ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g25 No. 1 ojú ìwé 6-9
  • Máa Fọgbọ́n Náwó

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Máa Fọgbọ́n Náwó
  • Jí!—2025
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • ÌDÍ TÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ FI ṢE PÀTÀKÌ
  • OHUN TÓ O LÈ ṢE
  • Bó O Ṣe Lè Máa Ṣọ́wó Ná
    Àkójọ Àpilẹ̀kọ àti Fídíò
  • 2 | Ṣe Ohun Tí Ò Ní Jẹ́ Kí Àtijẹ Àtimu Nira Fún Ẹ
    Jí!—2022
  • Ọ̀nà Tí A Lè Gbà Bọ́ Lọ́wọ́ Gbèsè
    Jí!—1996
  • Báwo Ni Mo Ṣe Lè Máa Ṣọ́wó Ná?
    Jí!—2006
Àwọn Míì
Jí!—2025
g25 No. 1 ojú ìwé 6-9
Àwòrán: 1. Tọkọtaya kan wà níbi tí wọ́n ti máa ń jẹun nílé wọn, wọ́n ń ṣàyẹ̀wò bí wọ́n ṣe ń náwó, ọmọbìnrin wọn wà lọ́wọ́ ẹ̀yìn níbi ilé ìdáná. 2. Àwọn ìwé tí wọ́n fi rajà àtàwọn rìsí ìtì wà lórí tábìlì, wọ́n sì ṣí kakulétọ̀ sórí fóònù tó wà lórí àwọn ìwé náà.

NǸKAN Ń GBÓWÓ LÓRÍ! ỌGBỌ́N WO LO LÈ DÁ SÍ I?

Máa Fọgbọ́n Náwó

Kò sẹ́ni tọ́rọ̀ owó ọjà tó ń lọ sókè ò kàn, gbogbo wa pátá ló ń ni lára. Àmọ́, ṣó wá yẹ kíyẹn mú kó o máa kárí sọ? Rárá o. Àwọn nǹkan kan wà tó o lè ṣe tó ò fi ní máa kọ́kàn sókè ju bó ṣe yẹ lọ.

ÌDÍ TÍ Ọ̀RỌ̀ YÌÍ FI ṢE PÀTÀKÌ

Tẹ́nì kan ò bá fọgbọ́n ná owó tó ń wọlé fún un, ó lè bẹ̀rẹ̀ sí í jẹ gbèsè. Ìyẹn ò sì ní jẹ́ kọ́kàn ẹ̀ balẹ̀, kódà ńṣe ló máa dá kún ìṣòro ẹ̀. Tó ò bá tiẹ̀ fi bẹ́ẹ̀ lówó lọ́wọ́, àwọn nǹkan kan wà tó o lè ṣe kó o lè máa fọgbọ́n náwó.

OHUN TÓ O LÈ ṢE

Ṣe bó o ti mọ. Tó o bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, o ò ní máa náwó nínàákúnàá. Ìyẹn ò sì ní jẹ́ kó o máa kọ́kàn sókè ju bó ṣe yẹ lọ tí nǹkan àìròtẹ́lẹ̀ bá ṣẹlẹ̀.

Kó o má bàa máa náwó nínàákúnàá, á dáa kó o ṣètò bí wàá ṣe máa náwó. Ìyẹn máa gba pé kó o kọ iye tó ń wọlé fún ẹ àti iye tó o fẹ́ ná. Lẹ́yìn náa, rí i dájú pé o mọ àwọn nǹkan tó o nílò gangan. Kó o wá pinnu pé o ò ní ná ju iye tó o kọ sílẹ̀ lọ. Tí iye tó ń wọlé fún ẹ bá yí pa dà tàbí tí owó ọjà yí pa dà, kó o yí ohun tó o kọ sílẹ̀ náà pa dà. Tó o bá sì ti ní ọkọ tàbí aya, á dáa kó jẹ́ pé ẹ̀yin méjèèjì lẹ jọ máa ṣètò ìnáwó náà.

Gbìyànjú èyí wò: Dípò tí wàá fi máa ra nǹkan láwìn, tó bá ṣeé ṣe, máa san owó nǹkan tó o bá rà lójú ẹsẹ̀. Àwọn kan ti gbìyànjú ẹ̀, wọ́n sì rí i pé kì í jẹ́ káwọn náwó nínàákúnàá, wọn kì í sì í jẹ gbèsè. Bákan náà, máa fara balẹ̀ ṣàyẹ̀wò àkọsílẹ̀ báǹkì ẹ tàbí kó o máa ṣàkọsílẹ̀ bó o ṣe ń náwó, kó o lè mọ iye tó ń wọlé àti iye tó ń jáde lóṣooṣù. Tó o bá mọ iye tó o ní lọ́wọ́, o ò ní máa náwó yàlàyòlò débi tí wàá fi jẹ gbèsè, tí wàá sì máa kọ́kàn sókè.

