-
1 Sámúẹ́lì 8:1-3Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
-
-
8 Nígbà tí Sámúẹ́lì darúgbó, ó yan àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ láti máa ṣe onídàájọ́ Ísírẹ́lì. 2 Orúkọ ọmọkùnrin rẹ̀ àkọ́bí ni Jóẹ́lì, orúkọ èkejì sì ni Ábíjà;+ wọ́n jẹ́ onídàájọ́ ní Bíá-ṣébà. 3 Àmọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ kò tẹ̀ lé àpẹẹrẹ rẹ̀; ọkàn wọn ń fà sí jíjẹ èrè tí kò tọ́,+ wọ́n ń gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀,+ wọ́n sì ń yí ìdájọ́ po.+
-