-
2 Kíróníkà 5:11-14Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
11 Nígbà tí àwọn àlùfáà jáde láti ibi mímọ́ (nítorí gbogbo àwọn àlùfáà tó wà níbẹ̀ ni wọ́n ti ya ara wọn sí mímọ́,+ láìka àwùjọ tí wọ́n wà sí),+ 12 gbogbo àwọn ọmọ Léfì tó jẹ́ akọrin+ tí wọ́n jẹ́ ti Ásáfù,+ ti Hémánì,+ ti Jédútúnì + àti ti àwọn ọmọ wọn àti àwọn arákùnrin wọn ló wọ aṣọ àtàtà, síńbálì* wà lọ́wọ́ wọn àti àwọn ohun ìkọrin olókùn tín-ín-rín àti háàpù; wọ́n dúró sí apá ìlà oòrùn pẹpẹ, àwọn pẹ̀lú ọgọ́fà (120) àlùfáà tó ń fun kàkàkí.+ 13 Gbàrà tí àwọn tó ń fun kàkàkí àti àwọn akọrin bẹ̀rẹ̀ sí í yin Jèhófà, tí wọ́n sì ń dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀ pẹ̀lú ohùn tó ṣọ̀kan, tí ìró kàkàkí àti síńbálì pẹ̀lú àwọn ohun ìkọrin míì ń dún sókè bí wọ́n ṣe ń yin Jèhófà, “nítorí ó jẹ́ ẹni rere; ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ sì wà títí láé,”+ ni ìkùukùu+ bá kún inú ilé náà, ìyẹn ilé Jèhófà. 14 Àwọn àlùfáà kò lè dúró ṣe iṣẹ́ wọn nítorí ìkùukùu náà, torí pé ògo Jèhófà kún inú ilé Ọlọ́run tòótọ́.+
-