-
Fi Ara Rẹ fún Ìwé KíkàJàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
-
-
Fi Ara Rẹ fún Ìwé Kíkà
ÀWỌN ẹranko ò lè ṣe ohun tó ò ń ṣe lọ́wọ́ yìí. Èèyàn kan nínú ẹni mẹ́fà láyé ni kò mọ̀wé kà, ó sì sábà máa ń jẹ́ nítorí àìláǹfààní láti lọ sílé ẹ̀kọ́, kódà lára àwọn tó tiẹ̀ mọ̀wé kà pàápàá, ọ̀pọ̀ ni kì í kà á déédéé. Síbẹ̀, kíkà tó o lè ka ohun tí a bá tẹ̀ ń jẹ́ kí o lè fojú inú rìnrìn àjò lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, kí o bá àwọn èèyàn tí ayé wọn lè mú kí ayé rẹ túbọ̀ dáa sí i pàdé, ó sì ń jẹ́ kí o lè jèrè ìmọ̀ tó ṣeé mú lò, èyí tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti kojú àwọn àníyàn inú ayé.
Ohun tó ò ń kà sétígbọ̀ọ́ àwọn ọmọ rẹ lè kọ́ wọn ní irú ìwà tí wọn yóò máa hù
Bí ọmọ kan bá ṣe mọ ìwé kà sí ni yóò ṣe jàǹfààní tó látinú ẹ̀kọ́ tó ń kọ́ nílé ẹ̀kọ́. Bó bá sì di pé ó ń wáṣẹ́, bó ṣe mọ ìwé kà sí lè nípa lórí irú iṣẹ́ tó máa rí ṣe àti iye wákàtí tí yóò máa lò láti fi ṣiṣẹ́ láti lè gbọ́ bùkátà ara rẹ̀. Àwọn ìyàwó ilé tó bá mọ ìwé kà dáadáa yóò lè tọ́jú ìdílé wọn dáadáa tó bá di ọ̀ràn fífún wọn lóúnjẹ aṣaralóore, ṣíṣe ìmọ́tótó, àti dídènà àìsàn. Ìyá tó bá sì ń kàwé dáadáa tún lè nípa tó dára lórí bí ọpọlọ ọmọ rẹ̀ ṣe máa jí pépé tó.
Àmọ́ ṣá, àǹfààní gíga jù lọ tí o lè rí gbà látinú ìwé kíkà ni pé, ó lè mú kí o “rí ìmọ̀ Ọlọ́run gan-an.” (Òwe 2:5) Ọ̀pọ̀ nínú àwọn ọ̀nà tí a gbà ń sin Ọlọ́run ló gba pé kéèyàn mọ ìwé kà. A máa ń ka Ìwé Mímọ́ àti àwọn ìtẹ̀jáde tó dá lórí Bíbélì ní àwọn ìpàdé ìjọ. Bí o ṣe mọ ìwé kà sí máa ń nípa gidigidi lórí bí o ṣe máa já fáfá tó lóde ẹ̀rí. Bẹ́ẹ̀ sì rèé, mímúra sílẹ̀ fún ìgbòkègbodò wọ̀nyí gba ìwé kíkà. Nítorí náà, bí o ṣe ń tẹ̀ síwájú sí nípa tẹ̀mí sinmi ní pàtàkì lórí bí o ṣe ń kàwé.
Lo Àǹfààní Tó Ṣí Sílẹ̀ Yìí
Kọ́ bí a ṣe ń kàwé ní gbangba lọ́nà tó dán mọ́rán
Àwọn kan tó ń kọ́ nípa ọ̀nà Ọlọ́run kò kàwé púpọ̀. Èyí ń béèrè pé kí á kọ́ wọn ní ìwé kíkà láti lè mú kí ìtẹ̀síwájú wọn nípa tẹ̀mí gbé pẹ́ẹ́lí sí i. Ó sì lè jẹ́ pé wọ́n nílò ìrànlọ́wọ́ láti mú kí òye ìwé kíkà wọn já gaara sí i. Tí irú àwọn tó nílò ìrànlọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ bá wà nínú ìjọ kan, ìjọ máa ń gbìyànjú láti ṣètò fún ilé ẹ̀kọ́ mọ̀ọ́kọ-mọ̀ọ́kà. Ẹgbẹẹgbẹ̀rún ló ti jàǹfààní gidigidi látinú ìṣètò yìí. Nítorí pé mímọ̀wé kà lọ́nà tó já gaara ṣe pàtàkì gan-an, àwọn ìjọ kan dá ilé ẹ̀kọ́ kàwé-já-gaara sílẹ̀, èyí tí wọ́n máa ń ṣe nígbà tí Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run bá ń lọ lọ́wọ́. Kódà, níbi tí irú ìṣètò bẹ́ẹ̀ kò bá ti sí, èèyàn ṣì lè tẹ̀ síwájú dáadáa bí ó bá ń wá àkókò díẹ̀ láti kàwé sókè lójoojúmọ́, kí ó tún máa wá sí Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run déédéé kí ó sì máa kópa nínú rẹ̀.
Ó bani nínú jẹ́ pé, àwọn ìwé tó ń fi kìkì àwòrán sọ ìtàn àti tẹlifíṣọ̀n wíwò ti fẹ́rẹ̀ẹ́ paná ìfẹ́ ìwé kíkà lọ́kàn àwọn èèyàn. Tẹlifíṣọ̀n wíwò àti àìkì í fi bẹ́ẹ̀ kàwé lè máà jẹ́ kéèyàn tẹ̀ síwájú nínú ìwé kíkà, kéèyàn má sì lè ronú tàbí kó lo làákàyè rẹ̀ lọ́nà tó yè kooro, ó sì lè máà jẹ́ kéèyàn lè ṣàlàyé ara rẹ̀ dáadáa.
“Ẹrú olóòótọ́ àti olóye” máa ń pèsè àwọn ìtẹ̀jáde tó ń ràn wá lọ́wọ́ láti lóye Bíbélì. Ìwọ̀nyí máa ń jẹ́ ká ní ọ̀pọ̀ ìsọfúnni nípa àwọn ohun tẹ̀mí tó ṣe pàtàkì. (Mát. 24:45; 1 Kọ́r. 2:12, 13) Wọ́n tún ń jẹ́ ká tètè mọ àwọn ọ̀ràn pàtàkì tó ń lọ láyé àti ìtumọ̀ wọn, wọ́n ń jẹ́ ká túbọ̀ lóye àwọn ìṣẹ̀dá inú ayé, wọ́n sì ń kọ́ wa ní àwọn ọ̀nà tí a lè gbà yanjú àwọn ọ̀ràn tó bá kàn wá. Ju gbogbo rẹ̀ lọ, wọ́n ń darí àfiyèsí sí bí a ṣe lè sin Ọlọ́run lọ́nà tí ó tẹ́wọ́ gbà kí á sì rí ojú rere rẹ̀. Kíka irú àwọn ìtẹ̀jáde tó gbámúṣé bẹ́ẹ̀ yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti túbọ̀ tẹ̀ síwájú nípa tẹ̀mí.
Òótọ́ ni pé kéèyàn kàn mọ ìwé kà geerege lásán kò lè dá ṣeni láǹfààní. Èèyàn ní láti lo ẹ̀bùn yẹn lọ́nà títọ́. Bí oúnjẹ tí à ń jẹ ni ìwé kíkà ṣe rí, a ní láti ṣàṣàyàn nínú ohun tí à ń kà. Kí nìdí tí wàá fi máa jẹ oúnjẹ tí kò lè ṣe ara rẹ lóore tàbí èyí tó tiẹ̀ lè jẹ́ májèlé fún ọ? Bákan náà, kí nìdí tí wàá fi máa ka ohun tó lè sọ èrò inú àti ọkàn rẹ dìbàjẹ́, ì báà tiẹ̀ jẹ pé o fẹ́ kà á ṣeré lásán? Àwọn ìlànà Bíbélì ló yẹ kó pèsè ìlànà tí a ó fi pinnu irú ìwé tó yẹ kí á kà. Kí o tó pinnu ohun tó o máa kà, kọ́kọ́ fi àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ yìí sọ́kàn, àwọn bí Oníwàásù 12:12, 13; Éfésù 4:22-24; 5:3, 4; Fílípì 4:8; Kólósè 2:8; 1 Jòhánù 2:15-17; àti 2 Jòhánù 10.
Ète Tí Ó Tọ́ Ni Kí Ó Sún Ọ Kàwé
Bí a bá ṣàyẹ̀wò ìtàn àwọn ìwé Ìhìn Rere, a ó rí bí ó ti ṣe pàtàkì tó pé kó jẹ́ ète tí ó tọ́ ló ń súnni kàwé. Bí àpẹẹrẹ, nínú Ìhìn Rere Mátíù, a rí i pé Jésù bi àwọn aṣáájú ìsìn tó ti ka Ìwé Mímọ́ lákàtúnkà ní àwọn ìbéèrè bí, “Ẹ kò ha kà pé?” àti “Ṣé ẹ kò tíì ka èyí rí pé?” kí ó tó ṣẹ̀ṣẹ̀ wá fi Ìwé Mímọ́ dáhùn àwọn ìbéèrè ẹ̀kẹ́ẹ̀dẹ tí wọ́n ń bí i. (Mát. 12:3, 5; 19:4; 21:16, 42; 22:31) Ẹ̀kọ́ kan tí a rí kọ́ látinú èyí ni pé, bí kò bá jẹ́ ète tí ó tọ́ ló ń sún wa kàwé, a lè ṣi ohun tá a ń kà lóye tàbí kó má tilẹ̀ yé wa rárá. Ńṣe ni àwọn Farisí ń ka Ìwé Mímọ́ nítorí wọ́n rò pé kíkà tí àwọ́n ń kà á làwọn á fi rí ìyè àìnípẹ̀kun gbà. Àmọ́, bí Jésù ṣe sọ, àwọn tí kò bá fẹ́ràn Ọlọ́run tí wọn ò sì tẹ́wọ́ gba ọ̀nà tí Ọlọ́run fi ń pèsè ìgbàlà, kò lè rí èrè ìyè gbà rárá. (Jòh. 5:39-43) Ète onímọtara ẹni nìkan ní ń bẹ lọ́kàn àwọn Farisí; nípa bẹ́ẹ̀ ọ̀pọ̀ ibi tí wọ́n parí èrò wọn sí ló lòdì.
