ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Mátíù 4:13-16
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 13 Bákan náà, lẹ́yìn tó kúrò ní Násárẹ́tì, ó wá lọ ń gbé ní Kápánáúmù + lẹ́gbẹ̀ẹ́ òkun ní agbègbè Sébúlúnì àti Náfútálì, 14 kí ohun tí a sọ nípasẹ̀ wòlíì Àìsáyà lè ṣẹ, ẹni tó sọ pé: 15 “Ìwọ ilẹ̀ Sébúlúnì àti ilẹ̀ Náfútálì, ní ojú ọ̀nà òkun, ní òdìkejì Jọ́dánì, Gálílì àwọn orílẹ̀-èdè! 16 Àwọn èèyàn tó jókòó sínú òkùnkùn rí ìmọ́lẹ̀ tó mọ́lẹ̀ yòò, ní ti àwọn tó jókòó sí agbègbè òjìji ikú, ìmọ́lẹ̀+ tàn sórí wọn.”+

  • Lúùkù 1:78, 79
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 78 torí ojú àánú Ọlọ́run wa. Pẹ̀lú àánú yìí, ojúmọ́ kan máa mọ́ wa láti ibi gíga, 79 láti fún àwọn tó jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú ní ìmọ́lẹ̀,+ kó sì darí ẹsẹ̀ wa ní ọ̀nà àlàáfíà.”

  • Lúùkù 2:30-32
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 30 torí ojú mi ti rí ohun tí o máa fi gbani là,+ 31 èyí tí o pèsè níṣojú gbogbo èèyàn,+ 32 ìmọ́lẹ̀+ láti mú ìbòjú kúrò lójú àwọn orílẹ̀-èdè+ àti ògo àwọn èèyàn rẹ Ísírẹ́lì.”

  • Jòhánù 1:9
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 9 Ìmọ́lẹ̀ tòótọ́ tó ń fún onírúurú èèyàn ní ìmọ́lẹ̀ máa tó wá sí ayé.+

  • Jòhánù 8:12
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
    • 8 12 Jésù tún sọ fún wọn pé: “Èmi ni ìmọ́lẹ̀ ayé.+ Ó dájú pé ẹnikẹ́ni tó bá ń tẹ̀ lé mi kò ní rìn nínú òkùnkùn, àmọ́ ó máa ní ìmọ́lẹ̀+ ìyè.”

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́