-
Ẹ́kísódù 20:8-11Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
8 “Máa rántí ọjọ́ Sábáàtì, kí o lè yà á sí mímọ́.+ 9 Ọjọ́ mẹ́fà ni kí o fi ṣiṣẹ́, kí o sì fi ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ,+ 10 àmọ́ ọjọ́ keje jẹ́ sábáàtì fún Jèhófà Ọlọ́run rẹ. O ò gbọ́dọ̀ ṣiṣẹ́ kankan, ìwọ àti ọmọkùnrin rẹ àti ọmọbìnrin rẹ àti ẹrúkùnrin rẹ àti ẹrúbìnrin rẹ àti ẹran ọ̀sìn rẹ àti àjèjì tí ẹ jọ ń gbé.*+ 11 Torí ọjọ́ mẹ́fà ni Jèhófà fi dá ọ̀run àti ayé, òkun àti gbogbo ohun tó wà nínú wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í sinmi ní ọjọ́ keje.+ Ìdí nìyẹn tí Jèhófà fi bù kún ọjọ́ Sábáàtì, tó sì yà á sí mímọ́.
-
-
Diutarónómì 5:12-14Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
12 “‘Máa pa ọjọ́ Sábáàtì mọ́, kí o lè yà á sí mímọ́, bí Jèhófà Ọlọ́run rẹ ṣe pa á láṣẹ fún ọ gẹ́lẹ́.+ 13 Ọjọ́ mẹ́fà ni kí o fi ṣiṣẹ́, kí o sì fi ṣe gbogbo iṣẹ́ rẹ,+ 14 àmọ́ ọjọ́ keje jẹ́ sábáàtì fún Jèhófà Ọlọ́run rẹ.+ O ò gbọ́dọ̀ ṣiṣẹ́ kankan,+ ìwọ àti ọmọkùnrin rẹ àti ọmọbìnrin rẹ àti ẹrúkùnrin rẹ àti ẹrúbìnrin rẹ àti akọ màlúù rẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ àti èyíkéyìí nínú ẹran ọ̀sìn rẹ àti àjèjì tó ń gbé nínú àwọn ìlú* rẹ,+ kí ẹrúkùnrin rẹ àti ẹrúbìnrin rẹ lè sinmi bíi tìẹ.+
-