12 “Ní báyìí, ìwọ Ísírẹ́lì, kí ni Jèhófà Ọlọ́run rẹ fẹ́ kí o ṣe?+ Kò ju pé: kí o máa bẹ̀rù Jèhófà Ọlọ́run rẹ,+ kí o máa rìn ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀,+ kí o máa nífẹ̀ẹ́ rẹ̀, kí o máa fi gbogbo ọkàn rẹ àti gbogbo ara* rẹ sin Jèhófà Ọlọ́run rẹ,+
19 “Ọwọ́ rẹ̀ ni kó máa wà, kó sì máa kà á ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀,+ kó lè kọ́ láti máa bẹ̀rù Jèhófà Ọlọ́run rẹ̀, kó sì máa tẹ̀ lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú Òfin yìí àti àwọn ìlànà yìí, kí o máa pa wọ́n mọ́.+