-
1 Sámúẹ́lì 2:12-17Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
12 Àwọn ọmọkùnrin Élì jẹ́ èèyàn burúkú;+ wọn ò ka Jèhófà sí. 13 Ohun tí wọ́n ń ṣe sí ìpín tó tọ́ sí àwọn àlùfáà látọ̀dọ̀ àwọn èèyàn nìyí:+ Nígbàkigbà tí ọkùnrin èyíkéyìí bá ń rú ẹbọ, ìránṣẹ́ àlùfáà máa wá pẹ̀lú àmúga oníga mẹ́ta lọ́wọ́ rẹ̀, nígbà tí ẹran náà ṣì ń hó lórí iná, 14 á sì tì í bọ inú agbada tàbí ìkòkò oníga méjì tàbí ìkòkò irin tàbí ìkòkò oníga kan. Ohunkóhun tí àmúga náà bá mú wá sókè ni àlùfáà yóò mú. Bí wọ́n ṣe ń ṣe nìyẹn ní Ṣílò sí gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tó ń wá síbẹ̀. 15 Bákan náà, kí ọkùnrin tó ń rú ẹbọ tó mú ọ̀rá rú èéfín rárá,+ ìránṣẹ́ àlùfáà máa wá, á sì sọ fún un pé: “Fún àlùfáà ní ẹran tó máa yan. Kò ní gba ẹran bíbọ̀ lọ́wọ́ rẹ, àfi ẹran tútù.” 16 Nígbà tí ọkùnrin náà bá sọ fún un pé: “Jẹ́ kí wọ́n kọ́kọ́ mú ọ̀rá rú èéfín ná,+ lẹ́yìn ìyẹn, kí o mú ohun tí ọkàn rẹ bá fẹ́.”* Àmọ́ á sọ pé: “Rárá, fún mi báyìí-báyìí; àìjẹ́ bẹ́ẹ̀, màá mú un tipátipá!” 17 Nípa bẹ́ẹ̀, ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ náà wá pọ̀ gan-an níwájú Jèhófà,+ nítorí àwọn ọkùnrin náà hùwà àìlọ́wọ̀ sí ọrẹ Jèhófà.
-