Ká sòótọ́, kì í rọrùn láti máa sọ́wó ná. Àmọ́, o lè rí i ṣe tó o bá ń fara balẹ̀ ṣètò bó o ṣe ń náwó, tó ò sì ṣe jura ẹ lọ. Ìyẹn ò ní jẹ́ kó o máa ṣàníyàn ju bó ṣe yẹ lọ.

“Ṣírò ohun tó máa ná [ẹ].”—Lúùkù 14:28.


Má ṣe jẹ́ kí ọ̀nà àtijẹ ẹ dí. Ṣe gbogbo ohun tó o lè ṣe kíṣẹ́ má bàa bọ́ mọ́ ẹ lọ́wọ́. Ara ohun tó o lè ṣe nìyí: Máa tètè dé ibiṣẹ́. Máa fọwọ́ pàtàkì mú iṣẹ́ ẹ. Máa ṣe ohun tó yẹ kó o ṣe níbiṣẹ́ láìjẹ́ pé wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ ń sọ fún ẹ, má sì fiṣẹ́ ṣeré. Máa pọ́n àwọn èèyàn lé. Máa pa òfin ibiṣẹ́ mọ́, kó o sì máa wá bó o ṣe lè jáfáfá sí i lẹ́nu iṣẹ́ ẹ.


Má ṣe máa fowó ṣòfò. Bi ara ẹ pé, ‘Ṣé mi kì í náwó tó pọ̀ lórí àwọn nǹkan tí kò ṣe pàtàkì tàbí àwọn nǹkan tó lè pa mí lára?’ Bí àpẹẹrẹ, ọ̀pọ̀ èèyàn ló máa ń forí ṣe fọrùn ṣe kí wọ́n tó rówó, tí wọ́n bá wá rówó náà tán, wọ́n á máa ná an sórí oògùn olóró, tẹ́tẹ́, sìgá àti ọtí àmujù. Bẹ́ẹ̀ sì rèé, àwọn nǹkan yìí lè kó bá ìlera wọn, ó sì lè mú kíṣẹ́ bọ́ lọ́wọ́ wọn.

“Aláyọ̀ ni ẹni tó wá ọgbọ́n rí . . . Kéèyàn ní in sàn ju kéèyàn ní fàdákà.”—Òwe 3:13, 14.


Máa fowó pa mọ́ torí ohun àìròtẹ́lẹ̀. Tó bá ṣeé ṣe, máa tọ́jú owó díẹ̀ pa mọ́ kó o lè rí i lò tí ohun àìròtẹ́lẹ̀ bá ṣẹlẹ̀. Irú owó bẹ́ẹ̀ lè wúlò tí ìwọ tàbí mọ̀lẹ́bí ẹ kan bá ń ṣàìsàn, tíṣẹ́ bá bọ́ lọ́wọ́ ẹ tàbí táwọn ohun àìròtẹ́lẹ̀ míì bá ṣẹlẹ̀.

“Ìgbà àti èèṣì ń ṣẹlẹ̀ sí gbogbo [wọn].”—Oníwàásù 9:11.

Bó O Ṣe Lè Máa Ṣọ́wó Ná

Ìgò kan tí owó wà nínú ẹ̀.

Máa se oúnjẹ fúnra ẹ.

Tó bá jẹ́ pé gbogbo ìgbà lo máa ń ra oúnjẹ jẹ níta, wàá máa náwó tó pọ̀ jù. Òótọ́ ni pé ó lè má rọrùn láti máa se oúnjẹ fúnra ẹ torí ó máa ń gba ọ̀pọ̀ àkókò. Àmọ́ tó o bá ń ṣe bẹ́ẹ̀, wàá rí i pé owó tí wàá máa ná sórí oúnjẹ á dín kù. Yàtọ̀ síyẹn, wàá lè máa se oúnjẹ ẹ bó o ṣe fẹ́, o ò sì ní máa jẹ ìjẹkújẹ.

Máa fọgbọ́n rajà.

  • Máa kọ àwọn nǹkan tó o fẹ́ rà, kó o sì rí i pé o ò rà ju ohun tó o kọ sílẹ̀ lọ. Má kàn máa ra gbogbo nǹkan tó o bá ṣáà ti rí.

  • Dípò tí wàá fi máa ra nǹkan ní ẹyọ-ẹyọ, tó bá ṣeé ṣe o lè rà wọ́n lójú páálí tàbí kó o ra àpò. Àmọ́, rí i pé o mọ bó o ṣe lè tọ́jú àwọn nǹkan tó lè tètè bà jẹ́, kí wọ́n má bàa ṣòfò.

  • Dípò tí wàá fi máa ra àwọn ọjà tó lórúkọ, o lè ra àwọn ọjà tí kò fi bẹ́ẹ̀ lórúkọ àmọ́ tó ṣì jẹ́ gidi. Torí àwọn ọjà tó lórúkọ sábà máa ń wọ́n.

