-
Ìbẹ̀rẹ̀ Ọjọ́ Tí Ó Ṣekókó NaaỌkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
-
-
Orí 105
Ìbẹ̀rẹ̀ Ọjọ́ Tí Ó Ṣekókó Naa
NIGBA ti Jesu fi Jerusalẹmu silẹ ní alẹ́ Monday, ó pada sí Bẹtani ní ìlà-oòrùn gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Òkè Olifi. Ọjọ́ meji tí ó gbẹ̀hìn iṣẹ-ojiṣẹ rẹ̀ ní Jerusalẹmu ti parí. Láìsí iyemeji Jesu tún lo alẹ́ naa lẹẹkan sii lọ́dọ̀ Lasaru ọ̀rẹ́ rẹ̀. Lati igba tí ó ti dé lati Jẹriko ní Friday, eyi jẹ́ ọjọ́ kẹrin rẹ̀ ní Bẹtani.
Nisinsinyi, ní kùtùkùtù owúrọ̀ Tuesday, Nisan 11, oun ati awọn ọmọ-ẹhin rẹ̀ tún wà loju ọ̀nà lẹẹkan sii. Eyi jásí ọjọ́ kan tí ó ṣekókó ninu iṣẹ-ojiṣẹ Jesu, eyi ti ó kún fun igbokegbodo julọ títí di isinsinyi. Ó jẹ́ ọjọ́ tí ó farahan kẹhin ní tẹmpili. Ó sì tún jẹ́ ọjọ́ tí ó kẹhin ninu iṣẹ-ojiṣẹ rẹ̀ ní gbangba ṣaaju ìjẹ́jọ́ rẹ̀ ati ìfìyà ikú jẹ ẹ́.
Jesu ati awọn ọmọ-ẹhin rẹ̀ gba oju ọna kan naa lórí Òkè Olifi síhà Jerusalẹmu. Ní ojú ọ̀nà tí ó ti Bẹtani wá yẹn, Peteru ṣakiyesi igi naa tí Jesu fi bú ní òwúrọ̀ ọjọ́ tí ó ṣaaju. “Rabi, wò bí igi ọ̀pọ̀tọ́ tí iwọ fi bú ti gbẹ,” ni ó ṣe sáàfúlà.
Ṣugbọn èéṣe tí Jesu fi pa igi naa? Ó ṣalaye idi eyi nigba ti ó nbaa lọ lati wipe: “Lóòótọ́ ni mo wí fun yin, bí ẹyin bá ní igbagbọ, tí ẹ kò bá sì ṣiyemeji, ẹyin kì yoo ṣe kìkì eyi ti a ṣe sí igi ọ̀pọ̀tọ́ yii, ṣugbọn bí ẹyin bá tilẹ̀ wí fun òkè yii [Òkè Olifi lórí eyi ti wọn dúró sí], Ṣídìí, kí o sì bọ́ sinu òkun, yoo ṣẹ. Ohunkohun gbogbo tí ẹyin bá beere ninu adura pẹlu igbagbọ, ẹyin yoo rí i gbà.”
Nitori naa nipa mímú kí igi naa gbẹ, Jesu npese fun awọn ọmọ-ẹhin rẹ̀ ẹ̀kọ́ tí ó ṣeé fojúrí kan nipa àìní wọn lati ní igbagbọ ninu Ọlọrun. Gẹgẹ bi oun ti sọ: “Ohunkohun tí ẹyin bá tọrọ nigba ti ẹ bá ngbadura, ẹ gbagbọ pé ẹ ti rí wọn gbà ná, yoo sì rí bẹẹ fun yin.” Ẹ̀kọ́ ṣíṣe pàtàkì wo nìyìí fun wọn lati kọ́, paapaa lójú ìwòye awọn ìdánwò abanilẹru tí yoo dé laipẹ! Sibẹsibẹ, ìfarakọ́ra mìíràn wà láàárín gbígbẹ tí igi naa gbẹ ati animọ níní igbagbọ.
Orilẹ-ede Isirẹli, bii igi ọ̀pọ̀tọ́ yii, ní irisi ti ntannijẹ. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé orilẹ-ede naa wà ninu ibatan onímájẹ̀mú pẹlu Ọlọrun tí ó sì lè farahan lóde pe oun ńpa awọn ìlànà rẹ̀ mọ́, ó ti fi ẹ̀rí jíjẹ́ aláìní ìgbàgbọ́ hàn, tí kò lè mú èso tí ó dara jade. Nitori ṣíṣàìní igbagbọ, o tilẹ tún ńfẹ́ lati ṣá Ọmọkunrin Ọlọrun fúnraarẹ̀ tì! Nipa bayii, mímú kí igi ọ̀pọ̀tọ́ tí kò ní eso naa gbẹ, Jesu ńfihàn ni kedere ohun tí iyọrisi ikẹhin yoo jẹ́ fun orilẹ-ede tí kò ní eso, tí kò sì ní ìgbàgbọ́ yii.
Kété lẹhin naa, Jesu ati awọn ọmọ-ẹhin rẹ̀ wọ̀ Jerusalẹmu, ati gẹgẹ bi àṣà wọn, wọn lọ sí tẹmpili, nibi ti Jesu ti bẹ̀rẹ̀síí kọ́ni. Awọn olórí alufaa ati awọn àgbààgbà awọn eniyan naa, laiṣiyemeji ní ìgbésẹ̀ Jesu lodisi awọn tí nṣe pàṣípààrọ̀ owó ní ọjọ́ tí ó ṣaaju lọ́kàn, pè é níjà: “Ọlá-àṣẹ wo ni iwọ fi ńṣe nǹkan wọnyi? Ta ni ó sì fun ọ ní ọlá-àṣẹ yii?”
Ní fífèsìpadà Jesu wí pé: ‘Emi yoo sì bi yin léèrè ohun kan, bí ẹyin bá sọ fun mi, emi yoo sì sọ fun yin ọlá-àṣẹ tí emi fi ńṣe nǹkan wọnyi: Baptisi Johanu, níbo ni ó ti wá? Lati ọ̀run wá ni, tabi lati ọ̀dọ̀ eniyan?’
Awọn alufaa ati awọn àgbààgbà bẹ̀rẹ̀síí gbèrò láàárín araawọn niti bí awọn yoo ṣe dahun. “Bí awa bá wí pé, Lati ọ̀run wá ni, oun yoo wí fun wa pé, Èéhatiṣe tí ẹyin kò fi gbà á gbọ́? Ṣugbọn bí awa bá sì wipe, Lati ọ̀dọ̀ eniyan; awa nbẹru ìjọ eniyan, nitori gbogbo wọn kà Johanu sí wòlíì.”
Awọn aṣaaju naa kò mọ̀ ohun tí awọn yoo fi dahun. Nitori naa wọn dá Jesu lóhùn pé: “Awa kò mọ̀.”
Jesu, ẹ̀wẹ̀, wipe: ‘Nitori naa emi kì yoo sì wí fun yin ọlá-àṣẹ tí emi fi ńṣe nǹkan wọnyi.’ Matiu 21:19-27; Maaku 11:19-33; Luuku 20:1-8.
▪ Ki ni ohun tí ó jámọ́pàtàkì nipa Tuesday, Nisan 11?
▪ Awọn ẹ̀kọ́ wo ni Jesu pèsè nigba ti ó mú kí igi ọ̀pọ̀tọ́ kan gbẹ?
▪ Bawo ni Jesu ṣe dá awọn wọnni tí wọn beere nipa ọlá-àṣẹ tí oun fi ńṣe awọn nǹkan lohun?
-
-
Awọn Àkàwé Ọgbà Àjàrà Tú Wọn FóỌkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
-
-
Orí 106
Awọn Àkàwé Ọgbà Àjàrà Tú Wọn Fó
JESU wà ní tẹmpili. Oun ṣẹ̀ṣẹ̀ kó ìdààmú bá awọn aṣaaju-isin ti wọn nfi dandangbọ̀n béèrè nipa ọlá-àṣẹ ẹni ti oun fi ńṣe awọn nǹkan. Ṣaaju kí wọn tó bọ́ kuro ninú ìdàrúdàpọ̀ wọn, Jesu beere pe: “Ki ni ẹyin rò?” Ati pe lẹhin naa nipasẹ àkàwé kan, ó fihàn wọn irú eniyan tí wọn jẹ́ niti gidi.
“Ọkunrin kan ní ọmọ meji,” ni Jesu sọ. “Ní lílọ sọ́dọ̀ ekinni, ó wipe, ‘Ọmọ, lọ ṣiṣẹ́ lonii ninu ọgbà àjàrà.’ Ní ìdáhùn eleyii wipe, ‘Emi yoo lọ, baba,’ ṣugbọn kò jade lọ. Ní títọ ekeji lọ, ó wí nǹkan kan naa. Ní ìfèsìpadà eleyii wipe, ‘Emi kì yoo lọ.’ Lẹhin ìgbà naa ó kábàámọ̀ ó sì jade lọ. Ewo ninu awọn mejeeji ni ó ṣe ìfẹ́-inú baba rẹ̀?” ni Jesu beere.
“Ekeji,” ni awọn alatako rẹ̀ dáhùn.
Nitori naa Jesu ṣàlàyé pe: “Lóòótọ́ ni mo wí fun yin pe awọn agbowó-orí ati awọn aṣẹ́wó ńlọ ṣiwaju yin sínú ijọba Ọlọrun.” Awọn agbowó-orí ati awọn aṣẹ́wó niti tootọ, kọ̀ lati ṣiṣẹ́sìn Ọlọrun ní ìbẹ̀rẹ̀. Ṣugbọn lẹhin naa, gẹgẹ bi ọmọ keji, wọn ronúpìwàdà wọn sì ṣiṣẹ́sìn ín. Ní ọwọ́ keji ẹ̀wẹ̀, awọn aṣaaju isin, bi ọmọ àkọ́kọ́, jẹ́wọ́ pe awọn ńṣiṣẹ́sìn Ọlọrun, sibẹsibẹ, gẹgẹ bi Jesu ti sọ: “Johanu [Arinibọmi] wá sọ́dọ̀ yin ní ọ̀nà òdodo, ṣugbọn ẹyin kò gbà á gbọ́. Bí ó ti wù kí ó rí, awọn agbowó-orí ati awọn aṣẹ́wó gbà á gbọ́, ati ẹyin, bí ó tilẹ jẹ́ pe ẹyin rí eyi, kò kábàámọ̀ lẹhin ìgbà naa kí ẹ baa lè gbà á gbọ́.”
Tẹle eyi Jesu fihàn pe ìkùnà awọn aṣaaju-isin wọnyi kìí wulẹ ṣe ṣíṣàì fẹ́ ṣiṣẹ́sìn Ọlọrun. Bẹẹkọ, ṣugbọn wọn jẹ́ olubi niti tootọ, awọn eniyan buruku. “Ọkunrin kan wà, baálé ilé kan,” ni Jesu sọ, “ẹni tí ó gbìn ọgbà àjàrà kan tí ó sì sọ ọgbà yí i ká ó sì wá ilẹ̀ ìfúntí kan sínú rẹ̀ ó sì gbé ilé-ìṣọ́ kan nàró, ó sì fi i háyà fun awọn aroko, ó sì rin ìrìn àjò lọ sí ìdálẹ̀. Nigba ti àsìkò awọn èso dé, ó rán awọn ẹrú rẹ̀ lọ kíákíá sọ́dọ̀ awọn aroko naa lati gba awọn èso rẹ̀. Bí ó ti wù kí ó rí, awọn aroko naa mú awọn ẹrú rẹ̀, wọn sì lù ọ̀kan, wọn pa òmíràn, wọn sọ òmíràn lókùúta. Ó tún ran awọn ẹrú miiran lọ, tí wọn pọ̀ ju ti àkọ́kọ́, ṣugbọn wọn ṣe bakan naa sí awọn wọnyi.”
“Awọn ẹrú” naa ni awọn wolii tí “baálé ilé” naa, Jehofa Ọlọrun, rán sí “awọn aroko” “ọgbà àjàrà” rẹ̀. Awọn aroko wọnyi jẹ́ awọn aṣaaju aṣoju orílẹ̀-èdè Isirẹli, orílẹ̀-èdè tí Bibeli fihàn gẹgẹ bi “ọgbà àjàrà” Ọlọrun.
