ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ìràpadà Túbọ̀ Fi Òdodo Ọlọ́run Hàn
    Ilé Ìṣọ́—2005 | November 1
    • Ìràpadà Túbọ̀ Fi Òdodo Ọlọ́run Hàn

      LẸ́YÌN ìṣọ̀tẹ̀ Ádámù àti Éfà, Jèhófà sọ ohun tí òun ní lọ́kàn láti ṣe, ìyẹn ni láti pèsè Irú Ọmọ kan tí Sátánì yóò pa ní gìgísẹ̀. (Jẹ́nẹ́sísì 3:15) Èyí nímùúṣẹ nígbà táwọn ọ̀tá Ọlọ́run ṣekú pa Jésù Kristi lórí òpó igi oró. (Gálátíà 3:13, 16) Jésù kì í ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀, nítorí nípasẹ̀ agbára ẹ̀mí mímọ́ ni wúńdíá kan lóyún rẹ̀ lọ́nà ìyanu. Nítorí náà, ẹ̀jẹ̀ Jésù tó ta sílẹ̀ ni Ọlọ́run wá lò gẹ́gẹ́ bí owó ìràpadà, kí ìran èèyàn tó ti jogún ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú látọ̀dọ̀ Ádámù lè rí ìtúsílẹ̀.—Róòmù 5:12, 19.

      Kò sí ohunkóhun tó lè dá Jèhófà Ọlọ́run Olódùmarè dúró láti má ṣe mú ète rẹ̀ ṣẹ. Nípa bẹ́ẹ̀, lẹ́yìn tí ìran èèyàn di ẹlẹ́ṣẹ̀, ńṣe ló dà bíi pé a ti san owó ìràpadà náà lójú Jèhófà, ó sì ṣeé ṣe fún un láti bá àwọn èèyàn kan lò, ìyẹn àwọn tó fi ìgbàgbọ́ hàn nínú ìmúṣẹ àwọn ìlérí rẹ̀. Ìdí nìyẹn táwọn àtọmọdọ́mọ Ádámù bí Énọ́kù, Nóà àti Ábúráhámù tó jẹ́ ẹlẹ́ṣẹ̀ fi lè bá Ọlọ́run rìn, àní tó tiẹ̀ tún bá wọn dọ́rẹ̀ẹ́ pàápàá, tíyẹn ò sì kó àbàwọ́n bá jíjẹ́ tó jẹ́ ẹni mímọ́.—Jẹ́nẹ́sísì 5:24; 6:9; Jákọ́bù 2:23.

      Àwọn kan lára àwọn tó nígbàgbọ́ nínú Jèhófà dá àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tó burú gan-an. Àpẹẹrẹ kan ni Ọba Dáfídì. Ìbéèrè kan tó lè máa wá sí ọ lọ́kàn ni pé ‘Báwo ni Jèhófà ṣe lè máa bù kún Dáfídì Ọba nìṣó lẹ́yìn tó ti dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà pẹ̀lú Bátíṣébà tó sì tún jẹ́ pé òun ló wà nídìí ikú tó pa Ùráyà, ọkọ obìnrin náà?’ Kókó pàtàkì kan tó mú kí Jèhófà ṣe bẹ́ẹ̀ ni pé Dáfídì ronú pìwà dà tọkàntọkàn ó sì tún ní ìgbàgbọ́. (2 Sámúẹ́lì 11:1-17; 12:1-14) Nítorí ẹbọ Jésù Kristi tó ń bọ̀ lọ́jọ́ iwájú, ó ṣeé ṣe fún Ọlọ́run láti dárí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ Dáfídì tó ronú pìwà dà jì í, síbẹ̀ ìyẹn ò sọ Ọlọ́run di aláìṣòdodo àti ẹni tí ń ṣojúsàájú. (Sáàmù 32:1, 2) Láti jẹ́rìí sí èyí, Bíbélì ṣàlàyé ohun tó jẹ́ àgbàyanu jù lọ tí ìràpadà Jésù mú kó ṣeé ṣe, ìyẹn ni “láti fi òdodo [Ọlọ́run] hàn, nítorí òun ń dárí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí ó wáyé ní ìgbà tí ó ti kọjá jì” àti “ní àsìkò ìsinsìnyí.”—Róòmù 3:25, 26.

