13 Nítorí náà, Dáfídì sọ fún Gádì pé: “Ọ̀rọ̀ yìí kó ìdààmú bá mi gan-an. Jọ̀ọ́, jẹ́ kí n ṣubú sí ọwọ́ Jèhófà, nítorí àánú rẹ̀ pọ̀ gidigidi;+ ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí n ṣubú sí ọwọ́ èèyàn.”+
11 Ẹ wò ó! A ka àwọn tó ní ìfaradà sí aláyọ̀.*+ Ẹ ti gbọ́ nípa ìfaradà Jóòbù,+ ẹ sì ti rí ibi tí Jèhófà* jẹ́ kó yọrí sí,+ pé Jèhófà* ní ìfẹ́ oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́ tó pọ̀ gan-an,* ó sì jẹ́ aláàánú.+