Niwọn bi “awọn aroko” naa ti fojú “awọn ẹrú” wọnyi gbolẹ̀ tí wọn sì pa wọn, Jesu ṣàlàyé pe: “Ni ìgbẹ̀hìn [ẹni tí ó ni ọgbà àjàrà naa] rán ọmọkunrin rẹ̀ sí wọn kiakia, ní wiwi pe, ‘Wọn yoo bọ̀wọ̀ fun ọmọkunrin mi.’ Nigba tí wọn rí ọmọkunrin naa awọn aroko naa wí láàárín araawọn pe, ‘Eyi ni ajogún; ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á kí a sì gba ogún rẹ̀!’ Nitori naa wọn mú un wọn sì sọ ọ́ sóde ọgbà àjàrà naa wọn sì pa á.”
Nisinsinyi, ní sísọ̀rọ̀ tààràtà sí awọn aṣaaju-isin naa, Jesu beere pe: “Nigba ti ẹni tí ó ní ọgbà àjàrà naa bá dé, ki ni yoo ṣe fun awọn aroko wọnni?”
“Nitori pe wọn jẹ́ olubi,” ni awọn aṣaaju isin wọnni dáhùn, “oun yoo mú ìparun ibi wá sórí wọn yoo sì fi ọgbà àjàrà naa háyà fun awọn aroko miiran, awọn tí yoo fun un ní awọn èso nigba ti àkókò wọn bá tó.”
Awọn aṣaaju-isin naa nipa bayii pòkìkí ìdájọ́ sórí araawọn láìmọ̀, niwọn bi wọn ti wà lára awọn ọmọ Isirẹli “aroko” orílẹ̀-èdè Jehofa, “ọgbà àjàra” ti Isirẹli. Èso tí Jehofa reti lati ọ̀dọ̀ awọn aroko naa ni ìgbàgbọ́ ninu Ọmọkunrin rẹ̀, Mesaya tootọ naa. Nitori ìkùnà wọn lati pèsè irúfẹ́ èso bẹẹ, Jesu kìlọ̀ pe: “Ẹyin kò ha kà ninu Iwe Mimọ [ní Saamu 118:22, 23] pe, ‘Òkúta tí awọn ọ̀mọ̀lé ṣátì ni eyi tí ó ti di pàtàkì òkúta igun ilé. Lati ọ̀dọ̀ Jehofa ni eyi ti ṣẹlẹ̀, ó sì jẹ́ ìyanu ní ojú wa’? Eyi ni ìdí tí mo fi wí fun yin pe, A ó gba ijọba Ọlọrun lọwọ yin a ó sì fi i fun orílẹ̀-èdè kan tí yoo maa mú awọn èso rẹ̀ wá. Pẹlupẹlu, eniyan tí ó bá ṣubú lù òkúta yii ni a ó fọ́ túútúú. Ẹnikẹni tí ó bá sì ṣubú lù, yoo lọ̀ ọ́ lúúlúú.”
Awọn akọwe ofin ati awọn olórí alufaa wá mọ̀ nisinsinyi pe Jesu ńsọ̀rọ̀ nipa wọn, wọn sì fẹ́ lati pa á, “àjogún” títọ̀nà naa. Nitori naa àǹfààní jíjẹ́ awọn olùṣàkóso ninu Ijọba Ọlọrun ni a ó gbà kuro lọwọ wọn gẹgẹ bi orílẹ̀-èdè kan, orílẹ̀-èdè ‘awọn aroko ọgbà àjàrà,’ titun kan, ọ̀kan tí yoo maa mú awọn èso yíyẹ jáde ni a o sì dá silẹ.
Nitori awọn aṣaaju-isin naa bẹ̀rù awọn ogunlọgọ, tí wọn ka Jesu sí wolii kan, wọn kò gbìyànjú lati pa á ní àkókò yii. Matiu 21:28-46, NW; Maaku 12:1-12; Luuku 20:9-19; Aisaya 5:1-7.
▪ Awọn wo ni awọn ọmọ meji naa ninu àkàwé àkọ́kọ́ Jesu naa dúró fun?
▪ Ninu akawe keji, ta ni “baálé ilé,” “ọgbà àjàrà,” “awọn aroko,” “awọn ẹrú,” ati “ajogún” naa dúró fún?
▪ Ki ni yoo ṣẹlẹ̀ sí ‘awọn aroko ọgbà àjàrà’ naa, awọn wo ni yoo sì rọ́pò wọn?
-
-
Àkàwé Nipa Àsè ÌgbéyàwóỌkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
-
-
Orí 107
Àkàwé Nipa Àsè Ìgbéyàwó
NIPASẸ awọn àkàwé meji, Jesu ti túdìí àṣírí awọn akọwe ofin ati awọn olórí alufaa, wọn sì fẹ́ lati pa á. Ṣugbọn Jesu kò tíì ṣetán pẹlu wọn rárá. Ó nbaa lọ lati sọ àkàwé miiran fun wọn sibẹsibẹ, ní wiwi pe:
“Ijọba awọn ọrun ti dabi ọkunrin kan, ọba kan, tí ó se àsè igbeyawo fun ọmọkunrin rẹ̀. Ó sì rán awọn ẹrú rẹ̀ jade lati késí awọn wọnni tí a pè sí àsè ìgbéyàwó naa, ṣugbọn wọn kò fẹ́ lati wá.”
Jehofa Ọlọrun ni Ọba naa tí ó pèsè àsè ìgbéyàwó kan silẹ fun Ọmọkunrin rẹ̀, Jesu Kristi. Nikẹhin, 144,000 iyawo rẹ̀, awọn ọmọlẹhin ẹni àmì-òróró ni a ó sopọ̀ṣọ̀kan pẹlu rẹ̀ ninu ọ̀run. Awọn ọmọ-abẹ́ Ọba naa ni awọn eniyan Isirẹli, awọn ẹni tí wọn gba àǹfààní naa lati di “ijọba awọn alufaa” nigba tí a mú wọn wá sínú majẹmu Òfin ní 1513 B.C.E. Nipa bayii, ní àkókò yẹn, a nawọ́ ìkésíni sí wọn ní ìpilẹ̀ṣẹ̀ lati wá síbi àsè ìgbéyàwó naa.
Bí ó ti wù kí ó rí, ìpè àkọ́kọ́ sí awọn tí a késí wọnni kò jáde lọ títí di ìgbà ìwọ́wé 29 C.E., nigba ti Jesu ati awọn ọmọ-ẹhin rẹ̀ (awọn ẹrú ọba naa) bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ wọn ti wiwaasu Ijọba naa. Ṣugbọn awọn ọmọ Isirẹli àbínibí tí wọn gba ìpè tí ó jade lati ọ̀dọ̀ awọn ẹrú naa lati 29 C.E. sí 33 C.E. kò ṣetan lati wá. Nitori naa Ọlọrun fun orílẹ̀-èdè awọn ẹni tí a késí naa ní àǹfààní miiran, gẹgẹ bi Jesu ti ṣalaye:
“Oun sì tún rán awọn ẹrú miiran, wipe, ‘Ẹ sọ fun awọn wọnni tí a ti pè: “Ẹ wòó! mo ti pèsè oúnjẹ mi silẹ, a ti pa awọn akọ maluu ati awọn ẹranko àbọ́pa mi, ohun gbogbo sì ti wà ní sẹpẹ́. Ẹ wá sí àsè ìgbéyàwó naa.”’” Ìpè keji tí ó gbẹ̀hìn yii sí awọn wọnni tí a késí bẹ̀rẹ̀ ní Pẹntikọsi 33 C.E., nigba ti a tú ẹmi mimọ jáde sórí awọn ọmọlẹhin Jesu. Ìpè yii nbaa lọ títí di 36 C.E.
Eyi ti o pọ julọ ninu awọn ọmọ Isirẹli, bí ó ti wù kí ó rí, kọ ìpè yii silẹ tẹ̀gàntẹ̀gàn pẹlu. “Wọn lọ láìbìkítà,” ni Jesu ṣàlàyé, “ọ̀kan sí pápá tirẹ̀, òmíràn sí iṣẹ́ òwò rẹ̀; ṣugbọn awọn yooku, ní dídi awọn ẹrú rẹ̀ mú, hùwà àfojúdi sí wọn wọn sì pa wọn.” “Ṣugbọn,” Jesu nbaa lọ, “ọba naa kún fun ìbínú, ó sì rán awọn ọmọ-ogun rẹ̀ ó sì pa awọn àpànìyàn wọnni run ó sì fi iná sun ìlú wọn.” Eyi wáyé ní 70 C.E., nigba ti a run Jerusalẹmu délẹ̀ wómúwómú lati ọwọ́ awọn ara Roomu, tí a sì pa awọn àpànìyàn wọnni.
Lẹhin naa Jesu ṣalaye ohun tí ó wáyé láàárín àkókò naa: “Nigba naa [ni ọba] wí fun awọn ẹrú rẹ̀ pe, ‘Àsè ìgbéyàwó naa ti wà ní sẹpẹ́, ṣugbọn awọn tí a ti pè jẹ́ aláìyẹ. Nitori naa ẹ lọ sí ojú ọ̀nà tí ó jade kuro ní ìlú naa, ẹnikẹni tí ẹyin bá sì rí ni kí ẹ pè wá sí àsè ìgbéyàwó naa.’” Awọn ẹrú naa ṣe eyi, “iyàrá fun ayẹyẹ ìgbéyàwó naa sì kún fun awọn wọnni tí wọn ńrọ̀gbọ̀kú nídìí tábìlì.”
Iṣẹ́ kíkó awọn àlejò jọ yii lati awọn ojú ọ̀nà ní òde ìlú awọn ẹni tí a késí naa bẹ̀rẹ̀ ní 36 C.E. Ọ̀gágun ara Roomu naa, Kọniliu ati idile rẹ̀ ni awọn aláìkọlà ti kii ṣe Juu àkọ́kọ́ tí a kójọ. Ìkówọlé awọn ẹni tí kii ṣe Juu wọnyi, gbogbo awọn ẹni tí wọn jẹ́ arọ́pò fun awọn wọnni tí wọn kọ ìpè naa ni ìpilẹ̀ṣẹ̀, tí nbaa lọ wọnú ọ̀rúndún ogún yii.
Ó jẹ́ láàárín ọ̀rúndún ogún yii ni iyàrá fun ayẹyẹ ìgbéyàwó naa kún. Jesu sọ ohun tí ó wáyé lẹhin naa, ni wiwi pe: “Nigba ti ọba wọlé wá lati ṣe àyẹ̀wò awọn àlejò naa ó rí ọkunrin kan nibẹ tí kò wọ ẹ̀wù ìgbéyàwó. Nitori naa ó wí fun un pe, ‘Àwé, bawo ni iwọ ṣe wọ ìhín wá láìwọ ẹ̀wù ìgbéyàwó?’ Oun kò sì lè fèsì. Nigba naa ni ọba wí fun awọn iranṣẹ rẹ̀ pe, ‘Ẹ dì í tọwọ́tẹsẹ̀ kí ẹ sì sọ ọ́ sínú òkùnkùn lóde. Nibẹ ni sísunkún ati pípahínkeke rẹ̀ yoo wà.’”
Ọkunrin tí kò wọ ẹ̀wù ìgbéyàwó naa ṣàpẹẹrẹ awọn fàwọ̀rajà Kristẹni ti Kristẹndọmu. Ọlọrun kò fi ìgbà kankan wò wọn gẹgẹ bi awọn tí wọn ní àmì ìdánimọ̀ títọnà gẹgẹ bi ọmọ Isirẹli tẹmi. Ọlọrun kò fi igba kankan fòróró yàn wọn pẹlu ẹ̀mí mímọ́ gẹgẹ bi awọn ajogún Ijọba. Nitori naa a jù wọn sóde sínú òkùnkùn níbi tí wọn yoo ti jìyà ìparun.