      Bẹ́ẹ̀ ni, nítorí pé ẹ̀jẹ̀ Jésù ṣeyebíye gan-an, ọ̀pọ̀ àǹfààní ńláǹlà laráyé ń rí gbà. Nítorí ìràpadà náà, àwọn èèyàn tó bá ronú pìwà dà ẹ̀ṣẹ̀ wọn lè ní àjọṣe tímọ́tímọ́ pẹ̀lú Ọlọ́run. Ìyẹn nìkan kọ́, ẹbọ ìràpadà náà tún ṣí ọ̀nà sílẹ̀ fún àjíǹde àwọn òkú sínú ayé tuntun Ọlọ́run. Àwọn olóòótọ́ ìránṣẹ́ Ọlọ́run tí wọ́n kú kó tó di pé Jésù san owó ìràpadà náà yóò wà lára wọn. Kódà, ọ̀pọ̀ àwọn tó kú sípò àìmọ̀kan tí wọn ò sì jọ́sìn Jèhófà yóò jí dìde. Bíbélì sọ pé: “Àjíǹde àwọn olódodo àti àwọn aláìṣòdodo yóò wà.” (Ìṣe 24:15) Nítorí ìràpadà náà, Jèhófà yóò fún gbogbo àwọn tó bá ṣègbọràn ní ìyè àìnípẹ̀kun lákòókò yẹn. (Jòhánù 3:36) Jésù fúnra rẹ̀ ṣàlàyé pé: “Nítorí Ọlọ́run nífẹ̀ẹ́ ayé tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́ tí ó fi fi Ọmọ bíbí rẹ̀ kan ṣoṣo fúnni, kí olúkúlùkù ẹni tí ó bá ń lo ìgbàgbọ́ nínú rẹ̀ má bàa pa run, ṣùgbọ́n kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun.” (Jòhánù 3:16) Gbogbo àǹfààní yìí ni yóò jẹ́ ti aráyé nítorí ẹbọ ìràpadà tí Ọlọ́run pèsè.

      Àmọ́ ohun tó ṣe pàtàkì jù nípa ìràpadà náà kì í ṣe àwọn àǹfààní tá a rí gbà látinú rẹ̀. Ohun tí ìràpadà Kristi ṣe fún orúkọ Jèhófà ló ṣe kókó jù. Ó jẹ́ kó hàn kedere pé Jèhófà jẹ́ Ọlọ́run tí kì í ṣègbè rárá, tó lè bá àwọn èèyàn tó jẹ́ ẹlẹ́ṣẹ̀ lò, síbẹ̀ kó ṣì jẹ́ ẹni mímọ́ àti ẹni tí kò lábàwọ́n. Ká ní Ọlọ́run kò ṣètò láti pèsè ìràpadà ni, kì bá máà sí àtọmọdọ́mọ Ádámù kankan tó máa lè bá Jèhófà rìn tàbí tó máa lè jẹ́ ọ̀rẹ́ rẹ̀, kódà ì bá má ṣeé ṣe fún Énọ́kù, Nóà, àti Ábúráhámù pàápàá. Onísáàmù mọ èyí, ìdí nìyẹn tó fi kọ̀wé pé: “Bí ó bá jẹ́ pé àwọn ìṣìnà ni ìwọ ń ṣọ́, Jáà, Jèhófà, ta ni ì bá dúró?” (Sáàmù 130:3) Ẹ ò rí i pé ó yẹ ká fọpẹ́ fún Jèhófà gan-an fún rírán tó rán Ọmọ rẹ̀ ọ̀wọ́n wá sáyé, ká sì tún fọpẹ́ fún Jésù tó fínnúfíndọ̀ fi ìwàláàyè rẹ̀ rúbọ láti fi ṣe ìràpadà fún wa!—Máàkù 10:45.

