-
Jẹ́nẹ́sísì 41:18-21Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
18 Màlúù méje tó rẹwà tó sì sanra ń jáde bọ̀ látinú odò náà, wọ́n sì ń jẹ koríko+ tó wà ní odò Náílì. 19 Lẹ́yìn náà, màlúù méje míì tí ìrísí wọn ò dáa, tí wọn ò lẹ́wà rárá, tí wọ́n sì rù ń jáde bọ̀. Mi ò rí irú màlúù tí ìrísí wọn burú tó bẹ́ẹ̀ rí ní gbogbo ilẹ̀ Íjíbítì. 20 Àwọn màlúù tí kò dáa tí wọ́n sì rù kan egungun yẹn wá ń jẹ màlúù méje àkọ́kọ́ tó sanra ní àjẹrun. 21 Àmọ́ nígbà tí wọ́n jẹ wọ́n tán, kò sẹ́ni tó lè mọ̀ pé wọ́n jẹ nǹkan kan, torí kò hàn lára wọn. Ni mo bá jí.
-