23 Lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ọdún,* ọba Íjíbítì kú,+ àmọ́ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń kérora torí wọ́n wà lóko ẹrú, wọ́n sì ń ráhùn, igbe tí wọ́n ń ké fún ìrànlọ́wọ́ torí pé wọ́n ń fi wọ́n ṣe ẹrú sì dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run tòótọ́.+
7 Jèhófà sì sọ pé: “Mo ti rí ìyà tó ń jẹ àwọn èèyàn mi ní Íjíbítì, mo sì ti gbọ́ igbe wọn torí àwọn tó ń fipá kó wọn ṣiṣẹ́; mo mọ̀ dáadáa pé wọ́n ń jẹ̀rora.+