Ìfẹ́ tí a ní sí Jèhófà ni ète mímọ́ jù lọ tó yẹ kó sún wa máa ka Ọ̀rọ̀ rẹ̀. Irú ìfẹ́ bẹ́ẹ̀ ló máa ń mú kí á kọ́ nípa ohun tí Ọlọ́run ń fẹ́, nítorí ìfẹ́ “a máa yọ̀ pẹ̀lú òtítọ́.” (1 Kọ́r. 13:6) Àní bí a kò bá tilẹ̀ fẹ́ràn ìwé kíkà tẹ́lẹ̀, fífi tí a fi “gbogbo èrò inú” wa fẹ́ Jèhófà yóò sún wa láti làkàkà gidigidi láti gba ìmọ̀ Ọlọ́run sọ́kàn. (Mát. 22:37) Ìfẹ́ máa ń mú kí nǹkan wuni, tí nǹkan bá sì ti wuni a óò fẹ́ láti kọ́ nípa rẹ̀.
Ronú Lórí Bí O Ṣe Ń Yára Kàwé Sí
Ńṣe ni ìwé kíkà àti dídá ọ̀rọ̀ mọ̀ jọ máa ń lọ ní ìfẹ̀gbẹ́kẹ̀gbẹ́. Kódà bó o ṣe ń kàwé yìí, ò ń dá àwọn ọ̀rọ̀ mọ̀, o sì ń rántí ohun tí wọ́n túmọ̀ sí. O lè mú kí ìwé kíkà rẹ yá kankan sí i bí o bá mú kí ìwọ̀n ọ̀rọ̀ tí ò ń dá mọ̀ lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo túbọ̀ pọ̀ sí i. Dípò kí o máa dúró wo ọ̀rọ̀ kọ̀ọ̀kan, gbìyànjú láti rí ọ̀rọ̀ bíi mélòó kan lẹ́ẹ̀kan náà. Bí o bá ń ṣe èyí, ìwọ yóò rí i pé ohun tó ò ń kà yóò túbọ̀ yé ọ sí i.
Kíkàwé pa pọ̀ máa ń mú kí àwọn tó wà nínú ìdílé fà mọ́ra tímọ́tímọ́
Àmọ́, nígbà tó o bá ń ka ohun tó túbọ̀ jinlẹ̀ sí i, o lè jèrè púpọ̀ sí i látinú ìsapá rẹ bó o bá lo ọgbọ́n mìíràn. Nígbà tí Jèhófà ń fún Jóṣúà nímọ̀ràn lórí kíka Ìwé Mímọ́, ó ní: “Ìwé òfin yìí kò gbọ́dọ̀ kúrò ní ẹnu rẹ, kí o sì máa fi ohùn jẹ́ẹ́jẹ́ẹ́ kà láti inú rẹ̀.” (Jóṣ. 1:8) Èèyàn sábà máa ń lo ohùn jẹ́ẹ́jẹ́ẹ́ nígbà tó bá ń ro àròjinlẹ̀. Nítorí náà, ọ̀rọ̀ Hébérù tí a túmọ̀ sí “fi ohùn jẹ́ẹ́jẹ́ẹ́ kà” ni a tún túmọ̀ sí “ṣe àṣàrò.” (Sm. 63:6; 77:12; 143:5) Nígbà tí èèyàn bá ń ṣe àṣàrò, ṣe ló máa ń ronú jinlẹ̀; kì í kánjú ṣe é. Béèyàn bá ń kàwé ní àkàronújinlẹ̀, ìyẹn máa ń jẹ́ kí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run túbọ̀ nípa lórí èrò inú àti ọkàn ẹni. Bíbélì ní àsọtẹ́lẹ̀ nínú, ìmọ̀ràn, àwọn òwe, ewì, àwọn ìpolongo ìdájọ́ Ọlọ́run, ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ àlàyé nípa ète Jèhófà, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ àpẹẹrẹ àwòkọ́ṣe téèyàn lè tẹ̀ lé ní ìgbésí ayé, tó sì jẹ́ pé gbogbo rẹ̀ ló wúlò fún ẹnikẹ́ni tó bá fẹ́ rìn ní àwọn ọ̀nà Jèhófà. Ó mà ṣàǹfààní gan-an o pé kí o ka Bíbélì lọ́nà tí yóò fi lè wọni lọ́kàn kó sì wọni lára!
Kọ́ Bí A Ṣe Ń Pọkàn Pọ̀
Bí o ṣe ń kàwé sí lè nípa lórí bí o ṣe ń tẹ̀ síwájú sí nípa tẹ̀mí
Bó o ṣe ń kàwé, jẹ́ kí ó dà bíi pé o wà níbi tí ohun tí ìwé náà ń ṣàpèjúwe ti ṣẹlẹ̀. Gbìyànjú láti fojú inú wo àwọn ẹni tí ìtàn náà ń sọ̀rọ̀ wọn, kí o sì fi ara rẹ sípò wọn láti mọ bí nǹkan ṣe rí lára wọn. Èyí dà bíi pé ó máa ń rọrùn láti ṣe bó o bá ń ka irú ìtàn bíi ti Dáfídì àti Gòláyátì, èyí tó wà nínú Sámúẹ́lì kìíní orí kẹtàdínlógún. Kódà àwọn kúlẹ̀kúlẹ̀ nípa bí wọ́n ṣe kọ́ àgọ́ ìjọsìn àti ìfilọ́lẹ̀ ipò àlùfáà, èyí tó wà nínú ìwé Ẹ́kísódù àti Léfítíkù pàápàá, yóò dà bí ohun tó ń ṣẹlẹ̀ lójú rẹ bí o bá ń fojú inú wo ìbú àti òró àwọn nǹkan tí Ìwé Mímọ́ mẹ́nu kàn àti bí nǹkan wọ̀nyẹn ṣe rí lójú, tàbí bí o bá ń ṣe bí ẹní gbọ́ òórùn tùràrí, òórùn àwọn ọkà sísun àti àwọn ẹran tí wọ́n fi ń rú ọrẹ ẹbọ sísun. Fojú inú wo bí yóò ṣe jẹ́ ohun ẹ̀rù tó láti máa ṣe iṣẹ́ àlùfáà! (Lúùkù 1:8-10) Bí o bá ń fi iyè inú àti ìmọ̀lára rẹ bá ohun tó ò ń kà lọ lọ́nà yìí, yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti mọ ìtumọ̀ ohun tó ò ń kà, ìyẹn á sì lè jẹ́ kí o rántí wọn.
Ṣùgbọ́n bí o kò bá ṣọ́ra, bí o bá ń gbìyànjú láti kàwé, ọkàn rẹ lè máa rìn gbéregbère kiri. O lè ranjú mọ́ ìwé náà, síbẹ̀ kó jẹ́ pé ibòmíràn ni ọkàn rẹ wà. Ṣé orin ò máa lọ lábẹ́lẹ̀? Ṣé o ò tan tẹlifíṣọ̀n sílẹ̀? Ṣé àwọn ará ilé ò máa pariwo? Tó bá ṣeé ṣe, ibi tó pa rọ́rọ́ ló dára jù lọ fúnni láti kàwé. Àmọ́, ìpínyà ọkàn lè tinú ẹni lọ́hùn-ún wá o. Bóyá o fi àárọ̀ ṣúlẹ̀ ṣiṣẹ́ kárakára. Wẹ́rẹ́ báyìí ni ìrònú nípa ìgbòkègbodò ọjọ́ yẹn lè padà wá sí ọ lọ́kàn! Lóòótọ́, ó dára pé kéèyàn padà ronú lórí ìgbòkègbodò ẹni lójúmọ́, àmọ́ kò yẹ kó jẹ́ ìgbà tó o bá ń kàwé. Bóyá o tilẹ̀ pọkàn pọ̀ nígbà tó o bẹ̀rẹ̀, o tiẹ̀ lè ti gbàdúrà kó o tó bẹ̀rẹ̀ sí kàwé. Ṣùgbọ́n kó di pé bó o ṣe ń kàwé lọ, ọkàn rẹ bẹ̀rẹ̀ sí kúrò níbẹ̀ díẹ̀díẹ̀. Tún gbìyànjú láti pọkàn pọ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i. Fi kọ́ra láti máa pọkàn pọ̀ sórí ohun tí o bá ń kà. Ní kẹ̀rẹ̀kẹ̀rẹ̀, wàá rí i pé o túbọ̀ ń ṣe dáadáa sí i.
Kí lo máa ń ṣe bí o bá débi ọ̀rọ̀ kan tí kò yé ọ? Àlàyé tàbí ìtumọ̀ àwọn kan lára àwọn ọ̀rọ̀ tí o kò mọ̀ yìí lè wà nínú ìwé náà. O sì lè róye ìtumọ̀ rẹ̀ látinú ọ̀rọ̀ tó yí i ká. Bí kò bá rí bẹ́ẹ̀, wá àyè láti wo ọ̀rọ̀ náà nínú ìwé atúmọ̀ èdè kan bí ó bá wà lárọ̀ọ́wọ́tó, tàbí kí o sàmì sí ọ̀rọ̀ yẹn kí o lè béèrè ìtumọ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ ẹnì kan lẹ́yìn náà. Èyí á jẹ́ kí àwọn ọ̀rọ̀ tó o mọ̀ túbọ̀ pọ̀ sí i, á sì jẹ́ kí ohun tí o bá ń kà túbọ̀ máa yé ọ sí i.
Kíkàwé ní Gbangba
Máa bá a lọ ní fífi ara rẹ fún ìwé kíkà ní gbangba
Nígbà tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù sọ fún Tímótì pé kó máa bá a lọ ní fífi ara rẹ̀ fún ìwé kíkà, ọ̀rọ̀ nípa kíkàwé sétígbọ̀ọ́ àwọn ẹlòmíràn ló ń sọ ní pàtó. (1 Tím. 4:13) Kì í ṣe kéèyàn kàn máa pe ọ̀rọ̀ inú ìwé sókè lásán là ń pè ní kíkàwé ní gbangba lọ́nà tó jáfáfá. Òǹkàwé ní láti mọ ìtumọ̀ ọ̀rọ̀ wọ̀nyẹn kí ó sì lóye èrò tí wọ́n ń gbé jáde. Ìgbà tí òye yẹn bá yé e nìkan ló tó lè gbé èrò yẹn jáde lọ́nà títọ́ kí ó sì gbé bí nǹkan ṣe rí lára yọ níbẹ̀ lọ́nà tó bá a mu rẹ́gí. Ó dájú pé èyí ń béèrè ìmúrasílẹ̀ àti àṣedánrawò tó múná dóko. Ìdí nìyẹn tí Pọ́ọ̀lù fi gbani níyànjú pé: “Máa bá a lọ ní fífi ara rẹ fún ìwé kíkà ní gbangba.” Ìwọ yóò gba ìdánilẹ́kọ̀ọ́ tó jíire nípa rẹ̀ nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run.
