-
Ẹ́sítà 1:10-12Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
10 Ní ọjọ́ keje, nígbà tí wáìnì ń mú inú ọba dùn,* ó sọ fún Méhúmánì, Bísítà, Hábónà,+ Bígítà, Ábágítà, Sétárì àti Kákásì, àwọn òṣìṣẹ́ méje tó wà láàfin tí wọ́n jẹ́ ẹmẹ̀wà* Ọba Ahasuérúsì fúnra rẹ̀, 11 pé kí wọ́n lọ mú Fáṣítì Ayaba wá síwájú ọba pẹ̀lú ìwérí ayaba* lórí rẹ̀, láti fi ẹwà rẹ̀ han àwọn èèyàn àti àwọn ìjòyè, nítorí ó lẹ́wà gan-an. 12 Ṣùgbọ́n Fáṣítì Ayaba kọ̀, kò wá ní gbogbo ìgbà tí àwọn òṣìṣẹ́ ààfin wá jíṣẹ́ ọba fún un. Nítorí náà, inú bí ọba gidigidi, ó sì gbaná jẹ.
-