-
Jẹ́nẹ́sísì 13:8, 9Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
8 Ábúrámù wá sọ fún Lọ́ọ̀tì+ pé: “Jọ̀ọ́, kò yẹ kí ìjà wáyé láàárín èmi àti ìwọ àti láàárín àwọn tó ń da ẹran mi àti àwọn tó ń da ẹran rẹ, torí arákùnrin ni wá. 9 Ṣebí gbogbo ilẹ̀ ló wà níwájú rẹ yìí? Jọ̀ọ́, jẹ́ ká lọ lọ́tọ̀ọ̀tọ̀. Tí o bá lọ sí apá òsì, èmi á lọ sí apá ọ̀tún; àmọ́ tí o bá lọ sí apá ọ̀tún, èmi á lọ sí apá òsì.”
-
-
1 Sámúẹ́lì 25:23, 24Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
23 Nígbà tí Ábígẹ́lì tajú kán rí Dáfídì, ní kíá ó sọ̀ kalẹ̀ lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó kúnlẹ̀, ó sì dojú bolẹ̀ níwájú Dáfídì. 24 Ó kúnlẹ̀ síbi ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì sọ pé: “Olúwa mi, jẹ́ kí ẹ̀bi náà wà lórí mi; jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ bá ọ sọ̀rọ̀, kí o sì fetí sí ọ̀rọ̀ tí ìránṣẹ́bìnrin rẹ fẹ́ sọ.
-