Máa Wá Àyè Láti Kàwé
“Dájúdájú, àwọn ìwéwèé ẹni aláápọn máa ń yọrí sí àǹfààní, ṣùgbọ́n ó dájú pé àìní ni olúkúlùkù ẹni tí ó bá ń kánjú forí lé.” (Òwe 21:5) Òótọ́ gbáà nìyẹn jẹ́ tó bá di ti ìwé kíkà! Bí a bá fẹ́ jẹ “àǹfààní” yìí, a ní láti wéwèé dáadáa kí àwọn ìgbòkègbodò mìíràn má bàa gbapò ìwé kíkà.
Ìgbà wo lo máa ń kàwé ná? Ṣé ìdájí ló pé ọ láti máa jí kàwé? Tàbí ọwọ́ ìrọ̀lẹ́ ni ara rẹ máa ń yá sí ìwé kíkà jù lọ? Bí o bá lè ya ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀ẹ́dógún sí ogún ìṣẹ́jú sọ́tọ̀ lóòjọ́ láti fi kàwé, àṣeyọrí tó o máa ṣe yóò yà ọ́ lẹ́nu. Kókó pàtàkì ibẹ̀ ni pé kó o máa kà á déédéé.
Kí nìdí tí Jèhófà fi yàn pé kí àwọn ète rẹ̀ àgbàyanu wà lákọọ́lẹ̀ nínú ìwé kan? Kí àwọn èèyàn lè máa ṣàyẹ̀wò àkọsílẹ̀ Ọ̀rọ̀ rẹ̀ ni. Èyí á mú kí wọ́n lè gbé àwọn iṣẹ́ àrà Jèhófà yẹ̀ wò, kí wọ́n sọ wọ́n fún àwọn ọmọ wọn, kí wọ́n má sì gbàgbé àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run. (Sm. 78:5-7) Ọ̀nà tí a gbà ń ṣakitiyan láti ka Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tó ń fúnni ní ìyè yìí ló máa sọ bí a ṣe mọrírì inúure tí Jèhófà fi hàn nípasẹ̀ ohun tó ṣe yìí tó.
-
-
Ìkẹ́kọ̀ọ́ LérèJàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
-
-
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Lérè
ǸJẸ́ o ti rí ibi tí àwọn èèyàn ti ń ṣa èso rí? Ọ̀pọ̀ jù lọ ló máa ń wo bí àwọ̀ rẹ̀ ṣe rí àti bó ṣe tóbi tó láti fi mọ bí ó ṣe pọ́n sí. Àwọn mìíràn máa ń fi imú gbóòórùn èso yẹn wò. Àwọn mìíràn yóò fi ọwọ́ kàn án, wọ́n a tiẹ̀ tẹ̀ ẹ́ wò. Àwọn mìíràn a tún wo bó ṣe tẹ̀wọ̀n sí, wọ́n á sọ ọ́ wò láti fi bó ṣe wúwo tó mọ èyí tó lómi nínú jù. Kí lèrò ọkàn àwọn èèyàn wọ̀nyí ná? Ńṣe ni wọ́n ń ṣàyẹ̀wò àwọn kúlẹ̀kúlẹ̀ kan, wọ́n ń wo bí àwọn èso wọ̀nyẹn ṣe yàtọ̀ síra, láìgbàgbé bí èyí tí wọ́n mú tẹ́lẹ̀ ṣe rí, wọn a sì fi ohun tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ ń rí báyìí wé èyí tí wọ́n ti mọ̀ tẹ́lẹ̀. Nítorí pé wọ́n fara balẹ̀ ṣa èso wọn, èso tó dùn ló máa bá wọn délé.
Dájúdájú, èrè kíkẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ju ìyẹn lọ dáadáa. Bó bá ti di pé irú ìkẹ́kọ̀ọ́ bẹ́ẹ̀ gba ipò pàtàkì nínú ayé wa, ìgbàgbọ́ wa yóò lágbára sí i, ìfẹ́ wa á túbọ̀ jinlẹ̀, àṣeyọrí iṣẹ́ ìsìn wa yóò pọ̀ sí i, àwọn ìpinnu tí a bá sì ṣe yóò fi ẹ̀rí hàn pé a túbọ̀ ní òye àti ọgbọ́n látọ̀dọ̀ Ọlọ́run. Òwe 3:15 sọ nípa irú èrè yẹn, ó ní: “A kò . . . lè mú gbogbo àwọn nǹkan mìíràn tí í ṣe inú dídùn rẹ bá a dọ́gba.” Ṣé o ń jẹ irú èrè bẹ́ẹ̀? Ọ̀nà tó o gbà ń kẹ́kọ̀ọ́ lè jẹ́ kókó pàtàkì tí yóò pinnu ìyẹn.—Kól. 1:9, 10.
Lo àkókò láti ṣàṣàrò
Kí ni ìkẹ́kọ̀ọ́? Ó ju ìwé kíkà oréfèé lọ. Ó wé mọ́ lílo ọpọlọ rẹ láti fara balẹ̀ gbé kókó kan yẹ̀ wò, tàbí láti rò ó jinlẹ̀. Ó kan fífọ́ ohun tó ò ń kà sí wẹ́wẹ́, fífi í wéra pẹ̀lú ohun tó o ti mọ̀ tẹ́lẹ̀, àti ṣíṣàkíyèsí àwọn ìdí tí wọ́n fi ṣe irú àlàyé tí wọ́n ṣe níbẹ̀. Nígbà tó o bá ń kẹ́kọ̀ọ́, máa ronú jinlẹ̀ lórí gbogbo ohun tí wọ́n ṣàlàyé níbẹ̀ tí o kò mọ̀ tẹ́lẹ̀. Tún ronú lórí bí ìwọ fúnra rẹ ṣe lè túbọ̀ fi ìmọ̀ràn Ìwé Mímọ́ sílò lẹ́kùn-únrẹ́rẹ́. Bí o ṣe jẹ́ Ẹlẹ́rìí Jèhófà, ó tún yẹ kó o ronú nípa àwọn ìgbà tó o lè láǹfààní láti fi ohun tó o kọ́ yẹn ṣèrànwọ́ fún àwọn ẹlòmíràn. Ó dájú pé àṣàrò ṣíṣe jẹ́ apá kan ẹ̀kọ́ kíkọ́.
Mímúra Ọkàn Rẹ Sílẹ̀ Láti Kẹ́kọ̀ọ́
Láti jàǹfààní kíkún rẹ́rẹ́ látinú ìkẹ́kọ̀ọ́ rẹ, múra ọkàn rẹ sílẹ̀
Bí o bá ń múra láti kẹ́kọ̀ọ́, o máa ń mú Bíbélì rẹ, àwọn ìtẹ̀jáde èyíkéyìí tó o bá ní lọ́kàn láti lò àti ohun ìkọ̀wé rẹ, bóyá o tún máa ń mú ìwé tó o máa kọ nǹkan sí pẹ̀lú. Ọkàn rẹ wá ńkọ́, ǹjẹ́ ò ń múra rẹ̀ sílẹ̀? Bíbélì sọ fún wa pé Ẹ́sírà “múra ọkàn-àyà rẹ̀ sílẹ̀ láti ṣe ìwádìí nínú òfin Jèhófà àti láti pa á mọ́ àti láti máa kọ́ni ní ìlànà àti ìdájọ́ òdodo ní Ísírẹ́lì.” (Ẹ́sírà 7:10) Kí ni irú ìmúra ọkàn ẹni sílẹ̀ bẹ́ẹ̀ wé mọ́?
Àdúrà máa ń jẹ́ ká lè fi ọkàn tí ó tọ́ bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run. Ohun tí à ń fẹ́ ni pé kí ìtọ́ni tí Jèhófà ń fún wa lè ríbi jókòó sí nínú ọkàn wa, ìyẹn ẹni tá a jẹ́ nínú lọ́hùn-ún. Ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ kọ̀ọ̀kan, bẹ Jèhófà pé kí ó fẹ̀mí rẹ̀ ràn ọ́ lọ́wọ́. (Lúùkù 11:13) Sọ fún un pé kí ó ràn ọ́ lọ́wọ́ láti lè mọ ìtumọ̀ ohun tó o fẹ́ kọ́, kí o mọ bí wọ́n ṣe wé mọ́ ète rẹ̀, kí o mọ bí yóò ṣe jẹ́ kí o lè mọ ìyàtọ̀ láàárín ohun rere àti búburú, kí o mọ bí o ṣe lè fi àwọn ìlànà rẹ̀ sílò nínú ìgbésí ayé rẹ, kí o sì mọ bí ẹ̀kọ́ náà yóò ṣe nípa lórí àjọṣe rẹ pẹ̀lú rẹ̀. (Òwe 9:10) Bí o ṣe ń kẹ́kọ̀ọ́ lọ, “máa bá a nìṣó ní bíbéèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run” pé kó fún ọ lọ́gbọ́n. (Ják. 1:5) Fi ohun tó ò ń kọ́ yẹ ara rẹ wò láìṣẹ̀tàn, bí o ṣe ń bẹ̀bẹ̀ fún ìrànlọ́wọ́ Jèhófà pé kí o lè borí àwọn èròkérò tàbí ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́. Máa “fi ìdúpẹ́ dá Jèhófà lóhùn” nígbà gbogbo nítorí àwọn ohun tó ń ṣí payá. (Sm. 147:7) Fífi àdúrà bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ lọ́nà báyìí máa ń mú kéèyàn sún mọ́ Jèhófà tímọ́tímọ́, nítorí ó máa ń jẹ́ kí a lè kọbi ara sí ohun tó ń tipa Ọ̀rọ̀ rẹ̀ bá wa sọ.—Sm. 145:18.
