-
2 Sámúẹ́lì 16:1Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
16 Nígbà tí Dáfídì kọjá orí òkè+ náà díẹ̀, Síbà+ ìránṣẹ́ Méfíbóṣétì+ wá pàdé rẹ̀ níbẹ̀ pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ méjì tí wọ́n de ohun tí wọ́n fi ń jókòó mọ́,* igba (200) búrẹ́dì, ọgọ́rùn-ún (100) ìṣù àjàrà gbígbẹ, ọgọ́rùn-ún (100) ìṣù èso ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn* àti ìṣà* wáìnì ńlá+ kan sì wà lórí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.
-
-
2 Sámúẹ́lì 17:27-29Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
27 Gbàrà tí Dáfídì dé Máhánáímù, Ṣóbì ọmọkùnrin Náháṣì láti Rábà+ ti àwọn ọmọ Ámónì àti Mákírù+ ọmọkùnrin Ámíélì láti Lo-débà pẹ̀lú Básíláì+ ọmọ Gílíádì láti Rógélímù 28 kó ibùsùn wá, wọ́n tún kó bàsíà, ìkòkò, àlìkámà,* ọkà bálì, ìyẹ̀fun, àyangbẹ ọkà, ẹ̀wà pàkálà, ẹ̀wà lẹ́ńtìlì àti ẹ̀gbẹ ọkà wá, 29 wọ́n sì kó oyin, bọ́tà, àgùntàn àti wàrà wá.* Wọ́n kó gbogbo nǹkan yìí wá fún Dáfídì àti àwọn èèyàn tó wà pẹ̀lú rẹ̀ láti jẹ,+ torí wọ́n sọ pé: “Ebi ń pa àwọn èèyàn náà, ó ti rẹ̀ wọ́n, òùngbẹ sì ń gbẹ wọ́n ní aginjù.”+
-