  • Ìwà Rere Méso Jáde
    Ilé Ìṣọ́—2005 | November 1
    • Ìwà Rere Méso Jáde

      NÍ ERÉKÙṢÙ kékeré kan tí kò jìnnà sí etíkun tó wà lápá gúúsù ilẹ̀ Japan, ìyá kan àtàwọn ọmọ rẹ̀ kéékèèké mẹ́ta bẹ̀rẹ̀ sí kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì lọ́dọ̀ àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà. Báwọn ará àdúgbò wọn tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ àṣà ìbílẹ̀ wọn lágbègbè àdádó yìí ṣe rí ohun tí wọ́n ń ṣe yìí, ni wọ́n bá bẹ̀rẹ̀ sí fojú pa obìnrin náà rẹ́ tí wọ́n bá ti rí i. Obìnrin náà sọ pé: “Ohun tó tiẹ̀ wá dùn mí ju bí wọ́n ṣe ń fojú pa mí rẹ́ ni bí wọn ò ṣe ń dá ọkọ mi àtàwọn ọmọ mi lóhùn tí wọ́n bá ti kí wọn.” Síbẹ̀síbẹ̀, ó sọ fáwọn ọmọ rẹ̀ pé: “A gbọ́dọ̀ máa kí àwọn aládùúgbò wa nítorí pé ohun tí Jèhófà fẹ́ nìyẹn.”—Mátíù 5:47, 48.

      Ó kọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ nílé pé kí wọ́n máa bọ̀wọ̀ fáwọn èèyàn báwọn èèyàn náà ò tiẹ̀ kà wọ́n sí. Tí wọ́n bá ń lọ síbi ìsun omi gbígbóná kan tí wọ́n máa ń lọ déédéé ládùúgbò wọn, àwọn ọmọ yìí á máa fi bí wọn yóò ṣe kí àwọn èèyàn dánra wò nínú ọkọ̀ ayọ́kẹ́lẹ́ wọn. Báwọn ọmọ náà bá sì ṣe ń wọnú ilé náà ni wọ́n á máa sọ tọ̀yàyàtọ̀yàyà pé, “Konnichiwa!,” tó túmọ̀ sí “Ẹ ǹ lẹ́ o!” Ìdílé yìí sáà ń fi sùúrù kí gbogbo àwọn tí wọ́n bá rí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwà àwọn aládùúgbò náà kò yí padà. Síbẹ̀, àwọn èèyàn ò ṣàì kíyè sí ìwà dáadáa táwọn ọmọ náà ń hù.

      Nígbà tó yá làwọn aládùúgbò náà níkọ̀ọ̀kan bá bẹ̀rẹ̀ sí dá àwọn ọmọ náà lóhùn tí wọ́n bá ti kí wọn, àwọn náà á ní “Konnichiwa.” Lẹ́yìn ọdún méjì, ó fẹ́rẹ̀ẹ́ jẹ́ gbogbo àwọn tó wà nínú ìlú kékeré náà ló ti ń dáhùn tí ìdílé náà bá ti kí wọn. Àwọn aládùúgbò náà tiẹ̀ tún wá ń kí ara wọn, wọ́n sì túbọ̀ ń ṣe dáadáa síra wọn ju ti tẹ́lẹ̀ lọ. Èyí ló mú kí igbákejì olórí ìlú náà fẹ́ dá àwọn ọmọ náà lọ́lá fún ipa tí wọ́n kó nínú ìyípadà yìí. Àmọ́ màmá wọn ṣàlàyé fún un pé ohun tó yẹ káwọn Kristẹni máa ṣe làwọ́n ń ṣe. Lẹ́yìn ìgbà yẹn, ìdíje kan lórí ọ̀rọ̀ sísọ tó kan gbogbo erékùṣù náà wáyé, ọ̀kan lára àwọn ọmọ náà sì sọ bí màmá òun ṣe kọ́ gbogbo wọn nínú ìdílé wọn láti máa fi tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ kí àwọn èèyàn yálà àwọn èèyàn dáhùn tàbí wọn ò dáhùn. Ọ̀rọ̀ rẹ̀ ló gbapò kìíní, wọ́n sì tẹ ọ̀rọ̀ náà jáde nínú ìwé ìròyìn ìlú kékeré náà. Lónìí, ńṣe ni inú ìdílé náà ń dùn gan-an pé títẹ̀lé ìlànà Kristẹni mú irú èso rere bẹ́ẹ̀ jáde. Ó máa ń rọrùn gan-an láti sọ ìhìn rere nígbà táwọn èèyàn bá túra ká síni.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́