Níní irú àyà ìgbàṣe báyìí ni àwọn èèyàn Jèhófà fi yàtọ̀ sí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ yòókù. Láàárín àwọn tí kò ní ìfọkànsin Ọlọ́run, ohun tó wọ́pọ̀ ni pé, wọ́n máa ń ṣiyè méjì nípa ohun tó wà lákọọ́lẹ̀, tàbí kí wọ́n máa ṣàríwísí rẹ̀. Àmọ́ àwa kò ní irú ìwà yẹn ní tiwa. Jèhófà la gbẹ́kẹ̀ lé. (Òwe 3:5-7) Bí nǹkan kan ò bá yé wa, a ò kàn ní fi ìkùgbù gbà pé àṣìṣe ló ní láti jẹ́. Bí a ṣe ń wá ìdáhùn kiri, tí a sì ń ṣèwádìí jinlẹ̀ lórí rẹ̀, a óò dúró de Jèhófà. (Míkà 7:7) Ohun tí Ẹ́sírà ṣe làwa náà ń fẹ́ ṣe, ńṣe la fẹ́ fi ohun tí à ń kọ́ sílò ká sì tún fi kọ́ ẹlòmíràn pẹ̀lú. Bí a bá ti fi èyí sọ́kàn, ó dájú pé a ó jàǹfààní lẹ́kùn-únrẹ́rẹ́ látinú ìkẹ́kọ̀ọ́ wa.
Bí A Ṣe Ń Kẹ́kọ̀ọ́
Dípò tí wàá kàn ṣáà fi bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ látorí ìpínrọ̀ kìíní tí wàá sì máa bá a lọ bẹ́ẹ̀ títí dé ìparí rẹ̀, kọ́kọ́ fẹ̀sọ̀ ṣàyẹ̀wò àpilẹ̀kọ tàbí orí ìwé tó o fẹ́ kà látòkèdélẹ̀ ná. Lẹ́yìn náà wá ronú lórí ìtumọ̀ àkòrí ohun tó o fẹ́ kà yìí. Òun ni ẹṣin ọ̀rọ̀ ohun tó o fẹ́ kẹ́kọ̀ọ́. Lẹ́yìn náà wá fara balẹ̀ kíyè sí bí àwọn àkọlé kéékèèké inú rẹ̀ ṣe tan mọ́ ẹṣin ọ̀rọ̀ yìí. Ṣàyẹ̀wò àwọn àwòrán, àwọn atọ́ka, tàbí àwọn àpótí ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́ tó bá wà nínú ibi tó o fẹ́ kà. Bi ara rẹ léèrè pé: ‘Lójú àyẹ̀wò tí mo kọ́kọ́ ṣe yìí, kí ni mo ń retí láti kọ́ ná? Ọ̀nà wo ni yóò gbà wúlò fún mi?’ Èyí á jẹ́ atọ́nà fún ìkẹ́kọ̀ọ́ rẹ.
Mọ àwọn ohun èlò ìṣèwádìí tó wà ní èdè rẹ dunjú
Wá gbé àlàyé ẹ̀kọ́ yẹn yẹ̀ wò wàyí. A máa ń tẹ àwọn ìbéèrè sí àwọn àpilẹ̀kọ fún ìkẹ́kọ̀ọ́ Ilé Ìṣọ́ àti àwọn ìwé kan. Bí o ṣe ń ka ìpínrọ̀ kọ̀ọ̀kan, ó dáa pé kí o sàmì sí àwọn ìdáhùn tó wà níbẹ̀. Bí kò bá tiẹ̀ sí ìbéèrè fún ìkẹ́kọ̀ọ́ níbẹ̀, o ṣì lè sàmì sí àwọn kókó pàtàkì tó o fẹ́ láti rántí. Bí o bá ka nǹkan kan tí o kò mọ̀ tẹ́lẹ̀, lo àkókò díẹ̀ lórí rẹ̀ láti rí i dájú pé ó yé ọ dáadáa. Máa kíyè sí àwọn àpèjúwe tàbí àwọn àlàyé tí yóò wúlò fún ọ lóde ẹ̀rí tàbí èyí tí o lè lò nínú ọ̀rọ̀ tí wọ́n bá yàn fún ọ láti sọ lọ́jọ́ iwájú. Ronú nípa àwọn ẹni pàtó kan tí o lè sọ ohun tó ò ń kọ́ fún tí yóò sì gbé ìgbàgbọ́ wọn ró. Sàmì sí àwọn kókó tó o fẹ́ lò, kí o sì ṣàtúnyẹ̀wò wọn nígbà tó o bá parí ìkẹ́kọ̀ọ́ rẹ.
Bí o ṣe ń gbé ẹ̀kọ́ yẹn yẹ̀ wò, ka àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tí wọ́n tọ́ka sí. Ronú nípa bí ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kọ̀ọ̀kan ṣe wé mọ́ ẹ̀kọ́ pàtàkì tí ìpínrọ̀ yẹn ń kọ́ni.
O lè pàdé àwọn kókó kan tí kò fi bẹ́ẹ̀ yé ọ, tàbí èyí tó o máa fẹ́ túbọ̀ ṣèwádìí dáadáa nípa rẹ̀. Dípò fífi ìyẹn dí ara rẹ lọ́wọ́, kọ ọ́ sílẹ̀ kí o lè fún un láfiyèsí tó bá yá. Lọ́pọ̀ ìgbà, wọ́n á ṣàlàyé kókó yẹn níwájú bí o ṣe ń ka ìwé náà lọ. Bí kò bá rí bẹ́ẹ̀, o lè ṣe àfikún ìwádìí nípa rẹ̀. Àwọn nǹkan wo lo lè kọ sílẹ̀ láti gbé yẹ̀ wò lọ́nà bẹ́ẹ̀? Bóyá wọ́n fa ọ̀rọ̀ ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan yọ tí kò fí bẹ́ẹ̀ yé ọ tó, tàbí o lè má fi bẹ́ẹ̀ rí bó ṣe kan kókó tí wọ́n ń jíròrò. Bóyá o sì rò pé òye ohun kan nínú ìwé yẹn yé ọ, àmọ́ kò yé ọ tó èyí tó o fi lè ṣàlàyé rẹ̀ fún ẹlòmíràn. Dípò tí wàá kàn fi gbójú fò wọ́n, ó lè bọ́gbọ́n mu pé kí o ṣe ìwádìí nípa wọn lẹ́yìn tó o bá parí ẹ̀kọ́ tí ò ń kọ́ lọ́wọ́.
Rí i dájú pé o ka àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ ibẹ̀
Nígbà tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù ń kọ lẹ́tà alálàyé kíkún rẹ́rẹ́ sí àwọn Hébérù tó jẹ́ Kristẹni, ó dá ọ̀rọ̀ tó ń sọ bọ̀ dúró díẹ̀ láàárín kan, ó ní: “Lájorí kókó rẹ̀ nìyí.” (Héb. 8:1) Ǹjẹ́ o máa ń dúró bẹ́ẹ̀ látìgbàdégbà láti rántí ohun tí ò ń bá bọ̀? Wo ìdí tí Pọ́ọ̀lù fi ṣe bẹ́ẹ̀. Nínú àwọn orí ìṣáájú nínú lẹ́tà rẹ̀ onímìísí yìí, ó ti kọ́kọ́ fi hàn pé Kristi tí Ọlọ́run fi jẹ Àlùfáà Àgbà títóbi ti wọ ọ̀run lọ́hùn-ún lọ. (Héb. 4:14–5:10; 6:20) Síbẹ̀, bí Pọ́ọ̀lù ṣe dá lájorí kókó yẹn yà sọ́tọ̀, tó sì wá tẹnu mọ́ ọn ní ìbẹ̀rẹ̀ Héb orí kẹjọ ẹsẹ 1, ńṣe ló fi ìyẹn múra ọkàn àwọn òǹkàwé rẹ̀ sílẹ̀, kí wọ́n lè ronú jinlẹ̀ lórí bí ó ṣe kan ìgbésí ayé tiwọn. Ó wá fi hàn pé Kristi ti lọ fara hàn níwájú Ọlọ́run tìkára rẹ̀ fún wọn, ó sì wá ṣí ọ̀nà sílẹ̀ fún wọn kí àwọn náà lè wọnú “ibi mímọ́” yẹn ní ọ̀run. (Héb. 9:24; 10:19-22) Dídájú tí ìrètí wọn dájú yìí yóò mú kí wọ́n lè fi ìmọ̀ràn tó sọ síwájú sí i nínú lẹ́tà rẹ̀ sílò, ìmọ̀ràn nípa ìgbàgbọ́, ìfaradà, àti ìwà híhù Kristẹni. Bákan náà, bí a bá ń kẹ́kọ̀ọ́, fífi ọkàn sí àwọn kókó pàtàkì ibẹ̀ yóò jẹ́ kí a lè róye bí ẹṣin ọ̀rọ̀ yẹn ṣe ń tẹ̀ síwájú, yóò sì jẹ́ kí àwọn ìdí yíyèkooro tó fi yẹ kí á ṣe ohun tí ọ̀rọ̀ yẹn sọ wọ̀ wá lọ́kàn ṣinṣin.
Ṣé ìdákẹ́kọ̀ọ́ rẹ yóò sún ọ láti fi ohun tó o kọ́ sílò? Ìbéèrè yìí ṣe kókó. Bí o bá ti kọ́ nǹkan kan, bi ara rẹ léèrè pé: ‘Ipa wo ló yẹ kí èyí ní lórí ìwà mi àti àwọn ohun tí mò ń lépa nínú ìgbésí ayé? Báwo ni mo ṣe lè lo ìsọfúnni yìí nígbà tí mo bá fẹ́ yanjú ìṣòro, nígbà tí mo bá ń ṣe ìpinnu, tàbí nígbà tí mo bá ń lépa nǹkan kan? Báwo ni mo ṣe lè lò ó nínú ìdílé mi, lóde ẹ̀rí, àti nínú ìjọ?’ Ronú jinlẹ̀ nípa àwọn ìbéèrè wọ̀nyí, kí o sì ronú nípa àwọn ipò gidi tó o ti lè lo ìmọ̀ rẹ.
Bí o bá ka orí kan tàbí àpilẹ̀kọ kan tán, lo àsìkò díẹ̀ láti fi ṣàtúnyẹ̀wò ráńpẹ́. Wò ó bóyá o lè rántí àwọn kókó pàtàkì ibẹ̀ àti àwọn àlàyé tí wọ́n ṣe nípa wọn. Ìgbésẹ̀ yìí yóò jẹ́ kí o lè rántí ìsọfúnni yẹn láti lè lò ó lọ́jọ́ iwájú.
