-
Léfítíkù 7:1Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
7 “‘Òfin ẹbọ ẹ̀bi+ nìyí: Ohun mímọ́ jù lọ ni.
-
-
Léfítíkù 14:2Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
2 “Èyí ni òfin tí ẹ ó máa tẹ̀ lé nípa adẹ́tẹ̀, ní ọjọ́ tí àlùfáà máa kéde rẹ̀ pé ó ti di mímọ́, tí wọ́n á sì mú un wá sọ́dọ̀ àlùfáà.+
-
-
Léfítíkù 19:20, 21Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
20 “‘Tí ọkùnrin kan bá dùbúlẹ̀ ti obìnrin kan, tó sì bá a lò pọ̀, tó sì jẹ́ pé ìránṣẹ́ ọkùnrin míì ni obìnrin náà, àmọ́ tí wọn ò tíì rà á pa dà tàbí dá a sílẹ̀, ẹ gbọ́dọ̀ fìyà jẹ wọ́n. Àmọ́, ẹ má pa wọ́n, torí wọn ò tíì dá obìnrin náà sílẹ̀. 21 Kí ọkùnrin náà mú ẹbọ ẹ̀bi rẹ̀ wá fún Jèhófà ní ẹnu ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, àgbò kan fún ẹbọ ẹ̀bi.+
-
-
Nọ́ńbà 6:12Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
12 Kó tún ara rẹ̀ yà sọ́tọ̀ fún Jèhófà ní àwọn ọjọ́ tó fi jẹ́ Násírì, kó sì mú ọmọ àgbò ọlọ́dún kan wá láti fi rú ẹbọ ẹ̀bi. Àmọ́ kò ní ka àwọn ọjọ́ tó ti kọjá torí ó ti ba Násírì rẹ̀ jẹ́.
-