ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Gbọ́rọ̀ Kalẹ̀ Lọ́nà Tó Máa Bá Onírúurú Ipò Mu
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2005 | January
    • Gbọ́rọ̀ Kalẹ̀ Lọ́nà Tó Máa Bá Onírúurú Ipò Mu

      Bí a bá nífẹ̀ẹ́ àwọn èèyàn látọkànwá, a ó fojú sílẹ̀ láti mọ ìṣòro tí wọ́n ní ká bàa lè kọ́ wọn nípa bí Ìjọba Ọlọ́run yóò ṣe yanjú àwọn ìṣòro wọn. (Fílí. 2:4) Báwọn akéde kan ṣe máa ń gbé ọ̀rọ̀ wọn kalẹ̀ tó sábà máa ń bá ipò onílé mu ni pé wọ́n máa ń jẹ́ kí onílé sọ èrò rẹ̀ lórí àwọn àwòrán bí Párádísè yóò ṣe rí tó wà nínú àwọn ìwé wa, bí irú àwọn tá a tò sí apá ọ̀tún ìwé yìí. Láti ṣe èyí, o lè lo ọ̀kan lára àwọn ìnasẹ̀ ọ̀rọ̀ tó tẹ̀ lé e yìí:

      ◼ “Ǹjẹ́ o rò pé ọjọ́ kan ń bọ̀ tí gbogbo èèyàn á máa gbádùn bíi tàwọn tó wà nínú àwòrán yìí?”

      ◼ “Kò sí ẹni tí kò wù káwọn ọmọ ẹ̀ gbádùn ayé wọn bíi tàwọn tó wà nínú àwòrán yìí. Kí lo rò pé ó lè mú kí èyí ṣeé ṣe?”

      ◼ “Nígbà tí ìfẹ́ Ọlọ́run bá di ṣíṣe lórí ilẹ̀ ayé bíi ti ọ̀run, bí ilé ayé wa ṣe máa rí rèé. Nínú àwòrán yìí, ǹjẹ́ o rí ohun tó yàtọ̀ sí ohun tó ń ṣẹlẹ̀ láyé wa lónìí?”

      ◼ “Ṣé wàá fẹ́ gbé nínú irú ibi tó wà nínú àwòrán yìí? [Jẹ́ kó fèsì.] Ǹjẹ́ o rò pé èyí lè ṣẹlẹ̀ lójú ẹ̀mí wa?”

      Fara balẹ̀ gbọ́ ìdáhùn rẹ̀, kó o wá bi í ní ìbéèrè kan tàbí méjì sí i láti fi mọ èrò ọkàn rẹ̀. Tí àwọn kan bá wá fèsì pé ní tàwọn o, àwọn ò fẹ́ láti gbé nínú irú ibi tó wà nínú àwòrán yẹn tàbí tí wọ́n bá sọ pé àlá tí ò lè ṣẹ ni, má ṣe yára kà wọ́n sẹ́ni tí ò níkan-án ṣe. Ńṣe ni kó o fọgbọ́n wádìí ohun tó fà á tí wọ́n fi sọ bẹ́ẹ̀. Ó ṣeé ṣe kí ìdáhùn wọn fi hàn pé àwọn ìṣòro tó dà bíi pé kò lójútùú tí ọmọ aráyé ń ní ló ti bà wọ́n lọ́kàn jẹ́ tó bẹ́ẹ̀.—Ìsík. 9:4.

      Bó o bá ti mọ ohun tó ń jẹ onílé lọ́kàn, gbọ́rọ̀ kalẹ̀ lọ́nà tó máa bá ipò rẹ̀ mu. Sọ̀rọ̀ nípa ohun tó bá àníyàn ọkàn rẹ̀ mu jù lọ nínú ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run. Ka ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan tàbí méjì tó sọ̀rọ̀ nípa ohun tó ń jẹ ẹ́ lọ́kàn. (Wo àwọn àbá tó wà lápá ọ̀tún ìwé yìí.) Jẹ́ kó fojú ara rẹ̀ rí ohun tí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sọ. Bó bá fìfẹ́ hàn, fún un ní ìwé náà kó o sì ṣètò láti padà wá. Nígbà tó o bá padà bẹ̀ ẹ́ wò, ṣàlàyé síwájú sí í nípa ohun tẹ́ ẹ jọ sọ níṣàájú.

  • Lẹ́tà Látọ̀dọ̀ Ẹgbẹ́ Olùṣàkóso
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba—2005 | January
    • Lẹ́tà Látọ̀dọ̀ Ẹgbẹ́ Olùṣàkóso

      Lásìkò yìí tá a ti wà ní bèbè ayé tuntun, ó túbọ̀ ṣe pàtàkì gan-an pé ká máa fojú sọ́nà fún dídé Jèhófà. (Sef. 3:8) Wòlíì Dáníẹ́lì sọ pé “Ọlọ́run . . . jẹ́ Olùṣí àwọn àṣírí payá, ó sì ti sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní apá ìgbẹ̀yìn ọjọ́ di mímọ̀.” (Dán. 2:28) Àǹfààní ńlá ló mà jẹ́ fún wa o pé à ń gbé ní òpin àsìkò tí ẹsẹ Bíbélì yìí sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, àti pé à ń lóye àwọn àṣírí tí Jèhófà ń ṣí payá!