Ohun Tí A Máa Lò fún Ìkẹ́kọ̀ọ́
Bí a ṣe jẹ́ èèyàn Jèhófà, a ní ohun púpọ̀ láti kọ́. Àmọ́ ibo ni ká ti bẹ̀rẹ̀ ná? Lójoojúmọ́, ó dára pé kí á ka ẹsẹ ojoojúmọ́ àti àlàyé rẹ̀ látinú ìwé Ṣíṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́. Lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀, a ń lọ sí àwọn ìpàdé ìjọ, ẹ̀kọ́ tí a bá kọ́ láti fi múra ìpàdé wọ̀nyí sílẹ̀ yóò jẹ́ ká lè jàǹfààní púpọ̀ gan-an. Láfikún sí èyí, àwọn kan ń lo àkókò wọn lọ́nà tó bọ́gbọ́n mu, wọ́n fi ń ka àwọn kan lára àwọn ìtẹ̀jáde Kristẹni tó ti wà kí wọ́n tó kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́. Àwọn mìíràn ń yan apá kan nínú Bíbélì kíkà ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀ wọn, wọ́n á ṣe ìwádìí tó jinlẹ̀ lórí àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ wọ̀nyẹn.
Bí ipò tó yí ọ ká kò bá jẹ́ kó o lè fara balẹ̀ ka gbogbo ìsọfúnni tí a máa gbé yẹ̀ wò láwọn ìpàdé ìjọ ọ̀sọ̀ọ̀sẹ̀ ńkọ́? Yẹra fún àṣìṣe pé kí o sáré ka ìwé yẹn fìrìfìrì láti kàn rí i pé o ṣáà kà á, tàbí àṣìṣe tó tiẹ̀ burú jù ìyẹn lọ, ìyẹn ni kí o tìtorí pé o kò ní lè ka gbogbo rẹ̀ tán kó o máà kúkú ka ìkankan rárá lára rẹ̀. Kàkà bẹ́ẹ̀, wo ìwọ̀nba tó o bá lè kà, kí o sì kà á dáadáa. Máa kà á bẹ́ẹ̀ lọ́sọ̀ọ̀sẹ̀. Nígbà tó bá yá, gbìyànjú láti máa kárí àwọn apá ìpàdé tí o kì í kárí tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀.
“Gbé Agbo Ilé Rẹ Ró”
Jèhófà mọ̀ pé àwọn olórí ìdílé ní láti ṣiṣẹ́ kára láti lè gbọ́ bùkátà àwọn ará ilé wọn. Òwe 24:27 sọ pé: “Múra iṣẹ́ rẹ sílẹ̀ lóde, kí o sì pèsè rẹ̀ sílẹ̀ fún ara rẹ ní pápá.” Síbẹ̀, o kò lè gbójú fo ohun tí ìdílé rẹ nílò nípa tẹ̀mí. Ìyẹn ni ẹsẹ yẹn fi tẹ̀ síwájú pé: “Lẹ́yìn ìgbà náà, kí o gbé agbo ilé rẹ ró pẹ̀lú.” Báwo ni àwọn olórí ìdílé ṣe lè ṣe èyí? Òwe 24:3 sọ pé: “Nípa ìfòyemọ̀ [ni agbo ilé] yóò fi fìdí múlẹ̀ gbọn-in gbọn-in.”
Báwo ni ìfòyemọ̀ ṣe lè ṣàǹfààní fún ìdílé rẹ? Ìfòyemọ̀ ni pé kéèyàn lè fi làákàyè mọ ohun tí kò hàn sójú táyé. Nípa bẹ́ẹ̀, ńṣe ni ká sọ pé ìkẹ́kọ̀ọ́ ìdílé tó gbéṣẹ́ bẹ̀rẹ̀ láti orí fífarabalẹ̀ ṣàyẹ̀wò ìdílé rẹ fúnra rẹ. Báwo ni àwọn tó wà nínú ìdílé rẹ ṣe ń tẹ̀ síwájú sí nípa tẹ̀mí? Fetí sílẹ̀ dáadáa bí ẹ bá jọ ń sọ̀rọ̀. Ṣé ẹ̀mí ìráhùn tàbí ìkórìíra wà níbẹ̀? Ṣé ìlépa ọrọ̀ àlùmọ́ọ́nì ló jẹ wọ́n lógún? Bí ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ bá wà lóde ẹ̀rí, ṣé ó máa ń yá wọn lára láti sọ lójú àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn pé Ẹlẹ́rìí Jèhófà ni àwọn? Ǹjẹ́ ètò ìkẹ́kọ̀ọ́ àti Bíbélì kíkà ti ìdílé ń gbádùn mọ́ wọn? Ǹjẹ́ wọ́n ń fi ọ̀nà Jèhófà ṣe ọ̀nà ìgbésí ayé wọn ní ti tòótọ́? Bí o bá fẹ̀sọ̀ ṣàkíyèsí wọn, wàá lè mọ ohun tí ìwọ olórí ìdílé ní láti ṣe láti lè gbin ànímọ́ tẹ̀mí sọ́kàn olúkúlùkù ẹni tó wà nínú ìdílé rẹ.
Wo inú Ilé Ìṣọ́ àti Jí! láti rí àwọn àpilẹ̀kọ tó sọ̀rọ̀ nípa àwọn ohun pàtó kan tó ń fẹ́ àbójútó. Kó o wá sọ ohun tí ẹ máa kẹ́kọ̀ọ́ nípa rẹ̀ fún ìdílé rẹ ṣáájú, kí àwọn náà lè ronú lórí ìsọfúnni yẹn. Jẹ́ kí àsìkò ìkẹ́kọ̀ọ́ yín tura. Ṣàlàyé bí ohun tí ẹ ń gbé yẹ̀ wò lọ́wọ́ ṣe wúlò, kí o sọ bí ó ṣe kan ohun tó ń fẹ́ àbójútó nínú ìdílé yín ní pàtó láìsí pé o ń sọ kòbákùngbé ọ̀rọ̀ sí ẹnikẹ́ni nínú ìdílé tàbí pé o ń dójú ti ẹnikẹ́ni. Jẹ́ kí gbogbo ìdílé pátá lóhùn sí i. Ran olúkúlùkù lọ́wọ́ láti rí bí Ọ̀rọ̀ Jèhófà ṣe “pé” ní ti ọ̀nà tó gbà ń pèsè ohun tí ẹnì kọ̀ọ̀kan nílò gan-an ní ìgbésí ayé rẹ̀.—Sm. 19:7.
Èrè Rẹ̀
Àwọn èèyàn tó lákìíyèsí, ṣùgbọ́n tí wọn kò lóye ohun tẹ̀mí, lè ṣèwádìí nípa ojú ọ̀run, àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ inú ayé, àti nípa àwọn fúnra wọn pàápàá, síbẹ̀ kí wọ́n má mọ ìtumọ̀ ohun tí wọ́n ń rí ní ti gidi. Láìdàbíi tiwọn, àwọn tó ń kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run déédéé ń tipasẹ̀ ìrànlọ́wọ́ ẹ̀mí Ọlọ́run rí òye iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ látinú àwọn nǹkan wọ̀nyí, wọ́n ń rí ìmúṣẹ àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì, àti bí Ọlọ́run ṣe ń ṣí ète tí yóò fi bù kún àwọn onígbọràn nínú aráyé, payá.—Máàkù 13:4-29; Róòmù 1:20; Ìṣí. 12:12.
Bí ìyẹn sì ṣe jẹ́ ohun ìyanu tó yìí, kò yẹ kí ó mú wa gbéra ga rárá. Kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe ni àyẹ̀wò Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lójoojúmọ́ ń ràn wá lọ́wọ́ láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀. (Diu. 17:18-20) Ó tún ń gbà wá lọ́wọ́ “agbára ìtannijẹ ẹ̀ṣẹ̀,” nítorí pé bí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run bá ti ń ṣiṣẹ́ nínú ọkàn wa, wíwù tí ẹ̀ṣẹ̀ máa ń wuni kò ní lè borí ìpinnu tí a ti ṣe láti dènà ẹ̀ṣẹ̀. (Héb. 2:1; 3:13; Kól. 3:5-10) Nípa bẹ́ẹ̀, a óò lè “máa rìn lọ́nà tí ó yẹ Jèhófà fún ète wíwù ú ní kíkún bí [a] ti ń bá a lọ ní síso èso nínú iṣẹ́ rere gbogbo.” (Kól. 1:10) Nítorí kí a lè máa ṣe bẹ́ẹ̀ gan-an la kúkú ṣe ń kẹ́kọ̀ọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ṣíṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́lẹ́ ló sì jẹ́ èrè tó ga jù lọ.
-
-
Bí A Ṣe Ń Ṣe ÌwádìíJàǹfààní Nínú Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run
-
-
Bí A Ṣe Ń Ṣe Ìwádìí
SÓLÓMỌ́NÌ ỌBA “fẹ̀sọ̀ ronú, ó sì ṣe àyẹ̀wò fínnífínní, kí ó lè ṣètò ọ̀pọ̀lọpọ̀ òwe lọ́nà gígún régé.” Kí nìdí rẹ̀? Nítorí ó fẹ́ láti kọ “àwọn ọ̀rọ̀ títọ̀nà tí ó jẹ́ òtítọ́.” (Oníw. 12:9, 10) Lúùkù “tọpasẹ̀ ohun gbogbo láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ìpéye” kí ó lè sọ ìtàn ohun tó ṣẹlẹ̀ nígbà ayé Kristi bí ó ṣe ṣẹlẹ̀ tẹ̀ léra gẹ́lẹ́. (Lúùkù 1:3) Ìwádìí ni ohun tí àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run méjèèjì yìí ń ṣe.
Kí ni ìwádìí? Ìwádìí jẹ́ fífẹ̀sọ̀ wá ìsọfúnni nípa ohun kan. Ó kan ìwé kíkà, ó sì gba kéèyàn fi àwọn ìlànà tó rọ̀ mọ́ ẹ̀kọ́ kíkọ́ sílò. Ó tún lè mú fífi ọ̀rọ̀ wáni lẹ́nu wò lọ́wọ́.
