ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g25 No. 1 ojú ìwé 4-5
  • Gbà Pé Ńṣe Ni Nǹkan Á Máa Wọ́n Sí I

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Gbà Pé Ńṣe Ni Nǹkan Á Máa Wọ́n Sí I
  • Jí!—2025
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • ÌDÍ TÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ FI ṢE PÀTÀKÌ
  • OHUN TÓ O LÈ ṢE
  • Kí Ni Bíbélì Sọ Nípa Bí Nǹkan Ṣe Túbọ̀ Ń Gbówó Lórí Kárí Ayé?
    Àkójọ Àpilẹ̀kọ àti Fídíò
  • Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Yìí
    Jí!—2025
  • Gbà Pé Nǹkan Ṣì Máa Dáa
    Jí!—2025
  • Máa Fọgbọ́n Náwó
    Jí!—2025
Àwọn Míì
Jí!—2025
g25 No. 1 ojú ìwé 4-5
Àwòrán: 1. Obìnrin kan ń ra tòmátò lọ́jà. 2. Ó ń sanwó nǹkan tó rà.

NǸKAN Ń GBÓWÓ LÓRÍ! ỌGBỌ́N WO LO LÈ DÁ SÍ I?

Gbà Pé Ńṣe Ni Nǹkan Á Máa Wọ́n Sí I

Táwọn nǹkan bá ń gbówó lórí díẹ̀díẹ̀, èèyàn lè má tètè mọ̀ ọ́n lára, àgàgà tí owó tó ń wọlé fúnni bá ń pọ̀ sí i. Àmọ́ tówó ọjà bá lọ sókè lójijì, tí owó tó ń wọlé ò sì pọ̀ sí i, èèyàn lè bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́kàn sókè. Kódà, ó lè mú káyé súni, pàápàá téèyàn bá láwọn tó ń gbọ́ bùkátà ẹ̀.

Òótọ́ kan ni pé, kò sóhun tá a lè ṣe tí nǹkan ò fi ní máa wọ́n sí i. Tá a bá ń fi èyí sọ́kàn, ó máa ṣe wá láǹfààní.

ÌDÍ TÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ FI ṢE PÀTÀKÌ

Téèyàn bá gbà pé ńṣe ni nǹkan á máa wọ́n sí i . . .

  • kò ní máa kọ́kàn sókè ju bó ṣe yẹ lọ. Èyí á jẹ́ kó lè máa ronú jinlẹ̀, á sì máa ṣe àwọn nǹkan tó mọ́gbọ́n dání.

  • kò ní máa ṣe àwọn nǹkan táá kó o sí gbèsè. Bí àpẹẹrẹ, á máa san àwọn owó tó yẹ kó san lásìkò, kó má bàa di pé èlé á gorí ẹ̀ nígbà tó bá yá. Kò sì ní máa náwó nínàákúnàá.

  • kò ní jẹ́ kí ọ̀rọ̀ owó máa dá wàhálà sílẹ̀ nínú ìdílé.

  • á máa wá bó ṣe máa ṣọ́wó ná. Bí àpẹẹrẹ, kò ní máa náwó sórí àwọn nǹkan tí kò ṣe pàtàkì.

OHUN TÓ O LÈ ṢE

Ṣe tán láti ṣe àwọn àyípadà kan. Lásìkò tí nǹkan bá ń gbówó lórí, á dáa kéèyàn máa ṣọ́wó ná. Bí àpẹẹrẹ, àwọn kan máa ń tọrùn bọ gbèsè torí kí wọ́n lè ṣe fàájì tàbí kí wọ́n lè bẹ́gbẹ́ pé. Ìyẹn ò wá ní jẹ́ kọ́kàn wọn balẹ̀. Torí ṣe ni wọ́n á kàn máa ṣe kìràkìtà lásán, awọ ò sì ní kájú ìlù. Tó bá jẹ́ torí kó o lè máa bójú tó ìdílé ẹ lo ṣe ń forí ṣe fọrùn ṣe, ìyẹn dáa. Síbẹ̀, ó yẹ kó o máa rántí pé: Ohun tó ṣe pàtàkì jù ni pé kó o máa wáyè fún ìdílé ẹ, kẹ́ ẹ jọ máa sọ̀rọ̀, kó o sì máa fìfẹ́ hàn sí wọn.

“Èwo nínú yín ló lè fi ìgbọ̀nwọ́ kan kún ìwàláàyè rẹ̀, tó bá ń ṣàníyàn”—Lúùkù 12:25.

“Ẹ má ṣàníyàn láé nípa ọ̀la, torí ọ̀la máa ní àwọn àníyàn tirẹ̀. Wàhálà ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ti tó fún un.”—Mátíù 6:34.

Téèyàn bá ń tọrùn bọ gbèsè torí fàájì tàbí kó lè bẹ́gbẹ́ pé, ọkàn ẹ̀ ò ní balẹ̀, ṣe lá kàn máa ṣe kìràkìtà lásán, awọ ò sì ní kájú ìlù

Phazilya.

“Ní 2 Tímótì 3:1, Bíbélì sọ pé ‘nǹkan máa le gan-an, ó sì máa nira’ lákòókò tá a wà yìí. Torí náà, kò yà mí lẹ́nu bí ọrọ̀ ajé ṣe ń dẹnu kọlẹ̀, tí nǹkan sì ń gbówó lórí. Kí nǹkan lè rọrùn fún mi, mi ò kì í náwó sórí àwọn nǹkan tí kò ṣe pàtàkì.”—Phazilya, Azerbaijan.

    Yorùbá Publications (1987-2026)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́