      Jèhófà ń tipasẹ̀ “ẹrú olóòótọ́ àti olóye” ṣí ohun tó fẹ́ ṣe payá ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé, ìyẹn ni láti kó “ogunlọ́gọ̀ ńlá” àwọn olùjọsìn jọ kárí ayé “láwọn ọjọ́ ìkẹyìn” tó kún fún ìdààmú yìí. (Mát. 24:45; Ìṣí. 7:9; 2 Tím. 3:1) Aísáyà 2:2, 3 fi hàn pé “apá ìgbẹ̀yìn àwọn ọjọ́” ni kíkó tí Jèhófà máa kó àwọn olùjọsìn jọ nígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé yìí yóò wáyé. Lọ́dọọdún ni ìkójọ yìí ń tẹ̀ síwájú láìka rògbòdìyàn àti ìwà ipá tó gbòde jákèjádò ayé sí.

      Lọ́dún 2004, ètò àjọ Jèhófà ti jẹ́ ká rí i pé ó yẹ ká túbọ̀ fiyè sí ọ̀rọ̀ Jésù tó sọ pé: “Ẹ máa bá a nìṣó ní ṣíṣọ́nà . . . Ẹ wà ní ìmúratán.” (Mát. 24:42, 44) Àwọn Kristẹni tó mọ “àwọn àmì àkókò” tí wọ́n sì ń gbé ìgbésẹ̀ tó yẹ máa ń tètè róye ohun tí làásìgbò inú ayé túmọ̀ sí. (Mát. 16:1-3) Ọ̀rọ̀ tí Jèhófà sọ nínú Bíbélì ń ṣẹ lóòótọ́, pé òun ò ní padà lẹ́yìn àwọn èèyàn òun tí òun gbé iṣẹ́ ìwàásù lé lọ́wọ́, bó ti wù kí àtakò tó dojú kọ wọ́n pọ̀ tó.

      Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn kan ń gbógun lọ́tùn-ún lósì láti dí iṣẹ́ ìwàásù Ìjọba Ọlọ́run lọ́wọ́ tàbí láti dá a dúró, síbẹ̀ àwọn ará wa ń polongo òtítọ́ nìṣó, wọ́n sì ń péjọ pọ̀ déédéé. (Ìṣe 5:19, 20; Héb. 10:24, 25) Ní Rọ́ṣíà, lóṣù June 2004, ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn kan nílùú Moscow fara mọ́ ìpinnu tílé ẹjọ́ kan ṣe pé kí wọ́n fòfin de iṣẹ́ àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà àti àwọn àjọ tó ń ṣojú wa lábẹ́ òfin ní ìlú yẹn. Síbẹ̀ àwọn ará ò jẹ́ kí ìyẹn kó wọn láyà jẹ; wọ́n mọ ohun tí Ọlọ́run ń fẹ́ kí wọ́n ṣe, wọ́n sì ń ṣègbọràn sí i gẹ́gẹ́ bí Olùṣàkóso dípò àwọn ènìyàn. (Ìṣe 5:29) Ó dá wa lójú pé Jèhófà yóò kọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ mọ̀ọ́ṣe kódà bí ilé ẹjọ́ bá tiẹ̀ ń dá wọn lẹ́bi.

      Ní orílẹ̀-èdè Georgia, láti bí ọdún díẹ̀ sẹ́yìn làwọn èèyànkéèyàn ti ń fi dúkìá àwọn ará ṣòfò, tí àwọn jàǹdùkú ń ṣe wọ́n níṣe ìkà, tí wọ́n sì ń jó àwọn ìwé ìkẹ́kọ̀ọ́ wọn níná lójú wọn. Àmọ́ o, kò sí ohun ìjà èyíkéyìí tí wọ́n gbé sókè sí wọn tó ṣe àṣeyọrí sí rere. (Aísá. 54:17) Lọ́dún iṣẹ́ ìsìn 2004, ìjọba ilẹ̀ Georgia tún fọwọ́ sí ẹ̀sìn àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà padà pé ó jẹ́ ẹ̀sìn tó bófin mu. Àwọn ará wa ti ń ṣe àwọn àpéjọ wọn láìsí ìdààmú èyíkéyìí, ìwé ìkẹ́kọ̀ọ́ sì ń wọlé sí orílẹ̀-èdè náà láìsọsẹ̀. Àwọn akéde ti pọ̀ sí i ju ti ìgbàkígbà rí lọ, bákan náà niye àwọn tó wá sí Iṣe Ìrántí pọ̀ sí i.

