-
2 Àwọn Ọba 22:11-13Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
11 Gbàrà tí ọba gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ inú ìwé Òfin náà, ó fa aṣọ rẹ̀ ya.+ 12 Ọba wá pa àṣẹ yìí fún àlùfáà Hilikáyà, Áhíkámù+ ọmọ Ṣáfánì, Ákíbórì ọmọ Mikáyà, Ṣáfánì akọ̀wé àti Ásáyà ìránṣẹ́ ọba pé: 13 “Ẹ lọ wádìí lọ́dọ̀ Jèhófà nítorí tèmi àti nítorí àwọn èèyàn yìí àti nítorí gbogbo Júdà nípa àwọn ọ̀rọ̀ inú ìwé tí a rí yìí; torí ìbínú Jèhófà tó ń jó bí iná lórí wa kò kéré,+ nítorí àwọn baba ńlá wa kò tẹ̀ lé àwọn ọ̀rọ̀ inú ìwé yìí láti ṣe gbogbo ohun tó wà lákọsílẹ̀ fún wa.”
-