Kí làwọn nǹkan tó lè mú kí ìwádìí yẹ ní ṣíṣe? Àwọn àpẹẹrẹ mélòó kan rèé. Àwọn ìbéèrè tó ṣe pàtàkì lójú rẹ lè jẹ yọ nígbà ìdákẹ́kọ̀ọ́ rẹ tàbí bí o bá ń ka Bíbélì. Ẹni tí o wàásù fún lè béèrè ìbéèrè kan tí wàá fẹ́ ní ìsọfúnni pàtó láti fi dáhùn ìbéèrè yẹn. Ó sì lè jẹ́ pé a yan ọ̀rọ̀ kan fún ọ láti sọ ni.
Wo àpẹẹrẹ ọ̀rọ̀ tí a yàn fún ọ láti sọ. Ó lè jẹ́ kókó kan tó kó ohun púpọ̀ mọ́ra ni wọ́n ní kí o sọ̀rọ̀ lé lórí. Báwo ni wàá ṣe mú un bá ohun tó ń ṣẹlẹ̀ nínú ìjọ mu? Ńṣe ni kí o ṣe ìwádìí nípa rẹ̀ láti mú kí ó túbọ̀ kún fún ẹ̀kọ́. Bí o bá fi ìsọfúnni oníṣirò bíi mélòó kan, tàbí àpẹẹrẹ kan tó bá ọ̀rọ̀ rẹ mu tó sì tún wọ àwọn tó ò ń bá sọ̀rọ̀ lọ́kàn, ṣàlàyé kókó kan tó dà bíi pé àwọn èèyàn ti mọ̀ bí ẹní mowó, kókó yẹn á di èyí tó kún fún ẹ̀kọ́, yóò tiẹ̀ tún tani jí pàápàá. Àpilẹ̀kọ tí wọ́n gbé ọ̀rọ̀ tó o fẹ́ sọ kà lè jẹ́ èyí tí a kọ fún ìlò àwọn òǹkàwé jákèjádò ayé, bẹ́ẹ̀ sì rèé, o ní láti ṣàlàyé ọ̀rọ̀ náà, kí o fi àpèjúwe tì í lẹ́yìn, kí o sì mú àwọn kókó inú rẹ̀ bá ìjọ tàbí ẹnì kan pàtó mu. Ọ̀nà wo lo máa wá gbé e gbà?
Kí o tó bẹ̀rẹ̀ ìwádìí rẹ rárá, kọ́kọ́ ronú nípa àwùjọ tó o fẹ́ bá sọ̀rọ̀. Kí ni wọ́n á ti mọ̀ nípa kókó yẹn? Kí ló yẹ kí wọ́n mọ̀? Lẹ́yìn náà, wá pinnu ohun tó o fẹ́ ṣe. Ṣé o fẹ́ ṣàlàyé nǹkan kan ni? tàbí o fẹ́ mú nǹkan kan dáni lójú? tàbí o fẹ́ já ohun kan ní koro? tàbí o fẹ́ rọni láti ṣe nǹkan kan? Àlàyé ṣíṣe ń béèrè pé kéèyàn pèsè ìsọfúnni síwájú sí i láti mú kí ọ̀ràn kan yéni yékéyéké. Àwọn kókó inú ọ̀rọ̀ yẹn lè yé wọn o, ṣùgbọ́n ó lè jẹ́ pé wàá túbọ̀ ṣàlàyé nípa ìgbà tí wọ́n máa ṣe ohun tí wọ́n gbọ́ tàbí bí wọ́n ṣe máa ṣe é. Mímú nǹkan dáni lójú ń béèrè pé kéèyàn ṣàlàyé àwọn ìdí tí ohun tá à ń sọ fi rí bẹ́ẹ̀, títí kan mímú ẹ̀rí wá. Jíjá nǹkan ní koro ń béèrè pé kéèyàn mọwá kó sì mẹ̀yìn ọ̀ràn ọ̀hún, kó sì tún ṣàlàyé àwọn ẹ̀rí tó bá lò yéni yékéyéké. Ó dájú ṣá o, pé ète wa kì í ṣe láti kàn wá àwọn gbankọgbì ẹ̀rí láti fi bi ọ̀rọ̀ ṣubú, bí kò ṣe láti fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ ṣàlàyé òótọ́ ọ̀rọ̀. Rírọni láti ṣe nǹkan kan wé mọ́ sísọ̀rọ̀ lọ́nà tó wọni lọ́kàn. Ó túmọ̀ sí pé a óò bá àwùjọ sọ̀rọ̀ lọ́nà tí yóò ta wọ́n jí, a ó sì gbin èrò tí yóò mú kí wọ́n tara ṣàṣà láti ṣe ohun tí a ń wí sí wọn lọ́kàn. Mímú àpẹẹrẹ àwọn tó ti ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀, àní lójú ìnira pàápàá wá, lè jẹ́ kí ọ̀rọ̀ náà wọni lọ́kàn ṣinṣin.
O ti fẹ́ bẹ̀rẹ̀ ìwádìí wàyí, àbí? Ṣì ní sùúrù ná. Ronú nípa ìwọ̀n ìsọfúnni tó o nílò. Àkókò tí o máa fi sọ ọ́ tún ṣe pàtàkì. Bó bá ṣe pé o fẹ́ sọ ọ̀rọ̀ ọ̀hún fún àwọn kan ni, báwo ni àkókò tó o ní láti fi sọ ọ́ ṣe pọ̀ tó? Ṣé ìṣẹ́jú márùn-ún ni? Ṣé ìṣẹ́jú márùndínláàádọ́ta ni? Ṣé ó ti ní àkókò pàtó tó wà fún un, bíi ti ìpàdé ìjọ tàbí kò níye àkókò kan pàtó, bíi ti ìgbà tí a bá lọ ṣe ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì tàbí ìbẹ̀wò olùṣọ́ àgùntàn?
Lákòótán, àwọn ohun èlò ìṣèwádìí wo lo lè rí lò? Láfikún sí àwọn tó o ní nílé, ṣé ó tún ku àwọn mìíràn tó o lè rí nínú ibi ìkówèésí ní Gbọ̀ngàn Ìjọba yín? Ṣé àwọn ará tó ti ń sin Jèhófà láti ọ̀pọ̀ ọdún wá yóò jẹ́ kí o lo àwọn ohun èlò ìṣèwádìí tiwọn? Ṣé ibi ìkówèésí ti ìlú wà lágbègbè rẹ, níbi tó o ti lè rí àwọn ìwé ìṣèwádìí lò bí ó bá yẹ bẹ́ẹ̀?
Lílo Bíbélì—Ohun Èlò Ìṣèwádìí Wa Tó Gba Iwájú Jù Lọ
Bí ohun tó ò ń ṣèwádìí nípa rẹ̀ bá kan mímọ ìtumọ̀ ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan, kúkú bẹ̀rẹ̀ látinú Bíbélì fúnra rẹ̀.
Gbé Ohun Tó Fa Ọ̀rọ̀ Yẹn Yẹ̀ Wò. Bi ara rẹ léèrè pé: ‘Ta ni ẹsẹ yìí ń bá sọ̀rọ̀? Kí ni àwọn ẹsẹ tó yí i ká fi hàn nípa ohun tó fà á tí wọ́n fi sọ ọ̀rọ̀ yẹn, tàbí ìwá àwọn èèyàn tí ẹsẹ yẹn ń sọ?’ Irú àwọn kúlẹ̀kúlẹ̀ bí ìwọ̀nyí sábà máa ń jẹ́ ká lè lóye ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan, wọ́n sì tún lè mú kí ọ̀rọ̀ tí o sọ nígbà tó o lò wọ́n túbọ̀ lárinrin.
Bí àpẹẹrẹ, a sábà máa ń lo ọ̀rọ̀ Hébérù 4:12 láti fi sọ bí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ṣe lágbára láti gún ọkàn ní kẹ́ṣẹ́ kí ó sì nípa lórí ìgbésí ayé ẹni. Ohun tó fa ọ̀rọ̀ yẹn túbọ̀ jẹ́ kí a mọyì bí ó ṣe lè rí bẹ́ẹ̀. Ọ̀rọ̀ nípa ìrírí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì nígbà ogójì ọdún tí wọ́n lò nínú aginjù kí wọ́n tó wọnú ilẹ̀ tí Jèhófà ṣèlérí fún Ábúráhámù ló ti ń sọ bọ̀. (Héb. 3:7–4:13) “Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run,” ìyẹn ìlérí tó ṣe láti mú wọn wá sí ibi ìsinmi ní ìbámu pẹ̀lú májẹ̀mú tó bá Ábúráhámù dá, kì í ṣe òkú ọ̀rọ̀; ààyè ọ̀rọ̀ tó ń báṣẹ́ lọ síbi tí yóò ti ní ìmúṣẹ ni. Kò sì sídìí tí kò fi yẹ kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gbà á gbọ́. Àmọ́ o, bí Jèhófà ṣe ń ṣamọ̀nà wọn lọ láti Íjíbítì sí Òkè Sínáì, àti sí ọ̀nà Ilẹ̀ Ìlérí, léraléra ni wọ́n hùwà àìnígbàgbọ́. Nípa bẹ́ẹ̀, ìhùwàsí wọn nípa ọ̀nà tí Ọlọ́run gbà ń mú ọ̀rọ̀ ṣẹ wá fi ohun tó wà nínú ọkàn wọn hàn gbangba. Lọ́nà kan náà, láyé ìgbà tiwa yìí, ọ̀rọ̀ tí ó jẹ́ ìlérí Ọlọ́run máa ń fi ohun tó wà nínú ọkàn àwọn èèyàn hàn.