Jesu pari àkàwé rẹ̀ nipa wíwí pe: “Nitori ọpọlọpọ ni a késí, ṣugbọn diẹ ni a yàn.” Bẹẹni, ọpọlọpọ ni a késí lati inú orílẹ̀-èdè Isirẹli lati di mẹmba iyawo Kristi, ṣugbọn kìkì iwọnba diẹ awọn ọmọ Isirẹli àbínibí ni a yàn. Ọ̀pọ̀ jùlọ ninu awọn 144,000 àlejò naa tí wọn rí èrè ti ọ̀run gbà fi ẹ̀rí hàn pe wọn kii ṣe ọmọ Isirẹli. Matiu 22:1-14; Ẹkisodu 19:1-6; Iṣipaya 14:1-3, NW.
▪ Awọn wo ni a késí ní ìpilẹ̀ṣẹ̀ síbi àsè aṣeyẹ ìgbéyàwó naa, nigba wo ni a sì nawọ́ ìkésíni naa sí wọn?
▪ Nigba wo ni ìpè naa kọ́kọ́ jáde lọ fun awọn tí a késí, awọn wo sì ni awọn ẹrú tí a lò lati mú ìpè naa jáde?
▪ Nigba wo ni a nawọ́ ìpè keji, awọn wo ni a sì késí nígbẹ̀hìn gbẹ́hín?
▪ Awọn wo ni ọkunrin tí kò ní ẹ̀wù aṣeyẹ ìgbéyàwó naa ṣapẹẹrẹ?
▪ Awọn wo ni ọpọlọpọ tí a késí, ati iwọnba diẹ tí a yàn?
-
-
Wọn Kùnà Lati Dẹkùn Mú JesuỌkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
-
-
Orí 108
Wọn Kùnà Lati Dẹkùn Mú Jesu
NITORI Jesu ti ńkọ́ni ninu tẹmpili tí ó sì ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ àkàwé mẹta fun awọn ọ̀tá rẹ̀ onisin tí ó túdìí àṣírí ìwà burúkú wọn, awọn Farisi binu, wọn sì gbìmọ̀pọ̀ lati mú kí ó sọ ohun kan ti wọn lè tipasẹ̀ rẹ̀ fàṣẹ ọba mú un. Wọn hùmọ̀ rìkíṣí kan wọn sì rán awọn ọmọ-ẹhin wọn, papọ pẹlu awọn ọmọlẹhin ẹgbẹ́ Hẹrọdu, lati gbiyanju lati mú un ṣe àṣìṣe ninu ọ̀rọ̀ sísọ.
Awọn ọkunrin wọnyi wipe: “Olukọ, awa mọ̀ pe iwọ jẹ́ olùṣòtítọ́ iwọ sì ńkọ́ni ni ọ̀nà Ọlọrun ni otitọ, iwọ kò sì bikita fun ẹnikẹni, nitori iwọ kìí wò ìrísí ode awọn eniyan. Nitori naa, sọ fun wa, Ki ni iwọ rò? Ó ha bófinmú lati san owó-orí fun Kesari tabi bẹẹkọ?”
Àpọ́nlé naa kò mú Jesu hùwà bí òmùgọ̀. Ó mọ pe bí oun bá sọ pe, ‘Bẹẹkọ, kò bófinmu tabi tọ̀nà lati san owó-orí yii,’ oun yoo jẹ̀bi ìṣọ̀tẹ̀ sí ijọba Roomu. Sibẹ, bí oun bá wipe, ‘Bẹẹni, ẹyin nilati san owó-orí yii,’ awọn Juu, tí wọn ńtẹ́ḿbẹ́lú ìtẹ̀lóríba wọn fun Roomu, yoo koriira rẹ̀. Nitori naa ó dahun pe: “Eeṣe ti ẹ fi ńdán mi wò, ẹyin àgàbàgebè? Ẹ fi ẹyọ-owó kan hàn mi.”
Nigba ti wọn mú ọ̀kan wá fun un, ó beere pe: “Àwòrán ati àkọlé ta ni eyi?”
“Ti Kesari ni,” ni wọn fèsìpadà.
“Nitori naa, ẹ san awọn ohun ti Kesari padà fun Kesari, ṣugbọn awọn ohun ti Ọlọrun fun Ọlọrun.” Tóò, nigba ti awọn ọkunrin wọnyi gbọ idahun titayọlọla yii, ẹnu yà wọn. Wọn lọ kuro wọn sì fi i silẹ jẹ́jẹ́.
Ní rírí ìkùnà awọn Farisi lati rí ohun kan lodisi Jesu, awọn Sadusi, tí wọn sọ pe ajinde kò sí, sunmọ ọn wọn sì beere pe: “Olukọ, Mose wipe, ‘Bí ọkunrin eyikeyii kan bá kú láìní awọn ọmọ, arakunrin rẹ̀ gbọdọ gbé aya rẹ̀ ni iyawo kí ó sì gbé ọmọ-inú dide fun arakunrin rẹ̀.’ Nisinsinyi awọn arakunrin meje ti wà lọ́dọ̀ wa; ekinni sì gbéyàwó o sì kú, bí ko sì ti ní ọmọ, o fi aya rẹ̀ silẹ fun arakunrin rẹ̀. Ó ṣẹlẹ̀ ni ọ̀nà kan naa pẹlu sí ekeji ati ẹkẹta, títí dé ọ̀dọ̀ awọn mejeeje. Ní ikẹhin gbogbo wọn obinrin naa kú. Nitori naa, ní ajinde, aya ti ta ni yoo jẹ́ ninu awọn mejeeje? Nitori gbogbo wọn ti fẹ́ ẹ.”
Ní fífèsìpadà Jesu wipe: “Eyi ha kọ ni ìdí ti ẹyin fi ṣe àṣìṣe, mímọ̀ tí ẹ kò mọ̀ Iwe Mimọ tabi agbára Ọlọrun? Nitori nigba ti wọn bá dide kuro ninu òkú, awọn ọkunrin kìí gbéyàwó bẹẹni a kìí fi awọn obinrin funni ni ìgbeyàwó, ṣugbọn wọn dabi awọn angẹli ninu awọn ọ̀run. Ṣugbọn niti awọn òkú, pe a ńgbé wọn dide, ẹyin kò ha ti kà ninu iwe Mose, ninu àkọsílẹ̀ nipa igbó ẹ̀gún, bí Ọlọrun ti wi fun un pe, ‘Emi ni Ọlọrun Aburahamu ati Ọlọrun Isaki ati Ọlọrun Jakọbu’? Oun jẹ́ Ọlọrun, kìí ṣe ti awọn òkú, bikoṣe ti awọn alààyè. Ẹyin ṣe àṣìṣe pupọ.”
Lẹẹkan sii awọn ogunlọgọ naa ni háà ṣe sí idahun Jesu. Koda diẹ lara awọn akọ̀wé òfin jẹ́wọ́ pe: “Olukọ, o sọ̀rọ̀ daradara.”
Nigba ti awọn Farisi rí i pe Jesu ti pa awọn Sadusi lẹnu mọ́, wọn tọ̀ ọ́ wá ni awujọ kanṣoṣo. Lati dán an wò siwaju sii, akọwe ofin kan ninu wọn beere pe: “Olukọ, ewo ni òfin tí ó tobi julọ ninu Ofin?”
Jesu fèsì pe: “Ekinni ni, ‘Gbọ, Óò Isirẹli, Jehofa Ọlọrun wa Jehofa kan ni, iwọ sì gbọdọ nífẹ̀ẹ́ Jehofa Ọlọrun rẹ pẹlu gbogbo ọkàn-àyà rẹ̀ ati pẹlu gbogbo ọkàn rẹ ati pẹlu gbogbo èrò-inú rẹ ati pẹlu gbogbo okun rẹ.’ Ekeji ni eyi, ‘Iwọ gbọdọ nífẹ̀ẹ́ aládùúgbò rẹ̀ gẹgẹ bi araarẹ.’ Kò si òfin miiran tí ó tobi ju iwọnyi.” Nitootọ, Jesu fikun un pe: “Lori òfin meji wọnyi ni gbogbo Òfin rọ̀ mọ́, ati awọn Wolii.”
“Olukọ, iwọ wi daadaa ni ibamu pẹlu otitọ,” ni akọ̀wé òfin naa gba. “‘Oun jẹ Ọ̀kan, kò sì sí ẹlomiran ju Oun lọ’; ati nínífẹ̀ẹ́ rẹ̀ yii pẹlu gbogbo ọkàn-àyà ẹni ati gbogbo òye ẹni ati pẹlu gbogbo okun ẹni ati nínífẹ̀ẹ́ aládùúgbò ẹni yii gẹgẹ bi ara-ẹni ṣeyebíye pupọ jìnnà jù gbogbo ọrẹ ẹbọ sísun ati awọn ẹbọ.”
Ní mímọ̀ pe akọ̀wé òfin naa ti dahun pẹlu ọgbọ́n, Jesu sọ fun un pe: “Iwọ kò jinna sí ijọba Ọlọrun.”
Fun ọjọ́ mẹta nisinsinyi—Sunday, Monday, ati Tuesday—Jesu ti ńkọni ni tẹmpili. Awọn eniyan naa ti fetisilẹ si i pẹlu idunnu, sibẹ awọn aṣaaju isin ńfẹ́ lati pa á, ṣugbọn titi di àkókò yii ìsapá wọn ni a ti mú jákulẹ̀. Matiu 22:15-40; Maaku 12:13-34; Luuku 20:20-40, NW.
▪ Rìkíṣí wo ni awọn Farisi pète lati fi mú Jesu, ki ni yoo sì yọrisi bí oun bá nilati funni ni idahun bẹẹni tabi bẹẹkọ?
▪ Bawo ni Jesu tún ṣe peékan ìgbìdánwò awọn Sadusi lati mú un?
▪ Ìgbìdánwò siwaju sii wo ni awọn Farisi ṣe lati dán Jesu wò, kí sì ni àbárèbábọ̀ rẹ̀?
▪ Lakooko iṣẹ́-òjìṣẹ́ rẹ̀ tí ó gbẹ̀hìn ni Jerusalẹmu, ọjọ́ meloo ni Jesu fi kọni ni tẹmpili, pẹlu iyọrisi wo sì ni?
-
-
Jesu Fi Awọn Alátakò Rẹ̀ BúỌkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
-
-
Orí 109
Jesu Fi Awọn Alátakò Rẹ̀ Bú
JESU ti kó ìdààmú bá awọn onísìn alátakò rẹ̀ pátápátá tobẹẹ tí wọn fi bẹ̀rù lati bi í leere ohunkohun siwaju sii. Nitori naa ó lo ìdánúṣe lati túdìí àìmọ̀kan wọn. “Ki ni ẹyin rò nipa Kristi naa?” ni oun beere. “Ọmọkunrin ta ni oun jẹ́?”
“Ti Dafidi,” ni awọn Farisi naa dahun.
Bí ó tilẹ jẹ́ pe Jesu kò sẹ́ pe Dafidi jẹ́ babanla Kristi, tabi Mesaya naa nipa ti ara, ó beere pe: “Nigba naa, bawo ni Dafidi, nipasẹ ìmísí [ní Saamu 110] ṣe pè é ní ‘Oluwa,’ wipe, ‘Jehofa wí fun Oluwa mi pe: “Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi títí emi yoo fi fi awọn ọ̀tá rẹ sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ”’? Nitori naa, bí Dafidi bá pè é ní ‘Oluwa,’ bawo ni oun ṣe jẹ́ ọmọkunrin rẹ̀?”
Awọn Farisi naa dákẹ́, nitori wọn kò mọ ẹni tí Kristi, tabi ẹni àmì-òróró naa jẹ́ nitootọ. Mesaya naa kìí wulẹ ṣe ènìyàn ọmọ-ìran Dafidi, gẹgẹ bi ó ti hàn gbangba pe awọn Farisi gbàgbọ́ pe ó jẹ́, ṣugbọn oun ti wà ní ọ̀run rí ó sì ti jẹ Oluwa Dafidi, tabi ẹni tí ó ga lọ́lá jù ú lọ.
