ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • “Ẹ Wà ní Ìmúratán”
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2003 | November
    • “Ẹ Wà ní Ìmúratán”

      1 Nínú àsọtẹ́lẹ̀ pàtàkì tí Jésù sọ nípa òpin ètò àwọn nǹkan ìsinsìnyí, ó kìlọ̀ fún wa pé ká má ṣe jẹ́ kí àníyàn fún àwọn nǹkan tayé gbà wá lọ́kàn. (Mát. 24:36-39; Lúùkù 21:34, 35) Níwọ̀n bó ti jẹ́ pé ìpọ́njú ńlá lè bẹ̀rẹ̀ nígbàkigbà, ó pọn dandan pé ká kọbi ara sí ìṣílétí Jésù pé: “Ẹ wà ní ìmúratán, nítorí pé ní wákàtí tí ẹ kò ronú pé yóò jẹ́, ni Ọmọ ènìyàn ń bọ̀.” (Mát. 24:44) Kí ló lè ràn wá lọ́wọ́ láti wà ní ìmúratán?

      2 Ṣíṣàì Gba Àníyàn àti Ìpínyà Ọkàn Láyè: Ọ̀kan lára àwọn ọ̀fìn tẹ̀mí tí a gbọ́dọ̀ máa ṣọ́ra fún ni “àwọn àníyàn ìgbésí ayé.” (Lúùkù 21:34) Ní àwọn ilẹ̀ kan, ipò òṣì, àìríṣẹ́ṣe àti owó ìgbọ́bùkátà tó ń ga sí i ń mú kó ṣòro láti ní àwọn ohun tó jẹ́ kòṣeémánìí nínú ìgbésí ayé. Ní àwọn ilẹ̀ mìíràn, tonílé tàlejò ló ń kó àwọn ohun ìní ti ara jọ. Bí àníyàn fún àwọn ohun ìní ti ara bá ti bẹ̀rẹ̀ sí í gbà wá lọ́kàn, kò ní ṣeé ṣe fún wa láti pọkàn pọ̀ sórí àwọn nǹkan tó ní í ṣe pẹ̀lú Ìjọba Ọlọ́run. (Mát. 6:19-24, 31-33) Àwọn ìpàdé Kristẹni máa ń ràn wá lọ́wọ́ láti pọkàn pọ̀. Ṣé góńgó rẹ ni láti máa lọ sí gbogbo ìpàdé ìjọ?—Héb. 10:24, 25.

      3 Ọ̀pọ̀ àwọn nǹkan tó ń fa ìpínyà ọkàn, tí wọ́n sì lè yára gba àkókò ṣíṣeyebíye mọ́ wa lọ́wọ́, kún inú ayé lónìí. Lílo kọ̀ǹpútà lè di ìdẹkùn béèyàn bá ń lo àkókò tó pọ̀ jù nídìí wíwá ìsọfúnni lórí Íńtánẹ́ẹ̀tì, kíka lẹ́tà orí kọ̀ǹpútà àti fífèsì irú lẹ́tà bẹ́ẹ̀, ṣíṣe àwọn eré orí kọ̀ǹpútà tàbí àwọn eré mìíràn. A lè pàdánù àìmọye wákàtí nídìí tẹlifíṣọ̀n, sinimá, àwọn ìgbòkègbodò àfipawọ́, ìwé ayé àti eré ìdárayá, débi tí a ò fi ní ní àkókò àti okun tó pọ̀ tó láti máa lépa àwọn nǹkan tẹ̀mí. Nígbà tó jẹ́ pé eré ìtura àti fàájì lè mú kí ara tù wá fún ìgbà díẹ̀, kíkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì fúnra ẹni àti pẹ̀lú ìdílé ẹni máa ń mú àǹfààní ayérayé wá. (1 Tím. 4:7, 8) Ǹjẹ́ o máa ń ra àkókò padà láti ṣàṣàrò lórí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lójoojúmọ́?—Éfé. 5:15-17.

      4 Àfi ká máa dúpẹ́ pé ètò àjọ Jèhófà ti ní ìtòlẹ́sẹẹsẹ àwọn ìtọ́ni tẹ̀mí tó lè ràn wá lọ́wọ́ láti “kẹ́sẹ járí ní yíyèbọ́ nínú gbogbo nǹkan . . . tí a ti yàn tẹ́lẹ̀ láti ṣẹlẹ̀, àti ní dídúró níwájú Ọmọ ènìyàn”! (Lúùkù 21:36) Ǹjẹ́ ká máa lo àwọn ìpèsè wọ̀nyí lẹ́kùn-ún rẹ́rẹ́, ká sì “wà ní ìmúratán” kí ìgbàgbọ́ wa bàa lè jẹ́ “èyí tí a rí gẹ́gẹ́ bí okùnfà fún ìyìn àti ògo àti ọlá nígbà ìṣípayá Jésù Kristi.”—1 Pét. 1:7.

