5 “Tí ọkùnrin kan bá ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó, kò gbọ́dọ̀ dara pọ̀ mọ́ àwọn ọmọ ogun, wọn ò sì gbọ́dọ̀ yan àwọn iṣẹ́ míì fún un. Kó wà lómìnira fún ọdún kan, kó sì dúró sílé kó lè máa múnú ìyàwó rẹ̀ dùn.+
9 Máa gbádùn ayé rẹ pẹ̀lú aya rẹ ọ̀wọ́n+ ní gbogbo ọjọ́ ayé asán rẹ, tí Ó fún ọ lábẹ́ ọ̀run,* ní gbogbo ọjọ́ ayé asán rẹ, torí ìyẹn ni ìpín rẹ nígbèésí ayé àti nínú iṣẹ́ àṣekára rẹ, èyí tí ò ń fi gbogbo agbára rẹ ṣe lábẹ́ ọ̀run.+