Ní yíyípadà nisinsinyi sí awọn ogunlọgọ naa ati sí awọn ọmọ-ẹhin rẹ̀, Jesu kìlọ̀ nipa awọn akọ̀wé òfin ati awọn Farisi. Niwọn bi awọn wọnyi ti ńkọ́ni ní Òfin Ọlọrun, tí ‘wọn ti fi araawọn jókòó ní ìjókòó Mose,’ Jesu rọ̀ wọn pe: “Ohun gbogbo tí wọn bá sọ fun yin, ni kí ẹ ṣe kí ẹ sì pamọ́.” Ṣugbọn ó fikun un pe: “Ẹ maṣe ṣe gẹgẹ bi awọn ìṣe wọn, nitori wọn a maa wí ṣugbọn wọn kìí ṣe.”
Alágàbàgebè ni wọn, Jesu sì fi wọn bú ní èdè kan naa gan-an tí oun lò nigba tí ó njẹun ní ilé Farisi kan ní ọ̀pọ̀ oṣu ṣaaju. Ó sọ pe, “Gbogbo iṣẹ́ tí wọn ńṣe ni wọn ńṣe kí eniyan ba lè rí wọn.” Ó sì pèsè awọn apejuwe, ní wiwi pe:
“Wọn sọ awọn àpò tí wọn ní iwe mimọ ninu di fífẹ̀ eyi tí wọn gbéwọ̀ gẹgẹ bi awọn ohun ìdáàbòbò.” Awọn àpò wọnyi tí wọn kéré ní ifiwera, tí wọn ńfi sí iwájú orí tabi wọ̀ sí apá, ní apá mẹrin lara Òfin ninu: Ẹkisodu 13:1-10, 11-16; ati Deutaronomi 6:4-9; 11:13-21. Ṣugbọn awọn Farisi sọ ìtóbi awọn àpò wọnyi di pupọ sii lati fúnni ní èrò pe wọn jẹ́ onítara nipa ti Òfin.
Jesu nba ọ̀rọ̀ rẹ lọ pe wọn “sọ ìṣẹ́tí ẹ̀wù wọn di títóbi.” Ní Numeri 15:38-40 awọn ọmọ Isirẹli ni a pa á láṣẹ fun lati ṣe ìṣẹ́tí sí etí ẹ̀wù wọn, ṣugbọn awọn Farisi mú kí tiwọn tubọ tóbi jù bí ti awọn ẹlomiran ti rí lọ. Ohun gbogbo ni wọn ṣe fun àṣehàn! “Wọn fẹ́ ibi ọlá julọ,” ni Jesu polongo.
Ó baninínújẹ́ pe, awọn ọmọ-ẹhin oun tìkáraarẹ̀ ni èèràn ìfẹ́ fun ọlá yii ti ràn. Nitori naa ó gbà wọn nímọ̀ràn pe: “Ṣugbọn ẹyin, kí a maṣe pè yin ní Rabi, nitori ọ̀kan ni olukọ yin, nigba tí gbogbo yin jẹ́ arakunrin. Jù bẹ́ẹ̀ lọ, ẹ maṣe pe ẹnikẹni ní baba yin lórí ilẹ̀-ayé, nitori ọ̀kan ni Baba yin, Ẹni tí nbẹ ní ọ̀run. Bẹẹ ni kí a maṣe pè yin ní ‘aṣaaju,’ nitori ọ̀kan ni Aṣaaju yin, Kristi.” Awọn ọmọ-ẹhin gbọdọ mú ìfẹ́-ọkàn lati di ẹni àkọ́kọ́ kuro láàárín araawọn! “Ẹni tí ó tóbi jùlọ láàárín yin gbọdọ jẹ́ òjíṣẹ́ yin,” ni Jesu ṣí wọn létí.
Lẹhin eyiini ni oun kéde ọ̀wọ́ awọn ègbé lé awọn akọwe ati awọn Farisi lórí, ní pípè wọn ní àgàbàgebè léraléra. Ó sọ pe, wọn “sénà ijọba awọn ọrun niwaju awọn eniyan,” ati pe “awọn sì ni awọn ẹni tí ńjẹ ilé awọn opó run ati nitori àṣehàn wọn ńgbàdúrà gígùn.”
“Ègbé ni fun yin, ẹyin afọ́jú amọ̀nà,” ni Jesu wí. Ó sọ̀rọ̀ lodisi àìní ero ìdíyelé tẹmi awọn Farisi, gẹgẹ bi ó ti hàn ninu ìyàsọ́tọ̀ aláìnírònú tí wọn maa nṣe. Fun apẹẹrẹ, wọn sọ pe, ‘Kò jẹ́ nǹkankan bí ẹnikan bá fi tẹmpili búra, ṣugbọn ẹni tí ó bá fi wúrà tẹmpili búra wà lábẹ́ àìgbọdọ̀máṣe.’ Nipa gbígbé ìtẹnumọ́ ka wúrà tí ó wà ní tẹmpili dípò kí ó jẹ́ lórí iniyelori tẹmi ibi ìjọsìn yẹn, wọn ṣí ìfọ́jú wọn nipa ti ìwàrere payá.
Lẹhin naa, gẹgẹ bi ó ti ṣe ní iṣaaju, Jesu dẹ́bi fún awọn Farisi fun ṣíṣàìnáání “awọn ọ̀ràn Òfin wíwúwo jù, eyiini ni, ìdájọ́ òdodo ati àánú ati ìṣòtítọ́” nigba tí ó jẹ́ pe wọn nfi àfiyèsí ti o pọ fun sísan ìdámẹ́wàá, tabi apákan ninu mẹ́wàá ti awọn ewé aláìjámọ́ nǹkan.
Jesu pe awọn Farisi naa ní “afọ́jú amọ̀nà, tí ńyọ kantíkantí kuro ṣugbọn tí ńgbé ìbákasíẹ mì!” Wọn maa ńyọ kantíkantí kuro ninu wáìnì wọn, kìí wulẹ ṣe kìkì nitori pe ó jẹ́ kòkòrò, ṣugbọn nitori pe ó jẹ́ aláìmọ́ lọna ayẹyẹ ìsìn. Sibẹ, ṣíṣàìnáání awọn ọ̀ràn Òfin wíwúwo jù ṣeefiwera pẹlu gbígbé ìbákasíẹ mì, ẹranko kan tí kò mọ́ lọna ayẹyẹ ìsìn bakan-naa. Matiu 22:41–23:24; Maaku 12:35-40; Luuku 20:41-47; Lefitiku 11:4, 21-24.
▪ Eeṣe tí awọn Farisi fi dákẹ́ nigba ti Jesu bi wọn ní ibeere nipa ohun tí Dafidi sọ ninu Saamu 110?
▪ Eeṣe tí awọn Farisi fi sọ awọn àpò tí wọn ní Iwe Mimọ ninu ati ìṣẹ́tí ẹ̀wù wọn di títóbi?
▪ Ìmọ̀ràn wo ni Jesu fun awọn ọmọ-ẹhin rẹ̀?
▪ Ìyàsọ́tọ̀ aláìnírònú wo ni awọn Farisi maa ńṣe, bawo sì ni Jesu ṣe dẹ́bi fún wọn fun ṣíṣàìnáání awọn ọ̀ràn wíwúwo jù?
-
-
Iṣẹ́-òjíṣẹ́ ní Tẹmpili ParíỌkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
-
-
Orí 110
Iṣẹ́-òjíṣẹ́ ní Tẹmpili Parí
JESU ṣe ìfarahàn rẹ̀ ikẹhin ni tẹmpili. Niti tootọ, oun npari iṣẹ́-òjíṣẹ́ rẹ̀ itagbangba lori ilẹ̀-ayé àyàfi awọn ìṣẹ̀lẹ̀ lakooko ìgbẹ́jọ́ ati ìfìyà ikú jẹni rẹ ní ọjọ́ mẹta lẹhin naa. Nisinsinyi oun nbá ìbáwí mímúná rẹ̀ fun awọn akọ̀wé òfin ati awọn Farisi nìṣó.
Ní igba mẹta sii oun ṣe sáàfúlà pe: “Ègbé ni fun yin ẹyin akọ̀wé ati ẹyin Farisi, àgàbàgebè!” Lákọ̀ọ́kọ́ oun pòkìkí ègbé le wọn nitori wọn ńfọ “òde ife ati ti àwo oúnjẹ mọ́, ṣugbọn ninu wọn kún fun ìpiyẹ́ ati àìmọníwọ̀n.” Nitori naa oun fun wọn ní ìṣílétí pe: “Ẹ kọ́kọ́ fọ̀ inu ife ati ti àwo oúnjẹ mọ́, kí òde rẹ̀ lè di mímọ́tónítóní pẹlu.”
Lẹhin naa oun kede ègbé sori awọn akọ̀wé ati awọn Farisi fun ìjẹrà ninu ati ìdíbàjẹ́ tí wọn gbiyanju lati fi pamọ nipa ẹ̀mí-ìsìn ìhà-òde. Oun wipe, “Ẹyin dabi awọn isà-òkú tí a fi ẹfun kùn, níhà òde wọn farahàn nitootọ bi ẹlẹ́wà ṣugbọn ninu wọn kún fun egungun awọn òkú eniyan ati gbogbo iru oriṣi àìmọ́.”
Nikẹhin, àgàbàgebè wọn farahàn kedere ninu ìfẹ́ wọn lati kọ́ ibojì fun awọn wolii ati lati ṣe é lóge lati fà àfiyèsí sí awọn iṣẹ́ àánú tiwọn funraawọn. Sibẹ, gẹgẹ bi Jesu ti ṣí i payá, wọn jẹ́ “ọmọkunrin awọn wọnni tí wọn ṣìkàpa awọn wolii.” Nitootọ, ẹnikẹni tí ó bá gbójúgbóyà lati tú àṣírí àgàbàgebè wọn wà ninu ewu!
Ní titẹsiwaju, Jesu sọ awọn ọ̀rọ̀ ìfibú rẹ̀ lílágbára julọ jade. “Ẹyin ejò, ìran ọmọ awọn paramọ́lẹ̀,” ni oun wi, “bawo ni ẹyin yoo ṣe sá fun idajọ Gẹhẹna?” Gẹhẹna ni àfonífojì tí wọn ńlò gẹgẹ bi ibi tí a ńda pàǹtírí sí ní Jerusalẹmu. Nitori naa Jesu nsọ pe nitori lílépa ipa-ọ̀nà buruku wọn, awọn akọ̀wé òfin ati awọn Farisi yoo jiya iparun àìnípẹ̀kun.
Nipa awọn wọnni tí oun ran jade lọ gẹgẹ bi awọn aṣojú rẹ̀, Jesu sọ pe: “Awọn kan ninu wọn ni ẹyin yoo pa tí ẹ o sì kànmọ́gi, awọn kan ninu wọn ni ẹyin yoo sì nà ní pàṣán ninu awọn sinagọgu yin tí ẹ o sì ṣe inunibinu sí lati ilu dé ilu; kí ẹ̀jẹ̀ gbogbo awọn olododo tí a ti tasílẹ̀ lori ilẹ̀-ayé lè wá sori yin, lati ẹ̀jẹ̀ Ebẹli olododo títí dé ẹ̀jẹ̀ Sekaraya ọmọkunrin Barakaya [tí a pè ni Jehoada ni Kironika Keji], ẹni tí ẹyin ṣìkàpa laaarin ibùjọsìn ati pẹpẹ. Loootọ ni mo wi fun yin, Gbogbo nǹkan wọnyi yoo wá sori iran eniyan yii.”
Nitori pe Sekaraya dá awọn aṣaaju Isirẹli lẹ́bi lọna rírorò, “wọn di rìkíṣí, wọn sì sọ ọ́ ni òkúta nipa aṣẹ ọba ní àgbàlá ilé Oluwa [“Jehofa,” NW].” Ṣugbọn, gẹgẹ bi Jesu ti sọtẹlẹ Isirẹli yoo ṣe isanpada irufẹ gbogbo ẹ̀jẹ̀ olododo bẹẹ tí wọn tasílẹ̀. Wọn san an pada ní 37 ọdun lẹhin naa, ní 70 C.E., nigba ti ọmọ ogun Roomu pa Jerusalẹmu run tí ohun tí ó ju million kan awọn Juu sì ṣègbé.