      Láwọn orílẹ̀-èdè bí Àméníà, Eritrea, Kòríà, Rwanda àti Turkmenistan, wọ́n fi àwọn arákùnrin wa sẹ́wọ̀n nítorí ìgbàgbọ́ wọn. Òótọ́ ni pé àwọn ará wọ̀nyí jìyà láìtọ́, ṣùgbọ́n wọ́n mọ̀ pé Ìwé Mímọ́ ti sọ bẹ́ẹ̀ tẹ́lẹ̀, ìyẹn ló jẹ́ kí wọ́n lè dúró ṣinṣin bí wọ́n ti ń retí ìdáǹdè látọ̀dọ̀ Jèhófà.—1 Pét. 1:6; 2 Pét. 2:9.

      Bó o ṣe ń ka “Highlights of the Past Year” (Àwọn Ìṣẹ̀lẹ̀ Mánigbàgbé Ọdún Tó Kọjá), tó o sì ń gbé “Worldwide Report” (Ìròyìn Iṣẹ́ Ìsìn Kárí Ayé) ọdún 2004 yẹ̀ wò nínú ìwé ọdọọdún wa, 2005 Yearbook of Jehovah’s Witnesses, inú rẹ yóò dùn bó o ṣe ń rí i pé oore Jèhófà pọ̀ lórí wa. (Sm. 31:19; 65:11) A nírètí pé ìwé ọdọọdún wa yìí yóò fún ọ níṣìírí kó o lè máa ṣe ohun tí Ọlọ́run fẹ́ nìṣó.—1 Tẹs. 4:1.

      A ò dẹwọ́ nínú bá a ṣe ń sapá láti mú kí ọ̀rọ̀ òtítọ́ détígbọ̀ọ́ gbogbo èèyàn. Bí àpẹẹrẹ, a ti ṣe ọ̀pọ̀ fídíò, àwo pẹlẹbẹ DVD, àtàwọn ohun ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́ mìíràn lédè àwọn adití, a sì ti tẹ àwọn ìwé jáde lédè àwọn afọ́jú pẹ̀lú láti fi ran àwọn adití àtàwọn afọ́jú lọ́wọ́ nípa tẹ̀mí. Ọ̀pọ̀ àwọn akéde Ìjọba Ọlọ́run ló ti kọ́ èdè táwọn àjèjì tó wà ní ìpínlẹ̀ ìjọ wọn ń sọ.

      Síwájú sí i, ọgọ́rọ̀ọ̀rún àwọn àwùjọ ni a ti dá sílẹ̀ láwọn ibi tó wà ní àdádó tó ṣòro láti dé. Ohun tó lé ní ọgọ́rùn-ún mẹ́ta àwùjọ tó wà ní àdádó ni ẹ̀ka ọ́fíìsì kan ń bójú tó, àwọn akéde tó lé ní ẹgbẹ̀rún méje ló sì wà níbẹ̀. Ẹ ò rí i pé ìrètí wà pé a máa dá ọ̀pọ̀ ìjọ tuntun sílẹ̀ láwọn àgbègbè wọ̀nyí! Yàtọ̀ síyẹn, nínú mílíọ̀nù mẹ́rìndínlógún ó lé ọ̀kẹ́ méjìdínlógójì àti ẹgbẹ̀ta ó lé méje (16,760,607) èèyàn tó wá sí ibi ayẹyẹ Ìṣe Ìrántí lọ́dún iṣẹ́ ìsìn yìí, èyí tó lé ní mílíọ̀nù mẹ́wàá lára wọn ni kì í ṣe Ẹlẹ́rìí Jèhófà. Ohun tí èyí túmọ̀ sí ni pé ọ̀pọ̀ jaburata iṣẹ́ ìkórè ló ṣì wà láti ṣe.

      A dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà ní tìtorí ọ̀pọ̀ rẹpẹtẹ ìbùkún rẹ̀ àti bó ṣe ń fìfẹ́ bójú tó wa lójoojúmọ́. (Òwe 10:22; Mál. 3:10; 1 Pét. 5:7) Bá a ṣe ń fi ẹ̀mí ìṣọ̀kan tẹ̀ síwájú ní “apá ìgbẹ̀yìn ọjọ́” yìí, Jèhófà la gbójú lé, òun la sì fẹ̀yìn tì. Bí iná ń jó tíjì ń jà, ẹṣin ọ̀rọ̀ ọdún 2005 yìí ni kẹ́ ẹ jẹ́ ká fi sọ́kàn, ìyẹn ni: “Ọ̀dọ̀ Jèhófà ni ìrànlọ́wọ́ mi ti wá.” (Sm. 121:2) A fẹ́ kẹ́ ẹ mọ̀ pé a nífẹ̀ẹ́ yín gidigidi, a sì ń rántí yín nínú àdúrà wa.

      Àwa arákùnrin yín,

      Ẹgbẹ́ Olùṣàkóso ti Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́