  • Gbígbóríyìn Fúnni Ń Mára Tuni
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2003 | November
    • Gbígbóríyìn Fúnni Ń Mára Tuni

      1 Pẹ̀lú omijé lójú ni ọmọdébìnrin kan fi béèrè lọ́wọ́ ìyá rẹ̀ nígbà tí wọ́n fẹ́ sùn pé: “Ṣé mi ò ṣe dáadáa lónìí ni?” Ìbéèrè yẹn ya ìyá rẹ̀ lẹ́nu gan-an ni. Pẹ̀lú bí ìyá náà ṣe kíyè sí i pé ọmọdébìnrin òun sa gbogbo ipá rẹ̀ tó láti hùwà ọmọlúwàbí lọ́jọ́ yẹn, kò tiẹ̀ yin ọmọ náà rárá. Ó yẹ kí ẹkún tí ọmọdébìnrin náà sun rán gbogbo wa létí pé kò sẹ́ni tí kì í fẹ́ kí wọ́n yin òun—yálà ó jẹ́ ọmọdé tàbí àgbàlagbà. Ǹjẹ́ a máa ń mú kí ara tu àwọn tó wà ní sàkáání wa nípa fífi ìmọrírì hàn fún ohun tí wọ́n bá ṣe?—Òwe 25:11.

      2 Àwọn tá a jọ jẹ́ Kristẹni máa ń ṣe ọ̀pọ̀ ohun rere tó yẹ ká yìn wọ́n fún. Àwọn alàgbà, àwọn ìránṣẹ́ iṣẹ́ òjíṣẹ́ àtàwọn aṣáájú ọ̀nà ń ṣiṣẹ́ kára láti bójú tó ẹrù iṣẹ́ wọn. (1 Tím. 4:10; 5:17) Àwọn òbí olùbẹ̀rù Ọlọ́run ń ṣe gbogbo ohun tí wọ́n lè ṣe láti tọ́ àwọn ọmọ wọn dàgbà ní ọ̀nà Jèhófà. (Éfé. 6:4) Àwọn ọ̀dọ́ tó jẹ́ Kristẹni ń sapá kíkankíkan láti yẹra fún “ẹ̀mí ayé.” (1 Kọ́r. 2:12; Éfé. 2:1-3) Àwọn mìíràn ń sin Jèhófà tọkàntọkàn láìka ọjọ́ ogbó, àìlera tàbí àwọn àdánwò mìíràn sí. (2 Kọ́r. 12:7) Ó yẹ ká máa gbóríyìn fún irú àwọn ẹni báwọ̀nyí. Ǹjẹ́ a máa ń fi hàn pé a mọrírì ìsapá wọn nípa gbígbóríyìn fún wọn?

      3 Lẹ́nì Kọ̀ọ̀kan àti ní Pàtó: Ó dájú pé gbogbo wa la máa ń mọrírì rẹ̀ bí a bá gbóríyìn fún gbogbo ìjọ lápapọ̀ látorí pèpéle. Àmọ́ ṣá o, ó máa ń tuni lára gan-an bí a bá gbóríyìn fún wa gẹ́gẹ́ bí ẹnì kan. Bí àpẹẹrẹ, ní orí 16 nínú lẹ́tà tí Pọ́ọ̀lù kọ sí àwọn ará Róòmù, ó sọ̀rọ̀ ìgbóríyìn ní pàtó fún Fébè, Pírísíkà àti Ákúílà, Tírífénà àti Tírífósà àti Pésísì, àtàwọn mìíràn. (Róòmù 16:1-4, 12) Ó dájú pé ọ̀rọ̀ rẹ̀ á tu àwọn olùṣòtítọ́ wọ̀nyẹn lára gan-an ni! Irú ọ̀rọ̀ ìyìn bẹ́ẹ̀ ń fi àwọn arákùnrin àti arábìnrin wa lọ́kàn balẹ̀ pé kòṣeémánìí ni wọ́n ó sì ń mú ká túbọ̀ sún mọ́ra pẹ́kípẹ́kí. Ṣé o ti sọ̀rọ̀ ìgbóríyìn fún ẹnì kan ní pàtó lẹ́nu àìpẹ́ yìí?—Éfé. 4:29.

      4 Látọkàn Wá: Kí ó bàa lè tuni lára, ó yẹ kí gbígbóríyìn fúnni ti inú ọkàn wá. Àwọn èèyàn lè mọ̀ bóyá ohun táà ń sọ ti inú ọkàn wa wá tàbí ńṣe la wulẹ̀ ‘ń fi ahọ́n wa pọ́n wọn lásán.’ (Òwe 28:23) Bí a bá fi kọ́ra láti máa kíyè sí ànímọ́ rere táwọn ẹlòmíràn ní, ọkàn wa á sún wa láti gbóríyìn fún wọn. Ǹjẹ́ kí ó má ṣe rẹ̀ wá láti máa gbóríyìn fúnni, níwọ̀n bí a ti mọ̀ pé ‘ọ̀rọ̀ tí ó bọ́ sí àkókò mà dára o’—Òwe 15:23.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́