Bí Jesu ti ńgbé ipò ti ndẹrubani yii yẹ̀wò, ìdààmú bá a. “Jerusalẹmu, Jerusalẹmu,” ni oun pòkìkí lẹẹkan sii, “bawo ni ó ti jẹ́ nígbàkugbà tó ti emi ti fẹ kó ọmọ rẹ jọpọ̀ ní ọ̀nà tí àgbébọ̀ adìyẹ fi ńkó awọn òròmọ adìyẹ jọpọ̀ sábẹ́ ìyẹ́-apá rẹ̀! Ṣugbọn ẹyin eniyan yii kò fẹ́ ẹ. Sáwòó! A pa ilé yin tì fun yin.”
Jesu fikun un lẹhin naa pe: “Ẹyin kì yoo rí mi mọ́ lọ́nàkọnà lati isinsinyi lọ́ títí ẹyin yoo fi wipe, ‘Olubukun ni ẹni naa tí ńbọ̀ ní orukọ Jehofa!’” Ọjọ́ yẹn yoo jẹ́ nigba wíwàníhìn-ín Kristi nigba ti ó bá dé sinu Ijọba rẹ̀ ti ọ̀run tí awọn eniyan sì rí i pẹlu ojú igbagbọ.
Jesu nisinsinyi sún sẹ́gbẹ́ẹ́kan nibi ti ó ti lè maa ṣọ́ awọn àpótí ìṣúra ninu tẹmpili ati awọn ogunlọgọ tí wọn nsọ owó sinu wọn. Awọn ọlọ́rọ̀ nsọ ọpọlọpọ ẹyọ-owó sinu rẹ̀. Ṣugbọn nigba naa òtòṣì opó kan wá sí ìtòsí ó sì sọ ẹyọ-owó kéékèèké meji tí wọn ní ìníyelórí kíkéré gan-an silẹ.
Ní pípè awọn ọmọ-ẹhin rẹ̀ súnmọ́tòsí, Jesu sọ pe: “Loootọ ni mo wi fun yin pe òtòṣì opó yii sọ owó pupọ sinu rẹ̀ ju gbogbo awọn wọnni tí ńsọ owó sinu àpótí ìṣúra.” Wọn gbọdọ ti ṣe kàyéfì bí eyi ṣe lè jẹ́ bẹẹ. Nitori naa Jesu ṣalaye pe: “Gbogbo wọn sọ sinu rẹ̀ lati inú ọpọ rẹpẹtẹ wọn, ṣugbọn oun, lati inú àìní rẹ̀, sọ gbogbo ohun tí ó ní sinu rẹ̀, gbogbo ohun-ìní igbesi-aye rẹ̀.” Lẹhin tí ó ti sọ awọn nǹkan wọnyi, Jesu jade lọ kuro ninu tẹmpili fun ìgbà ikẹhin.
Bi ẹnu tí yà wọn sí ìtóbi ati ẹwà tẹmpili naa, awọn ọmọ-ẹhin rẹ̀ ṣe sáàfúlà pe: “Olukọ, woo! Iru awọn òkúta ati iru awọn ilé-kíkọ́ tí ó wà nihinyii!” Nitootọ, awọn òkúta naa ni a rohin rẹ̀ pe wọn gùn jù 35 ẹsẹ̀-bàtà, wọn fẹ̀ ju 15 ẹsẹ̀-bàtà, wọn sì ga sókè ní ìwọ̀n tí ó jù 10 ẹsẹ̀-bàtà!
“Ṣe ẹ rí awọn ilé-kíkọ́ ńláǹlà wọnyi?” ni Jesu fèsìpadà. “A kì yoo fi òkúta kan sílẹ̀ níhìn-ín lọ́nàkọnà lórí ekeji tí a kì yoo wó lulẹ̀.”
Lẹhin tí ó ti sọ awọn nǹkan wọnyi, Jesu ati awọn apọsiteli rẹ̀ rekọja Àfonífojì Kidironi wọn sì gùn Òkè Olifi. Lati ibẹ̀ wọn lè maa wò tẹmpili gbígbórín naa lati òkè. Matiu 23:25–24:3; Maaku 12:41–13:3; Luuku 21:1-6; 2 Kironika 24:20-22, NW.
▪ Ki ni Jesu ṣe nigba ìbẹ̀wò rẹ̀ ikẹhin sí tẹmpili?
▪ Bawo ni àgàbàgebè awọn akọ̀wé òfin ati awọn Farisi ṣe farahàn?
▪ Ki ni “idajọ Gẹhẹna” tumọsi?
▪ Eeṣe ti Jesu fi sọ pe opó naa ṣe itọrẹ tí ó pọ̀ jù ti awọn ọlọ́rọ̀?
-
-
Àmì Awọn Ọjọ IkẹhinỌkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
-
-
Orí 111
Àmì Awọn Ọjọ Ikẹhin
ỌSAN Tuesday ni ó jẹ́ nisinsinyi. Bí Jesu ti jókòó sórí Òkè Olifi, tí ó ńwo tẹmpili nísàlẹ̀, Peteru, Anderu, Jakọbu, ati Johanu tọ̀ ọ́ wá ní ìkọ̀kọ̀. Wọn ńdàníyàn nipa tẹmpili naa, niwọn bi Jesu ti ṣẹ̀ṣẹ̀ sọtẹ́lẹ̀ pe ‘a kì yoo fi òkúta kan silẹ lórí èkejì ninu rẹ̀.’
Ṣugbọn bí ó ti hàn gbangba wọn tilẹ ní ohun pupọ sii lọ́kàn bí wọn ti sunmọ Jesu. Ní awọn ọsẹ diẹ ṣaaju, oun ti sọ̀rọ̀ nipa “wíwàníhìn-ín” rẹ̀, laaarin àkókò kan ‘nigba ti a o ṣí Ọmọkunrin eniyan payá.’ Ati ní àkókò kan ṣaaju, oun ti sọ fun wọn nipa “òpin ètò-ìgbékalẹ̀ awọn nǹkan.” Nitori naa awọn apọsiteli nífẹ̀ẹ́ ìtọpinpin gidigidi.
“Sọ fun wa,” ni wọn wí, “nigba wo ni nǹkan wọnyi yoo ṣẹ [tí yoo yọrísí ìparun Jerusalẹmu ati tẹmpili rẹ̀], ki ni yoo sì ṣe àmì wíwàníhìn-ín rẹ ati ti òpin ètò-ìgbékalẹ̀ awọn nǹkan?” Niti tootọ, ibeere wọn jẹ́ alápá mẹ́ta. Lakọọkọ, wọn fẹ́ lati mọ̀ nipa òpin Jerusalẹmu ati tẹmpili rẹ̀, lẹhin naa nipa wíwàníhìn-ín Jesu ninu agbára Ijọba, ati nikẹhin nipa òpin gbogbo ètò-ìgbékalẹ̀ awọn nǹkan lódidi.
Ninu ìdáhùnpadà rẹ̀ gígùn, Jesu dáhùn gbogbo awọn apá mẹtẹẹta ibeere naa. Ó pèsè àmì kan tí ó dáfi àkókò naa hàn tí ètò-ìgbékalẹ̀ awọn nǹkan Juu yoo dópin; ṣugbọn ó pèsè pupọ sii. Ó tún fúnni ní àmì kan pẹlu tí yoo mú awọn ọmọ-ẹhin rẹ̀ ọjọ iwaju wà lójúfò kí wọn baa lè mọ̀ pe awọn ńgbé ní àkókò wíwàníhìn-ín rẹ̀ ati nítòsí òpin gbogbo ètò-ìgbékalẹ̀ awọn nǹkan lódidi.
Bí awọn ọdun ti ńkọjá, awọn apọsiteli bẹrẹsii kíyèsí ìmúṣẹ asọtẹlẹ Jesu. Bẹẹni, awọn ohun naa gan-an tí oun sọtẹ́lẹ̀ bẹrẹsii ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ wọn. Nipa bayii, awọn Kristẹni tí wọn walaaye ní 37 ọdun lẹhin ìgbà naa ní 70 C.E., ni ìparun ètò-ìgbékalẹ̀ awọn Juu pẹlu tẹmpili rẹ̀ kò bá lojiji.
Bí ó ti wù kí ó rí, wíwàníhìn-ín Jesu ati òpin ètò-ìgbékalẹ̀ awọn nǹkan kò ṣẹlẹ̀ ní 70 C.E. Wíwàníhìn-ín rẹ̀ ninu agbára Ijọba ṣẹlẹ̀ ní àkókò pípẹ́ lẹhin naa. Ṣugbọn nigba wo? Ìgbéyẹ̀wò asọtẹlẹ Jesu ṣí eyi payá.
Jesu sọtẹ́lẹ̀ pe “awọn ogun ati awọn ìròhìn ogun” yoo wà. “Orílẹ̀-èdè yoo dìde sí orílẹ̀-èdè,” ni oun wí, àìtó ounjẹ yoo sì wà, ìsẹ̀lẹ̀, ati àjàkálẹ̀ àrùn. Awọn ọmọ-ẹhin rẹ̀ ni a ó kórìíra tí a ó sì pa. Awọn wolii eke yoo dìde wọn yoo sì ṣi ọpọlọpọ lọ́nà. Ìwà àìlófin yoo pọ̀sí i, ìfẹ́ awọn eniyan pupọ yoo sì di tútù. Ní àkókò kan naa, ihinrere Ijọba Ọlọrun ni a ó waasu gẹgẹ bi ẹ̀rí fun gbogbo orílẹ̀-èdè.
Bí ó tilẹ jẹ́ pe asọtẹlẹ Jesu ní ìmúṣẹ aláàlà ṣaaju iparun Jerusalẹmu ní 70 C.E., ìmúṣẹ titobi rẹ̀ ṣẹlẹ̀ lákòókò wíwàníhìn-ín rẹ̀ ati òpin ètò-ìgbékalẹ̀ awọn nǹkan. Àtúnyẹ̀wò àfẹ̀sọṣe nipa awọn ìṣẹ̀lẹ̀ ninu ayé lati 1914 ṣípayá pe asọtẹlẹ Jesu ṣiṣe pataki yii ti bẹ̀rẹ̀ sii ní ìmúṣẹ rẹ̀ titobi lati ọdun yẹn.
Apá miiran ninu àmì naa tí Jesu fúnni ni ìfarahàn “ohun ìsúni fún ìríra naa tí ńṣokùnfà ìsọdahoro.” Ní 66 C.E. ohun ìsúni fún ìríra yii farahàn ní ọna “awọn ẹgbẹ́ ọmọ ogun” Roomu “tí wọn pabùdó’ yí Jerusalẹmu ká tí wọn sì jin ògiri tẹmpili rẹ̀ lẹ́sẹ̀. “Ohun ìsúni fún ìríra naa” dúró sí ibi tí kò tọ́.
Ninu ìmúṣẹ titobi àmì naa, ohun ìsúni fún ìríra naa ni Imulẹ Awọn Orilẹ-ede ati olùgbapò rẹ̀, Iparapọ Awọn Orilẹ-ede. Ètò-àjọ fun alaafia àgbáyé yii ni Kristẹndọmu wò gẹgẹ bi arọ́pò fun Ijọba Ọlọrun. Ẹ wo bi ó ti súni fún ìríra tó! Nitori naa bí àkókò ti ńlọ, awọn agbára ìṣèlú tí wọn bá Iparapọ Awọn Orilẹ-ede kẹ́gbẹ́ yoo yíjú sí Kristẹndọmu (Jerusalẹmu amápẹẹrẹṣẹ) yoo sì sọ ọ́ dahoro.
Nipa bayii Jesu sọtẹ́lẹ̀ pe: “Ipọnju ńlá yoo wà irú eyi tí kò wáyé rí lati ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ayé wá títí di isinsinyi, ó tì, bẹẹni kò tún ní wáyé mọ́.” Nigba tí ó jẹ́ pe ìparun Jerusalẹmu ní 70 C.E. jẹ́ ipọnju ńlá kan nitootọ, pẹlu iye tí ó ju million kan tí a ròhìn pe a pa, kii ṣe ipọnju kan tí ó tóbi jù Ìkún omi agbaye ní ọjọ́ Noa. Nitori naa ìmúṣẹ titobi apá yii ninu asọtẹlẹ Jesu kò tii ní ìmúṣẹ sibẹ.
