-
Ẹ́kísódù 9:3, 4Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
3 wò ó! ọwọ́ Jèhófà+ máa kọ lu àwọn ẹran ọ̀sìn rẹ nínú oko. Àjàkálẹ̀ àrùn tó le gan-an+ yóò run àwọn ẹṣin, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ràkúnmí, ọ̀wọ́ ẹran àti agbo ẹran. 4 Ó dájú pé Jèhófà yóò fi ìyàtọ̀ sáàárín ẹran ọ̀sìn Ísírẹ́lì àti ẹran ọ̀sìn Íjíbítì, ìkankan ò sì ní kú nínú ẹran tó jẹ́ ti àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.”’”+
-
-
Ẹ́kísódù 10:23Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
23 Wọn ò rí ara wọn, ìkankan nínú wọn ò sì kúrò níbi tó wà fún ọjọ́ mẹ́ta; àmọ́ ìmọ́lẹ̀ wà níbi tí gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń gbé.+
-
-
Ẹ́kísódù 12:13Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
13 Ẹ̀jẹ̀ náà yóò jẹ́ àmì yín lára àwọn ilé tí ẹ wà; èmi yóò rí ẹ̀jẹ̀ náà, èmi yóò sì ré yín kọjá, ìyọnu náà ò sì ní pa yín run nígbà tí mo bá kọ lu ilẹ̀ Íjíbítì.+
-