-
Léfítíkù 22:20Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
20 Ẹ ò gbọ́dọ̀ mú ohunkóhun tó ní àbùkù+ wá, torí kò ní mú kí ẹ rí ìtẹ́wọ́gbà.
-
-
Diutarónómì 15:21Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
21 Àmọ́ tó bá ní àbùkù lára, bóyá ó jẹ́ arọ, afọ́jú tàbí tó ní oríṣi àbùkù míì tó le gan-an, o ò gbọ́dọ̀ fi rúbọ sí Jèhófà Ọlọ́run rẹ.+
-
-
Málákì 1:8Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
8 Nígbà tí ẹ bá ń fi ẹran tó fọ́jú rúbọ, ẹ̀ ń sọ pé: “Kò sí ohun tó burú níbẹ̀.” Tí ẹ bá sì ń mú ẹran tó yarọ tàbí èyí tó ń ṣàìsàn wá, ẹ̀ ń sọ pé: “Kò sí ohun tó burú níbẹ̀.”’”+
“Ẹ jọ̀ọ́, ẹ mú un lọ síwájú gómìnà yín. Ṣé inú rẹ̀ á dùn sí yín, ṣé ẹ sì máa rí ojúure rẹ̀?” ni Jèhófà Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun wí.
-