Ìgbọ́kànlé Lákòókò Awọn Ọjọ́ Ìkẹhìn
Bí Tuesday, Nisan 11, tí ńparí lọ, Jesu nba ijiroro rẹ̀ pẹlu awọn apọsiteli rẹ̀ nipa àmì wíwàníhìn-ín rẹ̀ ninu agbára Ijọba ati ti opin ètò-ìgbékalẹ̀ awọn nǹkan niṣo. Ó kìlọ̀ fun wọn nipa sísáré tẹ̀lé awọn eke Kristi. Oun wipe awọn ìgbìdánwò ni wọn yoo ṣe, “lati ṣì lọ́nà, bí ó ba ṣeeṣe, àní awọn ẹni àyànfẹ́ pàápàá.” Ṣugbọn, bí awọn idì tí ńríran jinna, awọn ẹni àyànfẹ́ wọnyi yoo kórajọ sí ibi tí wọn ti lè rí ounjẹ ti ẹ̀mí tootọ, eyiini ni, lọ́dọ̀ Kristi tootọ naa nigba wíwàníhìn-ín rẹ̀ aláìṣeérí. A kì yoo ṣì wọn lọ́nà kí wọn sì tipa bẹẹ korajọ sọ́dọ̀ eke Kristi.
Kìkì ìfarahàn tí ó ṣeérí ni awọn eke Kristi lè ṣe. Ní ìyàtọ̀, wíwàníhìn-ín Jesu yoo jẹ́ aláìṣeérí. Yoo wáyé ní akoko oníjìnnìjìnnì ninu ìtàn ẹ̀dá ènìyàn, gẹgẹ bi Jesu ti wi: “Òòrùn yoo ṣókùnkùn, òṣùpá kì yoo sì funni ni ìmọ́lẹ̀ rẹ̀.” Bẹẹni, eyi yoo jẹ́ sáà dídúdú julọ ninu ìgbà wíwà aráyé. Yoo dabi ẹni pe oòrùn ti ṣókùnkùn ní ọ̀sán, ati bi ẹni pe òṣùpá kò funni ni ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ní òru.
“Jesu nbaa lọ pe, “Awọn agbára ọ̀run ni a ó mì.” Ó tipa bayii fihan pe awọn ọ̀run tí ó ṣeérí yoo ní ìfarahàn alasọtẹlẹ. Awọn ọ̀run kì yoo wulẹ̀ jẹ́ àkóso awọn ẹyẹ mọ́, ṣugbọn wọn yoo kún fun awọn ọkọ̀ òfúúrufú ti a fi njagun, awọn àgbá rọkẹẹti, ati awọn ohun èèlò tí nriran wọnú òfúúrufú. Ìbẹ̀rù ati ìwà-ipá naa yoo rékọjá ohunkohun tí a ti ní ìrírí rẹ̀ ninu ìtàn ẹ̀dá ènìyàn.
Gẹgẹ bi ìyọrísí eyi, Jesu wipe, “làásìgbò awọn orilẹ-ede yoo wà, laimọ ọ̀nà àbájáde nitori ariwo omi òkun ati ìrugùdù rẹ̀, nigba ti awọn eniyan yoo dákú lati inú ìbẹ̀rù ati ìfojúsọ́nà awọn ohun tí ńbọ̀ wá sori ilẹ̀-ayé gbígbé.” Nitootọ, sáà dídúdú julọ yii ninu ìgbà wíwà ẹ̀dá ènìyàn yoo ṣamọ̀nà sí akoko naa nigba ti, gẹgẹ bi Jesu ti wi, “àmì Ọmọkunrin eniyan yoo farahàn ní ọ̀run, nigba naa sì nì gbogbo ẹ̀yà ilẹ̀-ayé yoo lù araawọn ninu ìdárò.”
Ṣugbọn kìí ṣe gbogbo eniyan ni yoo maa dárò nigba ti ‘Ọmọkunrin eniyan bá dé pẹlu agbára’ lati pa ètò-ìgbékalẹ̀ awọn nǹkan buruku yii run. “Awọn ẹni àyànfẹ́,” 144,000 tí yoo ṣajọpin pẹlu Kristi ninu Ijọba rẹ̀ ọ̀run, kì yoo dárò, bẹẹ naa sì ni awọn alábàákẹ́gbẹ́ wọn pẹlu, awọn ẹni tí Jesu pe ni “awọn agutan miiran” ni iṣaaju. Láìka gbigbe ti a ńgbé ni sáà dídúdú julọ ninu ìtàn ẹ̀dá ènìyàn sí, awọn wọnyi dáhùnpadà sí ìṣírí Jesu pe: “Bí awọn nǹkan wọnyi bá ti bẹ̀rẹ̀ sii wáyé, ẹ dìde duro, kí ẹ sì gbé orí yin sókè, nitori ìdáǹdè yin tí ńsúnmọ́ itòsí.”
Kí awọn ọmọ-ẹhin rẹ̀ tí yoo maa gbé ní awọn ọjọ́ ikẹhin baa lè pinnu ìsúnmọ́tòsí opin naa, Jesu funni ni àkàwé yii: “Ẹ kiyesi igi ọ̀pọ̀tọ́ ati gbogbo igi yooku: Nigba ti wọn bá ti wà ninu ìrudi, nipa kikiyesi i ẹyin mọ̀ funraayin pe nisinsinyi ìgbà ẹ̀rùn tí súnmọ́lé. Ni ọ̀nà yii pẹlu, nigba ti ẹ bá rí awọn nǹkan wọnyi tí ńṣẹlẹ̀, ẹ mọ̀ pe ijọba Ọlọrun tí súnmọ́. Nitootọ ni mo wi fun yin, Ìran eniyan yii kì yoo kọja lọ tán títí gbogbo nǹkan wọnyi yoo fi ṣẹlẹ.”
Nipa bayii, nigba ti awọn ọmọ-ẹhin rẹ̀ bá rí onírúurú apá ẹ̀ka àmì naa tí ńṣẹ, wọn nilati mọ̀ pe opin étó-ìgbékalẹ̀ awọn nǹkan ti súnmọ́lé ati pe Ijọba Ọlọrun láìpẹ́ yoo nù gbogbo ìwà burúkú kúrò. Niti tootọ, opin yoo wáyé ní ìgbà ìgbésí-ayé awọn eniyan tí wọn rí ìmúṣẹ gbogbo ohun tí Jesu sọtẹlẹ! Ní ṣíṣí awọn ọmọ-ẹhin wọnni tí yoo walaaye ní awọn ọjọ́ ikẹhin oníhílàhílo naa létí, Jesu wipe:
“Ẹ kiyesi araayin kí ọkàn-àyà yin máṣe di eyi tí a fi àjẹjù ati àmujù ati àníyàn igbesi-aye dẹ́rùpa láé, lojiji kí ọjọ́ yẹn wá dé bá yin gẹgẹ bi ìkẹkùn kan. Nitori yoo dé bá gbogbo awọn wọnni tí ńgbé ní gbogbo ilẹ̀-ayé. Ẹ maa wà lójúfò, nigba naa, ní gbogbo ìgbà ní gbigba àdúrà ẹ̀bẹ̀ kí ẹ lé ṣàṣeyọrí sí rere ní sísálà kuro ninu gbogbo nǹkan wọnyi tí a ti kàdárà lati wáyé, ati ní dídúró niwaju Ọmọkunrin eniyan.”
Awọn Wundia Ọlọ́gbọ́n ati Òmùgọ̀
Jesu ti ńdáhùn ohun tí awọn apọsiteli rẹ̀ beere fun eyi tí ó jẹ́ àmì wíwàníhìn-ín rẹ̀ ninu agbára Ijọba. Nisinsinyi oun pèsè awọn apá ẹ̀ka siwaju sí i nipa àmì naa ninu awọn òwe mẹta, tabi awọn àkàwé.
Ìmúṣẹ àkàwé kọọkan ni awọn wọnni tí wọn walaaye lákòókò wíwàníhìn-ín rẹ̀ lè kiyesi. Jesu nasẹ̀ àkọ́kọ́ pẹlu awọn ọ̀rọ̀ wọnyi: “Nigba naa ni a o fi ijọba ọ̀run wé awọn wundia mẹ́wàá, tí wọn mú fìtílà wọn, tí o sì jáde lọ pade ọkọ ìyàwó. Márùn-ún ninu wọn ṣe ọlọgbọ́n, márùn-ún sì ṣe aláìgbọ́n.”
Nipasẹ ọ̀rọ̀ naa “a o fi ijọba ọ̀run wé awọn wundia mẹ́wàá,” Jesu kò ní in lọ́kàn pe ìdajì awọn wọnni tí wọn yoo jogún Ijọba ọ̀run naa jẹ́ awọn aláìgbọ́n eniyan tí ìdajì sì jẹ́ awọn ọlọ́gbọ́n! Bẹẹkọ, ṣugbọn ohun tí oun nílọ́kàn ni pe ní ìsopọ̀ pẹlu Ijọba awọn ọ̀run, apá kan wà tí ó rí bí eyi tabi bí iyẹn, tabi awọn ọ̀ràn ní ìsopọ̀ pẹlu Ijọba naa yoo dabi ohun bayii ati bayii.
Awọn wundia mẹ́wàá naa ṣàpẹẹrẹ gbogbo awọn Kristẹni tí wọn wà ní ìlà fun tabi tí wọn sọ pe wọn wà ní ìlà fun Ijọba ọrun. Ní Pẹntikọsi 33 C.E. ni a ṣèlérí ijọ Kristẹni ni ìgbéyàwó fun Ọkọ iyawo tí a ti ṣe lógo, tí a ti jí dìde naa, Jesu Kristi. Ṣugbọn ìgbéyàwó naa yoo ṣẹlẹ̀ ní ọ̀run ní àkókò kan tí a kò sọ ní pàtó ní ẹ̀hìn-ọ̀la.
Ninu àkàwé naa, awọn wundia mẹ́wàá naa jáde lọ pẹlu ète lati kí ọkọ ìyàwó naa kaabọ ati lati darapọ̀ mọ́ ìtọ́wọ̀ọ́rìn ayẹyẹ ìgbéyàwó. Nigba ti ó bá dé, wọn yoo fi awọn àtùpà wọn tànmọ́lẹ̀ sí ojú ìrìnnà ìtọ́wọ̀ọ́rìn naa, ní títipa bayii bọlá fún ọkọ ìyàwó naa bí ó ti ńmú ìyàwó rẹ bọ̀ wá sí ilé tí a ti múrasílẹ̀ fun un. Bí ó ti wù kí ó rí, Jesu ṣàlàyé pe: “Awọn tí ó ṣe aláìgbọ́n mú fìtílà wọn, wọn kò sì mú òróró lọ́wọ́: ṣugbọn awọn ọlọgbọ́n mú òróró ninu kòlòbó pẹlu fìtílà wọn. Nigba tí ọkọ ìyàwó pẹ́, gbogbo wọn tòògbé, wọn sì sùn.”
Ìdádúró ọkọ ìyàwó naa fihàn pe wíwàníhìn-ín Kristi gẹgẹ bi Ọba tí ńṣàkóso yoo jẹ́ ní ọjọ́ ọ̀la jíjìnnàréré. Oun dé nígbẹ̀hìn gbẹ́hín sí ìtẹ́ rẹ̀ ní ọdun 1914. Láàárín àkókò òru gígùn tí ó ṣaaju ìṣẹ̀lẹ̀ yẹn, gbogbo awọn wundia naa tòògbé wọn sì sùn. Ṣugbọn a kò dá wọn lẹ́bi fun eyi. Ìdálẹ́bi awọn wundia aláìgbọ́n naa jẹ́ nitori ṣíṣàìmú òróró lọwọ ninu kòlòbó wọn. Jesu ṣàlàyé bí awọn wundia naa ṣe jí ṣaaju kí ọkọ ìyàwó tó dé: “Láàárín ọ̀gànjọ́, igbe ta sókè, wipe, Wòó, ọkọ ìyàwó ńbọ̀; ẹ jáde lọ pàdé rẹ̀, nigba naa ni gbogbo awọn wundia wọnni dìde, wọn sì tún fìtílà wọn ṣe. Awọn aláìgbọ́n sì wí fun awọn ọlọgbọ́n pe, Fun wa ninu òróró yin; nitori fìtílà wa ńkú lọ. Ṣugbọn awọn ọlọgbọ́n dá wọn lóhùn, wipe, Bẹẹkọ; kí ó má baa ṣe aláìtó fun awa ati ẹyin: ẹ kúkú tọ awọn tí ńtà lọ, kí ẹ sì rà fun ara yin.”
