣòtítọ́ pẹ̀lú rẹ̀ yóò ṣe bẹ́ẹ̀.”—Ìṣípayá 17:12-14.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́