ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • scl ojú ìwé 36-37
  • Ẹ̀mí Ìrẹ̀lẹ̀

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ẹ̀mí Ìrẹ̀lẹ̀
  • Àwọn Ẹsẹ Bíbélì Tó Lè Ran Àwa Kristẹni Lọ́wọ́
Àwọn Ẹsẹ Bíbélì Tó Lè Ran Àwa Kristẹni Lọ́wọ́
scl ojú ìwé 36-37

Ẹ̀mí Ìrẹ̀lẹ̀

Ojú wo ni Jèhófà fi ń wo àwọn onírẹ̀lẹ̀ àtàwọn agbéraga?

Sm 138:6; Owe 15:25; 16:18, 19; 22:4; 1Pe 5:5

Tún wo Owe 29:23; Ais 2:11, 12

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • 2Kr 26:3-5, 16-21—Ọba Ùsáyà di agbéraga; ó rú Òfin Ọlọ́run, inú sì bí i nígbà tí wọ́n fún un nímọ̀ràn, torí náà Jèhófà fi ẹ̀tẹ̀ kọ lù ú

    • Lk 18:9-14—Jésù sọ àpèjúwe kan láti fi ṣàlàyé ojú tí Jèhófà fi ń wo àdúrà àwọn agbéraga àtàwọn onírẹ̀lẹ̀

Kí ni Jèhófà máa ṣe tí ẹlẹ́ṣẹ̀ kan bá rẹ ara ẹ̀ sílẹ̀, tó sì ronú pìwà dà tọkàntọkàn?

2Kr 7:13, 14; Sm 51:2-4, 17

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • 2Kr 12:5-7—Ọba Rèhóbóámù àtàwọn ìjòyè Júdà rẹ ara wọn sílẹ̀ níwájú Jèhófà, torí náà Jèhófà ṣàánú wọn, kò sì pa wọ́n run mọ́

    • 2Kr 32:24-26—Ọba rere ni Hẹsikáyà, àmọ́ ó di agbéraga nígbà tó yá, ṣùgbọ́n nígbà tó rẹ ara ẹ̀ sílẹ̀, Jèhófà dárí jì í

Tá a bá jẹ́ onírẹ̀lẹ̀, báwo nìyẹn ṣe máa ràn wá lọ́wọ́ láti ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú àwọn èèyàn?

Ef 4:1, 2; Flp 2:3; Kol 3:12, 13

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Jẹ 33:3, 4—Inú ń bí Ísọ̀ sí Jékọ́bù, àmọ́ Jékọ́bù fi hàn pé òun jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ nígbà táwọn méjèèjì pàdé, ìyẹn sì mú kí àlàáfíà jọba láàárín wọn lẹ́ẹ̀kan sí i

    • Ond 8:1-3—Gídíónì fi ìrẹ̀lẹ̀ sọ fáwọn ọkùnrin Éfúrémù pé wọ́n sàn ju òun lọ, ìyẹn sì mú kí ìbínú wọn rọlẹ̀

Báwo ni Jésù ṣe jẹ́ ká mọ̀ pé ó ṣe pàtàkì kéèyàn jẹ́ onírẹ̀lẹ̀?

Mt 18:1-5; 23:11, 12; Mk 10:41-45

  • Àpẹẹrẹ inú Bíbélì:

    • Ais 53:7; Flp 2:7, 8—Níbàámu pẹ̀lú ohun táwọn wòlíì sọ, Jésù jẹ́ onírẹ̀lẹ̀, ó gbà láti wá sáyé kó lè wá kú ikú oró, kí wọ́n sì pa á ní ìpa ìkà

    • Lk 14:7-11—Jésù sọ àpèjúwe kan nípa báwọn èèyàn ṣe ń jókòó níbi àsè kó lè jẹ́ ká rí àǹfààní tó wà nínú kéèyàn jẹ́ onírẹ̀lẹ̀

    • Jo 13:3-17—Jésù kọ́ àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ pé ó yẹ kí wọ́n jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ nígbà tó rẹ ara ẹ̀ sílẹ̀ tó sì fọ ẹsẹ̀ àwọn àpọ́sítélì rẹ̀

Tá a bá ń fi ojú tó tọ́ wo ara wa àtàwọn ẹlòmíì, báwo nìyẹn ṣe máa ràn wá lọ́wọ́ láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀?

Ro 12:3, 16; 1Kọ 4:7; Flp 2:3, 4

Kí nìdí tí kò fi bọ́gbọ́n mu pé kéèyàn máa ṣojú ayé bíi pé òun jẹ́ onírẹ̀lẹ̀?

Mt 6:16-18; Kol 2:18, 23

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́