Yẹ Àwọn Atọ́ka Etí Ìwé Wò. Àwọn Bíbélì kan ní àwọn atọ́ka etí ìwé. Ṣé tìrẹ ní? Bí ó bá ní, ìyẹn lé ṣèrànwọ́. Wo àpẹẹrẹ kan látinú Ìwé Mímọ́ ní Ìtumọ̀ Ayé Tuntun. Ìwé 1 Pétérù 3:6 sọ nípa Sárà pé ó jẹ́ ẹni àwòkọ́ṣe fún àwọn Kristẹni aya. Atọ́ka etí ìwé ibẹ̀ tó tọ́ka sí Jẹ́nẹ́sísì 18:12 ti ọ̀rọ̀ yẹn lẹ́yìn nípa fífi hàn pé ńṣe ni Sárà sọ ọ́ “nínú ara rẹ̀” pé Ábúráhámù jẹ́ olúwa òun. Nípa bẹ́ẹ̀, ìtẹríba àtọkànwá ló ní. Láfikún sí àwọn ìjìnlẹ̀ òye bí èyí, atọ́ka etí ìwé tún lè tọ́ka rẹ sí àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó jẹ́ ká mọ ìmúṣẹ àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì kan tàbí àpẹẹrẹ májẹ̀mú Òfin kan. Àmọ́ ṣá o, kí ó yé ọ pé àwọn atọ́ka etí ìwé kan kò wà fún ṣíṣe irú àwọn àlàyé yẹn o. Ó kàn lè jẹ́ àwọn ọ̀rọ̀ tó jọra wọn ni wọ́n ń tọ́ka sí, tàbí ìtàn ìgbésí ayé ẹnì kan, tàbí ìsọfúnni nípa ìlú tàbí ilẹ̀ ibì kan.
Fi Atọ́ka Ọ̀rọ̀ Bíbélì Wá A. Atọ́ka ọ̀rọ̀ Bíbélì jẹ́ ìwé atọ́ka kan tí a to àwọn ọ̀rọ̀ tí wọ́n lò nínú Bíbélì sí lọ́nà A, B, D. Ó lè ràn ọ́ lọ́wọ́ láti ṣàwárí àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó jẹ mọ́ kókó tí ò ń ṣèwádìí nípa rẹ̀. Bí o bá ṣe ń yẹ̀ wọ́n wò, wàá tún mọ àwọn kúlẹ̀kúlẹ̀ àlàyé mìíràn tó lè ṣèrànwọ́ síwájú sí i. Ìwọ yóò rí ẹ̀rí nípa “àpẹẹrẹ” òtítọ́ tí a là lẹ́sẹẹsẹ tó wà nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run. (2 Tím. 1:13) Ìwé Mímọ́ ní Ìtumọ̀ Ayé Tuntun ní ìtòlẹ́sẹẹsẹ ṣókí fún “Atọ́ka Àṣàyàn Ọ̀rọ̀ Bíbélì.” Ìwé atọ́ka Comprehensive Concordance kún jù bẹ́ẹ̀ lọ. Bí ó bá wà ní èdè rẹ, yóò tọ́ka rẹ sí gbogbo ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tí wọ́n ti lo àwọn lájorí ọ̀rọ̀ kọ̀ọ̀kan nínú Bíbélì.
Kíkọ́ Láti Lo Àwọn Ohun Èlò Ìṣèwádìí Yòókù
Àpótí tó wà lójú ewé 33 tọ́ka sí àwọn ohun ìṣèwádìí mélòó kan tí “ẹrú olóòótọ́ àti olóye” ti pèsè. (Mát. 24:45-47) Ọ̀pọ̀ nínú wọn ní àtẹ kókó ẹ̀kọ́, púpọ̀ nínú wọn sì ní atọ́ka lápá ẹ̀yìn wọn, èyí tí a ṣe lọ́nà tí yóò fi lè ràn ọ́ lọ́wọ́ láti wá ìsọfúnni pàtó rí. Ní ìparí ọdún kọ̀ọ̀kan, a máa ń tẹ atọ́ka kókó àpilẹ̀kọ sínú Ilé Ìṣọ́ àti Jí! láti tọ́ka ọ̀wọ́ àpilẹ̀kọ ti ọdún náà.
Béèyàn bá mọ irú ìsọfúnni tó wà nínú àwọn ìtẹ̀jáde tó dá lórí Bíbélì yìí, ìyẹn lè mú kí ìwádìí yá kíákíá láti ṣe. Bí àpẹẹrẹ, tó o bá ń fẹ́ mọ̀ nípa àsọtẹ́lẹ̀, ẹ̀kọ́ ohun tá a gbà gbọ́, ìwà Kristẹni, tàbí ìlò àwọn ìlànà Bíbélì. Inú Ilé Ìṣọ́ ló ṣeé ṣe kí o ti rí ohun tí ò ń wá. Jí! máa ń jíròrò àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ lọ́ọ́lọ́ọ́, àwọn ìṣòro, ẹ̀sìn, sáyẹ́ǹsì, àti àwọn èèyàn ní onírúurú ilẹ̀ òde òní. Àlàyé lórí bí ọ̀kọ̀ọ̀kan ìtàn inú àwọn ìwé Ìhìn Rere ṣe ṣẹlẹ̀ ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé, wà nínú ìwé Ọkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí. Ìjíròrò odindi ìwé Bíbélì kan lẹ́sẹẹsẹ wà nínú irú ìtẹ̀jáde bí ìwé Ìṣípayá-Òtéńté Rẹ̀ Títóbi Lọ́lá Kù Sí Dẹ̀dẹ̀!, Kíyè sí Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì! àti apá méjèèjì ìwé Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé. Nínú ìwé Reasoning From the Scriptures, ìwọ yóò rí àwọn ìdáhùn tó tẹ́ni lọ́rùn sí ọgọ́rọ̀ọ̀rún àwọn ìbéèrè lórí Bíbélì, èyí tí wọ́n sábà máa ń béèrè tí a bá wà lóde ẹ̀rí. Bí o bá fẹ́ túbọ̀ mọ̀ sí i nípa àwọn ẹ̀sìn yòókù, nípa àwọn ẹ̀kọ́ wọn, àti ìtàn nípa bí wọ́n ṣe ti ń bá ẹ̀sìn wọn bọ̀ látẹ̀yìnwá, wo ìwé Mankind’s Search for God. Àwọn kúlẹ̀kúlẹ̀ ìtàn díẹ̀ nípa àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà òde òní wà nínú ìwé pẹlẹbẹ náà, Awọn Ẹlẹríi Jehofah—Nfi Pẹlu Iṣopọṣọkan Ṣe Ifẹ-Inú Ọlọrun Yíká Ayé. Fún ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ àlàyé nípa ohun tí a ti gbé ṣe lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù ìhìn rere jákèjádò ayé, wo Ilé Ìṣọ́ tí déètì rẹ̀ jẹ́ January 1 tó dé kẹ́yìn. Ìwé Insight on the Scriptures jẹ́ ìwé tó ń fúnni ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìsọfúnni nípa Bíbélì àti àwòrán àwọn ilẹ̀ tó sọ̀rọ̀ lé lórí. Bí o bá ń fẹ́ ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìsọfúnni nípa àwọn èèyàn, ilẹ̀, nǹkan, èdè, tàbí ìtàn àwọn ohun tó ṣẹlẹ̀ ní ìsopọ̀ pẹ̀lú Bíbélì, inú ìwé yẹn lo ti lè rí i.
Ìwé Atọ́ka “Watch Tower Publications Index.” Ìwé atọ́ka Watch Tower Publications Index tí a tẹ̀ jáde ní èyí tó ju ogún èdè lọ yìí, yóò tọ́ka rẹ sí ìsọfúnni tó wà nínú onírúurú ìtẹ̀jáde wa. A pín in sí ẹ̀ka atọ́ka kókó ẹ̀kọ́ àti ẹ̀ka atọ́ka ẹsẹ Ìwé Mímọ́. Tó o bá fẹ́ lo ẹ̀ka atọ́ka kókó ẹ̀kọ́, wá ọ̀rọ̀ tó jẹ mọ́ kókó ẹ̀kọ́ tó o fẹ́ ṣèwádìí nípa rẹ̀ níbẹ̀. Tó o bá fẹ́ lo ẹ̀ka ti atọ́ka ẹsẹ Ìwé Mímọ́, wá ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó o fẹ́ kó túbọ̀ yé ọ sí i lára àwọn tí a tò lẹ́sẹẹsẹ síbẹ̀. Bí a bá ti tẹ ohunkóhun jáde nípa kókó ẹ̀kọ́ kan tàbí nípa ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tó o ní lọ́kàn, nínú àwọn ọdún tí ìwé Index yẹn wà fún, ìwọ yóò rí àwọn ìwé tí o ti lè rí i níbẹ̀. Lo àlàyé àwọn àmì ìkékúrú orúkọ ìwé tó wà lápá ìbẹ̀rẹ̀ ìwé Index láti fi mọ orúkọ ìwé tí àwọn àmì ìkékúrú tí a tọ́ka sí wà fún. (Bí àpẹẹrẹ, tí o bá lo ìyẹn, yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ láti mọ̀ pé w99 3/1 15 tọ́ka sí Ilé Ìṣọ́ (Gẹ̀ẹ́sì) tí a tẹ̀ lọ́dún 1999, ẹ̀dà ti March 1, ojú ewé 15.) Àwọn lájorí àkòrí bíi “Field Ministry Experiences” [Àwọn Ìrírí Látinú Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ ní Pápá] àti “Life Stories of Jehovah’s Witnesses” [Ìtàn Ìgbésí Ayé Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà], lè wúlò gan-an nígbà tó o bá ń múra láti sọ ọ̀rọ̀ láti fi ta ìjọ jí.
Bó ṣe jẹ́ pé ìwádìí máa ń gbani láfiyèsí gan-an, ṣọ́ra kó o má bàa yà bàrá kúrò lórí ohun tó ò ń wá. Jẹ́ kí ọkàn rẹ wà lórí ète rẹ láti wá ìsọfúnni tó o fẹ́ lò fún iṣẹ́ tó wà lọ́wọ́ rẹ báyìí. Bí ìwé Index bá tọ́ka rẹ sí ìwé kan, ṣí ìwé yẹn sí ojú ìwé tí ó sọ, kí o wá lo àwọn àkòrí kéékèèké àti àwọn gbólóhùn tó bẹ̀rẹ̀ àwọn ìpínrọ̀ ibẹ̀ gẹ́gẹ́ bí atọ́nà láti fi rí ìsọfúnni tó o nílò. Bí o bá ń wá ìtumọ̀ ẹsẹ Bíbélì kan ní pàtó, kọ́kọ́ wá ẹsẹ Ìwé Mímọ́ yẹn lójú ewé tí Index tọ́ka rẹ sí ná. Lẹ́yìn náà, kí o wá wo àlàyé tí a ṣe nípa rẹ̀ níbẹ̀.