Òróró naa ṣàpẹẹrẹ ohun tí ó ńmú kí awọn Kristẹni maa tàn gẹgẹ bi afúnni ní ìmọ́lẹ̀. Eyi jẹ Ọ̀rọ̀ onímìísí Ọlọrun, eyi tí awọn Kristẹni dìmú ṣinṣin, papọ̀ pẹlu ẹ̀mí mímọ́, tí ó ńràn wọn lọ́wọ́ lati lóye Ọ̀rọ̀ yẹn. Òróró tẹ̀mí naa mú awọn wundia ọlọ́gbọ́n tóótun lati tan ìmọ́lẹ̀ jáde ní kíkí ọkọ ìyàwó káàbọ̀ lákòókò ìtówọ̀ọ́rìn lọ sí àsè ìgbéyàwó. Ṣugbọn ẹgbẹ́ wundia aláìgbọ́n naa kò ní ninu araawọn, ninu kòlòbó wọn, òróró tẹ̀mí tí wọn nílò. Nitori naa Jesu ṣàpèjúwe ohun tí ó ṣẹlẹ̀:
“Nigba tí [awọn wundia aláìgbọ́n naa] sì ńlọ rà [òróró], ọkọ ìyàwó dé; awọn tí ó sì múra tán bá a wọlé lọ sí ibi ìyàwó: a sì ti ilẹ̀kùn. Ní ikẹhin ni awọn wundia yooku sì dé, wọn nwipe, Oluwa, Oluwa, ṣílẹ̀kùn fun wa. Ṣugbọn ó dáhùn, wipe, Lóòótọ́ ni mo wí fun yin, emi kò mọ̀ yin.”
Lẹhin tí Kristi dé ninu Ijọba rẹ̀ ti ọ̀run, ẹgbẹ́ wundia ọlọ́gbọ́n ti awọn Kristẹni ẹni àmì-òróró tootọ jí sí àǹfààní wọn ti títan ìmọ́lẹ̀ ninu ayé tí a ti mú ṣókùnkùn yii sí ìyìn Ọkọ ìyàwó tí ó ti padà dé naa. Ṣugbọn awọn wọnni tí wundia aláìgbọ́n naa yaworan láìmúrasílẹ̀ lati pèsè ìyìn ìkínikáàbọ̀ yii. Nitori naa nigba ti àkókò dé, Kristi kò ṣí ilẹ̀kùn àsè ìgbéyàwó ní ọ̀run fun wọn. Ó fi wọn silẹ lóde ninu òru ayé tí ó ṣókùnkùn julọ, lati ṣègbé pẹlu gbogbo awọn oníṣẹ́ àìlófin yòókù. “Nitori naa, ẹ maa ṣọ́nà,” ni Jesu fi pari ọ̀rọ̀, “bí ẹyin kò ti mọ ọjọ, tabi wakati.”
Àkàwé Awọn Talẹnti
Jesu ńbá ìjíròrò pẹlu awọn apọsiteli rẹ̀ lọ lórí Òkè Olifi nipa sísọ àkàwé miiran fun wọn, èkejì ninu ọ̀wọ́ mẹta. Ní awọn ọjọ diẹ ṣaaju, nigba tí ó wà ní Jẹriko, ó sọ àkàwé awọn mina lati fihàn pe Ijọba naa ṣì wà sibẹsibẹ ní àkókò gígùn kan ní ọjọ iwaju. Àkàwé tí oun sọ nisinsinyi, bí ó tilẹ ní awọn apá pupọ tí wọn farajọra, ṣàpèjúwe ninu ìmúṣẹ rẹ̀ awọn ìgbòkègbodò lákòókò wíwàníhìn-ín Kristi ninu agbára Ijọba. Ó ṣàkàwé pe awọn ọmọ-ẹhin rẹ̀ gbọdọ maa ṣiṣẹ́ niwọn ìgbà ti wọn bá ṣì wà níhìn-ín lórí ilẹ̀-ayé lati mú “awọn ohun ìní rẹ̀” pọ̀sí i.
Jesu bẹ̀rẹ̀ pe: “Nitori ńṣe ni [eyiini ni, awọn àyíká tí wọn sopọ̀ mọ́ Ijọba naa] ó dabi ìgbà tí ọkunrin kan, tí ó maa tó rin ìrìn àjò lọ sí ìdálẹ̀ fi àṣẹ pè awọn ẹrú rẹ̀ wá tí ó sì fi awọn ohun ìní rẹ̀ lé wọn lọ́wọ́ lati tọ́jú.” Jesu ni ọkunrin naa ẹni tí, ṣaaju kí ó tó rìnrìn àjò lọ sí ìdálẹ̀ ni ọ́run, fi awọn ohun ìní rẹ̀ lé awọn ẹrú rẹ̀ lọwọ lati tọ́jú—awọn ọmọ-ẹhin tí wọn wà ní ìlà fun Ijọba ti ọrun. Awọn ohun ìní wọnyi kii ṣe awọn ìní ti ara, ṣugbọn wọn dúró fún pápá ríro kan ninu eyi tí oun ti gbin ṣiṣeeṣe lati dàgbàsókè sí fun mímú awọn ọmọ-ẹhin pupọ sí i jáde.
Jesu fi awọn ohun ìní rẹ̀ sikaawọ awọn ẹrú rẹ̀ kété ṣaaju ki o tó gòkè re ọ̀run. Bawo ni ó ṣe ṣe iyẹn? Nipa fífún wọn ní ìtọ́ni lati maa baa lọ ní ṣíṣiṣẹ́ ninu pápá ríro naa nipa wiwaasu ìhìn-iṣẹ́ Ijọba naa títí dé awọn apá ibi jíjìnnà julọ lórí ilẹ̀-ayé. Gẹgẹ bi Jesu ti wí: “Ó sì fun ọ̀kan ní talẹnti márùn-ún, òmíràn meji, òmíràn sibẹ ọ̀kan, fun olukuluku gẹgẹ bi agbára tirẹ̀, ó sì lọ sí ìdálẹ̀.”
Awọn talẹnti mẹjọ naa—awọn ohun ìní Kristi—ni a tipa bayii pín ni ibamu pẹlu agbára tabi awọn ṣíṣeéṣe nipa tẹ̀mí, ti awọn ẹrú naa. Awọn ẹrú naa dúró fún awọn ẹgbẹ́ awọn ọmọ-ẹhin. Ní ọ̀rúndún kìn-ínní, ẹgbẹ tí ó rí talẹnti márùn-ún naa gbà ní awọn apọsiteli nínú lọna tí ó hàn gbangba. Jesu nbaa lọ lati sọ pe awọn ẹrú naa tí wọn rí talẹnti márùn-ún ati meji gbà ni wọn sọ wọn di ìlọ́po meji nipa iwaasu wọn nipa Ijọba ati sísọni di ọmọ-ẹhin. Bí ó ti wù kí ó rí, ẹrú naa tí ó rí talẹnti kan gbà fi i pamọ́ láṣìírí ninu ilẹ.
“Lẹhin àkókò gígùn kan,” ni Jesu nbaa lọ, “ọ̀gá awọn ẹrú wọnni dé ó sì ṣe ìṣirò pẹlu wọn.” Nigba tí ó di ọ̀rúndún ogún yii, nǹkan bii 1,900 ọdun lẹhin ìgbà naa, ni Kristi tó padà wá lati ṣe ìṣirò, bẹẹ ni ó rí, nitootọ, “lẹhin àkókò gígùn kan.” Lẹhin naa Jesu ṣàlàyé pe:
“Eyi tí ó ti gba talẹnti márùn-ún wá síwájú ó sì mú àfikún talẹnti márùn-ún wá, wipe, ‘Ọ̀gá, iwọ fi talẹnti márùn-ún lé mi lọ́wọ́ lati tọ́jú; wòó, mo jèrè talẹnti márùn-ún sí i.’ Ọ̀gá rẹ̀ sì wí fun un pe, ‘O ṣeun, ẹrú daradara ati olóòótọ́! Iwọ ṣe olóòótọ́ lórí awọn nǹkan diẹ. Emi yoo yàn ọ sípò lórí ọpọlọpọ nǹkan. Wọ inú ayọ̀ ọ̀gá rẹ.’” Ẹrú tí ó gba talẹnti meji bẹẹ gẹ́gẹ́ sọ talẹnti tirẹ̀ di ìlọ́po meji, oun sì rí ìyìn ati ẹ̀san kan naa gbà.
Ṣugbọn, bawo ni awọn ẹrú olùṣòtítọ́ wọnyi ṣe wọnú ayọ̀ Ọ̀gá wọn? Ó dára, ayọ̀ Ọ̀gá wọn, Jesu Kristi, jẹ́ ti rírí ìní Ijọba naa gbà nigba ti ó lọ sí ìdálẹ̀ sí ọ̀dọ̀ Baba rẹ̀ ní ọ̀run. Niti awọn ẹrú olùṣòtítọ́ naa ní awọn àkókò òde-òní, wọn ní ayọ̀ ńláǹlà ti jíjẹ́ ẹni tí a fi awọn ẹrù-iṣẹ́ pupọ sí i ni isopọ pẹlu Ijọba naa sí ní ìkáwọ́, bí wọn sì ti ńparí ipa-ọ̀nà wọn lori ilẹ̀-ayé, wọn yoo ní ayọ̀ tí ó ti jíjẹ́ ẹni tí a jí dìde sí Ijọba ọ̀run naa. Ṣugbọn ki ni nipa ti ẹrú kẹta?
“Ọ̀gá, mo mọ̀ ọ ní ọkunrin kan tí ńfi ọ̀ranyàn gba nǹkan,” ni ẹrú yii ráhùn. “Nitori naa mo mo sì lọ fi talẹnti rẹ pamọ́ sínú ilẹ̀. Gba ohun tí ó jẹ́ tìrẹ nìyí.” Ẹrú naa mọ̀ọ́mọ̀ kọ̀ lati ṣiṣẹ́ ninu pápá ríro naa nipa wiwaasu ati sísọni di ọmọ-ẹhin. Nitori eyi ọ̀gá naa pé ẹrú yii ní “buruku ati sùẹ̀gbẹ̀” ó sì kéde ìdájọ́ naa: “Ẹ gba talẹnti naa kuro lọwọ rẹ̀ . . . Ẹ sì gbé ẹrú aláìdára fún ohunkohun naa sọ sóde ninu òkùnkùn lóde. Nibẹ ni ẹkún ati pípa ehín keke rẹ̀ yoo wà.” Awọn tí wọn jẹ́ ti ẹgbẹ́ ẹrú buburu yii, ti a gbá sọnu sóde, ni a fi ayọ̀ eyikeyii nipa tẹ̀mí dù.
Eyi gbé ẹ̀kọ́ àríkọ́gbọ́n ti o ṣe pàtàkì kan kalẹ̀ fun gbogbo awọn wọnni tí wọn fẹnujẹ́wọ́ pe awọn jẹ́ ọmọlẹhin Kristi. Bí wọn yoo bá gbádùn ìgbóríyìn fúnni ati ẹ̀san rẹ̀, bí wọn yoo bá sí yẹra fún dídi ẹni tí a jù sínú òkùnkùn lóde ati ìparun ìkẹhìn, wọn gbọdọ maa ṣiṣẹ́ fun ìbísí awọn ohun ìní Ọ̀gá wọn ọ̀rún nipasẹ níní ìpín kíkún ninu iṣẹ́ wiwaasu. Iwọ ha jẹ́ aláápọn ní ọ̀nà yii bí?
