15 Mi ò bá ti na ọwọ́ mi kí n lè fi àjàkálẹ̀ àrùn tó le gan-an kọ lu ìwọ àti àwọn èèyàn rẹ, kí n sì pa ọ́ rẹ́* kúrò ní ayé. 16 Àmọ́ ìdí tí mo fi dá ẹ̀mí rẹ sí ni pé: kí n lè fi agbára mi hàn ọ́, kí a sì lè ròyìn orúkọ mi ní gbogbo ayé.+
17 Nítorí Ìwé Mímọ́ sọ fún Fáráò pé: “Ìdí tí mo fi jẹ́ kí o máa wà nìṣó ni pé: kí n lè fi agbára mi hàn nípasẹ̀ rẹ àti pé kí a lè ròyìn orúkọ mi ní gbogbo ayé.”+