  • Gbìyànjú láti máa ra àwọn nǹkan kan lórí ìkànnì dípò tí wàá fi lọ rà wọ́n lọ́jà, ìyẹn á jẹ́ kó o lè máa kíyè sí bó o ṣe ń náwó. Torí tó o bá lọ sọ́jà, o lè ra àwọn nǹkan míì tí o ò ní lọ́kàn láti rà.

  • Ṣèwádìí nípa àwọn ibi tí wọ́n ti ń tajà ní ẹ̀dínwó. Kó o tó rajà, máa nájà láwọn ibi ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀. Kódà, o lè ṣe bẹ́ẹ̀ tó o bá fẹ́ ra àwọn nǹkan bí omi, gáàsì àtàwọn nǹkan míì.

Rò ó dáadáa kó o tó ra àwọn ẹ̀rọ ìgbàlódé.

Àwọn ilé iṣẹ́ tó ń ṣe fóònù àtàwọn ẹ̀rọ ìgbàlódé míì sábà máa ń gbé èyí tó jẹ́ tuntun jáde kí owó tó ń wọlé fún wọn lè máa pọ̀ sí i. Torí náà, á dáa kó o bi ara ẹ pé: ‘Kí nìdí tí mo fi fẹ́ ra fóònù tàbí ẹ̀rọ ìgbàlódé tó ṣẹ̀ṣẹ̀ jáde yìí? Ṣé mo nílò ẹ̀ báyìí? Tí mo bá sì nílò fóònù tàbí ẹ̀rọ́ ìgbàlódé kan, ṣé dandan ni kó jẹ́ pé èyí tó ṣẹ̀ṣẹ̀ jáde ni màá rà?’

Máa tún àwọn nǹkan tó bà jẹ́ ṣe.

Máa lo àwọn ẹ̀rọ ìgbàlódé tó o ní dáadáa kí wọ́n má bàa tètè bà jẹ́. Tí ẹ̀rọ kan bá sì bà jẹ́, gbìyànjú láti tún un ṣe, tíyẹn ò bá ní ná ẹ lówó tó pọ̀ jù. O tún lè ra èyí tó jẹ́ àlòkù, àmọ́ tó ṣì dáa.

Máa gbin nǹkan.

Tó bá ṣeé ṣe, wá ibi tó o lè fi dáko. Ìyẹn á dín owó tí wàá máa ná lórí oúnjẹ kù. Kódà, o tún lè rí tà lára ohun tó o bá gbìn tàbí kó o fún àwọn èèyàn.

“Àwọn ohun tí òṣìṣẹ́ kára gbèrò láti ṣe máa ń yọrí sí rere.”—Òwe 21:5.

Káàdì tí wọ́n fi ń rajà.

“A máa ń gbìyànjú láti mọ iye tí wọ́n ń ta àwọn nǹkan tá a máa ń lò déédéé. Bákan náà, a kì í sábà ra nǹkan láwìn.”—Miles, England.

Ìwé kékeré kan, báírò, àti kọ́kọ́rọ mọ́tò.

“Èmi àtìyàwó mi máa ń rí i pé a kọ àwọn nǹkan tá a fẹ́ rà sílẹ̀ ká tó lọ sọ́jà.”—Jeremy, Amẹ́ríkà.

Ìwé àkọsílè àti kakulétọ̀.

“Bí nǹkan ṣe ń wọ́n sí i, bẹ́ẹ̀ náà lèmi àti ìdílé mi ń yí iye tá a fẹ́ ná pa dà, a tún máa ń tọ́jú owó díẹ̀ pa mọ́ torí àwọn nǹkan tá ò rò tẹ́lẹ̀.”—Yael, Israel.

Spanner àti screwdriver.

“A kọ́ àwọn ọmọ wa láti máa tún àwọn nǹkan tó bà jẹ́ ṣe, dípò tí wọ́n á fi ra òmíì. Bí àpẹẹrẹ, àwa fúnra wa la máa ń tún ọkọ̀ wa ṣe títí kan àwọn nǹkan míì tá à ń lò nílé. Bákan náà, èmi àtìyàwó mi kì í sábà ra àwọn ẹ̀rọ ìgbàlódé tó bá ṣẹ̀ṣẹ̀ jáde.”—Jeffrey, Amẹ́ríkà.

“Mo máa ń gbin àwọn nǹkan jíjẹ bí ẹ̀fọ́ àtàwọn ewébẹ̀ míì, mo sì tún ń sin adìyẹ. Ìyẹn ti jẹ́ kí owó tí mò ń ná lórí oúnjẹ dín kù. Kódà, mo tún máa ń fún àwọn èèyàn lára àwọn nǹkan tí mò ń gbìn.”—Hono, Myanmar.

Obìnrin kan wà nínú ọgbà, ó ń kórè àwọn nǹkan tó gbìn.
    Yorùbá Publications (1987-2026)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́