-
Nọ́ńbà 10:29-32Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
29 Mósè sọ fún Hóbábù ọmọ Réúẹ́lì*+ ọmọ ilẹ̀ Mídíánì, bàbá ìyàwó Mósè pé: “À ń lọ síbi tí Jèhófà sọ nípa rẹ̀ pé, ‘Èmi yóò fún yín.’+ Bá wa lọ,+ a ó sì tọ́jú rẹ dáadáa, torí Jèhófà ti ṣèlérí àwọn ohun rere fún Ísírẹ́lì.”+ 30 Àmọ́ ó fèsì pé: “Mi ò ní bá yín lọ. Mo máa pa dà sí ilẹ̀ mi àti sọ́dọ̀ àwọn mọ̀lẹ́bí mi.” 31 Ni Mósè bá sọ fún un pé: “Jọ̀ọ́, má fi wá sílẹ̀, torí o mọ ibi tí a lè pàgọ́ sí nínú aginjù, o sì lè fọ̀nà hàn wá.* 32 Tí o bá sì bá wa lọ,+ ó dájú pé ohun rere èyíkéyìí tí Jèhófà bá ṣe fún wa la máa ṣe fún ọ.”
-