ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • 1 Sámúẹ́lì 28:7-11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 7 Níkẹyìn, Sọ́ọ̀lù sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé: “Ẹ bá mi wá obìnrin kan tí ó jẹ́ abẹ́mìílò,+ màá lọ wádìí lọ́wọ́ rẹ̀.” Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sọ fún un pé: “Wò ó! Obìnrin kan tí ó jẹ́ abẹ́mìílò wà ní Ẹ́ń-dórì.”+

      8 Nítorí náà, Sọ́ọ̀lù pa ara dà, ó wọ aṣọ míì, ó sì lọ sọ́dọ̀ obìnrin náà ní òru pẹ̀lú méjì lára àwọn ọkùnrin rẹ̀. Ó ní: “Jọ̀wọ́, bá mi fi agbára ìbẹ́mìílò+ rẹ pe ẹni tí mo bá dárúkọ rẹ̀ fún ọ jáde.” 9 Ṣùgbọ́n, obìnrin náà sọ fún un pé: “Ó yẹ kí o mọ ohun tí Sọ́ọ̀lù ṣe dáadáa, bí ó ṣe mú àwọn abẹ́mìílò àti àwọn woṣẹ́woṣẹ́ kúrò ní ilẹ̀ yìí.+ Kí wá nìdí tí o fi fẹ́ dẹkùn mú mi* kí wọ́n lè pa mí?”+ 10 Sọ́ọ̀lù wá fi Jèhófà búra fún un pé: “Bí Jèhófà ti wà láàyè, o ò ní jẹ̀bi kankan lórí ọ̀rọ̀ yìí!” 11 Ni obìnrin náà bá sọ pé: “Ta ni kí n bá ọ pè jáde?” Ó fèsì pé: “Bá mi pe Sámúẹ́lì jáde.”

  • Àìsáyà 8:19
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 19 Tí wọ́n bá sì sọ fún yín pé: “Ẹ lọ wádìí lọ́wọ́ àwọn abẹ́mìílò tàbí àwọn woṣẹ́woṣẹ́, àwọn tó ń ké ṣíoṣío, tí wọ́n sì ń jẹnu wúyẹ́wúyẹ́,” ṣebí ọwọ́ Ọlọ́run wọn ló yẹ kí àwọn èèyàn ti lọ wádìí? Ṣé ó yẹ kí wọ́n lọ wádìí ọ̀rọ̀ lọ́wọ́ òkú nítorí alààyè?+

  • Gálátíà 5:19, 20
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 19 Àwọn iṣẹ́ ti ara hàn kedere, àwọn sì ni ìṣekúṣe,*+ ìwà àìmọ́, ìwà àìnítìjú,*+ 20 ìbọ̀rìṣà, ìbẹ́mìílò,*+ ìkórìíra, wàhálà, owú, inú fùfù, awuyewuye, ìpínyà, ẹ̀ya ìsìn,

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́