“Watchtower Library” on CD-ROM [Àkójọ Ìtẹ̀jáde Society Tá A Ṣe Sórí Ike Pẹlẹbẹ Tá À Ń Fi Kọ̀ǹpútà Lò]. Bí o bá ń rí ẹ̀rọ kọ̀ǹpútà lò, o lè jàǹfààní lílo Watchtower Library on CD-ROM, èyí tó jẹ́ pé ó ní àkójọ àwọn ìtẹ̀jáde wa púpọ̀ rẹpẹtẹ nínú. Ètò tí a fi ń wá nǹkan rí tó wà nínú rẹ̀, tó rọrùn láti lò, yóò jẹ́ kí o lè wá ẹyọ ọ̀rọ̀ kan, gbólóhùn ọ̀rọ̀, tàbí ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan nínú èyíkéyìí nínú ìtẹ̀jáde tó wà nínú ètò Watchtower Library ọ̀hún. Ká tiẹ̀ sọ pé ohun èlò ìṣèwádìí yìí kò sí ní èdè rẹ, o ṣì lè jàǹfààní rẹ̀ bí o bá lo èyí tó wà ní èdè ilẹ̀ òkèèrè tó o bá mọ̀.
Àwọn Ibi Ìkówèésí Ìjọba Ọlọ́run Yòókù
Nínú lẹ́tà kejì onímìísí tí Pọ́ọ̀lù kọ sí Tímótì, ó sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin yẹn pé kí ó kó “àwọn àkájọ ìwé, ní pàtàkì àwọn ìwé awọ,” wá fún òun ní ìlú Róòmù. (2 Tím. 4:13) Pọ́ọ̀lù ka àwọn ìwé kan sí ohun ribiribi, ó sì pa wọ́n mọ́. Ìwọ náà lè ṣe bẹ́ẹ̀. Ǹjẹ́ o máa ń tọ́jú ẹ̀dà Ilé Ìṣọ́, Jí!, àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa tìrẹ pa mọ́ àní lẹ́yìn tí a bá tiẹ̀ ti kà wọ́n tán ní àwọn ìpàdé ìjọ? Bí ó bá rí bẹ́ẹ̀, ìwọ yóò lè rí wọn lò fún ìwádìí ṣíṣe, pa pọ̀ mọ́ àwọn ìtẹ̀jáde Kristẹni wa mìíràn tó o ti ní. Ọ̀pọ̀ jù lọ ìjọ ló ní àkójọ àwọn ìtẹ̀jáde ti ìjọba Ọlọ́run nínú ibi ìkówèésí ní Gbọ̀ngàn Ìjọba wọn. Ìwọ̀nyí wà fún àǹfààní ìjọ látòkèdélẹ̀, kí wọ́n lè lò wọ́n nígbà tí wọ́n bá wà ní Gbọ̀ngàn Ìjọba.
Ní Àkójọ Ìsọfúnni Tìrẹ Fúnra Rẹ
Máa kíyè sí àwọn ìsọfúnni tó wuni, tó jẹ́ pé o lè lò nígbà tó o bá ń sọ̀rọ̀ àti nígbà tó o bá ń kọ́ni. Bí o bá rí ìròyìn kan, ìsọfúnni oníṣirò tàbí àpẹẹrẹ kan nínú ìwé ìròyìn, èyí tí o lè lò nínú iṣẹ́ ìsìn, gé ìsọfúnni náà pa mọ́ tàbí kí o dà á kọ. Kọ ọjọ́ tí wọ́n tẹ̀ ẹ́, orúkọ ìwé ìròyìn yẹn, àti orúkọ òǹkọ̀wé tàbí ti òǹtẹ̀wé náà sí i bí ó bá ṣeé ṣe. Ní àwọn ìpàdé ìjọ, kọ àwọn kókó ọ̀rọ̀ àti àwọn àpèjúwe tó o lè fi ṣàlàyé òtítọ́ fún àwọn ẹlòmíràn sílẹ̀. Ǹjẹ́ àpèjúwe tó dára kan tíì wá sí ọ lọ́kàn rí, ṣùgbọ́n tí o kò láǹfààní láti lò ó lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀? Kọ ọ́ sílẹ̀, kí o sì fi í sínú àkójọ ìsọfúnni kan. Tó bá fi pẹ́ díẹ̀ tó o ti ń wá sí Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run, wàá ti sọ ọ̀rọ̀ akẹ́kọ̀ọ́ bíi mélòó kan sẹ́yìn. Dípò tí wàá fi kó àwọn ìwé tí o kọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí dà nù, tọ́jú wọn pa mọ́. Ìwádìí tó o ti ṣe lè padà wá wúlò tó bá yá.
Bá Àwọn Èèyàn Sọ̀rọ̀
Rántí pé àwọn èèyàn jẹ́ orísun pàtàkì tí a ti lè rí ìsọfúnni. Nígbà tí Lúùkù ń kọ ìtàn ìwé Ìhìn Rere tirẹ̀, ó dájú pé ó rí ìsọfúnni púpọ̀ gbà nípa fífi ọ̀rọ̀ wá àwọn tí ọ̀ràn ṣojú wọn lẹ́nu wò. (Lúùkù 1:1-4) Ó ṣeé ṣe kí Kristẹni ẹlẹgbẹ́ rẹ kan lè túbọ̀ là ọ́ lóye nípa ohun kan tó o ti ń ṣèwádìí nípa rẹ̀. Gẹ́gẹ́ bí Éfésù 4:8, 11-16 ṣe wí, Kristi ń lo “àwọn ẹ̀bùn tí ó jẹ́ ènìyàn” láti fi ràn wá lọ́wọ́ láti tẹ̀ síwájú nínú “ìmọ̀ pípéye nípa Ọmọ Ọlọ́run.” Fífi ọ̀rọ̀ wá àwọn tó ti nírìírí nínú iṣẹ́ ìsìn Ọlọ́run lẹ́nu wò lè jẹ́ kí o gbọ́ àwọn àlàyé tó wúlò gan-an ni. Bíbá àwọn èèyàn fọ̀rọ̀ jomi toro ọ̀rọ̀ tún lè jẹ́ kó o mọ ohun tí wọ́n ń rò, èyí sì lè ràn ọ́ lọ́wọ́ láti múra ọ̀rọ̀ tó gbéṣẹ́ ní ti gidi.
Díwọ̀n Àbájáde Ìwádìí Rẹ
Tí a bá kórè àlìkámà tán, a ní láti gbọn hóró àlìkámà yẹn yọ kúró nínú háhá tó bò ó. Bí ohun tó o rí kó jọ látinú ìwádìí rẹ ṣe rí nìyẹn. Kí ó tó ṣeé lò, o ní láti yọ ohun tó wúlò kúrò lára èyí tí kò ní láárí.
Bí ó bá jẹ́ pé inú ọ̀rọ̀ kan tó o máa sọ lo ti fẹ́ lo ìsọfúnni náà, bi ara rẹ léèrè pé: ‘Ǹjẹ́ kókó tí mo ń ronú láti lò yìí kó ipá kankan tó ní láárí nínú ọ̀rọ̀ tí mo fẹ́ sọ? Tàbí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìsọfúnni tó dára ni, ṣé kò ní mú ọkàn ẹni kúrò lórí kókó tó yẹ kí ọ̀rọ̀ mi dá lé?’ Bí o bá ń rò ó pé o fẹ́ lo ìsọfúnni nípa àwọn ohun tó ń ṣẹlẹ̀ ní lọ́ọ́lọ́ọ́ tàbí pé o fẹ́ mú ìsọfúnni látinú àwọn ẹ̀ka sáyẹ́ǹsì tàbí ti ìṣègùn, tó jẹ́ pé ó máa ń yí padà látìgbàdégbà, rí i dájú pé ìsọfúnni yẹn bóde mu. Sì tún mọ̀ dájú pé, àtúnṣe lè ti bá àwọn kókó ọ̀rọ̀ kan tó wà nínú àwọn ìtẹ̀jáde wa tó ti pẹ́ díẹ̀ sẹ́yìn, nítorí náà, ṣàyẹ̀wò ohun tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ tẹ̀ jáde láìpẹ́ lórí kókó ẹ̀kọ́ yẹn.
Ó ṣe pàtàkì pé kí o kíyè sára gidigidi bí o bá yàn láti lo ìsọfúnni látinú ìwé àwọn èèyàn ayé. Má ṣe gbàgbé pé Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ni òtítọ́. (Jòh. 17:17) Ipò pàtàkì ni Jésù wà nínú ìmúṣẹ ète Ọlọ́run. Nítorí náà, Kólósè 2:3 sọ pé: “Inú rẹ̀ ni a rọra fi gbogbo ìṣúra ọgbọ́n àti ti ìmọ̀ pa mọ́ sí.” Ìyẹn ni kó o fi máa díwọ̀n àbájáde ìwádìí rẹ. Nípa ti lílo ìwádìí àwọn ẹni ayé, bi ara rẹ léèrè pé: ‘Ǹjẹ́ àsọdùn, ìméfò, tàbí àìní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ òye wà nínú ọ̀rọ̀ yìí? Ṣé ẹ̀mí ìmọtara ẹni nìkan ló sún wọn kọ ọ́ ni, tàbí torí kí wọ́n ṣáà ti rí nǹkan tà? Ǹjẹ́ àwọn ìwé yòókù tó lẹ́sẹ̀ ńlẹ̀ gbà pẹ̀lú rẹ̀? Ju gbogbo rẹ̀ lọ, ǹjẹ́ ó bá òtítọ́ Bíbélì mu?’
Òwe 2:1-5 fún wa níṣìírí pé kí a wá ìmọ̀, òye, àti ìfòyemọ̀ bí ẹní wá ‘fàdákà, àti bí ẹní wá àwọn ìṣúra fífarasin.’ Ìyẹn túmọ̀ sí pé èèyàn á ṣakitiyan, á sì jèrè rẹpẹtẹ. Ìwádìí ṣíṣe gba ìsapá, àmọ́ bí o bá ń ṣe é yóò mú kí o lè mọ èrò Ọlọ́run lórí àwọn nǹkan, kí o lè ṣàtúnṣe sí àwọn èrò òdì, kí o sì lè di òtítọ́ mú ṣinṣin. Yóò tún jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ kún fún ẹ̀kọ́ kí ó sì tani jí, tí yóò mú kí wọ́n dùn mọ́ ọ láti sọ, kí wọ̀n sì wuni láti gbọ́.
-