Nigba Ti Kristi Dé Ninu Agbára Ijọba
Jesu ṣì wà pẹlu awọn apọsiteli rẹ̀ lórí Òkè Olifi síbẹ̀. Ní ìdáhùn sí ibeere wọn fun àmì kan nipa wíwàníhìn-ín rẹ̀ ati òpin ètò-ìgbékalẹ̀ awọn nǹkan, oun nisinsinyi sọ eyi tí ó kẹhin fun wọn ninu ọ̀wọ́ awọn àkàwé mẹta. Jesu bẹrẹ nipa sisọ pe: “Nigba ti Ọmọkunrin eniyan bá dé ninu ògo rẹ̀, ati gbogbo awọn angẹli pẹlu rẹ̀, nigba naa ni yoo jókòó lórí ìtẹ́ ògo rẹ̀.”
Awọn ènìyàn kò lè rí awọn angẹli ninu ògo wọn ti ọ̀run. Nitori naa dídé Ọmọkunrin eniyan naa, Jesu Kristi, pẹlu awọn angẹli gbọdọ jẹ́ aláìṣeérí fun ojú ènìyàn. Dídé naa ṣẹlẹ̀ ní ọdun 1914. Ṣugbọn fun ète wo ni? Jesu ṣàlàyé pe: “A ó sì kó gbogbo awọn orílẹ̀-èdè jọ sí iwaju rẹ̀, oun yoo sì ya awọn eniyan sọ́tọ̀ kuro ninu araawọn, gan-an gẹgẹ bi olùṣọ́ àgùtàn ti ńya àgùtàn sọ́tọ̀ kuro ninu ewúrẹ́. Oun yoo sì fi awọn àgùtàn sí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀, ṣugbọn awọn ewúrẹ́ sí ọwọ́ òsì rẹ̀.”
Ní ṣíṣàpèjúwe ohun tí yoo ṣẹlẹ̀ sí awọn wọnni tí ó wà ní ìhà tí a ṣojúrere sí, Jesu wipe: “Nigba naa ni ọba yoo wí fun awọn wọnni tí wọn wà ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ pe, ‘Ẹ wá, ẹyin tí Baba mi ti bùkún fun, ẹ jogún ijọba naa tí a ti pèsè sílẹ̀ dè yin lati ìgbà pípilẹ̀ ayé.’” Awọn àgùtàn inu akawe yii kì yoo ṣàkóso pẹlu Kristi ní ọ̀rún ṣugbọn wọn yoo jogún Ijọba naa ní ìtumọ̀ ti jíjẹ́ ọmọ-abẹ́ rẹ̀ ti ilẹ̀-ayé. “Ìgbà pípilẹ̀ ayé” ṣẹlẹ̀ nigba ti Adamu ati Efa kọ́kọ́ mú awọn ọmọ jáde tí wọn lè jàǹfààní lati inú ìpèsè Ọlọrun lati tún aráyé ràpadà.
Ṣugbọn eeṣe tí a fi ya awọn àgùtàn naa sọ́tọ̀ sí ọwọ́ ọ̀tún ojúrere Ọba naa? “Nitori ebí pa mí,” ni èsì ọba naa wipe, “ẹyin sì fun mi ní nǹkan lati jẹ; oungbẹ gbẹ mí ẹyin sì fun mi ní nǹkan lati mu. Mo jẹ́ àjèjì ẹyin sì gbà mi pẹlu ẹ̀mí àlejò ṣíṣe; mo wà ní ìhòhò, ẹyin sì daṣọ bò mi. Mo ṣàìsàn ẹyin sì bójútó mi. Mo wà ní ẹ̀wọ̀n ẹyin sì wá sọ́dọ̀ mi.”
Niwọn bi awọn àgùtàn naa ti wà lórí ilẹ̀-ayé, wọn fẹ́ lati mọ̀ bí wọn lè ṣe irúfẹ́ awọn iṣẹ́ rere bẹẹ fun Ọba wọn ọrun. “Oluwa, nigba wo ni awa rí ọ tí ebi ńpa ọ́ tí a sì bọ́ ọ,” ni wọn beere, “tabi tí oungbẹ ńgbẹ ọ́, tí a sì fun ọ ní nǹkan lati mu? Nigba wo ni awa rí ọ ní àjèjì tí a sì gbà ọ́ pẹlu ẹ̀mí àlejò ṣíṣe, tabi tí o wà ní ìhòhò, tí awa sì daṣọ bò ọ́? Nigba wo ni awa rí ọ tí o ṣàìsàn tabi wà ní ẹ̀wọ̀n tí awa sì lọ sọ́dọ̀ rẹ?”
“Lóòótọ́ ni mo wí fun yin,” ni Ọba naa fèsìpadà, “títí dé ìwọ̀n tí ẹ ṣe é fun ọ̀kan tí ó kéré jùlọ ninu awọn arakunrin mi wọnyi, ẹ ti ṣe é fun mi.” Awọn arakunrin Kristi jẹ́ awọn 144,000 tí wọn ṣẹ́kù lórí ilẹ̀-ayé tí wọn yoo ṣàkoso pẹlu rẹ̀ ni ọ̀run. Ati pe ṣíṣe dáradára sí wọn, ni Jesu wi, jẹ́ ọ̀kan naa gẹgẹ bi ṣíṣe daradara sí oun.
Tẹle eyi, Ọba naa darí ọ̀rọ̀ sí awọn ewúrẹ́. “Ẹ mú ọ̀nà yin pọ̀n kuro lọdọ mi, ẹyin tí a ti gégùn-ún fun, sínú iná ainipẹkun tí a ti pese sílẹ̀ fun Eṣu ati awọn angẹli rẹ̀. Nitori ebi pa mi, ṣugbọn ẹyin kò fun mi ní nǹkan lati jẹ, oungbẹ sì gbẹ mi, ṣugbọn ẹyin kò fun mi ní nǹkan lati mu. Mo jẹ́ àjèjì, ṣugbọn ẹyin kò gbà mi pẹlu ẹ̀mí àlejò ṣíṣe; mo wà ní ìhòhò, ṣugbọn ẹyin kò daṣọ bò mi; mo ṣàìsàn mo sì wà ninu ẹ̀wọ̀n, ṣugbọn ẹyin kò bojuto mi.”
Awọn ewurẹ naa, bí ó ti wù kí ó rí, ráhùn pe: “Oluwa, nigba wo ni awa rí ọ tí ebi ńpa ọ́ tabi tí oungbẹ ńgbẹ ọ tabi ní àjèjì tabi wà ní ìhòhò tabi ṣàìsàn tabi wà ninu ẹ̀wọ̀n tí awa kò sì ṣèránṣẹ́ fun ọ?” Awọn ewúrẹ́ naa gba ìdájọ́ aláìbáradé lórí ìpìlẹ̀ kan naa tí a fi dájọ́ tí ó báradé fun awọn àgùtàn naa. “Títí dé ìwọ̀n tí ẹ kò ṣé e fun ọ̀kan lára awọn tí wọn kéré jùlọ wọnyi [ti awọn arakunrin mi],” ni Jesu dáhùn, “ẹyin kò ṣe é fun mi.”
Nitori naa wíwàníhìn-ín Kristi ninu agbára Ijọba, kété ṣaaju òpin ètò-ìgbékalẹ̀ awọn nǹkan buruku yii ninu ipọnju nla, yoo jẹ́ àkókò ìdájọ́ kan. Awọn ewúrẹ́ “yoo lọ kúrò sínú ìkékúrò ainipẹkun, ṣugbọn awọn olódodo [awọn àgùtàn] sínú iye ainipẹkun.” Matiu 24:2–25:46, NW; 13:40, 49; Maaku 13:3-37; Luuku 21:7-36, NW; Lk 19:43, 44, NW; Lk 17:20-30, NW; 2 Timoti 3:1-5; Johanu 10:16; Iṣipaya 14:1-3.
▪ Ki ni ta ibeere awọn apọsiteli naa jí, ṣugbọn bi ó ti hàn gbangba ohun miiran wo ni wọn ní lọ́kàn?
▪ Apa wo ninu asọtẹlẹ Jesu ni ó ni ìmúṣẹ ní 70 C.E., ṣugbọn ki ni kò wáyé nigba naa?
▪ Nigba wo ni asọtẹlẹ Jesu ní ìmúṣẹ àkọ́kọ́, ṣugbọn nigba wo ni ó ní ìmúṣẹ titobi?
▪ Ki ni ohun ìsúni fún ìríra naa ninu ìmúṣẹ rẹ àkọ́kọ́ ati ti ìkẹhìn?
▪ Eeṣe tí ipọnju ńlá naa kò fi ní ìmúṣẹ rẹ̀ tí ó kẹ́hìn nigba ìparun Jerusalẹmu?
▪ Awọn ipò wo ninu ayé ni wọn sàmì sí wíwàníhìn-ín Kristi?
▪ Nigba wo ni ‘gbogbo ẹ̀yà ilẹ̀-ayé yoo lu araawọn ninu ìdárò,’ ṣugbọn ki ni awọn ọmọlẹhin Kristi yoo maa ṣe?
▪ Àkàwé wo ni Jesu pèsè lati ran awọn ọmọ-ẹhin rẹ̀ ọjọ́ ọ̀la lọ́wọ́ lati mọ̀ ìgba tí opin naa bá súnmọ́lé?
▪ Ìṣínilétí wo ni Jesu pèsè fun awọn ọmọ-ẹhin rẹ̀ wọnni tí wọn yoo walaaye ní awọn ọjọ́ ikẹhin?
▪ Ta ni awọn wundia mẹ́wàá naa ṣàpẹẹrẹ?
▪ Nigba wo ni a ṣe ìlérí ijọ Kristẹni ní ìgbéyàwó fun ọkọ ìyàwó, ṣugbọn nigba wo ni ọkọ iyawo dé lati mú ìyàwó rẹ̀ lọ sí àsè ìgbéyàwó?
▪ Ki ni òróró naa dúró fún, kí sì ni níní in lọwọ mú awọn wundia ọlọ́gbọ́n naa tóótun lati ṣe?
▪ Nibo ni àsè ìgbéyàwó naa ti ṣẹlẹ̀?
▪ Ẹ̀san títóbilọ́lá wo ni awọn wundia naa pàdánù rẹ̀, kí sì ni òpin wọn?
▪ Ẹ̀kọ́ àríkọ́gbọ́n wo ni àkàwé nipa talẹnti fikọ́ni?
▪ Ta ni awọn ẹrú naa jẹ́, kí sì ni awọn ohun ìní naa tí a fi sí ìkáwọ́ wọn?
▪ Nigba wo ni ọ̀gá naa dé lati ṣè ìṣirò, ki ni ohun tí oun sì rí?
▪ Ki ni ayọ̀ naa tí ẹrú olùṣòtítọ́ naa wọ inú rẹ̀, ki ni ó sì ṣẹlẹ̀ sí ẹrú burukú naa?
▪ Eeṣe tí wíwàníhìn-ín Kristi fi gbọdọ jẹ́ aláìṣeérí, iṣẹ́ wo ni oun sì ṣe ní àkókò yẹn?
▪ Ní ìtumọ̀ wo ni awọn àgùtàn fi jogún Ijọba naa?
▪ Nigba wo ni “ìgbà pípilẹ̀ ayé” ṣẹlẹ̀?
▪ Ki ni ìpìlẹ̀ ti a fi dájọ́ awọn eniyan yálà gẹgẹ bi àgùtàn tabi gẹgẹ bi ewúrẹ́?
-
-
Ìrékọjá Ìgbẹ̀hìn fun Jesu Kù Sí Dẹ̀dẹ̀Ọkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
-
-
Orí 112
Ìrékọjá Ìgbẹ̀hìn fun Jesu Kù Sí Dẹ̀dẹ̀
BÍ TUESDAY, Nisan 11, ti ńparí lọ, Jesu parí kíkọ́ awọn apọsiteli rẹ̀ lẹ́kọ̀ọ́ lori Òkè Olifi. Ẹ wo bi ọjọ naa ti kún fun iṣẹ́ àṣelàágùn tó! Nisinsinyi, boya nigba ti ó ńpadà sí Bẹtani lati lọ lò òru naa, ó sọ fun awọn apọsiteli rẹ̀ pe: “Ẹyin mọ̀ pe ọjọ́ meji sí isinsinyi ìrékọjá yoo wáyé, á ó sì fi Ọmọkunrin eniyan lé wọn lọwọ lati kànmọ́gi.”
-