3 “Mo bẹ̀ ọ́, Jèhófà, jọ̀ọ́ rántí+ bí mo ṣe fi òtítọ́ àti gbogbo ọkàn mi rìn níwájú rẹ,+ ohun tó dáa ní ojú rẹ sì ni mo ṣe.” Hẹsikáyà sì bẹ̀rẹ̀ sí í sunkún pẹ̀rẹ̀pẹ̀rẹ̀.
16 Ní àkókò yẹn, àwọn tó bẹ̀rù Jèhófà bá ara wọn sọ̀rọ̀, kálukú pẹ̀lú ẹnì kejì rẹ̀, Jèhófà sì ń fiyè sí i, ó sì ń fetí sílẹ̀. Wọ́n sì kọ ìwé ìrántí kan níwájú rẹ̀+ torí àwọn tó ń bẹ̀rù Jèhófà àti àwọn tó ń ṣe àṣàrò lórí orúkọ rẹ̀.*+