-
Nọ́ńbà 21:21-24Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
21 Ísírẹ́lì wá ní kí àwọn ìránṣẹ́ lọ bá Síhónì ọba àwọn Ámórì pé:+ 22 “Jẹ́ ká gba ilẹ̀ rẹ kọjá. A ò ní yà sínú oko tàbí sínú ọgbà àjàrà. A ò ní mu omi inú kànga kankan. Ojú Ọ̀nà Ọba la máa gbà títí a fi máa kọjá ní ilẹ̀+ rẹ.” 23 Àmọ́ Síhónì ò jẹ́ kí Ísírẹ́lì gba ilẹ̀ rẹ̀ kọjá. Kàkà bẹ́ẹ̀, Síhónì kó gbogbo àwọn èèyàn rẹ̀ jọ, wọ́n sì lọ gbéjà ko Ísírẹ́lì ní aginjù, nígbà tí wọ́n dé Jáhásì, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í bá Ísírẹ́lì+ jà. 24 Àmọ́ Ísírẹ́lì fi idà+ ṣẹ́gun rẹ̀, ó sì gba ilẹ̀+ rẹ̀ láti Áánónì+ lọ dé Jábókù,+ nítòsí àwọn ọmọ Ámónì, torí pé ààlà àwọn ọmọ Ámónì+ ni Jásérì+ wà.
-
-
Diutarónómì 2:32-34Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
32 Nígbà tí Síhónì àti gbogbo èèyàn rẹ̀ jáde wá gbógun jà wá ní Jáhásì,+ 33 Jèhófà Ọlọ́run wa fi í lé wa lọ́wọ́, a sì ṣẹ́gun òun àtàwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo èèyàn rẹ̀. 34 A gba gbogbo ìlú rẹ̀ nígbà yẹn, a sì pa gbogbo ìlú náà run, títí kan àwọn ọkùnrin, àwọn obìnrin àtàwọn ọmọdé. A ò dá ẹnikẹ́ni sí.+
-