-
2 Kíróníkà 1:7-10Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
7 Ní òru yẹn, Ọlọ́run fara han Sólómọ́nì, ó sì sọ fún un pé: “Béèrè ohun tí wàá fẹ́ kí n fún ọ.”+ 8 Ni Sólómọ́nì bá sọ fún Ọlọ́run pé: “O ti fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn sí Dáfídì bàbá mi+ lọ́nà tó ga, o sì ti fi mí jọba ní ipò rẹ̀.+ 9 Ní báyìí, Jèhófà Ọlọ́run, mú ìlérí tí o ṣe fún Dáfídì bàbá mi ṣẹ,+ nítorí o ti fi mí jọba lórí àwọn èèyàn tó pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀.+ 10 Fún mi ní ọgbọ́n àti ìmọ̀+ tí màá fi máa darí àwọn èèyàn yìí,* nítorí ta ló lè ṣe ìdájọ́ àwọn èèyàn rẹ tó pọ̀ yìí?”+
-