37 “Ní báyìí, èmi Nebukadinésárì ń yin Ọba ọ̀run,+ mò ń gbé e ga, mo sì ń fi ògo fún un, torí òtítọ́ ni gbogbo iṣẹ́ rẹ̀, ọ̀nà rẹ̀ tọ́,+ ó sì lè rẹ àwọn tó ń gbéra ga wálẹ̀.”+
5 Bákan náà, kí ẹ̀yin ọ̀dọ́kùnrin máa tẹrí ba fún àwọn àgbà ọkùnrin.*+ Àmọ́ kí gbogbo yín gbé ìrẹ̀lẹ̀* wọ̀* nínú àjọṣe yín, torí Ọlọ́run dojú ìjà kọ àwọn agbéraga, àmọ́ ó ń fi inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí hàn sí àwọn onírẹ̀lẹ̀.+