-
Jóṣúà 9:1, 2Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
9 Nígbà tí gbogbo àwọn ọba tó wà lápá ìwọ̀ oòrùn Jọ́dánì+ gbọ́ ohun tó ṣẹlẹ̀, àwọn tó wà ní agbègbè olókè, ní Ṣẹ́fẹ́là, ní gbogbo etí Òkun Ńlá*+ àti níwájú Lẹ́bánónì, ìyẹn àwọn ọmọ Hétì, àwọn Ámórì, àwọn ọmọ Kénáánì, àwọn Pérísì, àwọn Hífì àtàwọn ará Jébúsì,+ 2 wọ́n gbìmọ̀ pọ̀ láti bá Jóṣúà àti Ísírẹ́lì jà.+
-
-
Jóṣúà 9:9, 10Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
9 Wọ́n fèsì pé: Ọ̀nà tó jìn gan-an ni àwa ìránṣẹ́ rẹ ti wá,+ torí a gbọ́ nípa orúkọ Jèhófà Ọlọ́run rẹ, òkìkí rẹ̀ kàn dé ọ̀dọ̀ wa, a sì ti gbọ́ nípa gbogbo ohun tó ṣe ní Íjíbítì+ 10 àti gbogbo ohun tó ṣe sí àwọn ọba Ámórì méjèèjì tí wọ́n wà ní òdìkejì* Jọ́dánì, ìyẹn Síhónì+ ọba Hẹ́ṣíbónì àti Ógù+ ọba Báṣánì, tó wà ní Áṣítárótì.
-