27 “Màá mú kí àwọn èèyàn máa bẹ̀rù mi kí ẹ tó dé ọ̀dọ̀ wọn,+ màá sì da àárín gbogbo àwọn tí ẹ bá pàdé rú. Màá mú kí ẹ ṣẹ́gun gbogbo ọ̀tá yín, wọ́n á sì sá lọ.*+
25 Lónìí yìí, màá mú kí ẹ̀rù yín máa ba gbogbo èèyàn tó wà lábẹ́ ọ̀run tí wọ́n bá gbọ́ ìròyìn nípa yín. Ọkàn wọn kò ní balẹ̀, jìnnìjìnnì á sì bò wọ́n* torí yín.’+
25 Ẹnì kankan ò ní dìde sí yín.+ Jèhófà Ọlọ́run yín máa kó jìnnìjìnnì bá àwọn èèyàn gbogbo ilẹ̀ tí ẹ máa tẹ̀, kí wọ́n sì máa bẹ̀rù yín,+ bó ṣe ṣèlérí fún yín gẹ́lẹ́.