ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Nọ́ńbà 27:21
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 21 Á sì máa dúró níwájú àlùfáà Élíásárì, ẹni tí yóò máa bá a ṣe ìwádìí níwájú Jèhófà nípasẹ̀ ohun tí Úrímù+ bá sọ. Àṣẹ rẹ̀ ni wọ́n á máa tẹ̀ lé tí wọ́n bá ń jáde, àṣẹ rẹ̀ ni wọ́n á sì máa tẹ̀ lé tí wọ́n bá ń wọlé, òun àti gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pẹ̀lú gbogbo àpéjọ náà.”

  • Àwọn Onídàájọ́ 20:28
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 28 Fíníhásì+ ọmọ Élíásárì, ọmọ Áárónì, ló ń ṣiṣẹ́* níwájú rẹ̀ nígbà yẹn. Wọ́n béèrè pé: “Ṣé ká tún lọ bá àwọn arákùnrin wa, àwọn ọkùnrin Bẹ́ńjámínì jà, àbí ká má lọ mọ́?”+ Jèhófà fèsì pé: “Ẹ lọ, torí ọ̀la ni màá fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”

  • 1 Sámúẹ́lì 23:2
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 2 Torí náà, Dáfídì wádìí lọ́dọ̀ Jèhófà pé:+ “Ṣé kí n lọ mú àwọn Filísínì yìí balẹ̀?” Jèhófà sọ fún Dáfídì pé: “Lọ mú àwọn Filísínì náà balẹ̀, kí o sì gba Kéílà sílẹ̀.”

  • 1 Sámúẹ́lì 23:11
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 11 Ṣé àwọn olórí* Kéílà máa fi mí lé e lọ́wọ́? Ṣé Sọ́ọ̀lù máa wá lóòótọ́ bí ìránṣẹ́ rẹ ṣe gbọ́? Jèhófà Ọlọ́run Ísírẹ́lì, jọ̀wọ́ sọ fún ìránṣẹ́ rẹ.” Ni Jèhófà bá fèsì pé: “Ó máa wá.”

  • 1 Sámúẹ́lì 28:6
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 6 Bí Sọ́ọ̀lù tilẹ̀ ń wádìí lọ́dọ̀ Jèhófà,+ Jèhófà kò dá a lóhùn rárá, ì báà jẹ́ nípasẹ̀ àlá tàbí nípasẹ̀ Úrímù  + tàbí àwọn wòlíì.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́