21Jèhófà rántí Sérà gẹ́gẹ́ bí ó ṣe sọ, Jèhófà sì ṣe ohun tó ṣèlérí+ fún Sérà. 2 Sérà lóyún,+ ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Ábúráhámù ní ọjọ́ ogbó rẹ̀ ní àkókò tí Ọlọ́run ṣèlérí fún un.+
19 Lẹ́yìn náà, wọ́n dìde ní àárọ̀ kùtù, wọ́n forí balẹ̀ níwájú Jèhófà, wọ́n sì pa dà sí ilé wọn ní Rámà.+ Ẹlikénà ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú Hánà ìyàwó rẹ̀, Jèhófà sì ṣíjú àánú wò ó.*+