- 
	                        
            
            2 Sámúẹ́lì 16:5-7Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
- 
                            - 
                                        5 Nígbà tí Ọba Dáfídì dé Báhúrímù, ọkùnrin ará ilé Sọ́ọ̀lù kan tó ń jẹ́ Ṣíméì+ ọmọ Gérà jáde wá, ó sì ń ṣépè bí ó ṣe ń bọ̀.+ 6 Ó ń sọ òkúta lu Dáfídì àti gbogbo ìránṣẹ́ Ọba Dáfídì àti gbogbo àwọn èèyàn náà títí kan àwọn alágbára ọkùnrin tó wà lápá ọ̀tún àti lápá òsì rẹ̀. 7 Bí Ṣíméì ṣe ń ṣépè ló ń sọ pé: “Kúrò níbí, kúrò níbí, ìwọ apààyàn aláìníláárí yìí! 
 
- 
                                        
- 
	                        
            
            Sáàmù 69:4Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
- 
                            - 
                                        Àwọn tó fẹ́ pa mí, Àwọn oníbékebèke tí wọ́n jẹ́ ọ̀tá mi* ti pọ̀ gan-an. Àwọn nǹkan tí mi ò jí ni wọ́n ní kí n dá pa dà tipátipá. 
 
-